< 2 Kings 3 >
1 Jehoramu ọmọ Ahabu sì di ọba Israẹli ní Samaria ní ọdún kejìdínlógún ti Jehoṣafati ọba Juda, ó sì jẹ ọba fún ọdún méjìlá.
Jórám pedig, az Akháb fia kezde uralkodni Izráelen Samariában Josafátnak, a Júda királyának tizennyolczadik esztendejében, és uralkodék tizenkét esztendeig.
2 Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe bí ti ìyá àti baba rẹ̀ ti ṣe. Ó gbé òkúta ère ti Baali tí baba rẹ̀ ti ṣe kúrò.
És gonoszul cselekedék az Úrnak szemei előtt, de nem annyira, mint az ő atyja és anyja; mert elrontá a Baál képét, a melyet az ő atyja készíttetett volt.
3 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó fi ara mọ́ ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó ti fi Israẹli bú láti dẹ́ṣẹ̀; kò sì yí kúrò lọ́dọ̀ wọn.
De mindazáltal követé Jeroboámnak, a Nébát fiának bűneit, a ki vétekbe ejtette volt az Izráelt, és el nem távozék azoktól.
4 Nísinsin yìí Meṣa ọba Moabu ń sin àgùntàn, ó sì gbọdọ̀ fi fún ọba Israẹli pẹ̀lú ọ̀kẹ́ márùn-ún ọ̀dọ́-àgùntàn àti pẹ̀lú irun ọ̀kẹ́ márùn-ún àgbò.
És Mésának, a Moáb királyának nagyon sok juha volt, és az Izráel királyának adóban százezer bárány és százezer kos gyapját fizette.
5 Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ikú Ahabu, ọba Moabu ṣọ̀tẹ̀ lórí ọba Israẹli.
De mikor meghalt Akháb, a Moáb királya elszakadt az Izráel királyától.
6 Lásìkò ìgbà yìí ọba Jehoramu jáde kúrò ní Samaria ó sì yí gbogbo Israẹli ní ipò padà.
Kiméne azért Jórám király azon a napon Samariából, és megszámlálá az egész Izráelt;
7 Ó sì ránṣẹ́ yìí sí Jehoṣafati ọba Juda pé, “Ọba Moabu sì ṣọ̀tẹ̀ sí mi. Ṣé ìwọ yóò lọ pẹ̀lú mi láti lọ bá Moabu jà?” Ọba Juda sì dáhùn pé, “Èmi yóò lọ pẹ̀lú rẹ. Èmi jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti wà, ènìyàn rẹ bí ènìyàn mi, ẹṣin mi bí ẹṣin rẹ.”
És elméne, és külde követeket Josafáthoz, Júda királyához, ezt izenvén néki: A Moáb királya elszakadt tőlem; eljösz-é velem a Moáb ellen a hadba? Felele: Felmegyek, úgy én, mint te; úgy az én népem, mint a te néped; úgy az én lovam, mint a te lovaid.
8 “Nípa ọ̀nà wo ni àwa yóò gbà dojúkọ wọ́n?” Ó béèrè. “Lọ́nà aginjù Edomu,” ó dáhùn.
És monda: Mely úton menjünk fel? Felele: Az Edom pusztájának útján.
9 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli jáde lọ pẹ̀lú ọba Juda àti ọba Edomu. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n yíká fún ọjọ́ méje. Àwọn ọmọ-ogun wọn kò ní omi púpọ̀ fún ara wọn tàbí fún ẹranko tí ó wà pẹ̀lú wọn.
És elméne az Izráel királya és Júda királya és az Edom királya; és mikor hét napig bolyongtak az úton, nem volt vize sem a tábornak, sem a velök volt barmoknak.
10 “Kí ni?” ọba Israẹli kígbe sókè. “Ṣé Olúwa pe àwa ọba mẹ́tẹ̀ẹ̀ta papọ̀ láti fi wá lé Moabu lọ́wọ́?”
Akkor monda az Izráel királya: Jaj, jaj; az Úr azért hívta egybe e három királyt, hogy a Moáb kezébe adja őket!
11 Ṣùgbọ́n Jehoṣafati sì wí pé, “Ṣé kò sí wòlíì Olúwa níbí, tí àwa ìbá ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?” Ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ ọba Israẹli dáhùn pé, “Eliṣa ọmọ Ṣafati wà níbí. Ó máa sábà bu omi sí ọwọ́ Elijah.”
És monda Josafát: Nincs itt az Úr prófétái közül egy sem, hogy általa tanácsot kérhetnénk az Úrtól? És felele egy az Izráel királyának szolgái közül, és monda: Itt van Elizeus, a Sáfát fia, a ki Illésnek kezeire vizet tölt vala.
12 Jehoṣafati wí pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati àti ọba Edomu sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ lọ.
És monda Josafát: Nála van az Úrnak beszéde. És alámenének hozzá az Izráel királya és Josafát és az Edom királya.
13 Eliṣa wí fún ọba Israẹli pé, “Kí ni àwa ní ṣe pẹ̀lú ara wa? Lọ sọ́dọ̀ wòlíì baba rẹ àti wòlíì ti ìyá rẹ.” Ọba Israẹli dá a lóhùn, “Rárá, nítorí Olúwa ni ó pe àwa ọba mẹ́tẹ̀ẹ̀ta papọ̀ láti fi wá lé Moabu lọ́wọ́.”
És monda Elizeus az Izráel királyának: Mi közöm van hozzád? Menj a te atyádnak és anyádnak prófétáihoz! És monda néki az Izráel királya: Ne utasíts el; mert az Úr gyűjtötte össze ezt a három királyt, hogy a Moáb kezébe adja őket.
14 Eliṣa wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti wà pé Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà láyé, ẹni tí mo ń sìn tí èmi kò bá ní ọ̀wọ̀ fún ojú Jehoṣafati ọba Juda, èmi kò ní wò ó tàbí èmi kì bá ti rí ọ.
És monda Elizeus: Él a Seregek Ura, a ki előtt állok, ha nem nézném Josafátnak, a Júda királyának személyét, bizony téged nem néznélek, és rád sem tekintenék;
15 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, mú wá fún mi ohun èlò orin olókùn.” Nígbà tí akọrin náà n kọrin, ọwọ́ Olúwa wá sórí Eliṣa.
Hozzatok ide egy énekest. És mikor énekelt előtte az éneklő, az Úrnak keze lőn ő rajta.
16 Ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ‘Jẹ́ kí àfonífojì kún fún ọ̀gbun.’
És monda: Ezt mondja az Úr: Csináljatok itt és ott e patakon árkokat;
17 Nítorí èyí ni Olúwa wí, o kò ní í rí afẹ́fẹ́ tàbí òjò, bẹ́ẹ̀ ni àfonífojì yìí yóò kún pẹ̀lú omi, àti ìwọ àti ẹran ọ̀sìn àti pẹ̀lú àwọn ẹran yóò mu.
Mert ezt mondja az Úr: Nem láttok sem szelet, sem esőt, és mégis e patak megtelik vízzel, hogy ihattok mind ti, mind a ti nyájatok és barmaitok.
18 Èyí jẹ́ ohun tí kò lágbára níwájú Olúwa, yóò sì fi Moabu lé e yín lọ́wọ́ pẹ̀lú.
Kevés pedig még ez az Úr szemei előtt, hanem a Moábot is kezetekbe adja.
19 Ìwọ yóò sì bi gbogbo ìlú olódi àti gbogbo àgbà ìlú ṣubú. Ìwọ yóò sì gé gbogbo igi dáradára ṣubú, dá gbogbo orísun omi dúró, kí o sì pa gbogbo pápá dáradára pẹ̀lú òkúta run.”
És megvesztek minden kulcsos várost és minden szép várost, és minden jótermő fát kivagdaltok, és minden kútfőt betöltötök, és minden jó szántóföldet behánytok kövekkel.
20 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ní àsìkò ẹbọ, níbẹ̀ ni omí sàn láti ọ̀kánkán Edomu! Ilé náà sì kún pẹ̀lú omi.
És lőn reggel, a mikor áldozatot szoktak tenni, ímé vizek jőnek vala Edom útjáról, és megtelék a föld vízzel.
21 Nísinsin yìí gbogbo ará Moabu gbọ́ pé àwọn ọba tí dé láti bá wọn jà. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ènìyàn, ọmọdé àti àgbà tí ó lè ja ogun wọn pè wọ́n sókè wọ́n sì dúró ní etí ilẹ̀.
Mikor pedig meghallotta az egész Moáb, hogy feljöttek a királyok ő ellenök harczolni, egybegyűlének mindnyájan, a kik fegyvert foghattak, és megállottak az ő tartományuk határán.
22 Nígbà tí wọ́n dìde ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, oòrùn ti tàn sí orí omi náà sí àwọn ará Moabu ní ìkọjá ọ̀nà, omi náà sì pupa bí ẹ̀jẹ̀.
És mikor felkeltek reggel, és a nap feljött a vizekre, úgy láták a Moábiták, mintha ő ellenökbe az a víz vereslenék, mint a vér.
23 “Ẹ̀jẹ̀ ni èyí!” wọ́n wí pé, “Àwọn ọba wọ̀nyí lè ti jà kí wọn sì pa ara wọn ní ìpakúpa. Nísinsin yìí sí àwọn ìkógun Moabu!”
És mondának: Vér ez! Megvívtak a királyok egymással, és megölte egyik a másikát. Prédára most, Moáb!
24 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ará Moabu dé sí ibùdó ti Israẹli, àwọn ará Israẹli dìde, wọ́n sì kọlù wọ́n títí tí wọ́n fi sálọ. Àwọn ará Israẹli gbógun sí ilẹ̀ náà wọ́n sì pa Moabu run.
De mikor az Izráel táborához jutottak, felkeltek az Izráeliták, és megverték a Moábitákat, és azok megfutamodtak előttök; betörtek hozzájok és leverték Moábot.
25 Wọ́n sì wọ gbogbo ìlú náà olúkúlùkù ènìyàn, wọ́n ju òkúta sí gbogbo ohun dáradára orí pápá títí tí ó fi run. Wọ́n sì dá gbogbo orísun omi dúró wọ́n sì gé gbogbo orísun dáradára. Kiri-Hareseti nìkan ni wọ́n fi òkúta rẹ̀ sílẹ̀ ní ààyè rẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn ológun pẹ̀lú kànnàkànnà yíká, wọ́n sì kọlù ìlú náà.
És városaikat lerontották, és a jó szántóföldekre kiki követ hányt, és elborították azt kövekkel, és minden kútfőt behánytak, és minden jótermő fát kivágtak, úgy hogy csak Kir-Haréset kőfalait hagyták fenn; de körülvevék azt is a parittyások, és lerontották.
26 Nígbà tí ọba Moabu rí i wí pé ogun náà le ju ti òun lọ, ó mú idà pẹ̀lú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ọkùnrin onídà láti jà pẹ̀lú ọba Edomu, ṣùgbọ́n wọn kò yege.
Látván pedig a Moáb királya, hogy legyőzettetik a viadalban, maga mellé vett hétszáz fegyverfogó férfiút, hogy keresztül törjenek az Edom királyához; de nem bírtak.
27 Nígbà náà ó mú àkọ́bí ọmọkùnrin rẹ̀, tí kò bá jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọba, ó sì fi rú ẹbọ sísun ní orí ògiri ìlú. Wọ́n sì bínú lórí Israẹli púpọ̀púpọ̀; wọ́n yọ́ kúrò wọ́n sì padà sí ìlú wọn.
Akkor vevé az ő elsőszülött fiát, a ki ő helyette uralkodandó volt, és égőáldozatul megáldozá a kőfalon. Mely dolog felett az Izráel népe igen felháborodék, és elmenének onnét, és megtérének az ő földjökbe.