< 2 Kings 23 >

1 Nígbà náà ọba pe gbogbo àwọn àgbàgbà Juda àti Jerusalẹmu jọ.
Yuda hina bagade Yousaia da Yuda soge fi amola Yelusaleme fi ilia ouligisu dunu amo huluane gagadole,
2 Ó gòkè lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu, àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì—gbogbo àwọn ènìyàn láti ibi kéékèèké sí ńlá. Ó kà á sí etí ìgbọ́ ọ wọn, gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé májẹ̀mú, tí a ti rí nínú ilé Olúwa.
ili amola gobele salasu dunu huluane, amola balofede dunu huluane amola fi dunu huluanedafa (bagade gagui dunu amola hame gagui dunu) ilia da Debolo Diasuga gilisili asi. Ilia si da: iya, hina bagade Yousaia da Gousa: su Meloa amo ilia da Debolo Diasu ba: i, amo ganodini dedei huluane ilima idili i.
3 Ọba sì dúró lẹ́bàá òpó, ó sì sọ májẹ̀mú di tuntun níwájú Olúwa, láti tẹ̀lé Olúwa àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, ìlànà àti òfin pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀ àti gbogbo ẹ̀mí rẹ̀, àti láti ṣe ìwádìí àwọn ọ̀rọ̀ májẹ̀mú tí a kọ sínú ìwé yìí. Nígbà náà, gbogbo àwọn ènìyàn sì ṣèlérí fúnra wọn sí májẹ̀mú náà.
E da hina bagade duni bugi amo dafulili lelu, e da Hina Gode Ea sia: nabawane hamomusa: , dafawane ilegele sia: i. E da mae fisili, ea dogo amola asigi dawa: su huluane amoga, e da Hina Gode Ea sema amola hamoma: ne sia: i, amoma fa: no bobogemusa: , dafawane ilegele sia: i. Amo hamoma: ne sia: i amo da Gousa: su Meloa amo ganodini dedei, e da amo huluane nabawane hamomusa: , dafawane ilegele sia: i. Amola dunu huluane da amo defele hamomusa: , dafawane ilegele sia: i.
4 Ọba sì pàṣẹ fún Hilkiah olórí àlùfáà àti àwọn, àlùfáà tí ó tẹ̀lé e ní ipò àti àwọn olùṣọ́nà láti yọ kúrò nínú ilé Olúwa gbogbo ohun èlò tí a ṣe fún Baali àti Aṣerah àti gbogbo ẹgbẹ́ ogun ọ̀run. Ó sì sun wọ́n ní ìta Jerusalẹmu ní pápá àfonífojì Kidironi. Ó sì kó eérú wọn jọ sí Beteli.
Amalalu, Yousaia da gobele salasu ouligisudafa Hiligaia amola ea afoha gobele salasu dunu ili, amola Debolo logo holeiga sosodo aligisu dunu ili, ilia da loboga hamoi liligi Debolo ganodini dialu, amoga dunu da Ba: ile amola uda ‘gode’ Asila amola gasumuni ilima nodone sia: ne gadosu, amo liligi huluane gadili gaguli masa: ne sia: i. Yuda hina bagade da amo liligi huluane moilai hamega Gidalone Fago gadenene, amo laluga gobele salalu, nasubu amo Bedele moilaiga gaguli masa: ne sia: i.
5 Ó sì kúrò pẹ̀lú àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà tí a yàn láti ọwọ́ ọba Juda láti sun tùràrí ní ibi gíga ti ìlú Juda àti àwọn tí ó yí Jerusalẹmu ká. Àwọn tí ó ń sun tùràrí sí Baali, sí oòrùn àti òṣùpá, sí àwọn àmì ìràwọ̀ àti sí gbogbo ẹgbẹ́ ogun ọ̀run.
E da gobele salasu dunu, amo musa: Yuda hina bagade ilia da Yuda soge ganodini moilale gagai amola Yelusaleme gadenene dialu, amo ganodini ogogosu ‘gode’ oloda da: iya gobele salasu hamoma: ne ilegei, - gobele salasu dunu amo da Ba: ile amola eso amola oubi, amola gasumuni ilima gobele salalusu, amo huluane Yousaia da mugululi fasi.
6 Ó mú ère òrìṣà Aṣerah láti ilé Olúwa sí àfonífojì Kidironi ní ìta Jerusalẹmu, ó sì sun wọ́n níbẹ̀. Ó lọ̀ ọ́ bí àtíkè ó sì fọ́n eruku náà sórí isà òkú àwọn ènìyàn tí ó wọ́pọ̀.
E da wadela: i uda ‘gode’ Asila agoaila loboga hamoi amo Debolo ganodini dialu, amo gadili gaguli asili, moilai hamega Gidalone Fago gadenene laluga gobele, ea gasa ganumu amo huluane nasubu su agoane hamoma: ne dadabilalu, dunudafa ilia bogoi uli dogosu sogebi amo da: iya dudulisisi.
7 Ó sì wó ibùgbé àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà lulẹ̀. Tí ó wà nínú ilé Olúwa àti ibi tí àwọn obìnrin tí ń ṣe iṣẹ́ aṣọ híhun fún òrìṣà Aṣerah.
E da Debolo ganodini sesei dialu, amogawi hina: da: i bidi lasu uda amola dunu amogai esafulu, amo huluane wadela: lesi. (Amogawi, uda ilia da ogogole ‘gode’ Asilama nodoma: ne sia: ne gadomusa: , abula loboga amunasu.)
8 Josiah kó gbogbo àwọn àlùfáà láti àwọn ìlú Juda ó sì ba ibi mímọ́ wọ̀n-ọn-nì jẹ́ láti Geba sí Beerṣeba, níbi tí àwọn àlùfáà ti sun tùràrí. Ó wó àwọn ojúbọ lulẹ̀ ní ẹnu ìlẹ̀kùn—ní ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé ti Joṣua, baálẹ̀ ìlú ńlá tí ó wà ní apá òsì ẹnu ìlẹ̀kùn ìlú ńlá.
E da gobele salasu dunu amo da Yuda moilai hisu hisu ganodini esalu, amo huluane Yelusalemega oule misi. Amola Yuda soge huluane ganodini, e da oloda amo da: iya ilia gobele salalusu, amo huluane wadela: lesi. Amola e da oloda huluane amo da goudi wadela: i a: silibu amoma nodone sia: ne gadomusa: gagui, amo huluane Yousaia da gagoudane sasali. Amo oloda ilia da logo holei amo Yosiua (moilai ouligisu dunu) ea gagui, amo gadenene ba: i. Amola amo logo holei da moilai mimogo logo holei amo ea fofadidi dialebe ba: i.
9 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, àwọn àlùfáà ibi gíga kò jọ́sìn ní ibi pẹpẹ Olúwa ní Jerusalẹmu, wọ́n jẹ nínú àkàrà aláìwú pẹ̀lú àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn.
Gobele salasu dunu moilai hisu hisu amoga esalu, amo e da mugululi fasilalu, amo gobele salasu dunu da Yelusalemega oule misini, ilia da Debolo ganodini mae hawa: hamoma: ne sia: i. Be ilia da yisidi hame sali agi, amo da ilia na: iyado gobele salasu hawa: hamosu dunu, ilima i, amo fawane da ilia moma: ne sia: i.
10 Ó sì ba ohun mímọ́ Tofeti jẹ́, tí ó wà ní àfonífojì Beni-Hinnomu, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnìkan tí ó lè lò ó fún ẹbọ rírú fún ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tàbí ọmọ rẹ̀ obìnrin nínú iná sí Moleki.
Hina bagade Yousaia amolawane da ogogosu ‘gode’ma nodone sia: ne gadosu sogebi Hinome Fago ganodini diala, ea dio amo Doubede Sogebi, amo wadela: lesi. Bai amogawi musa: dunu ilia da ilia dunu mano o uda mano amo ogogosu ‘gode’ Moulegema gobele sasalalusu.
11 Ó sì kúrò láti ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé sí ilé Olúwa, àwọn ẹṣin tí àwọn ọba Juda ti yà sọ́tọ̀ sí oòrùn náà. Wọ́n wà nínú ilé ẹjọ́ lẹ́bàá yàrá oníṣẹ́ tí orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Natani-Meleki. Josiah sì sun àwọn kẹ̀kẹ́ tí a yà sọ́tọ̀ fún oòrùn.
Yousaia da hosi amolawane Yuda hina bagade ilia da esoma nodone sia: ne gadomusa: ilegei, amo huluane enodini asunasiagai. Amola esoma nodone sia: ne gadosu ‘sa: liode’, e da amo laluga gobele sali. (Amo ‘sa: liode’ ilia da Debolo gagoi ganodini, logo holei amola Na: ida: ne Milege (eagene ouligisu dunu bagade) ea diasu gadenene ouligi.)
12 Ó wó o palẹ̀ pẹpẹ tí àwọn ọba Juda ti wọ́n gbé dúró ní orí òrùlé lẹ́bàá yàrá òkè ti Ahasi pẹ̀lú àwọn pẹpẹ tí Manase ti kọ́ nínú ilé ẹjọ́ méjèèjì sí ilé Olúwa. Ó ṣí wọn kúrò níbẹ̀, ó fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́. Ó sì da ekuru wọn sínú àfonífojì Kidironi.
Hina bagade Yousaia da oloda huluane amo Yuda hina bagade ilia da hina bagade diasu figisu da: iya, hina bagade A: iha: se ea sesei amo gadodili gagui, amola oloda huluane amo hina bagade Ma: na: se da Debolo gagoi aduna ganodini gagui, amo huluane e da gagoudane fasili, amola Gidalone Fagoa galagugudui.
13 Ọba pẹ̀lú ba ohun mímọ́ àwọn ibi gíga jẹ́ tí ó wà ní ìhà ìlà-oòrùn Jerusalẹmu ní ìhà gúúsù ti òkè ìbàjẹ́—èyí tí Solomoni ọba Israẹli ti kọ́ fún Aṣtoreti ọlọ́run ìríra àwọn ará Sidoni, fún Kemoṣi ọlọ́run ìríra àwọn ará Moabu àti fún Moleki, ọlọ́run ìríra àwọn ènìyàn Ammoni.
Amola oloda huluane amo hina bagade Soloumane da Yelusalemega gusudili amola Olife Goumia gadili (south) amo wadela: idafa ogogosu loboga hamoi ‘gode’ (Saidone fi ilia uda ‘gode’ A: siadalode, Moua: be fi ilia ‘gode’ Gimosie, A:mone fi ilia ‘gode’ Moulege) ilima nodone sia: ne gadomusa: gagui, amo huluane Yousaia da wadela: lesi.
14 Josiah fọ́ òkúta yíyà sọ́tọ̀, ó sì gé ère Aṣerah lulẹ̀. Ó sì bo ẹ̀gbẹ̀gbẹ́ ẹ rẹ̀ pẹ̀lú egungun ènìyàn.
Hina bagade Yousaia da gelega hamoi momogoi huluane gagoudane sali, amola wadela: i uda ‘gode’ Asila ea loboga hamoi agoaila huluane abusa: le fasi. Ilia bugisisi osobo amo Yousaia da dunu gasaga dedebolesi.
15 Àní pẹpẹ tí ó wà ní Beteli ibi gíga tí Jeroboamu ọmọ Nebati dá. Tí ó ti fa Israẹli láti ṣẹ̀, àní pẹpẹ náà àti ibi gíga tí ó fọ́ túútúú. Ó jó àwọn ibi gíga, ó sì lọ̀ ọ́ sí ẹ̀tù, ó sì sun ère Aṣerah pẹ̀lú.
Yousaia amolawane, e da ogogosu ‘godema’ nodone sia: ne gadosu sogebi amo hina bagade Yelouboua: me (Niba: de egefe. E da Isala: ili fi wadela: le hamoma: ne oule asi) ea gagui liligi amo Yousaia da mugululi sali. Yousaia da oloda mugululi salalu, ilia gele gagoudane, su hamosu. Amola e da Asila e agoaila gobele sali.
16 Nígbà náà, Josiah wò yíká, nígbà tí ó sì rí àwọn isà òkú tí ó wà níbẹ̀ ní ẹ̀bá òkè, ó yọ egungun kúrò lára wọn, ó sì jó wọn lórí pẹpẹ láti sọ ọ́ di èérí ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Olúwa tí a ti kéde láti ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run tí ó ti àwọn nǹkan wọ̀nyí tẹ́lẹ̀.
Amalu Yousaia da agolo damana lela ba: legagaloba, dunu bogoi amo ilia gasa da gele gelaboga diafulubi ba: i. Ea sia: ga ilia da amo gasa gadili gaguli asili, oloda da: iya gobele sali. Yousaia da amo oloda agoane wadela: lesisi. Musa: , balofede dunu afae da lolo nabe amoga, hina bagade Yelouboua: me da amo oloda bega: dafulili lelebeba: le, amo hou huluane didili doaga: i. Hina bagade Yousaia da ba: le gagale, balofede dunu amo da musa: hou ba: la: lu, amo ea bogoi gele gelabo amo ba: i.
17 Ọba sì béèrè pé, “Kí ni ọwọ̀n isà òkú yẹn tí mo rí?” Àwọn ọkùnrin ìlú ńlá wí pé, “Ó sàmì sí isà òkú ènìyàn Ọlọ́run tí ó wá láti Juda, tí ó sì kéde ìdojúkọ pẹpẹ Beteli, ohun kan wọ̀nyí tí ìwọ ti ṣe sí wọn.”
E amane adole ba: i, “Amo bogoi gele gelabo da nowa eala: ? Bedele fi dunu da bu adole i, “Amo da balofede dunu, e da Yuda sogega misi amola dia wali olodaga hamobe amo ba: la: lu, amo balofede dunu bogoi amo ea: bogoi gele gelabo.”
18 “Fi sílẹ̀ nìkan,” Ó wí pé. “Má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni ó da àwọn egungun rẹ̀ láàmú.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n dá egungun rẹ̀ sí àti ti àwọn wòlíì tí ó wá láti Samaria.
Yousaia da amane sia: i, “Amanewane yolesima! Ea gasa mae muguluma!” Amaiba: le, ilia amo balofede ea gasa hame mugululi, amola balofede dunu eno amo da Samelia sogega misi, ea gasa amolawane hame mugului.
19 Gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ní Beteli, Josiah sì kúrò, ó sì ba gbogbo ojúbọ òrìṣà ti ibi gíga jẹ́, tí àwọn ọba Israẹli ti kọ́ sí àwọn ìlú ní Samaria, tí ó ti mú Olúwa bínú.
E da Samelia soge moilai huluane amo ganodini, ogogosu ‘gode’ma nodone sia: ne gadosu sogebi amo Isala: ili hina bagade ilia da hamobeba: le, Hina Gode da ougi bagade ba: i, Yousaia da Bedele moilaiga oloda hamoi mugululi fasi amo defele, amo oloda mugululi fasi.
20 Josiah dúńbú gbogbo àwọn àlùfáà ibi gíga lórí pẹpẹ. Ó sì sun egungun ènìyàn lórí wọn. Nígbà náà, ó padà lọ sí Jerusalẹmu.
Wadela: i gobele salasu dunu huluane, e da ilila: hawa: hamosu oloda da: iya medole legei. Amola oloda huluane amo wadela: ma: ne, e da amo da: iya dunu gasa udigili gobele sali. Amalu, e da Yelusalemega buhagi.
21 Ọba pàṣẹ fún gbogbo àwọn ènìyàn pé, “Ẹ ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá sí Olúwa Ọlọ́run yín, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sí inú ìwé májẹ̀mú yìí.”
Hina bagade Yousaia da Yuda fima, ilia da Hina Godema nodoma: ne, Baligisu Lolo Nasu amo Gousa: su Meloa ganodini dedei defele, amo hamoma: ne sia: i.
22 Kì í ṣe láti ọjọ́ àwọn Juda tí ó tọ́ Israẹli, ní gbogbo àwọn ọjọ́ àwọn ọba Israẹli àti àwọn ọba Juda. Ṣé wọ́n ti ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá rí.
Musa: bisisu dunu da Isala: ili ouligilalu amoganini amo esoha, amoga Isala: ili amola Yuda hina bagade ilia da Baligisu Lolo Nasu hamosu amo defele hame hamosu.
23 Ṣùgbọ́n ní ọdún kejìdínlógún tí ọba Josiah, àjọ ìrékọjá yìí ni a ṣe ìrántí sí Olúwa ní Jerusalẹmu.
Be wali, Yousaia ea ouligibi ode18 amoga, ilia da Yelusalemega Baligisu Lolo Nasu hamoi.
24 Síwájú sí, Josiah sì lé àwọn oṣó àti àwọn ẹ̀mí ní àwọn ìdílé, àti àwọn òrìṣà àti gbogbo àwọn nǹkan ìríra tí a rí ní Juda àti ní Jerusalẹmu. Èyí ni ó ṣe kí ó le è mú ọ̀rọ̀ òfin náà ṣe ní ti òfin tí a kọ sínú ìwé tí Hilkiah àlùfáà ti rí nínú ilé Olúwa.
Hina bagade Yousaia da Meloa amo da gobele salasu Ouligisudafa Hiligaia Debolo Diasu ganodini ba: i, amo sema huluane meloa ganodini dedei, amoga molole fa: no bobogemusa: dawa: i. Amaiba: le, e da gesami dasu dunu amola wadela: i ba: la: lusu dunu amola diasua ogogosu ‘gode’ liligi, amola loboga hamoi ‘gode’, amola ogogosu ‘gode’ma nodone sia: ne gadosu liligi huluanedafa mugululi fasi.
25 Kò sì sí ọba kankan níwájú tàbí lẹ́yìn Josiah tí ó dàbí rẹ̀, tí ó yí padà sí olúwa tinútinú àti gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe tọkàntọkàn pẹ̀lú gbogbo ẹ̀mí i rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo agbára rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo òfin Mose.
Hina bagade e agoai da musa: hame ba: i. E da ea dogoga amola ea asigi dawa: suga amola ea gasa huluanedafa, amoga e da Hina Gode Ea hawa: hamosu hamonanu. E da Mousese ea sema huluane nabawane hamosu. Amola e fa: no, hina bagade, e agoai hame ba: i.
26 Bí ó ti wù kí ó rí Olúwa kò yípadà kúrò nínú ìmúná ìbínú ńlá rẹ̀ tí ó jó sí Juda, nítorí gbogbo èyí tí Manase ti ṣe láti mú un bínú.
Be hina bagade Ma: na: se da musa: wadela: i hou bagade hamobeba: le, Hina Gode da Yuda fima ougi bagade heda: i, amola waha amolawane Ea ougi da hame gumi.
27 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí pé, “Èmi yóò mú Juda kúrò pẹ̀lú níwájú mi, bí mo ti mú Israẹli, èmi yóò sì kó Jerusalẹmu, ìlú ńlá tí mo yàn àti ilé Olúwa yìí, nípa èyí tí mo sọ, ‘Níbẹ̀ ni orúkọ mi yóò wà?’”
Hina Gode da amane sia: i, “Na da Isala: ili fima hamoi amo defele Na da Yuda fima hamomu. Na da Yuda dunu bu mae ba: ma: ne, mugululi fasimu. Amola Na da Yelusaleme amola Debolo Diasu, Na fi dunu da amogawi Nama nodone sia: ne gadomusa: ilegei dagoi. Be wali Na da Yelusaleme amola Debolo diasu amo higale, fisiagamu.”
28 Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Josiah, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Juda?
Yuda hina bagade Yousaia ea hawa: hamonanu eno huluane da “Yuda hina bagade Ilia Hamonanu Meloa” amo ganodini dedene legei.
29 Nígbà tí Josiah jẹ́ ọba, Farao Neko ọba Ejibiti gòkè lọ sí odò Eufurate láti lọ ran ọba Asiria lọ́wọ́. Ọba Josiah jáde lọ láti lọ bá a pàdé lójú ogun ṣùgbọ́n Neko dojúkọ ọ́, ó sì pa á ní Megido.
Yousaia da Yuda fi ouligilaloba, Idibidi hina bagade Nigou da Asilia hina bagade fidima: ne, ea dadi gagui wa: i amo Iufala: idisi Hanoga oule asi. Hina bagade Yousaia da Migidou moilai bai bagadega Idibidi dadi gagui wa: i ilia gusuba: i ahoasu amo hedofamusa: dawa: i, be amo gegesuga, e da medole legei dagoi ba: i.
30 Ìránṣẹ́ Josiah gbé ara rẹ̀ wá nínú kẹ̀kẹ́ láti Megido sí Jerusalẹmu ó sì sin ín sínú isà òkú rẹ̀. Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà mú Jehoahasi ọmọ Josiah. Ó fi àmì òróró yàn án, ó sì ṣe é ní ọba ní ipò baba a rẹ̀.
Ea dadi gagui wa: i ouligisu dunu ilia da ea bogoi da: i hodo amo ‘sa: liode’ da: iya ligisili, Yelusalemega bu gaguli misi. Amogawi, ilia da ea da: i hodo amo hina bagade bogoi uli dogosu sogebi amo ganodini uli dogone sali. Yuda fi dunu da Yousaia egefe Youaha: se amo hina bagade hamoma: ne, susuligi sogala: le ilegei dagoi.
31 Jehoahasi sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́tàlélógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún oṣù mẹ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Hamutali ọmọbìnrin Jeremiah; ó wá láti Libina.
Youaha: se da lalelegele, ode 23 esalu, e da muni Yuda hina bagade hamoi. E da Yelusalemega esala, oubi osodayale agoane Yuda fi ouligilalu. Ea ame da Hamiudale (Yelemaia ea idiwi. E da Libina moilai bai bagadega misi.)
32 Ó ṣe búburú lójú Olúwa gẹ́gẹ́ bí baba a rẹ̀ ti ṣe.
E da ea aowalali ilia hou defele, Hina Godema wadela: le hamoi.
33 Farao Neko sì fi sí inú ìdè ní Ribla ní ilẹ̀ Hamati, kí ó má ba à lè jẹ ọba ní Jerusalẹmu. Ó sì tan Juda jẹ fun iye ìwọ̀n ẹgbẹ̀rin tálẹ́ǹtì wúrà kan.
Idibidi hina bagade Nigou da Libila moilai bai bagadega (Ha: ima: de soge ganodini) amogawi Youaha: se gagulaligili, e da Yuda dunu ema silifa defei 3,000 gilo amola gouli 30 gilo dabe ema ima: ne sia: i.
34 Farao Neko ṣe Eliakimu ọmọ Josiah ní ọba ní ipò baba rẹ̀ Josiah. Ó sì yí orúkọ Eliakimu padà sí Jehoiakimu. Ṣùgbọ́n ó mú Jehoahasi, ó sì gbé e lọ sí Ejibiti, níbẹ̀ ni ó sì kú.
Hina bagade Nigou da Yousaia egefe eno Ilaiagime, amo Yousaia bagia Yuda hina bagade hamoi. E da Ilaiagime ea dio afadenene, bu Yihoiagimi dio ema asuli. Hina bagade Nigou da Youaha: se amo Idibidi sogega oule asili, e da amogawi bogoi.
35 Jehoiakimu sì san fún Farao Neko fàdákà àti wúrà tí ó béèrè. Láti ṣe bẹ́ẹ̀, ó bu owó òde fún ilẹ̀ náà láti san, ó fi agbára gba fàdákà àti wúrà láti ọwọ́ àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà ní ìbámu pẹ̀lú iye tí a pín.
Idibidi hina bagade da Yuda fi ilia ema su dabe ima: ne sia: i. Amo dabe hamomusa: , Yuda hina bagade Yihoiagimi da Yuda fi dunuma, liligi ilia gagui amo defele su dabe ima: ne sia: i.
36 Jehoiakimu jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlá orúkọ ìyá rẹ̀ ni Sebida ọmọbìnrin Pedaiah ó wá láti Ruma.
Yihoiagimi da lalelegele, ode 25 esalu, e da muni Yuda hina bagade hamoi. E da Yelusalemega esala, ode gidayale agoane Yuda fi ouligilalu. Ea ame da Sibiuda (Bida: ia ea idiwi. E da Luma moilaiga misi.)
37 Ó sì ṣe búburú lójú Olúwa gẹ́gẹ́ bí baba a rẹ̀ ti ṣe.
Yihoiagimi da ea aowalali fi defele, Hina Godema wadela: le hamoi.

< 2 Kings 23 >