< 2 Kings 22 >

1 Josiah jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́jọ nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlélọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jedida ọmọbìnrin Adaiah; ó wá láti Boskati.
[was] a son of Eight year[s] Josiah when became king he and thirty and one year[s] he reigned in Jerusalem and [the] name of mother his [was] Jedidah [the] daughter of Adaiah from Bozkath.
2 Ó sì ṣe èyí tí ó dára lójú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà Dafidi baba a rẹ̀, kò sì yípadà sí apá ọ̀tún tàbí sí apá òsì.
And he did the right in [the] eyes of Yahweh and he walked in all [the] way of David ancestor his and not he turned aside right [hand] and left [hand].
3 Ní ọdún kejìdínlógún tí ó fi jẹ ọba. Ọba Josiah rán akọ̀wé, Ṣafani ọmọ Asalia, ọmọ Meṣullamu, sí ilé Olúwa. Ó wí pé,
And it was in eight-teen year of the king Josiah he sent the king Shaphan [the] son of Azaliah [the] son of Meshullam the scribe [the] house of Yahweh saying.
4 “Gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ Hilkiah olórí àlùfáà, kí o sì jẹ́ kí ó ṣírò iye owó tí a mú wá sí ilé Olúwa, tí àwọn olùṣọ́nà ti gbà lọ́wọ́ àwọn ènìyàn.
Go up to Hilkiah the priest great so he may complete the money which has been brought [the] house of Yahweh which they have gathered [the] keepers of the threshold from with the people.
5 Ẹ sì jẹ́ kí wọn ó fi lé àwọn ọkùnrin tí a ti yàn láti bojútó iṣẹ́ náà lórí ilé Olúwa. Kí ẹ sì jẹ́ kí àwọn ọkùnrin san án fún àwọn òṣìṣẹ́ tí ó ń tún ilé Olúwa ṣe.
(And let them put it *Q(k)*) on [the] hand of [the] doers of the work who were appointed ([the] house of *Q(K)*) Yahweh and let them give it to [the] doers of the work who [are] in [the] house of Yahweh to repair [the] damage of the house.
6 Àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà, àwọn ọ̀mọ̀lé àti àwọn akọ́lé. Bákan náà ni wọ́n ra igi àti òkúta ọlọ́ṣọ̀ọ́ láti fi tún tẹmpili ṣe.
To the craftsmen and to the builders and to the masons and to acquire wood and stones of hewing to repair the house.
7 Ṣùgbọ́n wọn kò ní láti ṣe ìṣirò fún owó náà tí a fi fún wọn, nítorí wọ́n ṣe òtítọ́.”
Only not it will be accounted for with them the money which is put on hand their for in faithfulness they [are] working.
8 Hilkiah olórí àlùfáà sọ fún Ṣafani akọ̀wé pé, “Èmi rí ìwé òfin nílé Olúwa.” Ó fi fún Ṣafani, ẹni tí ó kà á.
And he said Hilkiah the priest great to Shaphan the scribe [the] scroll of the law I found in [the] house of Yahweh and he gave Hilkiah the scroll to Shaphan and he read it.
9 Nígbà náà, Ṣafani akọ̀wé lọ sí ọ̀dọ̀ ọba. Ó sì sọ fún un pé, “Àwọn ìjòyè rẹ ti san owó náà tí ó wà nínú ilé Olúwa. Èmi sì ti fi lé ọwọ́ àwọn tí ó ń ṣe iṣẹ́ náà àti àwọn alábojútó nílé Olúwa.”
And he went Shaphan the scribe to the king and he brought back the king word and he said they have poured out servants your the money which was found in the house and they have put it on [the] hand of [the] doers of the work who were appointed [the] house of Yahweh.
10 Nígbà náà Ṣafani akọ̀wé sọ fún ọba pé, “Hilkiah àlùfáà ti fún un ní ìwé kan.” Ṣafani kà lára rẹ̀ níwájú ọba.
And he told Shaphan the scribe to the king saying a scroll he gave to me Hilkiah the priest and he read aloud it Shaphan before the king.
11 Nígbà tí ọba gbọ́ ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé òfin, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya.
And it was when heard the king [the] words of [the] scroll of the law and he tore clothes his.
12 Ó pa àṣẹ yìí fún Ahikamu àlùfáà, Hilkiah ọmọ Ṣafani, Akbori ọmọ Mikaiah, àti Ṣafani akọ̀wé àti Asaiah ìránṣẹ́ ọba.
And he commanded the king Hilkiah the priest and Ahikam [the] son of Shaphan and Achbor [the] son of Micaiah and - Shaphan the scribe and Asaiah [the] servant of the king saying.
13 “Lọ, ẹ béèrè lọ́wọ́ Olúwa fún mi àti fún àwọn ènìyàn àti fún gbogbo Juda nípa ohun tí a kọ sínú ìwé yìí tí a ti rí. Títóbi ni ìbínú Olúwa tí ó ń jó sí wa nítorí àwọn baba wa kò tẹ̀lé ọ̀rọ̀ inú ìwé yìí; wọn kò ṣe ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ níbẹ̀ nípa wa.”
Go consult Yahweh for me and for the people and for all Judah on [the] words of the scroll which had been found this for [is] great [the] anger of Yahweh which it it has been kindled in us on that not they listened ancestors our to [the] words of the scroll this to do according to every [thing] written on us.
14 Hilkiah àlùfáà, Ahikamu àti Akbori Ṣafani pẹ̀lú Asaiah, lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì obìnrin Hulda láti lọ bá a sọ̀rọ̀, ẹni tí ó jẹ́ aya Ṣallumu ọmọ Tikfa ọmọ Harhasi alábojútó ibi ìpa aṣọ mọ́ sí. Ó ń gbé ní Jerusalẹmu ní ìdàkejì.
And he went Hilkiah the priest and Ahikam and Achbor and Shaphan and Asaiah to Huldah the prophetess [the] wife of - Shallum [the] son of Tikvah [the] son of Harhas [the] keeper of the garments and she [was] dwelling in Jerusalem in the second district and they spoke to her.
15 Ó wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, Sọ fún ọkùnrin tí ó rán an yín sí mi,
And she said to them thus he says Yahweh [the] God of Israel say to the man who he sent you to me.
16 ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Èmi yóò mú ibi wá sí ibí àti àwọn ènìyàn rẹ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ sínú ìwé tí ọba Juda ti kà.
Thus he says Yahweh here I [am] about to bring calamity to the place this and on inhabitants its all [the] words of the scroll which he has read [the] king of Judah.
17 Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, wọ́n sì tún sun tùràrí fún ọlọ́run mìíràn. Wọ́n sì mú mi bínú nípa gbogbo àwọn òrìṣà tí wọ́n ti fi ọwọ́ wọn dá. Ìbínú mi yóò ru sí ibí yìí, kì yóò sì rọlẹ̀.’
Because - that they have forsaken me and they have made smoke to gods other so as to provoke to anger me by all [the] work of hands their and it will be kindled anger my in the place this and not it will be quenched.
18 Sọ fún ọba Juda tí ó rán yín láti béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí nípa ọ̀rọ̀ wọ̀n-ọn-nì tí ìwọ ti gbọ́.
And to [the] king of Judah who sent you to consult Yahweh thus you will say to him thus he says Yahweh [the] God of Israel the words which you have heard.
19 Nítorí tí ọkàn rẹ rọ̀, tí ìwọ sì ti rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú Olúwa, nígbà tí ìwọ gbọ́ èyí tí mo sọ sí ibí yìí àti sí àwọn ènìyàn rẹ pé wọn yóò di ahoro àti ẹni ègún tí ìwọ sì fa aṣọ ọ̀ rẹ ya pẹ̀lú níwájú mi. Èmi ti gbọ́ tìrẹ, ni Olúwa wí.
Because it was soft heart your and you humbled yourself - from before Yahweh when hearing you [that] which I had spoken on the place this and on inhabitants its to become a horror and a curse and you tore clothes your and you wept before me and also I I have heard [the] utterance of Yahweh.
20 Nítorí náà èmi yóò kó ọ jọ sí ọ̀dọ̀ àwọn baba à rẹ, a ó sì sin ọ́ ní àlàáfíà. Ojú rẹ kì yóò rí gbogbo àwọn ibi tí èmi yóò mú wá bá ibí yìí.’” Bẹ́ẹ̀ wọ́n mú èsì rẹ̀ padà tọ ọba wá.
Therefore here I [will] gather you to ancestors your and you will be gathered to grave your in peace and not they will look eyes your on all the distress which I [will] bring on the place this and they brought back the king word.

< 2 Kings 22 >