< 2 Kings 23 >

1 Nígbà náà ọba pe gbogbo àwọn àgbàgbà Juda àti Jerusalẹmu jọ.
To naah siangpahrang Josiah mah, Judah hoi Jerusalem ih kacoehtanawk boih to kawk.
2 Ó gòkè lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu, àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì—gbogbo àwọn ènìyàn láti ibi kéékèèké sí ńlá. Ó kà á sí etí ìgbọ́ ọ wọn, gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé májẹ̀mú, tí a ti rí nínú ilé Olúwa.
Siagpahrang loe Judah kaminawk, Jerusalem ih kaminawk, qaimanawk hoi tahmaanawk, kathoeng kalen kaminawk boih hoi nawnto Angraeng ih im ah caeh tahang. Anih mah Angraeng imthung ah hnuk ih lokmaihaih cabu pong ih loknawk boih to kaminawk thaih hanah kroek pae.
3 Ọba sì dúró lẹ́bàá òpó, ó sì sọ májẹ̀mú di tuntun níwájú Olúwa, láti tẹ̀lé Olúwa àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, ìlànà àti òfin pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀ àti gbogbo ẹ̀mí rẹ̀, àti láti ṣe ìwádìí àwọn ọ̀rọ̀ májẹ̀mú tí a kọ sínú ìwé yìí. Nígbà náà, gbogbo àwọn ènìyàn sì ṣèlérí fúnra wọn sí májẹ̀mú náà.
Siangpahrang Josiah loe homh taengah angdoet, Angraeng hnukbang hanah, a lokpaekhaihnawk, a thuih ih loknawk, lok takroekhaih daanawk to palungthin tang hoi hinghaih boih hoiah pazui moe, hae lokmaihaih cabu thungah tarik ih loknawk to caksak hanah, Angraeng hmaa ah lokmaihaih to a sak. Kaminawk boih lokmaihaih hmaa ah angdoet o.
4 Ọba sì pàṣẹ fún Hilkiah olórí àlùfáà àti àwọn, àlùfáà tí ó tẹ̀lé e ní ipò àti àwọn olùṣọ́nà láti yọ kúrò nínú ilé Olúwa gbogbo ohun èlò tí a ṣe fún Baali àti Aṣerah àti gbogbo ẹgbẹ́ ogun ọ̀run. Ó sì sun wọ́n ní ìta Jerusalẹmu ní pápá àfonífojì Kidironi. Ó sì kó eérú wọn jọ sí Beteli.
Siangpahrang mah, qaima Hilkiah, anih tlim ah kaom qaimanawk hoi khongkha toep kaminawk khaeah, Baal sithaw, Asherah thing hoi cakaehnawk hanah sak o ih, laom sabaennawk boih to Angraeng im thung hoi tasa bangah pathok hanah lokpaek; to hmuennawk to Jerusalem vangpui tasa bang ih Kidron azawn ah hmai hoiah thlaek o moe, maiphu to Bethel ah sinh o.
5 Ó sì kúrò pẹ̀lú àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà tí a yàn láti ọwọ́ ọba Juda láti sun tùràrí ní ibi gíga ti ìlú Juda àti àwọn tí ó yí Jerusalẹmu ká. Àwọn tí ó ń sun tùràrí sí Baali, sí oòrùn àti òṣùpá, sí àwọn àmì ìràwọ̀ àti sí gbogbo ẹgbẹ́ ogun ọ̀run.
Judah prae hoi Jerusalem vangpui taeng ih hmuensangnawk boih ah hmuihoih thlaek hanah, Judah siangpahrangnawk mah suek ih, krang kabok qaimanawk, Baal, ni hoi khrah, van ih longnawk hoi cakaehnawk khaeah hmuihoih thlaek kaminawk to takhoe boih.
6 Ó mú ère òrìṣà Aṣerah láti ilé Olúwa sí àfonífojì Kidironi ní ìta Jerusalẹmu, ó sì sun wọ́n níbẹ̀. Ó lọ̀ ọ́ bí àtíkè ó sì fọ́n eruku náà sórí isà òkú àwọn ènìyàn tí ó wọ́pọ̀.
Angraeng im thung ih Asherah thing to a lak moe, Jerusalem vangpui tasa bang ih Kidron vacong ah a sinh pacoengah, to vacong taengah hmai hoiah a qoeng; kadip puengah naep pacoengah, to maiphu to kaminawk ih taprong ah a haeh.
7 Ó sì wó ibùgbé àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà lulẹ̀. Tí ó wà nínú ilé Olúwa àti ibi tí àwọn obìnrin tí ń ṣe iṣẹ́ aṣọ híhun fún òrìṣà Aṣerah.
Nongpatanawk mah Asherah thing hanah kahni sakhaih ahmuen, Angraeng im taeng ih nongpanawk hnukbang tangyat mii kadueh kaminawk ohhaih im doeh a phraek pae.
8 Josiah kó gbogbo àwọn àlùfáà láti àwọn ìlú Juda ó sì ba ibi mímọ́ wọ̀n-ọn-nì jẹ́ láti Geba sí Beerṣeba, níbi tí àwọn àlùfáà ti sun tùràrí. Ó wó àwọn ojúbọ lulẹ̀ ní ẹnu ìlẹ̀kùn—ní ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé ti Joṣua, baálẹ̀ ìlú ńlá tí ó wà ní apá òsì ẹnu ìlẹ̀kùn ìlú ńlá.
Josiah mah Judah prae thung boih ih qaimanawk to kawk moe, nihcae mah hmuihoih thlaekhaih hmuensangnawk to Geba hoi Beersheba khoek to panuet kaom ah sak; Jerusalem vangpui ukkkung, Joshua ih khongkha akunhaih banqoi bangah kaom, vangpui sipae khongkha ih hmuensangnawk doeh vah pae phaeng.
9 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, àwọn àlùfáà ibi gíga kò jọ́sìn ní ibi pẹpẹ Olúwa ní Jerusalẹmu, wọ́n jẹ nínú àkàrà aláìwú pẹ̀lú àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn.
Hmuensang ah toksah qaimanawk loe Jerusalem ih Angraeng hmaicam ah caeh o thai ai; toe taeh thuh ai ih takaw loe ampui qaimanawk hoi nawnto caak o thaih.
10 Ó sì ba ohun mímọ́ Tofeti jẹ́, tí ó wà ní àfonífojì Beni-Hinnomu, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnìkan tí ó lè lò ó fún ẹbọ rírú fún ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tàbí ọmọ rẹ̀ obìnrin nínú iná sí Moleki.
Josiah mah, Mi kawbaktih doeh a canu hoi a capanawk to Molek sithaw khaeah hmai angbawnhaih sak han ai ah, Ben-Hinom azawn ah kaom, Topheth sithaw to panuet thok ah a sak.
11 Ó sì kúrò láti ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé sí ilé Olúwa, àwọn ẹṣin tí àwọn ọba Juda ti yà sọ́tọ̀ sí oòrùn náà. Wọ́n wà nínú ilé ẹjọ́ lẹ́bàá yàrá oníṣẹ́ tí orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Natani-Meleki. Josiah sì sun àwọn kẹ̀kẹ́ tí a yà sọ́tọ̀ fún oòrùn.
Judah siangpahrangnawk mah Ni khaeah tathlangh o ih, Angraeng im akunhaih khongkha taeng ih Nathan-Melek ohhaih imkhaan taengah kaom, hrangnawk doeh vah pae king; ni khaeah tathlangh o ih hrang lakoknawk doeh hmai hoiah a thlaek pae.
12 Ó wó o palẹ̀ pẹpẹ tí àwọn ọba Juda ti wọ́n gbé dúró ní orí òrùlé lẹ́bàá yàrá òkè ti Ahasi pẹ̀lú àwọn pẹpẹ tí Manase ti kọ́ nínú ilé ẹjọ́ méjèèjì sí ilé Olúwa. Ó ṣí wọn kúrò níbẹ̀, ó fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́. Ó sì da ekuru wọn sínú àfonífojì Kidironi.
Judah siangpahrangnawk mah sak o ih, Ahaz imkhaan ranui ih hmaicamnawk, Manasseh mah Angraeng im longhma hnetto pongah sak ih hmaicamnawk to a phraek moe, kadip pueng khoek to boh pae phaeng pacoengah, maiphu dip to Kidron vacong ah a vah.
13 Ọba pẹ̀lú ba ohun mímọ́ àwọn ibi gíga jẹ́ tí ó wà ní ìhà ìlà-oòrùn Jerusalẹmu ní ìhà gúúsù ti òkè ìbàjẹ́—èyí tí Solomoni ọba Israẹli ti kọ́ fún Aṣtoreti ọlọ́run ìríra àwọn ará Sidoni, fún Kemoṣi ọlọ́run ìríra àwọn ará Moabu àti fún Moleki, ọlọ́run ìríra àwọn ènìyàn Ammoni.
Israel siangpahrang Solomon mah, Jerusalem vangpui ni angyae bang, amrohaih mae aloih bangah kaom, panuet thok Sidon kaminawk ih sithaw Ashtoreth, panuet thok Moab kaminawk ih sithaw Khemost hoi panuet thok Ammon kaminawk ih Milkom sithaw hanah, sak pae ih hmuensangnawk to panuet kaom ah a sak pae.
14 Josiah fọ́ òkúta yíyà sọ́tọ̀, ó sì gé ère Aṣerah lulẹ̀. Ó sì bo ẹ̀gbẹ̀gbẹ́ ẹ rẹ̀ pẹ̀lú egungun ènìyàn.
Josiah mah krangnawk to vah pae phaeng moe, Asherah thingnawk to pakhruk pae; nihcae ohhaih ahmuen to kami huh hoiah koisak.
15 Àní pẹpẹ tí ó wà ní Beteli ibi gíga tí Jeroboamu ọmọ Nebati dá. Tí ó ti fa Israẹli láti ṣẹ̀, àní pẹpẹ náà àti ibi gíga tí ó fọ́ túútúú. Ó jó àwọn ibi gíga, ó sì lọ̀ ọ́ sí ẹ̀tù, ó sì sun ère Aṣerah pẹ̀lú.
Bethel ih hmaicam, Israel kaminawk zaehaih sahsakkung, Nebat capa Jeroboam mah sak ih, hmuensang, to ah kaom hmaicam hoi hmuensangnawk doeh phraek pae king; hmuensang to hmai hoiah thlaek pacoengah, kadip pueng khoek to a boh pae; Asherah thing doeh hmai hoiah a thlaek.
16 Nígbà náà, Josiah wò yíká, nígbà tí ó sì rí àwọn isà òkú tí ó wà níbẹ̀ ní ẹ̀bá òkè, ó yọ egungun kúrò lára wọn, ó sì jó wọn lórí pẹpẹ láti sọ ọ́ di èérí ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Olúwa tí a ti kéde láti ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run tí ó ti àwọn nǹkan wọ̀nyí tẹ́lẹ̀.
Josiah mah khet moe, mae nuiah kaom taprongnawk to hnuk naah, kami to patoeh moe, taprong thung ih kami huh to laksak; Sithaw ih kami mah thuicoek ih Angraeng ih lok baktih toengah, ahuhnawk to hmaicam nuiah hmai hoiah thlaek moe, panuet kaom ah a sak.
17 Ọba sì béèrè pé, “Kí ni ọwọ̀n isà òkú yẹn tí mo rí?” Àwọn ọkùnrin ìlú ńlá wí pé, “Ó sàmì sí isà òkú ènìyàn Ọlọ́run tí ó wá láti Juda, tí ó sì kéde ìdojúkọ pẹpẹ Beteli, ohun kan wọ̀nyí tí ìwọ ti ṣe sí wọn.”
Siangpahrang mah, Taprong thlung nuiah ka hnuk ih hmuen loe tih aa? tiah a naa. Vangpui thung ih kaminawk mah, Hae loe Judah prae thung hoiah angzoh moe, vaihniah Bethel ih hmaicam nuiah na sak ih hmuen to ka koeh ai, tiah thuikung, Sithaw kami angmathaih ih taprong ni, tiah thuih pae o.
18 “Fi sílẹ̀ nìkan,” Ó wí pé. “Má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni ó da àwọn egungun rẹ̀ láàmú.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n dá egungun rẹ̀ sí àti ti àwọn wòlíì tí ó wá láti Samaria.
Anih mah, To tiah suem o duem ah; mi mah doeh anih ih ahuh to takhoe o hmah nasoe, tiah a naa. To pongah anih ih ahuh hoi Samaria hoiah angzo kaminawk ih ahuh to a caeh o taak.
19 Gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ní Beteli, Josiah sì kúrò, ó sì ba gbogbo ojúbọ òrìṣà ti ibi gíga jẹ́, tí àwọn ọba Israẹli ti kọ́ sí àwọn ìlú ní Samaria, tí ó ti mú Olúwa bínú.
Bethel vangpui ah sak ih baktih toengah, Josiah mah Angraeng palungphuisak hanah, Samaria vangpuinawk thungah Israel siangpahrangnawk mah sak o ih hmuensangnawk hoi bokhaih ahmuennawk to phraek pae king.
20 Josiah dúńbú gbogbo àwọn àlùfáà ibi gíga lórí pẹpẹ. Ó sì sun egungun ènìyàn lórí wọn. Nígbà náà, ó padà lọ sí Jerusalẹmu.
Josiah mah toksah qaimanawk to hmuensang ih hmaicamnawk nuiah hum boih moe, kami huhnawk to to hmaicam nuiah hmai hoi thlaek pacoengah, Jerusalem ah amlaem.
21 Ọba pàṣẹ fún gbogbo àwọn ènìyàn pé, “Ẹ ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá sí Olúwa Ọlọ́run yín, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sí inú ìwé májẹ̀mú yìí.”
Siangpahrang mah kaminawk boih khaeah, Hae lokmaihaih cabu thungah tarik ih baktih toengah, na Angraeng Sithaw khaeah misong loihaih poih to sah oh.
22 Kì í ṣe láti ọjọ́ àwọn Juda tí ó tọ́ Israẹli, ní gbogbo àwọn ọjọ́ àwọn ọba Israẹli àti àwọn ọba Juda. Ṣé wọ́n ti ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá rí.
Israel zaehoikung lokcaekkungnawk ih adung hoiah kamtong, Israel siangpahrangnawk hoi Judah siangpahrangnawk dung thung boih ah, to baktih misong loihaih poih to sah o vai ai;
23 Ṣùgbọ́n ní ọdún kejìdínlógún tí ọba Josiah, àjọ ìrékọjá yìí ni a ṣe ìrántí sí Olúwa ní Jerusalẹmu.
toe Josiah siangpahrang ah ohhaih saning hatlaitazetto naah, Angraeng khaeah misong loihhaih poih to Jerusalem ah sak o.
24 Síwájú sí, Josiah sì lé àwọn oṣó àti àwọn ẹ̀mí ní àwọn ìdílé, àti àwọn òrìṣà àti gbogbo àwọn nǹkan ìríra tí a rí ní Juda àti ní Jerusalẹmu. Èyí ni ó ṣe kí ó le è mú ọ̀rọ̀ òfin náà ṣe ní ti òfin tí a kọ sínú ìwé tí Hilkiah àlùfáà ti rí nínú ilé Olúwa.
To pacoengah Josiah loe, qaima Hilkiah mah Angraeng im thungah hnuk ih Sithaw lok cabu thungah tarik ih loknawk baktih toengah pazui hanah, pakhra hoi mauihnawk, krangnawk, sakcop ih krangnawk han toksah kaminawk, Judah prae hoi Jerusalem ah kaom panuet thok hmuennawk to a phraek boih.
25 Kò sì sí ọba kankan níwájú tàbí lẹ́yìn Josiah tí ó dàbí rẹ̀, tí ó yí padà sí olúwa tinútinú àti gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe tọkàntọkàn pẹ̀lú gbogbo ẹ̀mí i rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo agbára rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo òfin Mose.
Josiah siangpahrang ah om ai nathuem hoi anih siangpahrang ah oh pacoeng khoek to, Josiah baktiah poekhaih palungthin boih, a hinghaih boih, a thacakhaih boih hoi Mosi mah paek ih kaalok baktih toengah, Angraeng khaeah amlaem kami maeto doeh om ai.
26 Bí ó ti wù kí ó rí Olúwa kò yípadà kúrò nínú ìmúná ìbínú ńlá rẹ̀ tí ó jó sí Juda, nítorí gbogbo èyí tí Manase ti ṣe láti mú un bínú.
Toe Manasseh mah palungphuisak pongah, Judah nuiah Angraeng palungphuihaih to dipsak let thai ai.
27 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí pé, “Èmi yóò mú Juda kúrò pẹ̀lú níwájú mi, bí mo ti mú Israẹli, èmi yóò sì kó Jerusalẹmu, ìlú ńlá tí mo yàn àti ilé Olúwa yìí, nípa èyí tí mo sọ, ‘Níbẹ̀ ni orúkọ mi yóò wà?’”
Angraeng mah, Israel kaminawk ka hmaa hoi takhoe boih baktih toengah, Judahnawk doeh ka takhoe han; Ka Hmin loe, ka qoih ih hae vangpui, Jerusalem hoi to ih ahmuen ah om tih, tiah ka thuih ih im to ka takhoe ving han, tiah a thuih.
28 Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Josiah, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Juda?
Josiah siangpahrang ah oh nathung toksakhaihnawk hoi a sak ih hmuennawk loe, Judah siangpahrangnawk ahmin pakuemhaih cabu thungah tarik o na ai maw?
29 Nígbà tí Josiah jẹ́ ọba, Farao Neko ọba Ejibiti gòkè lọ sí odò Eufurate láti lọ ran ọba Asiria lọ́wọ́. Ọba Josiah jáde lọ láti lọ bá a pàdé lójú ogun ṣùgbọ́n Neko dojúkọ ọ́, ó sì pa á ní Megido.
Josiah siangpahrang dung ah, Izip siangpahrang Faro-Neko loe Euphrate vapui khoek to, Assyria siangpahrang tuk hanah caeh tahang; Josiah siangpahrang loe anih to tuk hanah caeh; Neko mah anih to Megiddo ah hnuk, misa angtuk hoi naah Josiah to anih mah hum.
30 Ìránṣẹ́ Josiah gbé ara rẹ̀ wá nínú kẹ̀kẹ́ láti Megido sí Jerusalẹmu ó sì sin ín sínú isà òkú rẹ̀. Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà mú Jehoahasi ọmọ Josiah. Ó fi àmì òróró yàn án, ó sì ṣe é ní ọba ní ipò baba a rẹ̀.
Josiah ih tamnanawk mah anih ih qok to hrang lakok pongah Megiddo hoi Jerusalem ah phawh o moe, angmah ih taprong ah aphum o. A prae thung ih kaminawk mah Josiah capa Jehoahaz to situi bawh o pacoengah, ampa zuengah siangpahrang ah suek o.
31 Jehoahasi sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́tàlélógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún oṣù mẹ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Hamutali ọmọbìnrin Jeremiah; ó wá láti Libina.
Jehoahaz siangpahrang ah oh nathuem ah, saning pumphae thumto oh boeh; anih mah Jerusalem to khrah thumto thung uk. Anih amno ih ahmin loe, Libnah ah kaom, Jeremiah canu Hamutal.
32 Ó ṣe búburú lójú Olúwa gẹ́gẹ́ bí baba a rẹ̀ ti ṣe.
Ampanawk mah sak ih hmuennawk baktih toengah, anih doeh Angraeng mikhnukah kahoih ai hmuen to sak.
33 Farao Neko sì fi sí inú ìdè ní Ribla ní ilẹ̀ Hamati, kí ó má ba à lè jẹ ọba ní Jerusalẹmu. Ó sì tan Juda jẹ fun iye ìwọ̀n ẹgbẹ̀rin tálẹ́ǹtì wúrà kan.
Siangpahrang mah Jerusalem to uk han ai ah, Faro-Neko mah anih to Hamath prae Riblah vangpui ah thongim pakhrak moe, Judah kaminawk han phoisa talent cumvaito hoi sui talent maeto tamut paeksak.
34 Farao Neko ṣe Eliakimu ọmọ Josiah ní ọba ní ipò baba rẹ̀ Josiah. Ó sì yí orúkọ Eliakimu padà sí Jehoiakimu. Ṣùgbọ́n ó mú Jehoahasi, ó sì gbé e lọ sí Ejibiti, níbẹ̀ ni ó sì kú.
Faro-Neko mah Josiah capa Eliakim to ampa Josiah zuengah siangpahrang ah suek moe, Eliakim to Jehoiakim, tiah ahmin athlaeng pae; toe Jehoahaz loe Izip prae ah misong ah caeh haih; anih loe to ah duek.
35 Jehoiakimu sì san fún Farao Neko fàdákà àti wúrà tí ó béèrè. Láti ṣe bẹ́ẹ̀, ó bu owó òde fún ilẹ̀ náà láti san, ó fi agbára gba fàdákà àti wúrà láti ọwọ́ àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà ní ìbámu pẹ̀lú iye tí a pín.
Faro-Neko mah tamut hnik baktih toengah, Jehoiakim mah sui hoi phoisa to paek; prae kaminawk khaeah paek koi angmah ih taham tamut to kok moe, sui hoi phoisa to Faro-Neko hanah paek.
36 Jehoiakimu jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlá orúkọ ìyá rẹ̀ ni Sebida ọmọbìnrin Pedaiah ó wá láti Ruma.
Jehoiakim loe siangpahrang ah oh naah, saning pumphae pangato oh boeh; anih mah Jerusalem to saning hatlaito thung uk. Amno loe Pedaiah canu Zebidah; anih loe Rumah ah kaom kami ni.
37 Ó sì ṣe búburú lójú Olúwa gẹ́gẹ́ bí baba a rẹ̀ ti ṣe.
Ampanawk mah sak o ih hmuennawk baktih toengah, anih mah doeh Angraeng mikhnukah kahoih ai hmuen to sak.

< 2 Kings 23 >