< 2 Kings 23 >

1 Nígbà náà ọba pe gbogbo àwọn àgbàgbà Juda àti Jerusalẹmu jọ.
Tedy posławszy król, aby się zebrali do niego wszyscy starsi Judzcy i Jeruzalemscy,
2 Ó gòkè lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu, àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì—gbogbo àwọn ènìyàn láti ibi kéékèèké sí ńlá. Ó kà á sí etí ìgbọ́ ọ wọn, gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé májẹ̀mú, tí a ti rí nínú ilé Olúwa.
Wstąpił król do domu Pańskiego, i wszyscy mężowie Judzcy, i wszyscy obywatele Jeruzalemscy z nim, i kapłani, i prorocy, i wszystek lud od małego aż do wielkiego; i czytał, gdzie wszyscy słyszeli wszystkie słowa ksiąg przymierza, które były znalezione w domu Pańskim.
3 Ọba sì dúró lẹ́bàá òpó, ó sì sọ májẹ̀mú di tuntun níwájú Olúwa, láti tẹ̀lé Olúwa àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, ìlànà àti òfin pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀ àti gbogbo ẹ̀mí rẹ̀, àti láti ṣe ìwádìí àwọn ọ̀rọ̀ májẹ̀mú tí a kọ sínú ìwé yìí. Nígbà náà, gbogbo àwọn ènìyàn sì ṣèlérí fúnra wọn sí májẹ̀mú náà.
Potem stanął król na majestacie, i uczynił przymierze przed Panem, że chce chodzić za Panem, i strzedz rozkazania jego, i świadectw jego, i wyroków jego ze wszystkiego serca, i ze wszystkiej duszy, i pełnić słowa przymierza tego, które były napisa ne w onych księgach. I przestał lud na onem przymierzu.
4 Ọba sì pàṣẹ fún Hilkiah olórí àlùfáà àti àwọn, àlùfáà tí ó tẹ̀lé e ní ipò àti àwọn olùṣọ́nà láti yọ kúrò nínú ilé Olúwa gbogbo ohun èlò tí a ṣe fún Baali àti Aṣerah àti gbogbo ẹgbẹ́ ogun ọ̀run. Ó sì sun wọ́n ní ìta Jerusalẹmu ní pápá àfonífojì Kidironi. Ó sì kó eérú wọn jọ sí Beteli.
I przykazał król Helkijaszowi, kapłanowi najwyższemu, i kapłanom wtórego rzędu, i odźwiernym, aby wyrzucili z kościoła Pańskiego wszystko naczynie, które sprawione było Baalowi, i gajowi poświęconemu, i wszystkiemu wojsku niebieskiemu, i spalił je precz za Jeruzalemem na polu Cedron, a zaniósł popiół ich do Betela.
5 Ó sì kúrò pẹ̀lú àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà tí a yàn láti ọwọ́ ọba Juda láti sun tùràrí ní ibi gíga ti ìlú Juda àti àwọn tí ó yí Jerusalẹmu ká. Àwọn tí ó ń sun tùràrí sí Baali, sí oòrùn àti òṣùpá, sí àwọn àmì ìràwọ̀ àti sí gbogbo ẹgbẹ́ ogun ọ̀run.
Złożył też z urzędu popów, których byli postanowili królowie Judzcy, aby kadzili po wyżynach w miastach Judzkich i około Jeruzalemu; przytem i onych, którzy kadzili Baalowi, słońcu i miesiącowi, i planetom, i wszystkiemu wojsku niebieskiemu.
6 Ó mú ère òrìṣà Aṣerah láti ilé Olúwa sí àfonífojì Kidironi ní ìta Jerusalẹmu, ó sì sun wọ́n níbẹ̀. Ó lọ̀ ọ́ bí àtíkè ó sì fọ́n eruku náà sórí isà òkú àwọn ènìyàn tí ó wọ́pọ̀.
Kazał też wynieść gaj święcony z domu Pańskiego precz z Jeruzalemu ku potokowi Cedron, a spalił go u potoku Cedron, i starł go w proch, a popiół jego rozmiotał na groby synów onegoż ludu.
7 Ó sì wó ibùgbé àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà lulẹ̀. Tí ó wà nínú ilé Olúwa àti ibi tí àwọn obìnrin tí ń ṣe iṣẹ́ aṣọ híhun fún òrìṣà Aṣerah.
Zburzył też domy Sodomczyków, które były w domu Pańskim, kędy niewiasty tkały opony do gaju poświęconego.
8 Josiah kó gbogbo àwọn àlùfáà láti àwọn ìlú Juda ó sì ba ibi mímọ́ wọ̀n-ọn-nì jẹ́ láti Geba sí Beerṣeba, níbi tí àwọn àlùfáà ti sun tùràrí. Ó wó àwọn ojúbọ lulẹ̀ ní ẹnu ìlẹ̀kùn—ní ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé ti Joṣua, baálẹ̀ ìlú ńlá tí ó wà ní apá òsì ẹnu ìlẹ̀kùn ìlú ńlá.
I zawołał wszystkich kapłanów z miast Judzkich, a splugawił wyżyny, na których kadzili, od Gabaa aż do Beerseba, i popsuł wyżyny przy bramach, które były w wejściu bramy Jozuego książęcia miasta, a było po lewej stronie wchodzącemu w bramę miejską.
9 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, àwọn àlùfáà ibi gíga kò jọ́sìn ní ibi pẹpẹ Olúwa ní Jerusalẹmu, wọ́n jẹ nínú àkàrà aláìwú pẹ̀lú àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn.
Wszakże nie przystępowali kapłani wyżyn do ołtarza Pańskiego w Jeruzalemie, ale jadali chleby przaśne między braćmi swoimi.
10 Ó sì ba ohun mímọ́ Tofeti jẹ́, tí ó wà ní àfonífojì Beni-Hinnomu, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnìkan tí ó lè lò ó fún ẹbọ rírú fún ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tàbí ọmọ rẹ̀ obìnrin nínú iná sí Moleki.
Splugawił też i Tofet, które było w dolinie syna Hennomowego, aby więcej nikt nie przewodził syna swego, ani córki swojej przez ogień ku czci Molochowi.
11 Ó sì kúrò láti ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé sí ilé Olúwa, àwọn ẹṣin tí àwọn ọba Juda ti yà sọ́tọ̀ sí oòrùn náà. Wọ́n wà nínú ilé ẹjọ́ lẹ́bàá yàrá oníṣẹ́ tí orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Natani-Meleki. Josiah sì sun àwọn kẹ̀kẹ́ tí a yà sọ́tọ̀ fún oòrùn.
Zagubił też one konie, które byli królowie Judzcy oddali słońcu, a stały, kędy wchodzą do domu Pańskiego, podle mieszkania Natanmelecha dworzanina, które było na przedmieściu; i wozy słońca spalił ogniem.
12 Ó wó o palẹ̀ pẹpẹ tí àwọn ọba Juda ti wọ́n gbé dúró ní orí òrùlé lẹ́bàá yàrá òkè ti Ahasi pẹ̀lú àwọn pẹpẹ tí Manase ti kọ́ nínú ilé ẹjọ́ méjèèjì sí ilé Olúwa. Ó ṣí wọn kúrò níbẹ̀, ó fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́. Ó sì da ekuru wọn sínú àfonífojì Kidironi.
Także ołtarze, które były na dachu sali Achazowej, które byli poczynili królowie Judzcy, i ołtarze, które był poczynił Manases w obu sieniach domu Pańskiego, pokaził król; a pospieszywszy się stamtąd kazał wrzucić proch ich w potok Cedron.
13 Ọba pẹ̀lú ba ohun mímọ́ àwọn ibi gíga jẹ́ tí ó wà ní ìhà ìlà-oòrùn Jerusalẹmu ní ìhà gúúsù ti òkè ìbàjẹ́—èyí tí Solomoni ọba Israẹli ti kọ́ fún Aṣtoreti ọlọ́run ìríra àwọn ará Sidoni, fún Kemoṣi ọlọ́run ìríra àwọn ará Moabu àti fún Moleki, ọlọ́run ìríra àwọn ènìyàn Ammoni.
Wyżyny także, które były przed Jeruzalem, i które były po prawej stronie góry Oliwnej, których był nabudował Salomon, król Izraelski, Astarotowi, obrzydłości Sydończyków, i Chamosowi, obrzydłości Moabczyków, i Melchomowi, obrzydłości synów Amm onowych, splugawił król.
14 Josiah fọ́ òkúta yíyà sọ́tọ̀, ó sì gé ère Aṣerah lulẹ̀. Ó sì bo ẹ̀gbẹ̀gbẹ́ ẹ rẹ̀ pẹ̀lú egungun ènìyàn.
I pokruszył słupy, a powycinał gaje, i napełnił miejsca ich kościami ludzkiemi.
15 Àní pẹpẹ tí ó wà ní Beteli ibi gíga tí Jeroboamu ọmọ Nebati dá. Tí ó ti fa Israẹli láti ṣẹ̀, àní pẹpẹ náà àti ibi gíga tí ó fọ́ túútúú. Ó jó àwọn ibi gíga, ó sì lọ̀ ọ́ sí ẹ̀tù, ó sì sun ère Aṣerah pẹ̀lú.
Nadto i ołtarz, który był w Betel, i wyżynę, którą był uczynił Jeroboam, syn Nabatowy, który przywiódł do grzechu lud Izraelski, i ten ołtarz, i wyżynę zepsuł, a spaliwszy onę wyżynę, starł na proch, i spalił gaj.
16 Nígbà náà, Josiah wò yíká, nígbà tí ó sì rí àwọn isà òkú tí ó wà níbẹ̀ ní ẹ̀bá òkè, ó yọ egungun kúrò lára wọn, ó sì jó wọn lórí pẹpẹ láti sọ ọ́ di èérí ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Olúwa tí a ti kéde láti ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run tí ó ti àwọn nǹkan wọ̀nyí tẹ́lẹ̀.
A obróciwszy się Jozyjasz, obaczył groby, które tam były na górze, a posławszy pobrał kości z onych grobów, i popalił je na tymże ołtarzu; a tak go splugawił według słowa Pańskiego, które mówił mąż Boży, który był te rzeczy przepowiedział.
17 Ọba sì béèrè pé, “Kí ni ọwọ̀n isà òkú yẹn tí mo rí?” Àwọn ọkùnrin ìlú ńlá wí pé, “Ó sàmì sí isà òkú ènìyàn Ọlọ́run tí ó wá láti Juda, tí ó sì kéde ìdojúkọ pẹpẹ Beteli, ohun kan wọ̀nyí tí ìwọ ti ṣe sí wọn.”
I rzekł: Cóż to jest za napis, który widzę? I odpowiedzieli mu mężowie miasta: Grób to męża Bożego, który przyszedłszy z Judy opowiedział te rzeczy, któreś uczynił nad ołtarzem w Betel.
18 “Fi sílẹ̀ nìkan,” Ó wí pé. “Má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni ó da àwọn egungun rẹ̀ láàmú.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n dá egungun rẹ̀ sí àti ti àwọn wòlíì tí ó wá láti Samaria.
A on rzekł: Zaniechajcie go, niechaj nikt nie rucha kości jego. I wybawili kości jego, i kości proroka onego, który był przyszedł z Samaryi.
19 Gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ní Beteli, Josiah sì kúrò, ó sì ba gbogbo ojúbọ òrìṣà ti ibi gíga jẹ́, tí àwọn ọba Israẹli ti kọ́ sí àwọn ìlú ní Samaria, tí ó ti mú Olúwa bínú.
Wszystkie też domy wyżyn, które były w miastach Samaryjskich, które byÜi pobudowali królowie Judzcy, draźniąc Pana, zniósł Jozyjasz, i uczynił im według wszystkiego, jako był uczynił w Betel.
20 Josiah dúńbú gbogbo àwọn àlùfáà ibi gíga lórí pẹpẹ. Ó sì sun egungun ènìyàn lórí wọn. Nígbà náà, ó padà lọ sí Jerusalẹmu.
Pozabijał także wszystkich kapłanów wyżyn, którzy tam byli na ołtarzach, i palił kości ludzkie na nich, potem się wrócił do Jeruzalemu.
21 Ọba pàṣẹ fún gbogbo àwọn ènìyàn pé, “Ẹ ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá sí Olúwa Ọlọ́run yín, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sí inú ìwé májẹ̀mú yìí.”
Rozkazał też król wszystkiemu ludowi, mówiąc: Obchodźcie święto przejścia Panu, Bogu waszemu, jako napisano w księgach przymierza tego.
22 Kì í ṣe láti ọjọ́ àwọn Juda tí ó tọ́ Israẹli, ní gbogbo àwọn ọjọ́ àwọn ọba Israẹli àti àwọn ọba Juda. Ṣé wọ́n ti ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá rí.
Bo nie obchodzono takiego święta przejścia ode dni sędziów, którzy sądzili Izraela, i przez wszystkie dni królów Izraelskich, i królów Judzkich.
23 Ṣùgbọ́n ní ọdún kejìdínlógún tí ọba Josiah, àjọ ìrékọjá yìí ni a ṣe ìrántí sí Olúwa ní Jerusalẹmu.
Jako ośmnastego roku króla Jozyjasza, obchodzono takie święto przejścia Panu w Jeruzalemie.
24 Síwájú sí, Josiah sì lé àwọn oṣó àti àwọn ẹ̀mí ní àwọn ìdílé, àti àwọn òrìṣà àti gbogbo àwọn nǹkan ìríra tí a rí ní Juda àti ní Jerusalẹmu. Èyí ni ó ṣe kí ó le è mú ọ̀rọ̀ òfin náà ṣe ní ti òfin tí a kọ sínú ìwé tí Hilkiah àlùfáà ti rí nínú ilé Olúwa.
Ale i wieszczków, i czarowników, i obrazy, i brzydkie bałwany, i wszystkie obrzydłości, co ich było widać w ziemi Judzkiej i w Jeruzalemie, wykorzenił Jozyjasz, aby wypełnił słowa zakonu napisane w księgach, które znalazł Helkijasz kapłan w dom u Pańskim.
25 Kò sì sí ọba kankan níwájú tàbí lẹ́yìn Josiah tí ó dàbí rẹ̀, tí ó yí padà sí olúwa tinútinú àti gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe tọkàntọkàn pẹ̀lú gbogbo ẹ̀mí i rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo agbára rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo òfin Mose.
I nie był podobny jemu król przed nim, któryby się nawrócił do Pana z całego serca swego, i ze wszystkiej duszy swojej, i ze wszystkiej siły swojej, według wszystkiego zakonu Mojżeszowego, ani po nim powstał jemu podobny.
26 Bí ó ti wù kí ó rí Olúwa kò yípadà kúrò nínú ìmúná ìbínú ńlá rẹ̀ tí ó jó sí Juda, nítorí gbogbo èyí tí Manase ti ṣe láti mú un bínú.
Wszakże nie odwrócił się Pan od popędliwości wielkiego gniewu swego, którą był wzruszony gniew jego przeciw Judzie dla wszelkiego rozdraźnienia, którem go był rozdraźnił Manases.
27 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí pé, “Èmi yóò mú Juda kúrò pẹ̀lú níwájú mi, bí mo ti mú Israẹli, èmi yóò sì kó Jerusalẹmu, ìlú ńlá tí mo yàn àti ilé Olúwa yìí, nípa èyí tí mo sọ, ‘Níbẹ̀ ni orúkọ mi yóò wà?’”
Przetoż rzekł Pan: I Judę odrzucę od obliczności mojej, jakom odrzucił Izraela, i wzgardzę to miasto, którem był obrał, to jest Jeruzalem, i dom ten, o którymem mówił: Będzie tam imię moje.
28 Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Josiah, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Juda?
A inne sprawy Jozyjaszowe, i wszystko, co czynił, opisane jest w kronikach o królach Judzkich.
29 Nígbà tí Josiah jẹ́ ọba, Farao Neko ọba Ejibiti gòkè lọ sí odò Eufurate láti lọ ran ọba Asiria lọ́wọ́. Ọba Josiah jáde lọ láti lọ bá a pàdé lójú ogun ṣùgbọ́n Neko dojúkọ ọ́, ó sì pa á ní Megido.
Za dni jego wyciągnął Farao Necho, król Egipski, przeciw królowi Assyryjskiemu ku rzece Eufrates; wyjechał też król Jozyjasz przeciwko niemu, którego on zabił w Megiddo, gdy go ujrzał.
30 Ìránṣẹ́ Josiah gbé ara rẹ̀ wá nínú kẹ̀kẹ́ láti Megido sí Jerusalẹmu ó sì sin ín sínú isà òkú rẹ̀. Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà mú Jehoahasi ọmọ Josiah. Ó fi àmì òróró yàn án, ó sì ṣe é ní ọba ní ipò baba a rẹ̀.
I przywieźli go słudzy jego umarłego z Megiddo, a przyprowadzili go do Jeruzalemu, i pogrzebli go w grobie jego. Potem wziąwszy lud onej ziemi Joachaza, syna Jozyjaszowego, pomazali go, i królem go postanowili miasto ojca jego.
31 Jehoahasi sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́tàlélógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún oṣù mẹ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Hamutali ọmọbìnrin Jeremiah; ó wá láti Libina.
Dwadzieścia lat i trzy miał Joachaz, gdy królować począł, a trzy miesiące królował w Jeruzalemie. A imię matki jego było Chamutal, córka Jeremijaszowa z Lebny.
32 Ó ṣe búburú lójú Olúwa gẹ́gẹ́ bí baba a rẹ̀ ti ṣe.
I czynił złe przed oczyma Pańskiemi według wszystkiego, co czynili ojcowie jego.
33 Farao Neko sì fi sí inú ìdè ní Ribla ní ilẹ̀ Hamati, kí ó má ba à lè jẹ ọba ní Jerusalẹmu. Ó sì tan Juda jẹ fun iye ìwọ̀n ẹgbẹ̀rin tálẹ́ǹtì wúrà kan.
I związał go Farao Necho w Rebli w ziemi Emat, gdy królował w Jeruzalemie, a ułożył dań na onę ziemię sto talentów srebra, i talent złota.
34 Farao Neko ṣe Eliakimu ọmọ Josiah ní ọba ní ipò baba rẹ̀ Josiah. Ó sì yí orúkọ Eliakimu padà sí Jehoiakimu. Ṣùgbọ́n ó mú Jehoahasi, ó sì gbé e lọ sí Ejibiti, níbẹ̀ ni ó sì kú.
A królem postanowił Farao Necho Elijakima, syna Jozyjaszowego, miasto Jozyjasza, ojca jego, i odmienił imię jego, a nazwał go Joakim; ale Joachaza wziął, który, gdy przyszedł do Egiptu, tamże umarł.
35 Jehoiakimu sì san fún Farao Neko fàdákà àti wúrà tí ó béèrè. Láti ṣe bẹ́ẹ̀, ó bu owó òde fún ilẹ̀ náà láti san, ó fi agbára gba fàdákà àti wúrà láti ọwọ́ àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà ní ìbámu pẹ̀lú iye tí a pín.
A to srebro i złoto dawał Joakim Faraonowi; przetoż szacował ziemię, aby mógł oddawać srebro według rozkazania Faraonowego; od każdego według szacunku jego, brał srebro i złoto od ludu ziemi, aby je oddawał Faraonowi Nechowi.
36 Jehoiakimu jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlá orúkọ ìyá rẹ̀ ni Sebida ọmọbìnrin Pedaiah ó wá láti Ruma.
Dwadzieścia i pięć lat miał Joakim, gdy królować począł, a jedenaście lat królował w Jeruzalemie. A imię matki jego było Zebuda, córka Fadajowa z Rumy.
37 Ó sì ṣe búburú lójú Olúwa gẹ́gẹ́ bí baba a rẹ̀ ti ṣe.
I czynił złe przed oczyma Pańskiemi według wszystkiego, jako czynili ojcowie jego.

< 2 Kings 23 >