< 2 Kings 23 >

1 Nígbà náà ọba pe gbogbo àwọn àgbàgbà Juda àti Jerusalẹmu jọ.
Padixaⱨ adǝmlǝrni ǝwǝtip, Yǝⱨuda bilǝn Yerusalemning ⱨǝmmǝ aⱪsaⱪallirini ɵz ⱪexiƣa qaⱪirtip kǝldi.
2 Ó gòkè lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu, àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì—gbogbo àwọn ènìyàn láti ibi kéékèèké sí ńlá. Ó kà á sí etí ìgbọ́ ọ wọn, gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé májẹ̀mú, tí a ti rí nínú ilé Olúwa.
Padixaⱨ Pǝrwǝrdigarning ɵyigǝ qiⱪti; barliⱪ Yǝⱨudadiki ǝr kixilǝr wǝ Yerusalemda turuwatⱪanlarning ⱨǝmmisi, kaⱨinlar bilǝn pǝyƣǝmbǝrlǝr, yǝni barliⱪ hǝlⱪ, ǝng kiqikidin tartip qongiƣiqǝ ⱨǝmmisi uning bilǝn billǝ qiⱪti. Andin u Pǝrwǝrdigarning ɵyidǝ tepilƣan ǝⱨdǝ kitabining ⱨǝmmǝ sɵzlirini ularƣa oⱪup bǝrdi.
3 Ọba sì dúró lẹ́bàá òpó, ó sì sọ májẹ̀mú di tuntun níwájú Olúwa, láti tẹ̀lé Olúwa àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, ìlànà àti òfin pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀ àti gbogbo ẹ̀mí rẹ̀, àti láti ṣe ìwádìí àwọn ọ̀rọ̀ májẹ̀mú tí a kọ sínú ìwé yìí. Nígbà náà, gbogbo àwọn ènìyàn sì ṣèlérí fúnra wọn sí májẹ̀mú náà.
Padixaⱨ tüwrükning yenida turup Pǝrwǝrdigarning aldida: — Pǝrwǝrdigarƣa ǝgixip pütün ⱪǝlbim wǝ pütkül jenim bilǝn Uning ǝmrlirini, ⱨɵküm-guwaⱨliⱪliri wǝ bǝlgilimilirini tutup, uxbu kitabta pütülgǝn ǝⱨdigǝ ǝmǝl ⱪilimǝn dǝp ǝⱨdigǝ ɵzini baƣlidi. Xuning bilǝn hǝlⱪning ⱨǝmmisimu ǝⱨdǝ aldida turup uningƣa ɵzini baƣlidi.
4 Ọba sì pàṣẹ fún Hilkiah olórí àlùfáà àti àwọn, àlùfáà tí ó tẹ̀lé e ní ipò àti àwọn olùṣọ́nà láti yọ kúrò nínú ilé Olúwa gbogbo ohun èlò tí a ṣe fún Baali àti Aṣerah àti gbogbo ẹgbẹ́ ogun ọ̀run. Ó sì sun wọ́n ní ìta Jerusalẹmu ní pápá àfonífojì Kidironi. Ó sì kó eérú wọn jọ sí Beteli.
Andin keyin padixaⱨ bax kaⱨin Ⱨilⱪiya bilǝn orun basar kaⱨinlarƣa wǝ ⱨǝm dǝrwaziwǝnlǝrgǝ: — Baalƣa, Axǝraⱨ butiƣa wǝ asmanning barliⱪ ⱪoxuniƣa atap yasalƣan barliⱪ ǝswab-üskünilǝrni Pǝrwǝrdigarning ɵyidin qiⱪiriwetinglar, dǝp ǝmr ⱪildi; u bularni Yerusalemning sirtida, Kidron etizliⱪida kɵydürdi wǝ küllirini Bǝyt-Əlgǝ elip bardi.
5 Ó sì kúrò pẹ̀lú àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà tí a yàn láti ọwọ́ ọba Juda láti sun tùràrí ní ibi gíga ti ìlú Juda àti àwọn tí ó yí Jerusalẹmu ká. Àwọn tí ó ń sun tùràrí sí Baali, sí oòrùn àti òṣùpá, sí àwọn àmì ìràwọ̀ àti sí gbogbo ẹgbẹ́ ogun ọ̀run.
U Yǝⱨuda padixaⱨlirining Yǝⱨuda xǝⱨǝrliridiki «yuⱪiri jaylar»da ⱨǝmdǝ Yerusalemning ǝtrapliridiki «yuⱪiri jaylar»da huxbuy yanduruxⱪa tikligǝn but kaⱨinlirini, xuningdǝk Baalƣa, ⱪuyaxⱪa, ayƣa, yultuz türkümlirigǝ ⱨǝmdǝ asmanning barliⱪ ⱪoxuniƣa huxbuy yaⱪⱪuqilarni ixtin ⱨǝydiwǝtti.
6 Ó mú ère òrìṣà Aṣerah láti ilé Olúwa sí àfonífojì Kidironi ní ìta Jerusalẹmu, ó sì sun wọ́n níbẹ̀. Ó lọ̀ ọ́ bí àtíkè ó sì fọ́n eruku náà sórí isà òkú àwọn ènìyàn tí ó wọ́pọ̀.
U Pǝrwǝrdigarning ɵyidin Axǝraⱨ butni elip qiⱪip Yerusalemning sirtiƣa elip berip, Kidron jilƣisiƣa apirip xu yǝrdǝ kɵydürüp kukum-talⱪan ⱪilip ezip, topisini addiy puⱪralarning ⱪǝbriliri üstigǝ qeqiwǝtti.
7 Ó sì wó ibùgbé àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà lulẹ̀. Tí ó wà nínú ilé Olúwa àti ibi tí àwọn obìnrin tí ń ṣe iṣẹ́ aṣọ híhun fún òrìṣà Aṣerah.
Andin u Pǝrwǝrdigarning ɵyigǝ jaylaxⱪan bǝqqiwazlarning turalƣulirini qeⱪip ƣulatti; bu ɵylǝrdǝ yǝnǝ ayallar Axǝraⱨ butⱪa qedir toⱪuytti.
8 Josiah kó gbogbo àwọn àlùfáà láti àwọn ìlú Juda ó sì ba ibi mímọ́ wọ̀n-ọn-nì jẹ́ láti Geba sí Beerṣeba, níbi tí àwọn àlùfáà ti sun tùràrí. Ó wó àwọn ojúbọ lulẹ̀ ní ẹnu ìlẹ̀kùn—ní ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé ti Joṣua, baálẹ̀ ìlú ńlá tí ó wà ní apá òsì ẹnu ìlẹ̀kùn ìlú ńlá.
U Yǝⱨuda xǝⱨǝrliridin barliⱪ kaⱨinlarni qaⱪirtip, ɵzigǝ yiƣdi. Andin u Gǝbadin tartip Bǝǝr-Xebaƣiqǝ kaⱨinlar huxbuy yaⱪidiƣan «yuⱪiri jaylar»ni buzup bulƣiwǝtti; u «dǝrwazilardiki yuⱪiri jaylar»ni qeⱪip buzdi; bular «Xǝⱨǝr baxliⱪi Yǝxuaning ⱪuwiⱪi»ning yenida, yǝni xǝⱨǝr ⱪuwiⱪiƣa kirix yolining sol tǝripidǝ idi
9 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, àwọn àlùfáà ibi gíga kò jọ́sìn ní ibi pẹpẹ Olúwa ní Jerusalẹmu, wọ́n jẹ nínú àkàrà aláìwú pẹ̀lú àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn.
(ǝmdi «yuⱪiri jaylar»diki kaⱨinlarning Yerusalemda Pǝrwǝrdigarning ⱪurbangaⱨiƣa qiⱪixi qǝklǝngǝnidi; lekin ular dawamliⱪ ɵz ⱪerindaxliri bilǝn birgǝ pitir nanlardin yeyixigǝ muyǝssǝr idi).
10 Ó sì ba ohun mímọ́ Tofeti jẹ́, tí ó wà ní àfonífojì Beni-Hinnomu, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnìkan tí ó lè lò ó fún ẹbọ rírú fún ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tàbí ọmọ rẹ̀ obìnrin nínú iná sí Moleki.
Yosiya ⱨeqkim ɵz oƣli yaki ⱪizini Molǝkkǝ atap ottin ɵtküzmisun dǝp, Ⱨinnomning oƣlining jilƣisidiki Tofǝtnimu buzup bulƣiwǝtti.
11 Ó sì kúrò láti ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé sí ilé Olúwa, àwọn ẹṣin tí àwọn ọba Juda ti yà sọ́tọ̀ sí oòrùn náà. Wọ́n wà nínú ilé ẹjọ́ lẹ́bàá yàrá oníṣẹ́ tí orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Natani-Meleki. Josiah sì sun àwọn kẹ̀kẹ́ tí a yà sọ́tọ̀ fún oòrùn.
Pǝrwǝrdigarning ɵyigǝ kiridiƣan yolning eƣizida Yǝⱨuda padixaⱨliri ⱪuyaxⱪa tǝⱪdim ⱪilip ⱪoyƣan atlarni xu yǝrdin yɵtkǝp, «ⱪuyax ⱨarwiliri»ni otta kɵydürdi (ular [ibadǝthanining] ⱨoyliliriƣa jaylaxⱪan, Natan-Mǝlǝk degǝn aƣwatning ɵyining yenida turatti).
12 Ó wó o palẹ̀ pẹpẹ tí àwọn ọba Juda ti wọ́n gbé dúró ní orí òrùlé lẹ́bàá yàrá òkè ti Ahasi pẹ̀lú àwọn pẹpẹ tí Manase ti kọ́ nínú ilé ẹjọ́ méjèèjì sí ilé Olúwa. Ó ṣí wọn kúrò níbẹ̀, ó fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́. Ó sì da ekuru wọn sínú àfonífojì Kidironi.
Padixaⱨ yǝnǝ Yǝⱨuda padixaⱨliri Aⱨazning balihanisining ɵgzisidǝ saldurƣan ⱪurbangaⱨlarni wǝ Manassǝⱨ Pǝrwǝrdigarning ɵyining ikki ⱨoylisiƣa yasatⱪan ⱪurbangaⱨlarni qeⱪip kukum-talⱪan ⱪiliwǝtti; u ularning topisini u yǝrdin elip, Kidron jilƣisiƣa qeqiwǝtti.
13 Ọba pẹ̀lú ba ohun mímọ́ àwọn ibi gíga jẹ́ tí ó wà ní ìhà ìlà-oòrùn Jerusalẹmu ní ìhà gúúsù ti òkè ìbàjẹ́—èyí tí Solomoni ọba Israẹli ti kọ́ fún Aṣtoreti ọlọ́run ìríra àwọn ará Sidoni, fún Kemoṣi ọlọ́run ìríra àwọn ará Moabu àti fún Moleki, ọlọ́run ìríra àwọn ènìyàn Ammoni.
Israilning padixaⱨi Sulayman Yerusalemning mǝxriⱪ tǝripigǝ wǝ «Ⱨalak teƣi»ning jǝnubiƣa Zidoniylarning yirginqlik buti Axtarot, Moabiylarning yirginqlik buti Kemox wǝ Ammonlarning yirginqlik buti Milkomƣa atap yasatⱪan «yuⱪiri jaylar»nimu padixaⱨ buzup bulƣiwǝtti.
14 Josiah fọ́ òkúta yíyà sọ́tọ̀, ó sì gé ère Aṣerah lulẹ̀. Ó sì bo ẹ̀gbẹ̀gbẹ́ ẹ rẹ̀ pẹ̀lú egungun ènìyàn.
U but tüwrüklǝrni parqilap, Axǝraⱨ butlirini kesip yiⱪitip, ular turƣan yǝrlǝrni adǝm sɵngǝkliri bilǝn toldurdi.
15 Àní pẹpẹ tí ó wà ní Beteli ibi gíga tí Jeroboamu ọmọ Nebati dá. Tí ó ti fa Israẹli láti ṣẹ̀, àní pẹpẹ náà àti ibi gíga tí ó fọ́ túútúú. Ó jó àwọn ibi gíga, ó sì lọ̀ ọ́ sí ẹ̀tù, ó sì sun ère Aṣerah pẹ̀lú.
U yǝnǝ Israilni gunaⱨⱪa putlaxturƣan, Nibatning oƣli Yǝroboam Bǝyt-Əldǝ saldurƣan ⱪurbangaⱨ bilǝn «yuⱪiri jay»ni, ularni buzup qaⱪti, andin keyin «yuⱪiri jay»ni kɵydürüp kukum-talⱪan ⱪiliwǝtti, Axǝraⱨ butinimu kɵydürüwǝtti.
16 Nígbà náà, Josiah wò yíká, nígbà tí ó sì rí àwọn isà òkú tí ó wà níbẹ̀ ní ẹ̀bá òkè, ó yọ egungun kúrò lára wọn, ó sì jó wọn lórí pẹpẹ láti sọ ọ́ di èérí ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Olúwa tí a ti kéde láti ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run tí ó ti àwọn nǹkan wọ̀nyí tẹ́lẹ̀.
Yosiya burulup ⱪarap, taƣdiki ⱪǝbrilǝrni kɵrüp, adǝm ǝwǝtip ⱪǝbrilǝrdiki sɵngǝklǝrni kolap qiⱪirip, ⱪurbangaⱨ üstidǝ kɵydürdi, xu yol bilǝn uni bulƣiwǝtti. Bu ixlar Pǝrwǝrdigarning kalamini yǝtküzüp, dǝl ularni aldin’ala bexarǝt ⱪilip jakarliƣan Hudaning adimining sɵzining ǝmǝlgǝ axuruluxi idi.
17 Ọba sì béèrè pé, “Kí ni ọwọ̀n isà òkú yẹn tí mo rí?” Àwọn ọkùnrin ìlú ńlá wí pé, “Ó sàmì sí isà òkú ènìyàn Ọlọ́run tí ó wá láti Juda, tí ó sì kéde ìdojúkọ pẹpẹ Beteli, ohun kan wọ̀nyí tí ìwọ ti ṣe sí wọn.”
Andin Yosiya: Kɵz aldimdiki bu ⱪǝbrǝ texi kimning? — dǝp soridi. Xǝⱨǝrdikilǝr uningƣa: Bu Yǝⱨudadin kǝlgǝn, silining Bǝyt-Əldiki ⱪurbangaⱨni buzƣan muxu ixlirini bexarǝt ⱪilƣan Hudaning adimining ⱪǝbrisi ikǝn, dedi.
18 “Fi sílẹ̀ nìkan,” Ó wí pé. “Má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni ó da àwọn egungun rẹ̀ láàmú.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n dá egungun rẹ̀ sí àti ti àwọn wòlíì tí ó wá láti Samaria.
Yosiya: — Uni ⱪoyunglar, ⱨeqkim uning sɵngǝklirini midirlatmisun, dǝp buyrudi. Xuning bilǝn ular uning sɵngǝkliri bilǝn Samariyǝdin kǝlgǝn pǝyƣǝmbǝrning sɵngǝklirigǝ ⱨeqkimni tǝgküzmidi.
19 Gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ní Beteli, Josiah sì kúrò, ó sì ba gbogbo ojúbọ òrìṣà ti ibi gíga jẹ́, tí àwọn ọba Israẹli ti kọ́ sí àwọn ìlú ní Samaria, tí ó ti mú Olúwa bínú.
Andin Yosiya Israilning padixaⱨliri Pǝrwǝrdigarning ƣǝzipini ⱪozƣiƣan, Samariyǝning xǝⱨǝrliridǝ yasatⱪan «yuⱪiri jaylar»diki barliⱪ ɵylǝrni qaⱪti; u ularni Bǝyt-Əldǝ ⱪilƣandǝk ⱪilip, yoⱪatti.
20 Josiah dúńbú gbogbo àwọn àlùfáà ibi gíga lórí pẹpẹ. Ó sì sun egungun ènìyàn lórí wọn. Nígbà náà, ó padà lọ sí Jerusalẹmu.
U u yǝrlǝrdiki «yuⱪiri jaylar»ƣa has bolƣan ⱨǝmmǝ kaⱨinlarni ⱪurbangaⱨning üstidǝ ɵltürüp, ⱪurbanliⱪ ⱪildi, andin ularning üstigǝ adǝm sɵngǝklirini kɵydürdi; u ahirda Yerusalemƣa yenip bardi.
21 Ọba pàṣẹ fún gbogbo àwọn ènìyàn pé, “Ẹ ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá sí Olúwa Ọlọ́run yín, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sí inú ìwé májẹ̀mú yìí.”
Padixaⱨ barliⱪ hǝlⱪⱪǝ yarliⱪ qüxürüp: — Bu ǝⱨdǝ kitabida pütülgǝndǝk, Hudayinglar Pǝrwǝrdigarƣa «ɵtüp ketix ⱨeyti»ni ɵtküzünglar, dǝp buyrudi.
22 Kì í ṣe láti ọjọ́ àwọn Juda tí ó tọ́ Israẹli, ní gbogbo àwọn ọjọ́ àwọn ọba Israẹli àti àwọn ọba Juda. Ṣé wọ́n ti ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá rí.
«Batur ⱨakimlar» Israilning üstidin ⱨɵküm sürgǝn künlǝrdin tartip, nǝ Israil padixaⱨlirining waⱪitlirida nǝ Yǝⱨuda padixaⱨlirining waⱪitlirida undaⱪ bir «ɵtüp ketix ⱨeyti» ɵtküzülüp baⱪmiƣanidi;
23 Ṣùgbọ́n ní ọdún kejìdínlógún tí ọba Josiah, àjọ ìrékọjá yìí ni a ṣe ìrántí sí Olúwa ní Jerusalẹmu.
Yosiya padixaⱨning sǝltǝnitining on sǝkkizinqi yilida, Pǝrwǝrdigarƣa atap bu «ɵtüp ketix ⱨeyti» Yerusalemda ɵtküzüldi.
24 Síwájú sí, Josiah sì lé àwọn oṣó àti àwọn ẹ̀mí ní àwọn ìdílé, àti àwọn òrìṣà àti gbogbo àwọn nǹkan ìríra tí a rí ní Juda àti ní Jerusalẹmu. Èyí ni ó ṣe kí ó le è mú ọ̀rọ̀ òfin náà ṣe ní ti òfin tí a kọ sínú ìwé tí Hilkiah àlùfáà ti rí nínú ilé Olúwa.
Xuningdǝk Yosiya Yǝⱨuda yurtida wǝ Yerusalemda pǝyda bolƣan jinkǝxlǝr wǝ palqilarni, tǝrafim mǝbudliri, ⱨǝrⱪandaⱪ butlar wǝ barliⱪ baxⱪa lǝnǝtlik nǝrsilǝrni zemindin yoⱪatti. Uning xundaⱪ ⱪilixining mǝⱪsiti, Ⱨilⱪiya kaⱨin Pǝrwǝrdigarning ɵyidin tapⱪan kitabta hatirilǝngǝn Tǝwrattiki sɵzlǝrgǝ ǝmǝl ⱪilixtin ibarǝt idi.
25 Kò sì sí ọba kankan níwájú tàbí lẹ́yìn Josiah tí ó dàbí rẹ̀, tí ó yí padà sí olúwa tinútinú àti gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe tọkàntọkàn pẹ̀lú gbogbo ẹ̀mí i rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo agbára rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo òfin Mose.
Uningdǝk Musaƣa qüxürülgǝn ⱪanunƣa intilip pütün ⱪǝlbi, pütün jeni wǝ pütün küqi bilǝn Pǝrwǝrdigarƣa ⱪaytip, ɵzini beƣixliƣan bir padixaⱨ uningdin ilgiri bolmiƣanidi wǝ uningdin keyinmu uningƣa ohxax birsi bolup baⱪmidi.
26 Bí ó ti wù kí ó rí Olúwa kò yípadà kúrò nínú ìmúná ìbínú ńlá rẹ̀ tí ó jó sí Juda, nítorí gbogbo èyí tí Manase ti ṣe láti mú un bínú.
Lekin Pǝrwǝrdigarning aqqiⱪi Manassǝⱨning Ɵzini rǝnjitkǝn barliⱪ rǝzillikliri tüpǝylidin Yǝⱨudaƣa tutaxⱪandin keyin, Ɵzining xiddǝtlik ƣǝzipidin yanmidi.
27 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí pé, “Èmi yóò mú Juda kúrò pẹ̀lú níwájú mi, bí mo ti mú Israẹli, èmi yóò sì kó Jerusalẹmu, ìlú ńlá tí mo yàn àti ilé Olúwa yìí, nípa èyí tí mo sọ, ‘Níbẹ̀ ni orúkọ mi yóò wà?’”
Pǝrwǝrdigar: — Israilni taxliƣandǝk Yǝⱨudanimu Ɵz kɵzümdin neri ⱪilimǝn wǝ Ɵzüm talliƣan bu xǝⱨǝr Yerusalemni wǝ Mǝn: — «Mening namim xu yǝrdǝ bolidu» degǝn xu ibadǝthanini tǝrk ⱪilimǝn, dedi.
28 Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Josiah, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Juda?
Yosiyaning baxⱪa ǝmǝlliri ⱨǝm ⱪilƣanlirining ⱨǝmmisi «Yǝⱨuda padixaⱨlirining tarih-tǝzkiriliri» degǝn kitabta pütülgǝn ǝmǝsmidi?
29 Nígbà tí Josiah jẹ́ ọba, Farao Neko ọba Ejibiti gòkè lọ sí odò Eufurate láti lọ ran ọba Asiria lọ́wọ́. Ọba Josiah jáde lọ láti lọ bá a pàdé lójú ogun ṣùgbọ́n Neko dojúkọ ọ́, ó sì pa á ní Megido.
Uning künliridǝ Misirning padixaⱨi Pirǝwn-Nǝko Asuriyǝning padixaⱨiƣa ⱨujum ⱪilƣili Əfrat dǝryasiƣa bardi. U qaƣda Yosiya padixaⱨ Pirǝwn bilǝn soⱪuxuxⱪa qiⱪti; lekin Pirǝwn uni kɵrüp Mǝgiddoda uni ɵltürdi.
30 Ìránṣẹ́ Josiah gbé ara rẹ̀ wá nínú kẹ̀kẹ́ láti Megido sí Jerusalẹmu ó sì sin ín sínú isà òkú rẹ̀. Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà mú Jehoahasi ọmọ Josiah. Ó fi àmì òróró yàn án, ó sì ṣe é ní ọba ní ipò baba a rẹ̀.
Hizmǝtkarliri uning ɵlükini jǝng ⱨarwisiƣa selip Mǝgiddodin Yerusalemƣa elip kelip, uni ɵz ⱪǝbrisidǝ dǝpnǝ ⱪildi. Yurt hǝlⱪi Yosiyaning oƣli Yǝⱨoaⱨazni mǝsiⱨ ⱪilip, atisining ornida padixaⱨ ⱪildi.
31 Jehoahasi sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́tàlélógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún oṣù mẹ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Hamutali ọmọbìnrin Jeremiah; ó wá láti Libina.
Yǝⱨoaⱨaz padixaⱨ bolƣanda yigirmǝ üq yaxta bolup, üq ay Yerusalemda sǝltǝnǝt ⱪildi. Uning anisining ismi Ⱨamutal idi; u Libnaⱨliⱪ Yǝrǝmiyaning ⱪizi idi.
32 Ó ṣe búburú lójú Olúwa gẹ́gẹ́ bí baba a rẹ̀ ti ṣe.
Yǝⱨoaⱨaz bowiliri barliⱪ ⱪilƣanliridǝk, Pǝrwǝrdigarning nǝziridǝ rǝzil bolƣanni ⱪildi.
33 Farao Neko sì fi sí inú ìdè ní Ribla ní ilẹ̀ Hamati, kí ó má ba à lè jẹ ọba ní Jerusalẹmu. Ó sì tan Juda jẹ fun iye ìwọ̀n ẹgbẹ̀rin tálẹ́ǹtì wúrà kan.
Əmdi Pirǝwn-Nǝko uning Yerusalemda sǝltǝnǝt ⱪilmasliⱪi üqün, uni Hamat yurtidiki Riblaⱨda solap ⱪoydi wǝ [Yǝⱨuda] zeminiƣa yüz talant kümüx bilǝn bir talant altun seliⱪ qüxürdi.
34 Farao Neko ṣe Eliakimu ọmọ Josiah ní ọba ní ipò baba rẹ̀ Josiah. Ó sì yí orúkọ Eliakimu padà sí Jehoiakimu. Ṣùgbọ́n ó mú Jehoahasi, ó sì gbé e lọ sí Ejibiti, níbẹ̀ ni ó sì kú.
Andin Pirǝwn-Nǝko Yosiyaning oƣli Eliakimni atisining ornida padixaⱨ ⱪilip, ismini Yǝⱨoakimƣa ɵzgǝrtti. U Yǝⱨoaⱨazni ɵzi bilǝn Misirƣa elip kǝtti; Yǝⱨoaⱨaz Misirƣa kelip xu yǝrdǝ ɵldi.
35 Jehoiakimu sì san fún Farao Neko fàdákà àti wúrà tí ó béèrè. Láti ṣe bẹ́ẹ̀, ó bu owó òde fún ilẹ̀ náà láti san, ó fi agbára gba fàdákà àti wúrà láti ọwọ́ àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà ní ìbámu pẹ̀lú iye tí a pín.
Yǝⱨoakim kümüx bilǝn altunni Pirǝwngǝ bǝrdi; lekin Pirǝwnning xu buyruⱪini ijra ⱪilip pulni tapxurux üqün yurtⱪa ⱨǝrbir adǝmning qamiƣa ⱪarap baj-alwan ⱪoyƣanidi; altun wǝ kümüxni u yurtning hǝlⱪidin, ⱨǝrbirigǝ salƣan ɵlqǝm boyiqǝ Pirǝwn-Nǝkoƣa berixkǝ yiƣⱪanidi.
36 Jehoiakimu jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlá orúkọ ìyá rẹ̀ ni Sebida ọmọbìnrin Pedaiah ó wá láti Ruma.
Yǝⱨoakim padixaⱨ bolƣanda yigirmǝ bǝx yaxta bolup, on bir yil Yerusalemda sǝltǝnǝt ⱪildi. Uning anisining ismi Zibidaⱨ idi; u Rumaⱨliⱪ Pǝdayaning ⱪizi idi.
37 Ó sì ṣe búburú lójú Olúwa gẹ́gẹ́ bí baba a rẹ̀ ti ṣe.
Yǝⱨoakim bowiliri barliⱪ ⱪilƣanliridǝk Pǝrwǝrdigarning nǝziridǝ rǝzil bolƣanni ⱪilatti.

< 2 Kings 23 >