< 2 Kings 3 >

1 Jehoramu ọmọ Ahabu sì di ọba Israẹli ní Samaria ní ọdún kejìdínlógún ti Jehoṣafati ọba Juda, ó sì jẹ ọba fún ọdún méjìlá.
Judah siangpahrang Jehoshaphat a bawi kum 18 nah, Ahab capa Jehoram teh Isarelnaw lathueng Samaria vah siangpahrang lah ao teh kum 12 touh a uk.
2 Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe bí ti ìyá àti baba rẹ̀ ti ṣe. Ó gbé òkúta ère ti Baali tí baba rẹ̀ ti ṣe kúrò.
BAWIPA mithmu vah thoenae a sak. Hatei a manu hoi a na pa patetlah na hoeh. Bangkongtetpawiteh, a na pa ni Baal talung a ung e hah a tâkhawng.
3 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó fi ara mọ́ ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó ti fi Israẹli bú láti dẹ́ṣẹ̀; kò sì yí kúrò lọ́dọ̀ wọn.
Hateiteh, Isarelnaw e yonnae ka saksakkung Nebat capa Jeroboam, yonnae koe a bawk van teh, cettakhai hoeh.
4 Nísinsin yìí Meṣa ọba Moabu ń sin àgùntàn, ó sì gbọdọ̀ fi fún ọba Israẹli pẹ̀lú ọ̀kẹ́ márùn-ún ọ̀dọ́-àgùntàn àti pẹ̀lú irun ọ̀kẹ́ márùn-ún àgbò.
Moab siangpahrang Mesha teh tu ka khoum e doeh. Isarel siangpahrang koevah, tuca ting touh e muen hoi, tutan ting touh e muen hoi, kum tangkuem tamuk hah ouk a poe.
5 Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ikú Ahabu, ọba Moabu ṣọ̀tẹ̀ lórí ọba Israẹli.
Hatei Ahab a due hnukkhu teh, Moab siangpahrang teh Isarel siangpahrang koe taran lah a thaw.
6 Lásìkò ìgbà yìí ọba Jehoramu jáde kúrò ní Samaria ó sì yí gbogbo Israẹli ní ipò padà.
Hote atueng nah, siangpahrang Jehoram teh Samaria kho hoi a tâco teh Isarel taminaw pueng hah a pâkhueng.
7 Ó sì ránṣẹ́ yìí sí Jehoṣafati ọba Juda pé, “Ọba Moabu sì ṣọ̀tẹ̀ sí mi. Ṣé ìwọ yóò lọ pẹ̀lú mi láti lọ bá Moabu jà?” Ọba Juda sì dáhùn pé, “Èmi yóò lọ pẹ̀lú rẹ. Èmi jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti wà, ènìyàn rẹ bí ènìyàn mi, ẹṣin mi bí ẹṣin rẹ.”
A tâco teh, Judah siangpahrang Jehoshaphat koevah, Moab siangpahrang ni na tuk teh, Moabnaw heh na tuk khai ngai han na ou telah tami a patoun. Ahnimouh ni oe na tuk khai han bo khei, kai hoi nang, ka tami hoi na tami, teh buet touh lah o teh, ka marang hoi na marang buet touh lah doeh ao atipouh.
8 “Nípa ọ̀nà wo ni àwa yóò gbà dojúkọ wọ́n?” Ó béèrè. “Lọ́nà aginjù Edomu,” ó dáhùn.
Pawiteh, nâ lam hoi maw takhang han vaw telah ati. Edom kahrawng lam koehoi cei han atipouh.
9 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli jáde lọ pẹ̀lú ọba Juda àti ọba Edomu. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n yíká fún ọjọ́ méje. Àwọn ọmọ-ogun wọn kò ní omi púpọ̀ fún ara wọn tàbí fún ẹranko tí ó wà pẹ̀lú wọn.
Hot patetlah, Isarel siangpahrang teh, Judah siangpahrang hoi Edom siangpahrangnaw hoi a cei awh. Hnin sari touh thung lawngven laihoi a cei awh teh, ransanaw hoi saringnaw nei hane tui awm hoeh.
10 “Kí ni?” ọba Israẹli kígbe sókè. “Ṣé Olúwa pe àwa ọba mẹ́tẹ̀ẹ̀ta papọ̀ láti fi wá lé Moabu lọ́wọ́?”
Isarel siangpahrang ni Aiyoe! BAWIPA ni siangpahrang kathum touh heh, hete Moabnaw koe poe hanelah na ceikhai awh e han doeh toe telah ati.
11 Ṣùgbọ́n Jehoṣafati sì wí pé, “Ṣé kò sí wòlíì Olúwa níbí, tí àwa ìbá ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?” Ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ ọba Israẹli dáhùn pé, “Eliṣa ọmọ Ṣafati wà níbí. Ó máa sábà bu omi sí ọwọ́ Elijah.”
Hateiteh, Jehoshaphat ni, awi hi vah, BAWIPA koe na ka het pouh kung BAWIPA e profet apihai awm hoeh namaw telah ati. Isarel siangpahrang a san buet touh ni Elijah kut dawk tui ouk ka awi e Shaphat capa Elisha hah atu hi ao atipouh.
12 Jehoṣafati wí pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati àti ọba Edomu sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ lọ.
Jehoshaphat ni ahni koe BAWIPA e lawk ao telah ati. Hahoi teh Isarel siangpahrang hoi Jehoshaphat hoi Edom siangpahrang teh ahni koevah a cei awh.
13 Eliṣa wí fún ọba Israẹli pé, “Kí ni àwa ní ṣe pẹ̀lú ara wa? Lọ sọ́dọ̀ wòlíì baba rẹ àti wòlíì ti ìyá rẹ.” Ọba Israẹli dá a lóhùn, “Rárá, nítorí Olúwa ni ó pe àwa ọba mẹ́tẹ̀ẹ̀ta papọ̀ láti fi wá lé Moabu lọ́wọ́.”
Elisha ni Isarel siangpahrang koe nang hoi kai kâkuetnae bangmaw kaawm. Na pa profetnaw hoi na manu profetnaw koe cet awh khe atipouh. Hatei, Isarel siangpahrang ni ahni koe ka cet mahoeh. Bangkongtetpawiteh, siangpahrang kathum touh heh, Moabnaw kut dawk poe hane BAWIPA ni na kaw awh teh na pâkhueng awh e doeh telah ati.
14 Eliṣa wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti wà pé Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà láyé, ẹni tí mo ń sìn tí èmi kò bá ní ọ̀wọ̀ fún ojú Jehoṣafati ọba Juda, èmi kò ní wò ó tàbí èmi kì bá ti rí ọ.
Elisha ni, a hmalah ouk ka kangduenae ransahu BAWIPA a hring e patetlah Judah siangpahrang Jehoshaphat heh barilawa ka tawn hoehpawiteh nang koelah kamlang hoiyah hmu patenghai na hmawt ngai mahoeh ei.
15 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, mú wá fún mi ohun èlò orin olókùn.” Nígbà tí akọrin náà n kọrin, ọwọ́ Olúwa wá sórí Eliṣa.
Bangtelah nakunghai, ratoung ka kueng panuek e na kaw pouh awh telah ati. Hahoi ratoung ka kueng panuek e ni a kueng pouh torei teh, BAWIPA e kut teh a tak dawk a pha.
16 Ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ‘Jẹ́ kí àfonífojì kún fún ọ̀gbun.’
BAWIPA Cathut ni telah a dei. Hete a yawn heh tuikhu hoi kawi sak awh.
17 Nítorí èyí ni Olúwa wí, o kò ní í rí afẹ́fẹ́ tàbí òjò, bẹ́ẹ̀ ni àfonífojì yìí yóò kún pẹ̀lú omi, àti ìwọ àti ẹran ọ̀sìn àti pẹ̀lú àwọn ẹran yóò mu.
Bangkongtetpawiteh, BAWIPA ni telah a dei. Kahlî thoseh, kho ka rak e thoseh na hmawt awh mahoeh toe, hatei hete tangkom heh tui hoi koung akawi han. Hahoi teh, namamouh hoi na saringnaw, moithangnaw ni a nei thai awh han telah ati.
18 Èyí jẹ́ ohun tí kò lágbára níwájú Olúwa, yóò sì fi Moabu lé e yín lọ́wọ́ pẹ̀lú.
Hetheh BAWIPA han teh hno titca e doeh. Moabnaw hai na kut dawk na poe awh han.
19 Ìwọ yóò sì bi gbogbo ìlú olódi àti gbogbo àgbà ìlú ṣubú. Ìwọ yóò sì gé gbogbo igi dáradára ṣubú, dá gbogbo orísun omi dúró, kí o sì pa gbogbo pápá dáradára pẹ̀lú òkúta run.”
Kacakpounge khonaw pueng hoi khopui kahawinaw pueng haiyah, na raphoe vaiteh, thing kahawi naw pueng hai na tâtueng awh han. Tuikhunaw pueng koung na paten awh vaiteh, hmuen kahawi naw pueng hah talung koung na paten awh han atipouh.
20 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ní àsìkò ẹbọ, níbẹ̀ ni omí sàn láti ọ̀kánkán Edomu! Ilé náà sì kún pẹ̀lú omi.
Hahoi a tangtho amom tavai thuengnae tueng navah, pouk laipalah Edom ram lahoi tui a lawng teh a ram teh tui yikkawi.
21 Nísinsin yìí gbogbo ará Moabu gbọ́ pé àwọn ọba tí dé láti bá wọn jà. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ènìyàn, ọmọdé àti àgbà tí ó lè ja ogun wọn pè wọ́n sókè wọ́n sì dúró ní etí ilẹ̀.
Moabnaw pueng ni ama tuk hanelah siangpahrang a kamthaw ti a panue navah, taran katukthai pueng a pâkhueng teh khori koevah sut a pawp awh.
22 Nígbà tí wọ́n dìde ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, oòrùn ti tàn sí orí omi náà sí àwọn ará Moabu ní ìkọjá ọ̀nà, omi náà sì pupa bí ẹ̀jẹ̀.
Hahoi teh, amom vah a thaw awh teh, kho a sei nah tui dawk khumbei a bet e hah, namran lahoi teh tui hah thi patetlah Moabnaw ni a hmu awh.
23 “Ẹ̀jẹ̀ ni èyí!” wọ́n wí pé, “Àwọn ọba wọ̀nyí lè ti jà kí wọn sì pa ara wọn ní ìpakúpa. Nísinsin yìí sí àwọn ìkógun Moabu!”
Ahnimanaw ni thi tangngak doeh toe. Siangpahrangnaw hah amamouh hoi amamouh a kâtuk awh teh, a kâthei awh mue toe, Moabnaw tho awh leih. A hnopainaw lawm awh lei sei a kâti awh.
24 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ará Moabu dé sí ibùdó ti Israẹli, àwọn ará Israẹli dìde, wọ́n sì kọlù wọ́n títí tí wọ́n fi sálọ. Àwọn ará Israẹli gbógun sí ilẹ̀ náà wọ́n sì pa Moabu run.
Isarelnaw e roenae hmuen koe a pha toteh, Isarelnaw a thaw awh teh, Moabnaw hah a tuk awh teh, koung a yawng awh. Moabnaw hah noenoe a thei awh teh, a ram totouh a pâlei awh.
25 Wọ́n sì wọ gbogbo ìlú náà olúkúlùkù ènìyàn, wọ́n ju òkúta sí gbogbo ohun dáradára orí pápá títí tí ó fi run. Wọ́n sì dá gbogbo orísun omi dúró wọ́n sì gé gbogbo orísun dáradára. Kiri-Hareseti nìkan ni wọ́n fi òkúta rẹ̀ sílẹ̀ ní ààyè rẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn ológun pẹ̀lú kànnàkànnà yíká, wọ́n sì kọlù ìlú náà.
Khonaw a raphoe pouh awh teh hmuen kahawinaw pueng hai talung hoi a dei pouh awh teh talung muen akawi. Tuikhunaw pueng muen a paten pouh awh teh, thing kahawinaw pueng hai koung a tâtueng awh. Hatei, Kirhareseth, rapan tumdum e teh tek awh hoeh. Hatei, tâyai kathoumnaw ni, a kalup awh teh a tâ awh.
26 Nígbà tí ọba Moabu rí i wí pé ogun náà le ju ti òun lọ, ó mú idà pẹ̀lú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ọkùnrin onídà láti jà pẹ̀lú ọba Edomu, ṣùgbọ́n wọn kò yege.
Moab siangpahrang ni na tuknae heh ka khang thai mahoeh tie a panue toteh, Edom siangpahrang koe pou yawng takhai hanlah a kâcai teh, tahloi ka patuem e cum sari touh a ceikhai. Hatei tapoung thai awh hoeh.
27 Nígbà náà ó mú àkọ́bí ọmọkùnrin rẹ̀, tí kò bá jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọba, ó sì fi rú ẹbọ sísun ní orí ògiri ìlú. Wọ́n sì bínú lórí Israẹli púpọ̀púpọ̀; wọ́n yọ́ kúrò wọ́n sì padà sí ìlú wọn.
Hahoi teh a camin ama yueng lah ka bawi hane hah rapan van vah, hmaisawi thuengnae lah a hno teh, Isarel taranlahoi lungkuephoehnae haw vah ao. Hottelah a ban takhai awh teh, amamae ram dawk a ban awh.

< 2 Kings 3 >