< 2 Kings 22 >
1 Josiah jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́jọ nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlélọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jedida ọmọbìnrin Adaiah; ó wá láti Boskati.
Ośm lat było Jozyjaszowi, gdy począł królować, a trzydzieści jeden lat królował w Jeruzalemie; a imię matki jego było Jedyda, córka Adaja z Besekatu.
2 Ó sì ṣe èyí tí ó dára lójú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà Dafidi baba a rẹ̀, kò sì yípadà sí apá ọ̀tún tàbí sí apá òsì.
I czynił, co było dobrego przed oczyma Pańskiemi, chodząc wszystkimi drogami Dawida, ojca swego, a nie uchylał się ani na prawo ani na lewo.
3 Ní ọdún kejìdínlógún tí ó fi jẹ ọba. Ọba Josiah rán akọ̀wé, Ṣafani ọmọ Asalia, ọmọ Meṣullamu, sí ilé Olúwa. Ó wí pé,
A ośmnastego roku króla Jozyjasza posłał król Safana, syna Azalijaszowego, syna Mesulama, pisarza, do domu Pańskiego, mówiąc:
4 “Gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ Hilkiah olórí àlùfáà, kí o sì jẹ́ kí ó ṣírò iye owó tí a mú wá sí ilé Olúwa, tí àwọn olùṣọ́nà ti gbà lọ́wọ́ àwọn ènìyàn.
Idź do Helkijasza, kapłana najwyższego, aby zebrał pieniądze, które wnoszono do domu Pańskiego, które wybierali stróżowie progu od ludu.
5 Ẹ sì jẹ́ kí wọn ó fi lé àwọn ọkùnrin tí a ti yàn láti bojútó iṣẹ́ náà lórí ilé Olúwa. Kí ẹ sì jẹ́ kí àwọn ọkùnrin san án fún àwọn òṣìṣẹ́ tí ó ń tún ilé Olúwa ṣe.
A niech je dawają w ręce rzemieślników, przełożonych nad robotą domu Pańskiego, aby je dawali robotnikom, którzy robili w domu Pańskim, naprawiając skazę domu;
6 Àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà, àwọn ọ̀mọ̀lé àti àwọn akọ́lé. Bákan náà ni wọ́n ra igi àti òkúta ọlọ́ṣọ̀ọ́ láti fi tún tẹmpili ṣe.
To jest, budownikom i cieślom, i murarzom, i na zkupowanie drzewa, i kamienia ciosanego ku naprawie domu.
7 Ṣùgbọ́n wọn kò ní láti ṣe ìṣirò fún owó náà tí a fi fún wọn, nítorí wọ́n ṣe òtítọ́.”
Wszakże niech nie czynią liczby z pieniędzy, które dawają do rąk ich; bo oni wiernie nimi szafować będą.
8 Hilkiah olórí àlùfáà sọ fún Ṣafani akọ̀wé pé, “Èmi rí ìwé òfin nílé Olúwa.” Ó fi fún Ṣafani, ẹni tí ó kà á.
I rzekł Helkijasz, kapłan najwyższy, do Safana pisarza. Księgi zakonu znalazłem w domu Pańskim. I dał Helkijasz one księgi Safanowi, i czytał je (Safan).
9 Nígbà náà, Ṣafani akọ̀wé lọ sí ọ̀dọ̀ ọba. Ó sì sọ fún un pé, “Àwọn ìjòyè rẹ ti san owó náà tí ó wà nínú ilé Olúwa. Èmi sì ti fi lé ọwọ́ àwọn tí ó ń ṣe iṣẹ́ náà àti àwọn alábojútó nílé Olúwa.”
Przyszedłszy tedy Safan pisarz do króla, odniósł to królowi, i rzekł: Zebrali słudzy twoi pieniądze, które się znalazły w domu Pańskim, i oddali je w ręce rzemieślników przełożonych nad robotą w domu Pańskim.
10 Nígbà náà Ṣafani akọ̀wé sọ fún ọba pé, “Hilkiah àlùfáà ti fún un ní ìwé kan.” Ṣafani kà lára rẹ̀ níwájú ọba.
Oznajmił też Safan pisarz królowi, mówiąc: Dał mi księgę Helkijasz kapłan; i czytał ją Safan przed królem.
11 Nígbà tí ọba gbọ́ ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé òfin, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya.
A gdy usłyszał król słowa ksiąg zakonu, rozdarł szaty swe.
12 Ó pa àṣẹ yìí fún Ahikamu àlùfáà, Hilkiah ọmọ Ṣafani, Akbori ọmọ Mikaiah, àti Ṣafani akọ̀wé àti Asaiah ìránṣẹ́ ọba.
I rozkazał król Helkijaszowi kapłanowi, i Ahykamowi, synowi Safanowemu, i Achborowi, synowi Micheaszowemu, i Safanowi pisarzowi, i Asajaszowi, słudze swemu, mówiąc:
13 “Lọ, ẹ béèrè lọ́wọ́ Olúwa fún mi àti fún àwọn ènìyàn àti fún gbogbo Juda nípa ohun tí a kọ sínú ìwé yìí tí a ti rí. Títóbi ni ìbínú Olúwa tí ó ń jó sí wa nítorí àwọn baba wa kò tẹ̀lé ọ̀rọ̀ inú ìwé yìí; wọn kò ṣe ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ níbẹ̀ nípa wa.”
Idźcie, poradźcie się Pana o mię, i o lud, i o wszystkiego Judę z strony słów tych ksiąg, które są znalezione; bo wielki jest gniew Pański, który się zapalił przeciwko nam, przeto iż nie posłuchali ojcowie nasi słów tych ksiąg, żeby czynili według wszystkiego, co nam jest napisane.
14 Hilkiah àlùfáà, Ahikamu àti Akbori Ṣafani pẹ̀lú Asaiah, lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì obìnrin Hulda láti lọ bá a sọ̀rọ̀, ẹni tí ó jẹ́ aya Ṣallumu ọmọ Tikfa ọmọ Harhasi alábojútó ibi ìpa aṣọ mọ́ sí. Ó ń gbé ní Jerusalẹmu ní ìdàkejì.
A tak poszedł Helkijasz kapłan, i Ahykam, i Achbor, i Safan, i Azajasz, do Huldy prorokini, żony Selluma, syna Tekui, syna Araaszowego, który był stróżem szat; a ona mieszkała w Jeruzalemie na drugiej stronie miasta; i mówili z nią.
15 Ó wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, Sọ fún ọkùnrin tí ó rán an yín sí mi,
Która rzekła do nich: Tak mówi Pan, Bóg Izraelski. Powiedzcie mężowi, który was posłał do mnie;
16 ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Èmi yóò mú ibi wá sí ibí àti àwọn ènìyàn rẹ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ sínú ìwé tí ọba Juda ti kà.
Tak mówi Pan: Oto Ja przywiodę złe na to miejsce i na obywateli jego według wszystkich słów ksiąg tych, które czytał król Judzki.
17 Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, wọ́n sì tún sun tùràrí fún ọlọ́run mìíràn. Wọ́n sì mú mi bínú nípa gbogbo àwọn òrìṣà tí wọ́n ti fi ọwọ́ wọn dá. Ìbínú mi yóò ru sí ibí yìí, kì yóò sì rọlẹ̀.’
Przeto, że mię opuścili, i kadzili bogom cudzym, aby mię draźnili wszystkiemi sprawami rąk swoich, dla czego rozpaliła się popędliwość moja przeciwko miejscu temu, i nie będzie ugaszona.
18 Sọ fún ọba Juda tí ó rán yín láti béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí nípa ọ̀rọ̀ wọ̀n-ọn-nì tí ìwọ ti gbọ́.
A królowi Judzkiemu, który was posłał o radę do Pana, tak powiedzcie: Tak mówi Pan, Bóg Izraelski, o słowach, któreś słyszał:
19 Nítorí tí ọkàn rẹ rọ̀, tí ìwọ sì ti rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú Olúwa, nígbà tí ìwọ gbọ́ èyí tí mo sọ sí ibí yìí àti sí àwọn ènìyàn rẹ pé wọn yóò di ahoro àti ẹni ègún tí ìwọ sì fa aṣọ ọ̀ rẹ ya pẹ̀lú níwájú mi. Èmi ti gbọ́ tìrẹ, ni Olúwa wí.
Ponieważ zmiękczone jest serce twoje, a upokorzyłeś się przed obliczem Pańskiem, słysząc, com powiedział przeciwko temu miejscu, i przeciwko obywatelom jego, iż ma przyjść w spustoszenie i w przeklęstwo; rozdarłeś szaty swe, a płakałeś przedemną, i Jam cię też wysłuchał, mówi Pan.
20 Nítorí náà èmi yóò kó ọ jọ sí ọ̀dọ̀ àwọn baba à rẹ, a ó sì sin ọ́ ní àlàáfíà. Ojú rẹ kì yóò rí gbogbo àwọn ibi tí èmi yóò mú wá bá ibí yìí.’” Bẹ́ẹ̀ wọ́n mú èsì rẹ̀ padà tọ ọba wá.
Przetoż oto Ja cię zbiorę do ojców twoich, a będziesz zebrany do grobu twego w pokoju, aby nie oglądały oczy twoje wszystkiego złego, które Ja przywiodę na to miejsce. I odniesiono tę rzecz królowi.