< 2 Kings 23 >

1 Nígbà náà ọba pe gbogbo àwọn àgbàgbà Juda àti Jerusalẹmu jọ.
Le roi envoya, et l'on rassembla auprès de lui tous les anciens de Juda et de Jérusalem.
2 Ó gòkè lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu, àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì—gbogbo àwọn ènìyàn láti ibi kéékèèké sí ńlá. Ó kà á sí etí ìgbọ́ ọ wọn, gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé májẹ̀mú, tí a ti rí nínú ilé Olúwa.
Le roi monta à la maison de l'Éternel, avec tous les hommes de Juda et tous les habitants de Jérusalem, les prêtres, les prophètes et tout le peuple, petits et grands, et il lut devant eux toutes les paroles du livre de l'alliance qui se trouvait dans la maison de l'Éternel.
3 Ọba sì dúró lẹ́bàá òpó, ó sì sọ májẹ̀mú di tuntun níwájú Olúwa, láti tẹ̀lé Olúwa àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, ìlànà àti òfin pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀ àti gbogbo ẹ̀mí rẹ̀, àti láti ṣe ìwádìí àwọn ọ̀rọ̀ májẹ̀mú tí a kọ sínú ìwé yìí. Nígbà náà, gbogbo àwọn ènìyàn sì ṣèlérí fúnra wọn sí májẹ̀mú náà.
Le roi se tint debout près de la colonne et fit alliance devant l'Éternel de marcher après l'Éternel et d'observer ses commandements, ses témoignages et ses lois, de tout son cœur et de toute son âme, afin de confirmer les paroles de cette alliance qui sont écrites dans ce livre.
4 Ọba sì pàṣẹ fún Hilkiah olórí àlùfáà àti àwọn, àlùfáà tí ó tẹ̀lé e ní ipò àti àwọn olùṣọ́nà láti yọ kúrò nínú ilé Olúwa gbogbo ohun èlò tí a ṣe fún Baali àti Aṣerah àti gbogbo ẹgbẹ́ ogun ọ̀run. Ó sì sun wọ́n ní ìta Jerusalẹmu ní pápá àfonífojì Kidironi. Ó sì kó eérú wọn jọ sí Beteli.
Le roi ordonna à Hilkija, le grand prêtre, aux prêtres du second ordre et aux gardiens du seuil de sortir du temple de Yahvé tous les ustensiles qui avaient été fabriqués pour Baal, pour l'ashère et pour toute l'armée du ciel; il les brûla hors de Jérusalem, dans les champs du Cédron, et porta leurs cendres à Béthel.
5 Ó sì kúrò pẹ̀lú àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà tí a yàn láti ọwọ́ ọba Juda láti sun tùràrí ní ibi gíga ti ìlú Juda àti àwọn tí ó yí Jerusalẹmu ká. Àwọn tí ó ń sun tùràrí sí Baali, sí oòrùn àti òṣùpá, sí àwọn àmì ìràwọ̀ àti sí gbogbo ẹgbẹ́ ogun ọ̀run.
Il se débarrassa des prêtres idolâtres que les rois de Juda avaient chargés d'offrir des parfums sur les hauts lieux des villes de Juda et des environs de Jérusalem, et qui offraient des parfums à Baal, au soleil, à la lune, aux planètes et à toute l'armée du ciel.
6 Ó mú ère òrìṣà Aṣerah láti ilé Olúwa sí àfonífojì Kidironi ní ìta Jerusalẹmu, ó sì sun wọ́n níbẹ̀. Ó lọ̀ ọ́ bí àtíkè ó sì fọ́n eruku náà sórí isà òkú àwọn ènìyàn tí ó wọ́pọ̀.
Il fit sortir l'ashère de la maison de Yahvé, hors de Jérusalem, jusqu'au torrent de Cédron, et la brûla au torrent de Cédron; il la réduisit en poussière et en jeta la poussière sur les tombes des gens du peuple.
7 Ó sì wó ibùgbé àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà lulẹ̀. Tí ó wà nínú ilé Olúwa àti ibi tí àwọn obìnrin tí ń ṣe iṣẹ́ aṣọ híhun fún òrìṣà Aṣerah.
Il démolit les maisons des prostituées qui se trouvaient dans la maison de l'Éternel, où les femmes tissaient des tentures pour les ashères.
8 Josiah kó gbogbo àwọn àlùfáà láti àwọn ìlú Juda ó sì ba ibi mímọ́ wọ̀n-ọn-nì jẹ́ láti Geba sí Beerṣeba, níbi tí àwọn àlùfáà ti sun tùràrí. Ó wó àwọn ojúbọ lulẹ̀ ní ẹnu ìlẹ̀kùn—ní ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé ti Joṣua, baálẹ̀ ìlú ńlá tí ó wà ní apá òsì ẹnu ìlẹ̀kùn ìlú ńlá.
Il fit sortir tous les prêtres des villes de Juda et souilla les hauts lieux où les prêtres avaient brûlé de l'encens, depuis Guéba jusqu'à Beersheba; il brisa les hauts lieux des portes qui étaient à l'entrée de la porte de Josué, gouverneur de la ville, et qui se trouvaient à la gauche d'un homme, à la porte de la ville.
9 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, àwọn àlùfáà ibi gíga kò jọ́sìn ní ibi pẹpẹ Olúwa ní Jerusalẹmu, wọ́n jẹ nínú àkàrà aláìwú pẹ̀lú àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn.
Cependant, les prêtres des hauts lieux ne montaient pas à l'autel de Yahvé à Jérusalem, mais ils mangeaient des pains sans levain parmi leurs frères.
10 Ó sì ba ohun mímọ́ Tofeti jẹ́, tí ó wà ní àfonífojì Beni-Hinnomu, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnìkan tí ó lè lò ó fún ẹbọ rírú fún ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tàbí ọmọ rẹ̀ obìnrin nínú iná sí Moleki.
Il souilla Topheth, qui est dans la vallée des enfants de Hinnom, afin que personne ne fasse passer son fils ou sa fille par le feu pour Moloc.
11 Ó sì kúrò láti ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé sí ilé Olúwa, àwọn ẹṣin tí àwọn ọba Juda ti yà sọ́tọ̀ sí oòrùn náà. Wọ́n wà nínú ilé ẹjọ́ lẹ́bàá yàrá oníṣẹ́ tí orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Natani-Meleki. Josiah sì sun àwọn kẹ̀kẹ́ tí a yà sọ́tọ̀ fún oòrùn.
Il enleva les chevaux que les rois de Juda avaient consacrés au soleil, à l'entrée de la maison de l'Éternel, près de la chambre de Nathan Melech, l'officier qui était à la cour, et il brûla au feu les chars du soleil.
12 Ó wó o palẹ̀ pẹpẹ tí àwọn ọba Juda ti wọ́n gbé dúró ní orí òrùlé lẹ́bàá yàrá òkè ti Ahasi pẹ̀lú àwọn pẹpẹ tí Manase ti kọ́ nínú ilé ẹjọ́ méjèèjì sí ilé Olúwa. Ó ṣí wọn kúrò níbẹ̀, ó fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́. Ó sì da ekuru wọn sínú àfonífojì Kidironi.
Le roi démolit les autels qui étaient sur le toit de la chambre haute d'Achaz, et que les rois de Juda avaient faits, et les autels que Manassé avait faits dans les deux cours de la maison de l'Éternel; il les abattit de là, et jeta leur poussière dans le torrent de Cédron.
13 Ọba pẹ̀lú ba ohun mímọ́ àwọn ibi gíga jẹ́ tí ó wà ní ìhà ìlà-oòrùn Jerusalẹmu ní ìhà gúúsù ti òkè ìbàjẹ́—èyí tí Solomoni ọba Israẹli ti kọ́ fún Aṣtoreti ọlọ́run ìríra àwọn ará Sidoni, fún Kemoṣi ọlọ́run ìríra àwọn ará Moabu àti fún Moleki, ọlọ́run ìríra àwọn ènìyàn Ammoni.
Le roi souilla les hauts lieux qui étaient devant Jérusalem, à droite de la montagne de la corruption, et que Salomon, roi d'Israël, avait bâtis pour Astarté, l'abomination des Sidoniens, pour Kemosh, l'abomination de Moab, et pour Milcom, l'abomination des enfants d'Ammon.
14 Josiah fọ́ òkúta yíyà sọ́tọ̀, ó sì gé ère Aṣerah lulẹ̀. Ó sì bo ẹ̀gbẹ̀gbẹ́ ẹ rẹ̀ pẹ̀lú egungun ènìyàn.
Il brisa les piliers, abattit les mâts d'ashère et remplit leurs places d'ossements d'hommes.
15 Àní pẹpẹ tí ó wà ní Beteli ibi gíga tí Jeroboamu ọmọ Nebati dá. Tí ó ti fa Israẹli láti ṣẹ̀, àní pẹpẹ náà àti ibi gíga tí ó fọ́ túútúú. Ó jó àwọn ibi gíga, ó sì lọ̀ ọ́ sí ẹ̀tù, ó sì sun ère Aṣerah pẹ̀lú.
Il démolit l'autel qui était à Béthel et le haut lieu qu'avait fait Jéroboam, fils de Nebath, qui avait fait pécher Israël; il brûla le haut lieu, le réduisit en poussière, et brûla l'Astre.
16 Nígbà náà, Josiah wò yíká, nígbà tí ó sì rí àwọn isà òkú tí ó wà níbẹ̀ ní ẹ̀bá òkè, ó yọ egungun kúrò lára wọn, ó sì jó wọn lórí pẹpẹ láti sọ ọ́ di èérí ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Olúwa tí a ti kéde láti ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run tí ó ti àwọn nǹkan wọ̀nyí tẹ́lẹ̀.
Comme Josias se retournait, il aperçut les sépulcres qui étaient là dans la montagne; il envoya prendre les ossements dans les sépulcres, les brûla sur l'autel et le souilla, selon la parole de l'Éternel qu'avait proclamée l'homme de Dieu qui annonçait ces choses.
17 Ọba sì béèrè pé, “Kí ni ọwọ̀n isà òkú yẹn tí mo rí?” Àwọn ọkùnrin ìlú ńlá wí pé, “Ó sàmì sí isà òkú ènìyàn Ọlọ́run tí ó wá láti Juda, tí ó sì kéde ìdojúkọ pẹpẹ Beteli, ohun kan wọ̀nyí tí ìwọ ti ṣe sí wọn.”
Alors il dit: « Quel est ce monument que je vois? » Les hommes de la ville lui dirent: « C'est le tombeau de l'homme de Dieu qui est venu de Juda et qui a proclamé ces choses que tu as faites contre l'autel de Béthel. »
18 “Fi sílẹ̀ nìkan,” Ó wí pé. “Má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni ó da àwọn egungun rẹ̀ láàmú.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n dá egungun rẹ̀ sí àti ti àwọn wòlíì tí ó wá láti Samaria.
Il dit: « Qu'il soit! Que personne ne déplace ses os. » On laissa donc ses os, avec les os du prophète qui était venu de Samarie.
19 Gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ní Beteli, Josiah sì kúrò, ó sì ba gbogbo ojúbọ òrìṣà ti ibi gíga jẹ́, tí àwọn ọba Israẹli ti kọ́ sí àwọn ìlú ní Samaria, tí ó ti mú Olúwa bínú.
Josias fit disparaître toutes les maisons des hauts lieux qui se trouvaient dans les villes de Samarie et que les rois d'Israël avaient construites pour irriter Yahvé, et il les traita comme il l'avait fait à Béthel.
20 Josiah dúńbú gbogbo àwọn àlùfáà ibi gíga lórí pẹpẹ. Ó sì sun egungun ènìyàn lórí wọn. Nígbà náà, ó padà lọ sí Jerusalẹmu.
Il tua tous les prêtres des hauts lieux qui se trouvaient là, sur les autels, et il y brûla des ossements d'hommes, puis il retourna à Jérusalem.
21 Ọba pàṣẹ fún gbogbo àwọn ènìyàn pé, “Ẹ ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá sí Olúwa Ọlọ́run yín, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sí inú ìwé májẹ̀mú yìí.”
Le roi donna cet ordre à tout le peuple: « Fêtez la Pâque en l'honneur de Yahvé, votre Dieu, comme il est écrit dans ce livre de l'alliance. »
22 Kì í ṣe láti ọjọ́ àwọn Juda tí ó tọ́ Israẹli, ní gbogbo àwọn ọjọ́ àwọn ọba Israẹli àti àwọn ọba Juda. Ṣé wọ́n ti ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá rí.
Certes, on n'a pas célébré une telle Pâque depuis l'époque des juges qui ont jugé Israël, ni pendant toute la durée des rois d'Israël et des rois de Juda;
23 Ṣùgbọ́n ní ọdún kejìdínlógún tí ọba Josiah, àjọ ìrékọjá yìí ni a ṣe ìrántí sí Olúwa ní Jerusalẹmu.
mais la dix-huitième année du roi Josias, cette Pâque fut célébrée en l'honneur de Yahvé à Jérusalem.
24 Síwájú sí, Josiah sì lé àwọn oṣó àti àwọn ẹ̀mí ní àwọn ìdílé, àti àwọn òrìṣà àti gbogbo àwọn nǹkan ìríra tí a rí ní Juda àti ní Jerusalẹmu. Èyí ni ó ṣe kí ó le è mú ọ̀rọ̀ òfin náà ṣe ní ti òfin tí a kọ sínú ìwé tí Hilkiah àlùfáà ti rí nínú ilé Olúwa.
Josias fit disparaître les esprits familiers, les sorciers, les théraphim, les idoles et toutes les abominations qu'on voyait dans le pays de Juda et à Jérusalem, afin de confirmer les paroles de la loi qui étaient écrites dans le livre que le prêtre Hilkija avait trouvé dans la maison de l'Éternel.
25 Kò sì sí ọba kankan níwájú tàbí lẹ́yìn Josiah tí ó dàbí rẹ̀, tí ó yí padà sí olúwa tinútinú àti gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe tọkàntọkàn pẹ̀lú gbogbo ẹ̀mí i rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo agbára rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo òfin Mose.
Il n'y a pas eu de roi comme lui avant lui, qui se soit tourné vers l'Éternel de tout son cœur, de toute son âme et de toute sa force, selon toute la loi de Moïse, et il n'y en a pas eu comme lui qui se soit levé après lui.
26 Bí ó ti wù kí ó rí Olúwa kò yípadà kúrò nínú ìmúná ìbínú ńlá rẹ̀ tí ó jó sí Juda, nítorí gbogbo èyí tí Manase ti ṣe láti mú un bínú.
Cependant, l'Éternel ne se détourna pas de l'ardeur de son grand courroux, avec lequel sa colère brûlait contre Juda, à cause de toutes les provocations que Manassé lui avait faites.
27 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí pé, “Èmi yóò mú Juda kúrò pẹ̀lú níwájú mi, bí mo ti mú Israẹli, èmi yóò sì kó Jerusalẹmu, ìlú ńlá tí mo yàn àti ilé Olúwa yìí, nípa èyí tí mo sọ, ‘Níbẹ̀ ni orúkọ mi yóò wà?’”
L'Éternel dit: « J'éloignerai aussi Juda de ma vue, comme j'ai éloigné Israël, et je rejetterai cette ville que j'ai choisie, Jérusalem, et la maison dont j'ai dit: 'Mon nom y sera'. »
28 Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Josiah, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Juda?
Le reste des actes de Josias, et tout ce qu'il a fait, cela n'est-il pas écrit dans le livre des Chroniques des rois de Juda?
29 Nígbà tí Josiah jẹ́ ọba, Farao Neko ọba Ejibiti gòkè lọ sí odò Eufurate láti lọ ran ọba Asiria lọ́wọ́. Ọba Josiah jáde lọ láti lọ bá a pàdé lójú ogun ṣùgbọ́n Neko dojúkọ ọ́, ó sì pa á ní Megido.
De son temps, Pharaon Necoh, roi d'Égypte, monta contre le roi d'Assyrie jusqu'au fleuve Euphrate. Le roi Josias marcha contre lui, mais Pharaon Necoh le tua à Megiddo quand il le vit.
30 Ìránṣẹ́ Josiah gbé ara rẹ̀ wá nínú kẹ̀kẹ́ láti Megido sí Jerusalẹmu ó sì sin ín sínú isà òkú rẹ̀. Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà mú Jehoahasi ọmọ Josiah. Ó fi àmì òróró yàn án, ó sì ṣe é ní ọba ní ipò baba a rẹ̀.
Ses serviteurs le transportèrent mort dans un char depuis Megiddo, l'amenèrent à Jérusalem et l'enterrèrent dans son propre tombeau. Le peuple du pays prit Joachaz, fils de Josias, l'oignit et l'établit roi à la place de son père.
31 Jehoahasi sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́tàlélógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún oṣù mẹ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Hamutali ọmọbìnrin Jeremiah; ó wá láti Libina.
Joachaz avait vingt-trois ans lorsqu'il devint roi, et il régna trois mois à Jérusalem. Le nom de sa mère était Hamutal, fille de Jérémie, de Libna.
32 Ó ṣe búburú lójú Olúwa gẹ́gẹ́ bí baba a rẹ̀ ti ṣe.
Il fit ce qui est mal aux yeux de Yahvé, selon tout ce qu'avaient fait ses pères.
33 Farao Neko sì fi sí inú ìdè ní Ribla ní ilẹ̀ Hamati, kí ó má ba à lè jẹ ọba ní Jerusalẹmu. Ó sì tan Juda jẹ fun iye ìwọ̀n ẹgbẹ̀rin tálẹ́ǹtì wúrà kan.
Pharaon Néco le mit en prison à Ribla, dans le pays de Hamath, pour qu'il ne règne pas à Jérusalem, et il imposa au pays un tribut de cent talents d'argent et un talent d'or.
34 Farao Neko ṣe Eliakimu ọmọ Josiah ní ọba ní ipò baba rẹ̀ Josiah. Ó sì yí orúkọ Eliakimu padà sí Jehoiakimu. Ṣùgbọ́n ó mú Jehoahasi, ó sì gbé e lọ sí Ejibiti, níbẹ̀ ni ó sì kú.
Le pharaon Néco établit roi Eliakim, fils de Josias, à la place de Josias, son père, et changea son nom en Jojakim; mais il emmena Joachaz, qui vint en Égypte et y mourut.
35 Jehoiakimu sì san fún Farao Neko fàdákà àti wúrà tí ó béèrè. Láti ṣe bẹ́ẹ̀, ó bu owó òde fún ilẹ̀ náà láti san, ó fi agbára gba fàdákà àti wúrà láti ọwọ́ àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà ní ìbámu pẹ̀lú iye tí a pín.
Jojakim donna l'argent et l'or à Pharaon; mais il imposa le pays pour donner l'argent selon l'ordre de Pharaon. Il exigea l'argent et l'or des habitants du pays, de chacun selon son évaluation, pour les donner à Pharaon Néco.
36 Jehoiakimu jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlá orúkọ ìyá rẹ̀ ni Sebida ọmọbìnrin Pedaiah ó wá láti Ruma.
Jojakim avait vingt-cinq ans lorsqu'il devint roi, et il régna onze ans à Jérusalem. Sa mère s'appelait Zebidah, fille de Pedaja, de Ruma.
37 Ó sì ṣe búburú lójú Olúwa gẹ́gẹ́ bí baba a rẹ̀ ti ṣe.
Il fit ce qui est mal aux yeux de Yahvé, selon tout ce qu'avaient fait ses pères.

< 2 Kings 23 >