< 2 Kings 25 >

1 Nígbà tí ó di ọdún kẹsànán ìjọba Sedekiah. Ní ọjọ́ kẹwàá oṣù kẹwàá, Nebukadnessari ọba Babeli yan lọ sí Jerusalẹmu pẹ̀lú gbogbo àwọn ogun rẹ̀. Ó sì pàgọ́ sí ìta ìlú ó sì mu àwọn iṣẹ́ ìdọ̀tí fi yí gbogbo rẹ̀ ká.
Nĩ ũndũ ũcio, mwaka-inĩ wa kenda wa ũthamaki wa Zedekia, mũthenya wa ikũmi, wa mweri wa ikũmi, Nebukadinezaru mũthamaki wa Babuloni agĩthiĩ kũhũũrana na Jerusalemu arĩ na ita rĩake rĩothe. Nake akĩamba hema nja ya itũũra rĩu inene, na agĩaka indo cia kũmũteithia gũtharĩkĩra itũũra mĩena yothe yarĩo.
2 Ìlú náà sì wà ní ìhámọ́ lábẹ́ ìgbóguntì títí di ọdún kọkànlá ti ọba Sedekiah.
Narĩo itũũra rĩkĩrigiicĩrio nginya mwaka wa ikũmi na ũmwe wa Mũthamaki Zedekia.
3 Nígbà tí ó di ọjọ́ kẹsànán oṣù kẹrin, ìyàn tí mú ní ìlú tí ó jẹ́ wí pé kò sí oúnjẹ fún àwọn ènìyàn láti jẹ.
Na rĩrĩ, mũthenya wa kenda wa mweri wa kana, ngʼaragu ĩkĩneneha itũũra-inĩ, o nginya gũkĩaga irio cia kũrĩĩo nĩ andũ.
4 Nígbà náà odi ìlú náà sì fọ́nká, gbogbo àwọn ọmọ-ogun sálọ ní òru láti ẹnu-ọ̀nà bodè láàrín ògiri méjì ní ẹgbẹ́ ọgbà ọba, àwọn ará Babeli wọ́n sì yí ìlú náà ká. Wọ́n sálọ sí ìkọjá Arabah.
Hĩndĩ ĩyo rũthingo rwa itũũra rĩu inene rũkĩmomorwo, nayo mbũtũ yothe ya ita ĩkĩũra ũtukũ ĩgereire kĩhingo-inĩ kĩrĩa kĩarĩ gatagatĩ ga thingo cierĩ hakuhĩ na mũgũnda wa mũthamaki, o na gũtuĩka andũ a Babuloni nĩmarigiicĩirie itũũra rĩu inene. Nayo ĩkĩũra ĩrorete Araba,
5 Ṣùgbọ́n ogun àwọn ará Kaldea sì lépa ọba, wọ́n sì lé e bá ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jeriko. Gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sì yà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ̀, wọ́n sì túká,
no mbũtũ ya ita ya Babuloni ĩgĩtengʼeria mũthamaki, ĩkĩmũkinyĩra werũ-inĩ ũrĩa mwaraganu wa Jeriko. Thigari ciake ciothe nĩciamũranĩtio nake na ikahurunjũka.
6 wọ́n sì mú un. Wọ́n sì mú lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Babeli ní Ribla, níbi tí à ti ṣe ìdájọ́ lórí rẹ̀.
Nayo mbũtũ ya ita ĩkĩnyiita mũthamaki ũcio, na agĩtwarwo kũrĩ mũthamaki wa Babuloni kũu Ribila kũrĩa aatuĩrĩirwo ciira.
7 Wọ́n sì pa ọmọ Sedekiah níwájú rẹ̀, wọ́n sì yọ ojú rẹ̀ jáde, wọn dè é pẹ̀lú ẹ̀wọ̀n idẹ wọ́n sì gbe é lọ sí Babeli.
Makĩũraga ariũ a Zedekia o hau mbere yake, magĩcooka makĩmũkũũra maitho, makĩmuoha na bĩngũ cia gĩcango, na makĩmũtwara Babuloni.
8 Ní ọjọ́ keje ní oṣù karùn-ún, ní ọdún kọkàndínlógún ti Nebukadnessari ọba Babeli, Nebusaradani olórí ẹ̀ṣọ́, ìránṣẹ́ ọba Babeli wá sí Jerusalẹmu;
Mũthenya wa mũgwanja wa mweri wa ĩtano mwaka-inĩ wa ikũmi na kenda wa Nebukadinezaru mũthamaki wa Babuloni, Nebuzaradani mũnene wa arangĩri a mũthamaki, ndungata nene ya mũthamaki wa Babuloni, agĩũka Jerusalemu.
9 ó sì finá sí ilé Olúwa, ilé ọba àti gbogbo àwọn tí ó wà ní Jerusalẹmu àti gbogbo ilé ńlá ńlá ni ó dáná sun.
Agĩcina hekarũ ya Jehova, na nyũmba ya ũthamaki, o na nyũmba ciothe cia Jerusalemu. Agĩcina nyũmba yothe yarĩ ya bata.
10 Gbogbo àwọn ogun Babeli, tí ó wà lọ́dọ̀ olórí ẹ̀ṣọ́, wó ògiri tí ó yí Jerusalẹmu ká lulẹ̀.
Nayo mbũtũ yothe ya ita ya Babuloni, ĩtongoretio nĩ mũnene wa arangĩri a mũthamaki ĩkĩmomora thingo iria ciathiũrũrũkĩirie Jerusalemu.
11 Nebusaradani olórí ẹ̀ṣọ́ kó gbogbo àwọn tálákà àti gbogbo àwọn tí ó kù ní ìlú, ní ìgbèkùn lọ sí Babeli, pẹ̀lú àwọn tí ó ya lọ, tí ó sì ya tọ ọba Babeli lọ, àti ìyókù àwọn ènìyàn náà.
Nebuzaradani mũnene wa arangĩri nĩathaamirie andũ arĩa othe maatigaire kũu itũũra-inĩ inene, hamwe na kĩrĩndĩ kĩu kĩngĩ, na arĩa othe maathiĩte kũrĩ mũthamaki wa Babuloni.
12 Ṣùgbọ́n olórí ẹ̀ṣọ́ fi àwọn tálákà ènìyàn ilẹ̀ náà sílẹ̀ láti máa bojútó àjàrà àti láti máa ṣe aroko.
No mũnene ũcio wa ita agĩtigia andũ amwe a arĩa athĩĩni mũno a bũrũri ũcio, nĩguo marutage wĩra mĩgũnda-inĩ ya mĩthabibũ na mĩgũnda-inĩ ĩrĩa ĩngĩ.
13 Àwọn ará Babeli fọ́ ọ̀wọ̀n idẹ wọ̀n-ọn-nì àti àwọn ìjókòó wọ̀n-ọn-nì, àti agbada idẹ títóbi wọ̀n-ọn-nì tí ń bẹ ní ilé Olúwa, àwọn ará Babeli fọ́ túútúú, wọ́n sì kó idẹ náà lọ sí Babeli.
Andũ a Babuloni nĩmoinangire itugĩ cia gĩcango, na metha cia kũigĩrĩra indo, na Karia ga gĩcango, iria ciarĩ hekarũ-inĩ ya Jehova, na magĩkuua icango icio magĩcitwara Babuloni.
14 Wọ́n sì kó àwọn ìkòkò wọ̀n-ọn-nì, ọkọ́ wọ̀n-ọn-nì, ọ̀pá fìtílà wọ̀n-ọn-nì, síbí wọ̀n-ọn-nì àti gbogbo ohun èlò idẹ wọ̀n-ọn-nì tí wọ́n fi ṣiṣẹ́ lọ.
Ningĩ magĩkuua nyũngũ, na icakũri, na magathĩ ma gũtinia ndaambĩ, na mbakũri, na indo ciothe cia icango iria ciahũthagĩrwo wĩra-inĩ wa hekarũ, magĩthiĩ nacio.
15 Olórí ẹ̀ṣọ́ kó ohun ìfọnná wọ̀n-ọn-nì, àti ọpọ́n wọ̀n-ọn-nì, èyí tí wọ́n fi wúrà àti fàdákà ṣe lọ.
Mũnene ũcio wa thigari cia mũthamaki nĩakuuire ngĩo cia mwaki na mbakũri cia kũminjaminjĩria, iria ciothe ciathondeketwo na thahabu therie kana betha.
16 Àwọn ọ̀wọ́n méjì, agbada ńlá kan, àti ìjókòó wọ̀n-ọn-nì tí Solomoni ti ṣe fún ilé Olúwa, idẹ ni gbogbo ohun èló wọ̀nyí, ó ju èyí tí a lé wọ́n lọ.
Nakĩo gĩcango kuuma itugĩ iria igĩrĩ, na gĩa Karia, na kĩa makaari marĩa Solomoni aakĩte marĩ ma hekarũ ya Jehova, gĩtingĩathimĩkire nĩ kũingĩha.
17 Gíga ọ̀wọ́n kọ̀ọ̀kan jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ méjìdínlógún, àti ọnà-orí rẹ̀ idẹ ni: àti gíga ọnà-orí náà ni ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ta; àti iṣẹ́ híhun náà, àti àwọn pomegiranate tí ó wà lórí ọnà-orí náà yíká, gbogbo rẹ̀ ti idẹ ni: gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́n yìí sì ni ọ̀wọ́n kejì pẹ̀lú iṣẹ́ híhun.
Gĩtugĩ o kĩmwe kĩarĩ kĩa ũraihu wa buti mĩrongo ĩĩrĩ na mũgwanja. Nakĩo kĩongo gĩakĩo kĩrĩa kĩarĩ igũrũ rĩa gĩtugĩ kĩmwe gĩacio kĩarĩ kĩa buti inya na nuthu kũraiha na igũrũ, na kĩagemetio na gĩgathiũrũrũkĩrio na mũkwa na makomamanga ma gĩcango. Gĩtugĩ kĩu kĩngĩ na mũkwa wakĩo nĩkĩahaanaine na kĩu kĩngĩ.
18 Olórí àwọn ẹ̀ṣọ́ sì mú gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́wọ̀n, Seraiah olórí àwọn àlùfáà, Sefaniah àlùfáà kejì, àti àwọn olùṣọ́ ìloro mẹ́ta.
Mũnene ũcio wa arangĩri nĩanyiitire Seraia mũthĩnjĩri-Ngai ũrĩa mũnene, na Zefania ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai wa keerĩ, na arangĩri arĩa atatũ maarangagĩra mĩrango.
19 Àti àwọn tí ó kù ní ìlú, ó mú ìwẹ̀fà kan tí ó fi se olórí àwọn ológun, àti ọkùnrin márùn-ún nínú àwọn tó ń gba ọba ní ìmọ̀ràn. Ó sì tún mú akọ̀wé olórí ogun, tí ó ń to àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà àti ọgọ́ta nínú àwọn ènìyàn rẹ̀ tí wọ́n rí ní ìlú.
Harĩ arĩa angĩ maatigaire kũu itũũra-inĩ inene, akĩnyiita mũnene ũrĩa warũgamĩrĩire andũ a mbaara, na andũ atano arĩa mataaraga mũthamaki. Ningĩ agĩkuua mwandĩki-marũa ũrĩa mũnene na nowe warĩ mũrori mũnene wa wandĩkithia wa andũ a bũrũri ũcio, na andũ ake mĩrongo ĩtandatũ arĩa maakorirwo itũũra-inĩ rĩu inene.
20 Nebusaradani, olórí àwọn ẹ̀ṣọ́ kó gbogbo wọn, ó sì mú wọn tọ ọba Babeli wá ní Ribla.
Nebuzaradani ũcio mũnene wa arangĩri akĩmakuua othe, akĩmatwara kũrĩ mũthamaki wa Babuloni kũu Ribila.
21 Níbẹ̀ ní Ribla, ní ilẹ̀ Hamati, ọba Babeli sì kọlù wọ́n. Bẹ́ẹ̀ ni a mú Juda kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀.
Nake mũthamaki wa Babuloni akĩmooragithĩria kũu Ribila, bũrũri wa Hamathu. Nĩ ũndũ ũcio andũ a Juda magĩtwarwo ithaamĩrio, kũraya na bũrũri wao.
22 Nebukadnessari ọba Babeli ó mú Gedaliah ọmọ Ahikamu ọmọ Ṣafani, láti jẹ baálẹ̀ lórí àwọn ènìyàn tí ó kù sílẹ̀ ní ilẹ̀ Juda.
Nebukadinezaru mũthamaki wa Babuloni agĩthuura Gedalia mũrũ wa Ahikamu, mũrũ wa Shafani akĩmũtua mũrori wa andũ arĩa maatigirwo Juda.
23 Nígbà tí gbogbo àwọn olórí ogun àti àwọn ọkùnrin wọn gbọ́ pé ọba Babeli ti yan Gedaliah gẹ́gẹ́ bí baálẹ̀, wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Gedaliah ni Mispa. Iṣmaeli ọmọ Netaniah, Johanani ọmọ Karea, Seraiah ọmọ Tanhumeti ará Netofa, Jaaṣaniah ọmọ ará Maakati, àti àwọn ọkùnrin wọn.
Rĩrĩa anene a mbũtũ cia ita othe na andũ ao maaiguire atĩ mũthamaki wa Babuloni nĩathuurĩte Gedalia atuĩke barũthi, magĩthiĩ kũrĩ Gedalia kũu Mizipa, nao nĩo, Ishumaeli mũrũ wa Nethania, na Johanani mũrũ wa Karea, na Seraia mũrũ wa Tanihumethu ũrĩa Mũnetofathi, na Jaazania mũrũ wa Mũmaakathi, na andũ ao.
24 Gedaliah sì búra láti fi dá àwọn ènìyàn rẹ̀ lójú. “Ẹ má ṣe bẹ̀rù àwọn ìjòyè ará Babeli,” ó wí pé, “Ẹ máa gbé ilẹ̀ náà kí ẹ sì sin ọba Babeli, yóò sì dára fún un yín.”
Gedalia akĩĩhĩta mwĩhĩtwa wa kũmoomĩrĩria hamwe na andũ ao, akĩmeera atĩrĩ, “Tigai gwĩtigĩra anene a Babuloni. Ikarai bũrũri-inĩ na mũtungatagĩre mũthamaki wa Babuloni, na nĩmũgũikara wega.”
25 Ní oṣù keje, ni Iṣmaeli ọmọ Netaniah, ọmọ Eliṣama, nínú irú-ọmọ ọba, wá pẹ̀lú àwọn ọkùnrin mẹ́wàá, ó sì kọlù Gedaliah àti pẹ̀lú àwọn ọkùnrin mẹ́wàá ará Juda àti àwọn ará Babeli tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ní Mispa.
No rĩrĩ, mweri-inĩ wa mũgwanja, Ishumaeli mũrũ wa Nethania, mũrũ wa Elishama ũrĩa warĩ wa thakame ya ũthamaki, agĩũka na andũ ikũmi, akĩũraga Gedalia o hamwe na andũ a Juda, na andũ a Babuloni arĩa maarĩ nake kũu Mizipa.
26 Nítorí èyí, gbogbo àwọn ènìyàn láti ẹni kékeré títí dé ẹni ńlá, àti pẹ̀lú àwọn olórí ogun, sálọ si Ejibiti nítorí ẹ̀rù àwọn ará Babeli.
Nĩ ũndũ wa ũguo andũ othe kuuma ũrĩa mũnini mũno nginya ũrĩa mũnene mũno, hamwe na atongoria a mbũtũ cia ita, makĩũrĩra Misiri nĩ ũndũ wa gwĩtigĩra andũ a Babuloni.
27 Ní ọdún kẹtàdínlógójì ìgbèkùn Jehoiakini ọba Juda, ní oṣù kejìlá, ọjọ́ kẹtàdínlógbọ̀n oṣù, Efili-Merodaki ọba Babeli, ní ọdún tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ní jọba, ó gbé orí Jehoiakini ọba Juda sókè, ó sì tú sílẹ̀ kúrò nínú túbú.
Mwaka-inĩ wa mĩrongo ĩtatũ na mũgwanja kuuma rĩrĩa Jehoiakini mũthamaki wa Juda aatwarirwo bũrũri ũngĩ, mwaka-inĩ o ũrĩa Evili-Merodaki aatuĩkire mũthamaki wa Babuloni, nĩ ohorithirie Jehoiakini kuuma njeera, mũthenya wa mĩrongo ĩĩrĩ na mũgwanja mweri-inĩ wa ikũmi na ĩĩrĩ.
28 Ó ń sọ̀rọ̀ rere fún un, ó sì gbé ìtẹ́ rẹ̀ ga ju ìtẹ́ àwọn ọba tókù lọ tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ní Babeli.
Akĩmwarĩria na ũhooreri na akĩmũhe gĩtĩ gĩa kũmũtĩĩithia gũkĩra athamaki acio angĩ maarĩ nao kũu Babuloni.
29 Ó sì pàrọ̀ àwọn aṣọ túbú rẹ̀, ó sì ń jẹun ní gbogbo ìgbà ní iwájú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.
Nĩ ũndũ ũcio Jehoiakini akĩruta nguo ciake cia njeera, na agĩtũũra arĩĩagĩra metha-inĩ ya mũthamaki matukũ mothe marĩa aatũũrire muoyo.
30 Ní ojoojúmọ́, ọba fún Jehoiakini ní ìpín tirẹ̀ bí ó tí ń bẹ láààyè.
Mũthamaki ũcio nĩaheaga Jehoiakini indo cia kũmũteithia cia o mũthenya, matukũ mothe marĩa aatũũrire muoyo.

< 2 Kings 25 >