< 2 Kings 25 >
1 Nígbà tí ó di ọdún kẹsànán ìjọba Sedekiah. Ní ọjọ́ kẹwàá oṣù kẹwàá, Nebukadnessari ọba Babeli yan lọ sí Jerusalẹmu pẹ̀lú gbogbo àwọn ogun rẹ̀. Ó sì pàgọ́ sí ìta ìlú ó sì mu àwọn iṣẹ́ ìdọ̀tí fi yí gbogbo rẹ̀ ká.
Or il arriva en la neuvième année du règne de Sédécias, au dixième jour, au dixième mois, que Nabuchodonosor, roi de Babylone, vint, lui et toute son armée, contre Jérusalem; et ils l’investirent, et y construisirent tout autour des fortifications.
2 Ìlú náà sì wà ní ìhámọ́ lábẹ́ ìgbóguntì títí di ọdún kọkànlá ti ọba Sedekiah.
Ainsi la ville fut enfermée et fortifiée jusqu’à la onzième année du roi Sédécias,
3 Nígbà tí ó di ọjọ́ kẹsànán oṣù kẹrin, ìyàn tí mú ní ìlú tí ó jẹ́ wí pé kò sí oúnjẹ fún àwọn ènìyàn láti jẹ.
Au neuvième jour du mois, et la famine régna dans la ville; et il n’y avait pas de pain pour le peuple du pays.
4 Nígbà náà odi ìlú náà sì fọ́nká, gbogbo àwọn ọmọ-ogun sálọ ní òru láti ẹnu-ọ̀nà bodè láàrín ògiri méjì ní ẹgbẹ́ ọgbà ọba, àwọn ará Babeli wọ́n sì yí ìlú náà ká. Wọ́n sálọ sí ìkọjá Arabah.
Et une brèche fut faite à la ville, et tous les hommes de guerre s’enfuirent durant la nuit, par la voie de la porte qui est entre le double mur près de la porte du jardin du roi (or les Chaldéens assiégeaient tout autour la ville): c’est pourquoi Sédécias s’enfuit par la voie qui conduit aux plaines du désert.
5 Ṣùgbọ́n ogun àwọn ará Kaldea sì lépa ọba, wọ́n sì lé e bá ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jeriko. Gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sì yà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ̀, wọ́n sì túká,
Et l’armée des Chaldéens poursuivit le roi, et le prit dans la plaine de Jéricho; et tous les combattants qui étaient avec lui furent dispersés et l’abandonnèrent.
6 wọ́n sì mú un. Wọ́n sì mú lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Babeli ní Ribla, níbi tí à ti ṣe ìdájọ́ lórí rẹ̀.
Ayant donc pris le roi, ils l’amenèrent au roi de Babylone à Réblatha, lequel prononça contre lui un arrêt.
7 Wọ́n sì pa ọmọ Sedekiah níwájú rẹ̀, wọ́n sì yọ ojú rẹ̀ jáde, wọn dè é pẹ̀lú ẹ̀wọ̀n idẹ wọ́n sì gbe é lọ sí Babeli.
Quant aux fils de Sédécias, il les tua devant lui, puis il lui creva les yeux, le chargea de chaînes et l’emmena à Babylone.
8 Ní ọjọ́ keje ní oṣù karùn-ún, ní ọdún kọkàndínlógún ti Nebukadnessari ọba Babeli, Nebusaradani olórí ẹ̀ṣọ́, ìránṣẹ́ ọba Babeli wá sí Jerusalẹmu;
Au cinquième mois, au septième jour du mois, c’est la dix-neuvième année même du roi de Babylone, Nabuzardan, chef d’armée, serviteur du roi de Babylone, vint à Jérusalem.
9 ó sì finá sí ilé Olúwa, ilé ọba àti gbogbo àwọn tí ó wà ní Jerusalẹmu àti gbogbo ilé ńlá ńlá ni ó dáná sun.
Et il brûla la maison du Seigneur et la maison du roi, et il consuma les maisons de Jérusalem, et toute espèce de maison.
10 Gbogbo àwọn ogun Babeli, tí ó wà lọ́dọ̀ olórí ẹ̀ṣọ́, wó ògiri tí ó yí Jerusalẹmu ká lulẹ̀.
Toute l’armée des Chaldéens, qui était avec ce chef de soldats, détruisit les murs de Jérusalem tout autour.
11 Nebusaradani olórí ẹ̀ṣọ́ kó gbogbo àwọn tálákà àti gbogbo àwọn tí ó kù ní ìlú, ní ìgbèkùn lọ sí Babeli, pẹ̀lú àwọn tí ó ya lọ, tí ó sì ya tọ ọba Babeli lọ, àti ìyókù àwọn ènìyàn náà.
Quant à l’autre partie du peuple qui était restée dans la ville, et aux transfuges qui avaient passé au roi de Babylone, et au reste du bas peuple, Nabuzardan, prince de la milice, les transporta à Babylone.
12 Ṣùgbọ́n olórí ẹ̀ṣọ́ fi àwọn tálákà ènìyàn ilẹ̀ náà sílẹ̀ láti máa bojútó àjàrà àti láti máa ṣe aroko.
Et il laissa d’entre les pauvres les vignerons et les laboureurs.
13 Àwọn ará Babeli fọ́ ọ̀wọ̀n idẹ wọ̀n-ọn-nì àti àwọn ìjókòó wọ̀n-ọn-nì, àti agbada idẹ títóbi wọ̀n-ọn-nì tí ń bẹ ní ilé Olúwa, àwọn ará Babeli fọ́ túútúú, wọ́n sì kó idẹ náà lọ sí Babeli.
Mais les colonnes d’airain qui étaient dans le temple du Seigneur, et les bases, et la mer d’airain qui était dans la maison du Seigneur, les Chaldéens les brisèrent, et ils transportèrent tout l’airain à Babylone.
14 Wọ́n sì kó àwọn ìkòkò wọ̀n-ọn-nì, ọkọ́ wọ̀n-ọn-nì, ọ̀pá fìtílà wọ̀n-ọn-nì, síbí wọ̀n-ọn-nì àti gbogbo ohun èlò idẹ wọ̀n-ọn-nì tí wọ́n fi ṣiṣẹ́ lọ.
Les marmites d’airain aussi, de même que les pelles, les tridents, les coupes, les petits mortiers, et tous les vases d’airain avec lesquels on faisait le service dans le temple, ils les emportèrent.
15 Olórí ẹ̀ṣọ́ kó ohun ìfọnná wọ̀n-ọn-nì, àti ọpọ́n wọ̀n-ọn-nì, èyí tí wọ́n fi wúrà àti fàdákà ṣe lọ.
Le prince de la milice emporta également les encensoirs et les patères, ce qui était d’or, à part, et ce qui était d’argent, à part.
16 Àwọn ọ̀wọ́n méjì, agbada ńlá kan, àti ìjókòó wọ̀n-ọn-nì tí Solomoni ti ṣe fún ilé Olúwa, idẹ ni gbogbo ohun èló wọ̀nyí, ó ju èyí tí a lé wọ́n lọ.
C’est-à-dire les deux colonnes, la mer et les bases qu’avait faites Salomon dans le temple du Seigneur; il n’y avait pas de poids pour l’airain de tous ces vases.
17 Gíga ọ̀wọ́n kọ̀ọ̀kan jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ méjìdínlógún, àti ọnà-orí rẹ̀ idẹ ni: àti gíga ọnà-orí náà ni ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ta; àti iṣẹ́ híhun náà, àti àwọn pomegiranate tí ó wà lórí ọnà-orí náà yíká, gbogbo rẹ̀ ti idẹ ni: gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́n yìí sì ni ọ̀wọ́n kejì pẹ̀lú iṣẹ́ híhun.
L’une des colonnes avait dix-huit coudées de hauteur, et le chapiteau d’airain de dessus, était de trois coudées de hauteur: et il y avait un réseau et des grenades sur le chapiteau de la colonne; le tout était d’airain: la seconde colonne aussi avait un semblable ornement.
18 Olórí àwọn ẹ̀ṣọ́ sì mú gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́wọ̀n, Seraiah olórí àwọn àlùfáà, Sefaniah àlùfáà kejì, àti àwọn olùṣọ́ ìloro mẹ́ta.
Le prince de la milice emmena aussi Saraïas, le premier prêtre, et Sophonias, second prêtre, et les trois portiers.
19 Àti àwọn tí ó kù ní ìlú, ó mú ìwẹ̀fà kan tí ó fi se olórí àwọn ológun, àti ọkùnrin márùn-ún nínú àwọn tó ń gba ọba ní ìmọ̀ràn. Ó sì tún mú akọ̀wé olórí ogun, tí ó ń to àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà àti ọgọ́ta nínú àwọn ènìyàn rẹ̀ tí wọ́n rí ní ìlú.
Et un eunuque de la ville qui commandait aux hommes de guerre, et cinq hommes qui étaient toujours devant le roi, qu’il trouva dans la ville, et Sopher, le prince de l’armée, qui exerçait les jeunes soldats pris d’entre le peuple du pays, et soixante hommes du bas peuple, qui avaient été trouvés dans la ville.
20 Nebusaradani, olórí àwọn ẹ̀ṣọ́ kó gbogbo wọn, ó sì mú wọn tọ ọba Babeli wá ní Ribla.
Nabuzardan, chef des soldats, les ayant pris, les amena au roi de Babylone à Réblatha.
21 Níbẹ̀ ní Ribla, ní ilẹ̀ Hamati, ọba Babeli sì kọlù wọ́n. Bẹ́ẹ̀ ni a mú Juda kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀.
Et le roi de Babylone les frappa et les tua à Réblatha, dans la terre d’Emath; ainsi Juda fut transféré hors de son pays,
22 Nebukadnessari ọba Babeli ó mú Gedaliah ọmọ Ahikamu ọmọ Ṣafani, láti jẹ baálẹ̀ lórí àwọn ènìyàn tí ó kù sílẹ̀ ní ilẹ̀ Juda.
Quant au peuple qui était resté dans la terre de Juda, qu’avait laissé Nabuchodonosor, roi de Babylone, il mit à sa tête Godolias, fils d’Ahicam, fils de Saphan.
23 Nígbà tí gbogbo àwọn olórí ogun àti àwọn ọkùnrin wọn gbọ́ pé ọba Babeli ti yan Gedaliah gẹ́gẹ́ bí baálẹ̀, wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Gedaliah ni Mispa. Iṣmaeli ọmọ Netaniah, Johanani ọmọ Karea, Seraiah ọmọ Tanhumeti ará Netofa, Jaaṣaniah ọmọ ará Maakati, àti àwọn ọkùnrin wọn.
Ce qu’ayant appris tous les chefs des soldats, eux et les hommes qui étaient avec eux, à savoir que le roi de Babylone avait établi Godolias pour gouverneur, Ismaël, fils de Nathanias, Johanan, fils de Carée, et Saraïa, fils de Thanéhumeth, le Nétophathite, et Jézonias, fils de Maachathi, vinrent vers Godolias à Maspha, eux et tous les leurs.
24 Gedaliah sì búra láti fi dá àwọn ènìyàn rẹ̀ lójú. “Ẹ má ṣe bẹ̀rù àwọn ìjòyè ará Babeli,” ó wí pé, “Ẹ máa gbé ilẹ̀ náà kí ẹ sì sin ọba Babeli, yóò sì dára fún un yín.”
Et Godolias leur jura, à eux et aux leurs, disant: Ne craignez point de servir les Chaldéens; demeurez dans cette terre, et servez le roi de Babylone, et vous serez bien.
25 Ní oṣù keje, ni Iṣmaeli ọmọ Netaniah, ọmọ Eliṣama, nínú irú-ọmọ ọba, wá pẹ̀lú àwọn ọkùnrin mẹ́wàá, ó sì kọlù Gedaliah àti pẹ̀lú àwọn ọkùnrin mẹ́wàá ará Juda àti àwọn ará Babeli tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ní Mispa.
Or il arriva, au septième mois après, qu’Ismaël, fils de Nathanias, fils d’Elisama, de la race royale, vint à Maspha, et dix hommes avec lui; et ils frappèrent Godolias, qui mourut, et aussi les Juifs et les Chaldéens qui étaient avec lui.
26 Nítorí èyí, gbogbo àwọn ènìyàn láti ẹni kékeré títí dé ẹni ńlá, àti pẹ̀lú àwọn olórí ogun, sálọ si Ejibiti nítorí ẹ̀rù àwọn ará Babeli.
Et se levant, tout le peuple, depuis le petit jusqu’au grand, et les chefs des soldats, vinrent en Egypte, craignant les Chaldéens.
27 Ní ọdún kẹtàdínlógójì ìgbèkùn Jehoiakini ọba Juda, ní oṣù kejìlá, ọjọ́ kẹtàdínlógbọ̀n oṣù, Efili-Merodaki ọba Babeli, ní ọdún tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ní jọba, ó gbé orí Jehoiakini ọba Juda sókè, ó sì tú sílẹ̀ kúrò nínú túbú.
Mais il arriva qu’en la trente-septième année de la captivité de Joachin, roi de Juda, au douzième mois, au vingt-septième jour du mois, Evilmérodach, roi de Babylone, en l’année même qu’il commença à régner tira Joachin, roi de Juda, de prison.
28 Ó ń sọ̀rọ̀ rere fún un, ó sì gbé ìtẹ́ rẹ̀ ga ju ìtẹ́ àwọn ọba tókù lọ tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ní Babeli.
Et il lui parla avec bonté, et il mit son trône au-dessus du trône des rois qui étaient auprès de lui à Babylone.
29 Ó sì pàrọ̀ àwọn aṣọ túbú rẹ̀, ó sì ń jẹun ní gbogbo ìgbà ní iwájú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.
Et il changea ses vêtements qu’il avait eus dans la prison; et Joachin mangea toujours du pain en sa présence tous les jour? de sa vie.
30 Ní ojoojúmọ́, ọba fún Jehoiakini ní ìpín tirẹ̀ bí ó tí ń bẹ láààyè.
Il lui assigna aussi sans interruption des vivres, qui même lui étaient donnés chaque jour par le roi, tous les jours de sa vie.