< 2 Kings 22 >

1 Josiah jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́jọ nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlélọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jedida ọmọbìnrin Adaiah; ó wá láti Boskati.
Josias was of eiyte yeer, whanne he bigan to regne, and he regnyde oon and thritti yeer in Jerusalem; the name of his modir was Ydida, the douytir of Phadaia of Besechath.
2 Ó sì ṣe èyí tí ó dára lójú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà Dafidi baba a rẹ̀, kò sì yípadà sí apá ọ̀tún tàbí sí apá òsì.
And he dide that, that was plesaunt bifor the Lord, and he yede be alle the wayes of Dauid, his fadir; he bowide not, nethir to the riytside, nethir of the leftside.
3 Ní ọdún kejìdínlógún tí ó fi jẹ ọba. Ọba Josiah rán akọ̀wé, Ṣafani ọmọ Asalia, ọmọ Meṣullamu, sí ilé Olúwa. Ó wí pé,
Forsothe in the eiytenthe yeer of kyng Josias, the kyng sente Saphan, sone of Asua, the sone of Mesulam, scryueyn, ethir doctour, of the temple of the Lord,
4 “Gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ Hilkiah olórí àlùfáà, kí o sì jẹ́ kí ó ṣírò iye owó tí a mú wá sí ilé Olúwa, tí àwọn olùṣọ́nà ti gbà lọ́wọ́ àwọn ènìyàn.
and seide to him, Go thou to Elchie, the grete preest, that the money, which is borun in to the temple of the Lord, be spendid, which money the porteris of the temple han gaderid of the puple;
5 Ẹ sì jẹ́ kí wọn ó fi lé àwọn ọkùnrin tí a ti yàn láti bojútó iṣẹ́ náà lórí ilé Olúwa. Kí ẹ sì jẹ́ kí àwọn ọkùnrin san án fún àwọn òṣìṣẹ́ tí ó ń tún ilé Olúwa ṣe.
and that it be youun to crafti men bi the souereyns of the hows of the Lord; which also departide that money to hem that worchen in the temple of the Lord, to reparele the rooues of the temple of the Lord,
6 Àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà, àwọn ọ̀mọ̀lé àti àwọn akọ́lé. Bákan náà ni wọ́n ra igi àti òkúta ọlọ́ṣọ̀ọ́ láti fi tún tẹmpili ṣe.
that is, to carpenteris, and to masouns, and to hem that maken brokun thingis, and that trees and stoonus of quarieris be bouyt, to reparele the temple of the Lord;
7 Ṣùgbọ́n wọn kò ní láti ṣe ìṣirò fún owó náà tí a fi fún wọn, nítorí wọ́n ṣe òtítọ́.”
netheles siluer, which thei taken, be not rekynyd to hem, but haue thei in power, and in feith.
8 Hilkiah olórí àlùfáà sọ fún Ṣafani akọ̀wé pé, “Èmi rí ìwé òfin nílé Olúwa.” Ó fi fún Ṣafani, ẹni tí ó kà á.
Forsothe Helchie, the bischop, seide to Saphan, the scryuen, Y haue founde the book of the lawe in the hows of the Lord. And Elchie yaf the book to Saphan, the scryuen, which also redde it.
9 Nígbà náà, Ṣafani akọ̀wé lọ sí ọ̀dọ̀ ọba. Ó sì sọ fún un pé, “Àwọn ìjòyè rẹ ti san owó náà tí ó wà nínú ilé Olúwa. Èmi sì ti fi lé ọwọ́ àwọn tí ó ń ṣe iṣẹ́ náà àti àwọn alábojútó nílé Olúwa.”
Also Saphan, the scryuen, cam to the kyng, and telde to hym tho thingis, whiche Elchie hadde comaundid, and he seide, Thi seruauntis han spendid the monei, which was foundun in the hows of the Lord, and yauen, that it schulde be departid to crafti men of the souereyns of werkis of the temple of the Lord.
10 Nígbà náà Ṣafani akọ̀wé sọ fún ọba pé, “Hilkiah àlùfáà ti fún un ní ìwé kan.” Ṣafani kà lára rẹ̀ níwájú ọba.
Also Saphan, the scriueyn, telde to the kyng, and seide, Helchie, the preest of God, yaf to me a book; and whanne Saphan hadde red that book bifor the kyng,
11 Nígbà tí ọba gbọ́ ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé òfin, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya.
and the kyng hadde herd the wordis of the book of the lawe of the Lord, he to-rente hise clothis.
12 Ó pa àṣẹ yìí fún Ahikamu àlùfáà, Hilkiah ọmọ Ṣafani, Akbori ọmọ Mikaiah, àti Ṣafani akọ̀wé àti Asaiah ìránṣẹ́ ọba.
And he comaundide to Elchie, the preest, and to Aicham, sone of Saphan, and to Achabor, sone of Mycha, and to Saphan, the scryuen, and to Achia, seruaunt of the kyng,
13 “Lọ, ẹ béèrè lọ́wọ́ Olúwa fún mi àti fún àwọn ènìyàn àti fún gbogbo Juda nípa ohun tí a kọ sínú ìwé yìí tí a ti rí. Títóbi ni ìbínú Olúwa tí ó ń jó sí wa nítorí àwọn baba wa kò tẹ̀lé ọ̀rọ̀ inú ìwé yìí; wọn kò ṣe ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ níbẹ̀ nípa wa.”
and seide, Go ye, and `counsele ye the Lord on me, and on the puple, and on al Juda, of the wordis of this book, which is foundun; for greet ire of the Lord is kyndlid ayens vs, for oure fadris herden not the wordis of this book, to do al thing which is writun to vs.
14 Hilkiah àlùfáà, Ahikamu àti Akbori Ṣafani pẹ̀lú Asaiah, lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì obìnrin Hulda láti lọ bá a sọ̀rọ̀, ẹni tí ó jẹ́ aya Ṣallumu ọmọ Tikfa ọmọ Harhasi alábojútó ibi ìpa aṣọ mọ́ sí. Ó ń gbé ní Jerusalẹmu ní ìdàkejì.
Therfor Helchie, the preest, and Aicham, and Achabor, and Saphan, and Asia, yeden to Olda, the prophetesse, the wijf of Sellum, sone of Thecue, sone of Aras, kepere of the clothis, which Olda dwellide in Jerusalem, in the secounde dwellyng; and thei spaken to hir.
15 Ó wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, Sọ fún ọkùnrin tí ó rán an yín sí mi,
And sche answeride to hem, The Lord God of Israel seith these thingis, Seie ye to the man,
16 ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Èmi yóò mú ibi wá sí ibí àti àwọn ènìyàn rẹ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ sínú ìwé tí ọba Juda ti kà.
that sente you to me, The Lord God of Israel seith these thingis, Lo! Y schal brynge yuelis on this place, and on the dwelleris therof, alle the wordis `of the lawe, whiche the kyng of Juda redde;
17 Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, wọ́n sì tún sun tùràrí fún ọlọ́run mìíràn. Wọ́n sì mú mi bínú nípa gbogbo àwọn òrìṣà tí wọ́n ti fi ọwọ́ wọn dá. Ìbínú mi yóò ru sí ibí yìí, kì yóò sì rọlẹ̀.’
for thei forsoken me, and maden sacrifice to alien goddis, and terriden me to ire in alle the werkis of her hondis; and myn indignacioun schal be kyndlid in this place, and schal not be quenchid.
18 Sọ fún ọba Juda tí ó rán yín láti béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí nípa ọ̀rọ̀ wọ̀n-ọn-nì tí ìwọ ti gbọ́.
Sotheli to the kyng of Juda, that sente you, that ye schulen `counsele the Lord, ye schulen seie thus, The Lord God of Israel seith these thingis, For thou herdist the wordis of the book,
19 Nítorí tí ọkàn rẹ rọ̀, tí ìwọ sì ti rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú Olúwa, nígbà tí ìwọ gbọ́ èyí tí mo sọ sí ibí yìí àti sí àwọn ènìyàn rẹ pé wọn yóò di ahoro àti ẹni ègún tí ìwọ sì fa aṣọ ọ̀ rẹ ya pẹ̀lú níwájú mi. Èmi ti gbọ́ tìrẹ, ni Olúwa wí.
and thin herte was aferd, and thou were maad meke bifor the Lord, whanne the wordis weren herd ayens this place and ayens the dwelleris therof, that is, that thei schulden be maad in to wondryng, and in to cursyng, and thou to-rentist thi clothis, and weptist bifor me, and Y herde, seith the Lord;
20 Nítorí náà èmi yóò kó ọ jọ sí ọ̀dọ̀ àwọn baba à rẹ, a ó sì sin ọ́ ní àlàáfíà. Ojú rẹ kì yóò rí gbogbo àwọn ibi tí èmi yóò mú wá bá ibí yìí.’” Bẹ́ẹ̀ wọ́n mú èsì rẹ̀ padà tọ ọba wá.
herfor Y schal gadere thee to thi fadris, and thou schalt be gaderid to thi sepulcre in pees; that thin iyen se not alle the yuelis, whiche Y schal brynge yn on this place.

< 2 Kings 22 >