< 2 Kings 24 >

1 Nígbà ìjọba Jehoiakimu, Nebukadnessari ọba Babeli gbógun sí ilẹ̀ náà, Jehoiakimu sì di ẹrú rẹ̀ fún ọdún mẹ́ta. Ṣùgbọ́n nígbà náà ó yí ọkàn rẹ̀ padà ó sì ṣọ̀tẹ̀ sí Nebukadnessari.
Za jego dni wyruszył Nabuchodonozor, król Babilonu, i Joakim stał się jego sługą przez trzy lata. Potem zbuntował się przeciwko niemu.
2 Olúwa sì rán àwọn ará Babeli, àwọn ará Aramu, àwọn ará Moabu àti àwọn ọmọ Ammoni. Ó rán wọn láti pa Juda run, ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti sọ nípasẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wòlíì.
A PAN posłał przeciwko niemu oddziały Chaldejczyków, oddziały Syryjczyków, oddziały Moabitów i oddziały synów Ammona. Posłał ich na Judę, aby go zniszczyć zgodnie ze słowem PANA, które wypowiedział przez swoje sługi, proroków.
3 Nítòótọ́ eléyìí ṣẹlẹ̀ sí Juda gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa, láti mú wọn kúrò níwájú rẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ Manase àti gbogbo nǹkan tí ó ṣe.
Owszem, zgodnie z poleceniem PANA spotkało to Judę, aby odrzucić go sprzed jego oblicza za grzechy Manassesa, za to wszystko, co uczynił;
4 Àti pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ tí a ta sílẹ̀ nítorí ó ti kún Jerusalẹmu pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ tí Olúwa kò sì fẹ́ láti dáríjì.
A także za krew niewinną, którą przelał, bo napełnił Jerozolimę krwią niewinną, czego PAN nie chciał przebaczyć.
5 Ní ti ìyókù iṣẹ́ ìjọba Jehoiakimu, àti gbogbo nǹkan tí ó ṣe, ṣé wọn kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ọba Juda?
A pozostałe dzieje Joakima i wszystko, co czynił, czy nie są zapisane w księdze kronik królów Judy?
6 Jehoiakimu sùn pẹ̀lú baba rẹ̀, Jehoiakini ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
I Joakim zasnął ze swymi ojcami, a jego syn Joachin królował w jego miejsce.
7 Ọba Ejibiti kò sì tún jáde ní ìlú rẹ̀ mọ́, nítorí ọba Babeli ti gba gbogbo agbègbè rẹ̀ láti odò Ejibiti lọ sí odò Eufurate.
A król Egiptu już więcej nie wyruszał ze swojej ziemi, gdyż król Babilonu wziął [wszystko], co należało do króla Egiptu, od rzeki Egiptu aż do rzeki Eufrat.
8 Jehoiakini jẹ́ ẹni ọdún méjìdínlógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún oṣù mẹ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ a sì máa jẹ́ Nehuṣita ọmọbìnrin Elnatani; ó wá láti Jerusalẹmu.
Joachin miał osiemnaście lat, kiedy zaczął królować, i królował trzy miesiące w Jerozolimie. Jego matka [miała] na imię Nechuszta [i była] córką Elnatana z Jerozolimy.
9 Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ ti ṣe.
Czynił on to, co złe w oczach PANA, zupełnie tak, jak czynił jego ojciec.
10 Ní àkókò náà àwọn ìránṣẹ́ Nebukadnessari ọba Babeli gbé ogun wá Jerusalẹmu, wọ́n sì gbé dó ti ìlú náà,
W tym czasie słudzy Nabuchodonozora, króla Babilonu, wyruszyli przeciw Jerozolimie i przyszło do oblężenia miasta.
11 Nebukadnessari ọba Babeli fúnra rẹ̀ wá sókè sí ìlú nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ fi ogun dó tì í.
Potem sam Nabuchodonozor, król Babilonu, nadciągnął przeciw miastu, a jego słudzy je oblegali.
12 Jehoiakini ọba Juda àti ìyá rẹ̀ àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ìwẹ̀fà àti àwọn ìjòyè gbogbo wọn sì jọ̀wọ́ ara wọn fún un. Ní ọdún kẹjọ ìjọba rẹ̀ ti ọba Babeli ó mú Jehoiakini ẹlẹ́wọ̀n.
Wtedy Joachin, król Judy, wyszedł do króla Babilonu, on i jego matka, jego słudzy, jego książęta i jego dworzanie. I król Babilonu pojmał go w ósmym roku swego panowania.
13 Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ Nebukadnessari kó gbogbo ìṣúra láti inú ilé Olúwa àti láti ilé ọba, ó sì mú u lọ gbogbo ohun èlò wúrà ti Solomoni ọba Israẹli ti kọ́ fún Olúwa.
I wyniósł stamtąd wszystkie skarby domu PANA i skarby domu królewskiego i pokruszył wszystkie przedmioty złote, które wykonał Salomon, król Izraela, dla świątyni PANA, tak jak zapowiedział PAN.
14 Ó kó wọn lọ sí ìgbèkùn gbogbo Jerusalẹmu: gbogbo ìjòyè àti àwọn akọni alágbára ọkùnrin, àti gbogbo oníṣọ̀nà àti ọlọ́nà tí àpapọ̀ rẹ̀ jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá, àwọn tálákà ènìyàn ilẹ̀ náà nìkan ni ó kù.
I przesiedlił całą Jerozolimę: wszystkich książąt, wszystkich dzielnych wojowników – dziesięć tysięcy jeńców, oraz wszystkich rzemieślników i kowali. Nie pozostał nikt oprócz ubogiego ludu tej ziemi.
15 Nebukadnessari mú Jehoiakini ní ìgbèkùn lọ sí Babeli. Ó sì tún mú ìyá ọba láti Jerusalẹmu lọ sí Babeli, ìyàwó rẹ̀ àwọn ìjòyè rẹ̀ àti àwọn olórí ilé náà.
Przeniósł też do Babilonu Joachina. A także matkę króla, żony króla, jego dworzan i dostojników tej ziemi zabrał do niewoli z Jerozolimy do Babilonu.
16 Àti gbogbo àwọn ọkùnrin ọlọ́lá tí ó jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin alágbára ọkùnrin, àti àwọn oníṣọ̀nà àti alágbẹ̀dẹ, ẹgbẹ̀rún, gbogbo àwọn alágbára tí ó yẹ fún ogun ni ọba Babeli kó ní ìgbèkùn lọ sí Babeli.
Także wszystkich dzielnych mężów [w liczbie] siedmiu tysięcy, tysiąc rzemieślników i kowali oraz wszystkich zdolnych do walki – tych zabrał król Babilonu do niewoli do Babilonu.
17 Ọba Babeli sì mú Mattaniah arákùnrin baba Jehoiakini, jẹ ọba ní ìlú rẹ̀ ó sì yí orúkọ rẹ̀ padà sí Sedekiah.
W jego miejsce król Babilonu ustanowił królem jego stryja Mattaniasza i zmienił mu imię na Sedekiasz.
18 Sedekiah jẹ́ ẹni ọdún mọ́kànlélógún nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ṣe ìjọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlá. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Hamutali ọmọbìnrin Jeremiah; ó sì wá láti Libina.
Sedekiasz miał dwadzieścia jeden lat, kiedy zaczął królować, i królował jedenaście lat w Jerozolimie. Jego matka [miała] na imię Chamutal [i była] córką Jeremiasza z Libny.
19 Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí Jehoiakimu ti ṣe.
Czynił on to, co złe w oczach PANA, zupełnie tak, jak czynił Joakim.
20 Nítorí tí ìbínú Olúwa, ni gbogbo èyí ṣe ṣẹ sí Jerusalẹmu, àti Juda, ní òpin ó ta wọ́n nù kúrò níwájú rẹ̀. Nísinsin yìí Sedekiah sì ṣọ̀tẹ̀ sí ọba Babeli.
Z powodu gniewu PANA przyszło to na Jerozolimę i Judę, aż odrzucił ich sprzed swego oblicza. A Sedekiasz zbuntował się przeciw królowi Babilonu.

< 2 Kings 24 >