< 2 Kings 3 >

1 Jehoramu ọmọ Ahabu sì di ọba Israẹli ní Samaria ní ọdún kejìdínlógún ti Jehoṣafati ọba Juda, ó sì jẹ ọba fún ọdún méjìlá.
Judah manghai Jehoshaphat kah kum hlai rhet dongah Ahab capa Jehoram loh Samaria ah Israel a manghai thil tih kum hlai nit manghai.
2 Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe bí ti ìyá àti baba rẹ̀ ti ṣe. Ó gbé òkúta ère ti Baali tí baba rẹ̀ ti ṣe kúrò.
Tedae a manu a napa bang lamtah BOEIPA mikhmuh ah boethae a saii moenih. A napa loh a saii Baal kah kaam te khaw a khoe pah.
3 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó fi ara mọ́ ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó ti fi Israẹli bú láti dẹ́ṣẹ̀; kò sì yí kúrò lọ́dọ̀ wọn.
Israel aka tholh sak Nebat capa Jeroboam kah tholhnah dongah balak tih te lamloh nong pawh.
4 Nísinsin yìí Meṣa ọba Moabu ń sin àgùntàn, ó sì gbọdọ̀ fi fún ọba Israẹli pẹ̀lú ọ̀kẹ́ márùn-ún ọ̀dọ́-àgùntàn àti pẹ̀lú irun ọ̀kẹ́ márùn-ún àgbò.
Te vaengah Moab manghai Mesha tah saelhung boei la om tih Israel manghai te tuca thawng yakhat, tutal thawng yakhat mul neh a thuung.
5 Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ikú Ahabu, ọba Moabu ṣọ̀tẹ̀ lórí ọba Israẹli.
Tedae Ahab a duek van neh Moab manghai loh Israel manghai taengah boe a koek.
6 Lásìkò ìgbà yìí ọba Jehoramu jáde kúrò ní Samaria ó sì yí gbogbo Israẹli ní ipò padà.
Manghai Jehoram tah amah khohnin ah Samaria lamloh cet tih Israel pum te a soep.
7 Ó sì ránṣẹ́ yìí sí Jehoṣafati ọba Juda pé, “Ọba Moabu sì ṣọ̀tẹ̀ sí mi. Ṣé ìwọ yóò lọ pẹ̀lú mi láti lọ bá Moabu jà?” Ọba Juda sì dáhùn pé, “Èmi yóò lọ pẹ̀lú rẹ. Èmi jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti wà, ènìyàn rẹ bí ènìyàn mi, ẹṣin mi bí ẹṣin rẹ.”
Cet tih Judah manghai Jehoshaphat taengla ol a pat vaengah, “Moab manghai loh kai taengah boe a koek coeng dongah Moab te caemtloek thil ham kai taengla na lo aya?” a ti nah. Te vaengah, “Ka lo ni, kai khaw nang banghui, ka pilnam khaw na pilnam banghui, ka marhang khaw na marhang banghui ni,” a ti nah.
8 “Nípa ọ̀nà wo ni àwa yóò gbà dojúkọ wọ́n?” Ó béèrè. “Lọ́nà aginjù Edomu,” ó dáhùn.
Te phoeiah, “Longpuei he me long nim n'caeh eh?” a ti nah vaengah, “Edom khosoek longpuei ah,” a ti nah.
9 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli jáde lọ pẹ̀lú ọba Juda àti ọba Edomu. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n yíká fún ọjọ́ méje. Àwọn ọmọ-ogun wọn kò ní omi púpọ̀ fún ara wọn tàbí fún ẹranko tí ó wà pẹ̀lú wọn.
Te dongah Israel manghai neh Judah manghai khaw, Edom manghai khaw cet uh tih hnin rhih longcaeh hil a hil uh vaengah tah lambong ham neh a kho kung kah rhamsa ham khaw tui om pawh.
10 “Kí ni?” ọba Israẹli kígbe sókè. “Ṣé Olúwa pe àwa ọba mẹ́tẹ̀ẹ̀ta papọ̀ láti fi wá lé Moabu lọ́wọ́?”
Israel manghai loh, “Ya-oe Manghai pathum he Moab kut ah tloeng ham nim BOEIPA loh n'khue dae,” a ti.
11 Ṣùgbọ́n Jehoṣafati sì wí pé, “Ṣé kò sí wòlíì Olúwa níbí, tí àwa ìbá ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?” Ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ ọba Israẹli dáhùn pé, “Eliṣa ọmọ Ṣafati wà níbí. Ó máa sábà bu omi sí ọwọ́ Elijah.”
Tedae Jehoshaphat loh, “Heah he BOEIPA kah tonghma a om moenih a? Anih lamloh BOEIPA te n'dawt lah mako,” a ti nah. Israel manghai kah sal pakhat loh a doo tih, “Shaphat capa Elisha, Elijah kut dongah tui a bueih te heah om,” a ti nah.
12 Jehoṣafati wí pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati àti ọba Edomu sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ lọ.
Te vaengah Jehoshaphat loh, “Anih taengah BOEIPA ol om,” a ti. Te dongah a taengla Israel manghai neh Jehoshaphat khaw, Edom manghai khaw suntla uh.
13 Eliṣa wí fún ọba Israẹli pé, “Kí ni àwa ní ṣe pẹ̀lú ara wa? Lọ sọ́dọ̀ wòlíì baba rẹ àti wòlíì ti ìyá rẹ.” Ọba Israẹli dá a lóhùn, “Rárá, nítorí Olúwa ni ó pe àwa ọba mẹ́tẹ̀ẹ̀ta papọ̀ láti fi wá lé Moabu lọ́wọ́.”
Elisha loh Israel manghai taengah, “Kai taeng neh nang taengah balae aka om? Na pa kah tonghma rhoek neh na nu kah tonghma rhoek taengah cet,” a ti nah. Tedae anih te Israel manghai loh, “Pawh, Moab kut ah tloeng hamla he manghai pathum he BOEIPA loh a khue,” a ti nah.
14 Eliṣa wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti wà pé Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà láyé, ẹni tí mo ń sìn tí èmi kò bá ní ọ̀wọ̀ fún ojú Jehoṣafati ọba Juda, èmi kò ní wò ó tàbí èmi kì bá ti rí ọ.
Elisha loh, “Caempuei BOEIPA kah hingnah bangla amah mikhmuh ah ni ka pai. Judah manghai Jehoshaphat kah maelhmai pawt koinih kai loh nang kan hinyah venim. Nang te kanpaelki pawt vetih nang te kan hmu pawt mako.
15 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, mú wá fún mi ohun èlò orin olókùn.” Nígbà tí akọrin náà n kọrin, ọwọ́ Olúwa wá sórí Eliṣa.
Tedae rhotoeng aka tum mah kai taengla hang khuen uh laeh,” a ti nah. Rhotoeng aka tum loh a tum van neh BOEIPA kut te anih sola cet coeng.
16 Ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ‘Jẹ́ kí àfonífojì kún fún ọ̀gbun.’
Te dongah, “BOEIPA loh he ni a thui. Soklong he tuito, tuito kak la om saeh.
17 Nítorí èyí ni Olúwa wí, o kò ní í rí afẹ́fẹ́ tàbí òjò, bẹ́ẹ̀ ni àfonífojì yìí yóò kún pẹ̀lú omi, àti ìwọ àti ẹran ọ̀sìn àti pẹ̀lú àwọn ẹran yóò mu.
He he BOEIPA loh a thui coeng dongah, khohli na hmu uh pawt tih khonal na hmuh uh pawt cakhaw, soklong he tui bae vetih namamih neh na boiva neh na rhamsa neh na ok uh bitni.
18 Èyí jẹ́ ohun tí kò lágbára níwájú Olúwa, yóò sì fi Moabu lé e yín lọ́wọ́ pẹ̀lú.
He he BOEIPA mik ah yoeikoek mai, Moab te na kut dongah m'paek ni.
19 Ìwọ yóò sì bi gbogbo ìlú olódi àti gbogbo àgbà ìlú ṣubú. Ìwọ yóò sì gé gbogbo igi dáradára ṣubú, dá gbogbo orísun omi dúró, kí o sì pa gbogbo pápá dáradára pẹ̀lú òkúta run.”
Khopuei hmuencak boeih neh khopuei tung boeih te na tloek uh vetih thing then boeih te na hum uh ni. Tuisih tui boeih te na mak uh vetih lo then boeih te lungto neh thak na khoeih sak uh bitni.
20 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ní àsìkò ẹbọ, níbẹ̀ ni omí sàn láti ọ̀kánkán Edomu! Ilé náà sì kún pẹ̀lú omi.
Mincang a pha tih khocang a nawn ham vaengah tah Edom longpuei lamloh tui tarha long tih khohmuen ah tui bae.
21 Nísinsin yìí gbogbo ará Moabu gbọ́ pé àwọn ọba tí dé láti bá wọn jà. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ènìyàn, ọmọdé àti àgbà tí ó lè ja ogun wọn pè wọ́n sókè wọ́n sì dúró ní etí ilẹ̀.
Amih taengah vathoh ham manghai rhoek a caeh te Moab pum loh a yaak vaengah cihin aka yen thai neh a so hang boeih te a khue tih khorhi ah pai uh.
22 Nígbà tí wọ́n dìde ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, oòrùn ti tàn sí orí omi náà sí àwọn ará Moabu ní ìkọjá ọ̀nà, omi náà sì pupa bí ẹ̀jẹ̀.
Mincang a thoh uh vaengah tah khomik loh tui soah a thoeng pah tih Moab loh tui te thii bangla a ling la a hmuh phai.
23 “Ẹ̀jẹ̀ ni èyí!” wọ́n wí pé, “Àwọn ọba wọ̀nyí lè ti jà kí wọn sì pa ara wọn ní ìpakúpa. Nísinsin yìí sí àwọn ìkógun Moabu!”
Te dongah, “Manghai rhoek a khah la khah uh thae kah thii ni he, hlang loh a hui khaw a ngawn coeng tih Moab kah kutbuem la om coeng,” a ti uh.
24 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ará Moabu dé sí ibùdó ti Israẹli, àwọn ará Israẹli dìde, wọ́n sì kọlù wọ́n títí tí wọ́n fi sálọ. Àwọn ará Israẹli gbógun sí ilẹ̀ náà wọ́n sì pa Moabu run.
Israel caem te a paan uh dongah Israel te thoo tih Moab te a ngawn. Te dongah amih mikhmuh lamloh rhaelrham uh coeng dae a pawk nah kungah khaw Moab te a ngawn la a ngawn uh.
25 Wọ́n sì wọ gbogbo ìlú náà olúkúlùkù ènìyàn, wọ́n ju òkúta sí gbogbo ohun dáradára orí pápá títí tí ó fi run. Wọ́n sì dá gbogbo orísun omi dúró wọ́n sì gé gbogbo orísun dáradára. Kiri-Hareseti nìkan ni wọ́n fi òkúta rẹ̀ sílẹ̀ ní ààyè rẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn ológun pẹ̀lú kànnàkànnà yíká, wọ́n sì kọlù ìlú náà.
Khopuei rhoek te a koengloeng uh tih lo then boeih khaw hlang loh lungto a voeih tih a kuk thiluh. Tuisih tui boeih te a mak uh. Kirhareseth ah lungto bueng a sueng hil thing then te boeih a hum uh. Tedae payai aka pom rhoek loh a vael uh tih a ngawn uh.
26 Nígbà tí ọba Moabu rí i wí pé ogun náà le ju ti òun lọ, ó mú idà pẹ̀lú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ọkùnrin onídà láti jà pẹ̀lú ọba Edomu, ṣùgbọ́n wọn kò yege.
Caemtloek loh amah a et te Moab manghai loh a hmuh vaengah amah taengkah cunghang aka pom hlang ya rhih te a khuen tih Edom manghai te a va dae coeng thai pawh.
27 Nígbà náà ó mú àkọ́bí ọmọkùnrin rẹ̀, tí kò bá jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọba, ó sì fi rú ẹbọ sísun ní orí ògiri ìlú. Wọ́n sì bínú lórí Israẹli púpọ̀púpọ̀; wọ́n yọ́ kúrò wọ́n sì padà sí ìlú wọn.
Te dongah amah yueng aka manghai ham a capa caming te a loh tih vongtung dongah hmueihhlutnah la a khuen. Israel soah a thinhul bat doela a taeng lamloh nong uh tih amah kho la mael uh.

< 2 Kings 3 >