< 2 Kings 22 >
1 Josiah jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́jọ nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlélọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jedida ọmọbìnrin Adaiah; ó wá láti Boskati.
Josias var otte Aar gammel, der han blev Konge, og regerede et og tredive Aar i Jerusalem, og hans Moders Navn var Jedida, Adajas Datter fra Bozkath.
2 Ó sì ṣe èyí tí ó dára lójú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà Dafidi baba a rẹ̀, kò sì yípadà sí apá ọ̀tún tàbí sí apá òsì.
Og han gjorde det, som var ret for Herrens Øjne, og vandrede i al Davids, sin Faders, Vej og veg ikke til den højre eller venstre Side.
3 Ní ọdún kejìdínlógún tí ó fi jẹ ọba. Ọba Josiah rán akọ̀wé, Ṣafani ọmọ Asalia, ọmọ Meṣullamu, sí ilé Olúwa. Ó wí pé,
Og det skete i Kong Josias's attende Aar, da sendte Kongen Safan, en Søn af Azalia, Mesullams Søn, Kansleren, til Herrens Hus og sagde:
4 “Gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ Hilkiah olórí àlùfáà, kí o sì jẹ́ kí ó ṣírò iye owó tí a mú wá sí ilé Olúwa, tí àwọn olùṣọ́nà ti gbà lọ́wọ́ àwọn ènìyàn.
Gak op til Hilkia, Ypperstepræsten, og lad ham samle i en Sum de Penge, som ere bragte til Herrens Hus, som Dørvogterne have samlet ind fra Folket,
5 Ẹ sì jẹ́ kí wọn ó fi lé àwọn ọkùnrin tí a ti yàn láti bojútó iṣẹ́ náà lórí ilé Olúwa. Kí ẹ sì jẹ́ kí àwọn ọkùnrin san án fún àwọn òṣìṣẹ́ tí ó ń tún ilé Olúwa ṣe.
og lad dem give dem i deres Haand, som have med Gerningen at gøre, og som ere beskikkede til Opsynsmænd ved Herrens Hus; og disse skulle give dem til dem, som gøre Gerningen, som sker ved Herrens Hus, for at udbedre Husets Brøst:
6 Àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà, àwọn ọ̀mọ̀lé àti àwọn akọ́lé. Bákan náà ni wọ́n ra igi àti òkúta ọlọ́ṣọ̀ọ́ láti fi tún tẹmpili ṣe.
Til Tømmermændene og Bygningsmændene og Murmestrene og til at købe Træ og hugne Stene til at udbedre Huset.
7 Ṣùgbọ́n wọn kò ní láti ṣe ìṣirò fún owó náà tí a fi fún wọn, nítorí wọ́n ṣe òtítọ́.”
Dog tog man ikke Regnskab af dem for de Penge, som gaves i deres Haand; thi de handlede redeligt.
8 Hilkiah olórí àlùfáà sọ fún Ṣafani akọ̀wé pé, “Èmi rí ìwé òfin nílé Olúwa.” Ó fi fún Ṣafani, ẹni tí ó kà á.
Og Hilkia, Ypperstepræsten, sagde til Safan, Kansleren: Jeg har fundet Lovbogen i Herrens Hus; og Hilkia gav Safan Bogen, og han læste den.
9 Nígbà náà, Ṣafani akọ̀wé lọ sí ọ̀dọ̀ ọba. Ó sì sọ fún un pé, “Àwọn ìjòyè rẹ ti san owó náà tí ó wà nínú ilé Olúwa. Èmi sì ti fi lé ọwọ́ àwọn tí ó ń ṣe iṣẹ́ náà àti àwọn alábojútó nílé Olúwa.”
Og Safan, Kansleren, kom til Kongen og bragte Kongen Svar tilbage og sagde: Dine Tjenere samlede de Penge, som fandtes i Huset, og gave dem i deres Haand, som have med Gerningen at gøre, og som ere beskikkede til Opsynsmænd ved Herrens Hus.
10 Nígbà náà Ṣafani akọ̀wé sọ fún ọba pé, “Hilkiah àlùfáà ti fún un ní ìwé kan.” Ṣafani kà lára rẹ̀ níwájú ọba.
Og Safan, Kansleren, forkyndte Kongen og sagde: Hilkia, Præsten, gav mig en Bog, og Safan læste den for Kongens Ansigt.
11 Nígbà tí ọba gbọ́ ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé òfin, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya.
Og det skete, der Kongen hørte Lovbogens Ord, da sønderrev han sine Klæder.
12 Ó pa àṣẹ yìí fún Ahikamu àlùfáà, Hilkiah ọmọ Ṣafani, Akbori ọmọ Mikaiah, àti Ṣafani akọ̀wé àti Asaiah ìránṣẹ́ ọba.
Og Kongen bød Hilkia, Præsten, og Ahikam, Safans Søn, og Akbor, Mikajas Søn, og Safan, Kansleren, og Asaja, Kongens Tjener, og sagde:
13 “Lọ, ẹ béèrè lọ́wọ́ Olúwa fún mi àti fún àwọn ènìyàn àti fún gbogbo Juda nípa ohun tí a kọ sínú ìwé yìí tí a ti rí. Títóbi ni ìbínú Olúwa tí ó ń jó sí wa nítorí àwọn baba wa kò tẹ̀lé ọ̀rọ̀ inú ìwé yìí; wọn kò ṣe ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ níbẹ̀ nípa wa.”
Gaar hen, adspørger Herren for mig og for Folket og for al Juda om denne Bogs Ord, som er funden; thi stor er Herrens Vrede, som er optændt imod os, fordi vore Fædre ikke have hørt paa denne Bogs Ord, saa de have gjort efter alt det, som er skrevet for os.
14 Hilkiah àlùfáà, Ahikamu àti Akbori Ṣafani pẹ̀lú Asaiah, lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì obìnrin Hulda láti lọ bá a sọ̀rọ̀, ẹni tí ó jẹ́ aya Ṣallumu ọmọ Tikfa ọmọ Harhasi alábojútó ibi ìpa aṣọ mọ́ sí. Ó ń gbé ní Jerusalẹmu ní ìdàkejì.
Da gik Hilkia, Præsten, og Ahikam og Akbor og Safan og Asaja til Profetinden Hulda, som var gift med Sallum, der var en Søn af Tikva, en Søn af Harhas, og havde Tilsyn med Klæderne, og hun boede i Jerusalem i den anden Del, og de talte til hende.
15 Ó wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, Sọ fún ọkùnrin tí ó rán an yín sí mi,
Og hun sagde til dem: saa sagde Herren, Israels Gud: Siger til den Mand, som sendte eder til mig:
16 ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Èmi yóò mú ibi wá sí ibí àti àwọn ènìyàn rẹ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ sínú ìwé tí ọba Juda ti kà.
Saa sagde Herren: Se, jeg fører Ulykke over dette Sted og over dets Indbyggere, nemlig alle Bogens Ord, som Judas Konge læste.
17 Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, wọ́n sì tún sun tùràrí fún ọlọ́run mìíràn. Wọ́n sì mú mi bínú nípa gbogbo àwọn òrìṣà tí wọ́n ti fi ọwọ́ wọn dá. Ìbínú mi yóò ru sí ibí yìí, kì yóò sì rọlẹ̀.’
Fordi de have forladt mig og gjort Røgelse for andre Guder til at opirre mig med al deres Hænders Gerning, derfor skal min Vrede optændes imod dette Sted og ikke udslukkes.
18 Sọ fún ọba Juda tí ó rán yín láti béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí nípa ọ̀rọ̀ wọ̀n-ọn-nì tí ìwọ ti gbọ́.
Men til Judas Konge, som sendte eder for at adspørge Herren, til ham skulle I sige saaledes: Saa sagde Herren, Israels Gud, angaaende de Ord, som du har hørt:
19 Nítorí tí ọkàn rẹ rọ̀, tí ìwọ sì ti rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú Olúwa, nígbà tí ìwọ gbọ́ èyí tí mo sọ sí ibí yìí àti sí àwọn ènìyàn rẹ pé wọn yóò di ahoro àti ẹni ègún tí ìwọ sì fa aṣọ ọ̀ rẹ ya pẹ̀lú níwájú mi. Èmi ti gbọ́ tìrẹ, ni Olúwa wí.
Fordi dit Hjerte er blevet blødt, og du ydmygede dig for Herrens Ansigt, da du hørte, hvad jeg har talt imod dette Sted og imod dets Indbyggere, at de skulle blive til Ødelæggelse og til Forbandelse, og du sønderrev dine Klæder og græd for mit Ansigt: Saa har ogsaa jeg hørt det, siger Herren.
20 Nítorí náà èmi yóò kó ọ jọ sí ọ̀dọ̀ àwọn baba à rẹ, a ó sì sin ọ́ ní àlàáfíà. Ojú rẹ kì yóò rí gbogbo àwọn ibi tí èmi yóò mú wá bá ibí yìí.’” Bẹ́ẹ̀ wọ́n mú èsì rẹ̀ padà tọ ọba wá.
Derfor se, jeg vil samle dig til dine Fædre, og du skal samles med dem i din Grav i Fred, og dine Øjne skulle ikke se paa al den Ulykke, som jeg vil føre over dette Sted. Og de bragte Kongen Svar tilbage.