< 2 Kings 21 >

1 Manase jẹ́ ẹni ọdún méjìlá nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ìjọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún márùndínlọ́gọ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Hẹfisiba.
Manase era în vârstă de doisprezece ani când a început să domnească și a domnit cincizeci și cinci de ani în Ierusalim. Și numele mamei lui era Hefțiba.
2 Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa, ó sì tẹ̀lé iṣẹ́ ìríra tí àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
Și el a făcut ce este rău înaintea ochilor DOMNULUI, după urâciunile păgânilor pe care DOMNUL îi alungase dinaintea copiilor lui Israel.
3 Ó sì tún ibi gíga tí baba rẹ̀ Hesekiah tí ó parun kọ́. Ó sì tún gbé pẹpẹ Baali dìde, ó sì ṣe ère òrìṣà Aṣerah, gẹ́gẹ́ bí Ahabu ọba Israẹli ti ṣe. Ó sì tẹríba sí gbogbo ogun ọ̀run, ó sì ń sìn wọ́n.
Fiindcă el a zidit din nou înălțimile pe care Ezechia, tatăl său, le distrusese; și a ridicat altare lui Baal și a făcut o dumbravă, precum făcuse Ahab, împăratul lui Israel; și s-a închinat înaintea întregii oștiri a cerului și le-a servit.
4 Ó sì kọ́ pẹpẹ nínú ilé tí a kọ́ fún Olúwa, èyí tí Olúwa ti sọ pé, “Ní Jerusalẹmu ni èmi yóò kọ orúkọ mi sí.”
Și el a zidit altare în casa DOMNULUI, despre care DOMNUL spusese: În Ierusalim voi pune numele meu.
5 Ní àgbàlá méjèèjì ilé Olúwa, ó sì kọ́ pẹpẹ fún gbogbo àwọn ìrúbọ nínú ilé, ṣe iṣẹ́ àkíyèsí àfọ̀ṣẹ, ó sì béèrè lọ́wọ́ àwọn òkú àti àwọn oṣó. Ó sì ṣe ọ̀pọ̀ búburú ní ojú Olúwa, ó sì mú un bínú.
Și a zidit altare pentru toată oștirea cerului în cele două curți ale casei DOMNULUI.
6 Ó fi àwọn ọmọ ara rẹ̀ rú ẹbọ nínú iná, ó ń ṣe àkíyèsí àfọ̀ṣẹ, ó sì ń lo àlúpàyídà, ó sì ń bá àwọn òku àti oṣó lò. Ó ṣe ọ̀pọ̀ ohun búburú ní ojú Olúwa láti mú un bínú.
Și și-a trecut fiul prin foc și a prezis viitorul și folosea descântare și consulta demoni și vrăjitori; a lucrat multă stricăciune înaintea ochilor DOMNULUI, pentru a-l provoca la mânie.
7 Ó sì gbé ère fínfín òrìṣà Aṣerah tí ó ti ṣe, ó sì gbé e sínú ilé Olúwa, èyí tí Olúwa ti sọ fún Dafidi àti sí ọmọ rẹ̀ Solomoni, “Nínú ilé Olúwa yìí àti ní Jerusalẹmu, tí èmi ti yàn jáde lára gbogbo ẹ̀yà Israẹli, èmi yóò kọ orúkọ mi títí láéláé.
Și a pus un chip cioplit al dumbrăvii, pe care îl făcuse, în casa despre care DOMNUL spusese lui David și lui Solomon, fiul său: În această casă și în Ierusalim, pe care l-am ales dintre toate triburile lui Israel, voi pune numele meu pentru totdeauna;
8 Èmi kò ní jẹ́ kí ẹsẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli yẹ̀ kúrò láti ilẹ̀ tí èmi fi fún àwọn baba ńlá wọn tí ó bá jẹ́ wí pé wọn yóò ṣe àkíyèsí láti ṣe gbogbo ohun tí èmi ti paláṣẹ fún wọn kí wọn sì pa gbogbo òfin tí ìránṣẹ́ mi Mose fi fún wọn mọ́.”
Și nu voi face picioarele lui Israel să mai iasă din țara pe care am dat-o părinților lor; numai dacă vor lua seama să facă după toate câte le-am poruncit și conform cu toată legea pe care servitorul meu, Moise, le-a poruncit-o.
9 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà kò tẹ́tí. Manase tàn wọ́n síwájú, bẹ́ẹ̀ ni kí wọ́n lè ṣe búburú ju gbogbo orílẹ̀-èdè tí Olúwa tí parun níwájú àwọn ọmọ Israẹli lọ.
Dar ei nu au dat ascultare; și Manase i-a amăgit pentru a face mai mult rău decât au făcut națiunile pe care DOMNUL le nimicise dinaintea copiilor lui Israel.
10 Olúwa sì wí nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ wòlíì pé,
Și DOMNUL a vorbit prin servitorii săi, profeții, spunând:
11 “Manase ọba Juda ti ṣe ẹ̀ṣẹ̀ ohun ìríra. Ó ti ṣe ohun búburú jùlọ ju àwọn ará Amori lọ ẹni tí ó ti wà ṣáájú rẹ̀ tí ó sì ti ṣáájú Juda sínú ẹ̀ṣẹ̀ pẹ̀lú àwọn ère rẹ̀.
Deoarece Manase, împăratul lui Iuda, a făcut aceste urâciuni și a lucrat cu stricăciune mai mult decât tot ce au făcut amoriții, care au fost înainte de el și a făcut de asemenea pe Iuda să păcătuiască cu idolii săi,
12 Nítorí náà èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, wí, Èmi le è lọ mú irú ibi báyìí wá sórí Jerusalẹmu àti Juda kí gbogbo etí olúkúlùkù tí ó gbọ́ nípa rẹ̀ le è hó.
De aceea astfel spune DOMNUL Dumnezeul lui Israel: Iată, voi aduce asupra Ierusalimului și a lui Iuda un astfel de rău, încât oricine aude de acesta, amândouă urechile îi vor țiui.
13 Èmi yóò sì nà okùn ìwọ̀n kan tí a lò lórí Jerusalẹmu àti lórí Samaria àti òjé ìdiwọ̀n ti a lò lórí ilé Ahabu. Èmi yóò sì nu Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí ọkàn tí ń nu àwokòtò nù tí o ń nù un tí o sì ń dorí rẹ̀ kodò.
Și voi întinde peste Ierusalim frânghia Samariei și firul cu plumb al casei lui Ahab; și voi șterge Ierusalimul precum un om șterge un vas, ștergându-l și răsturnându-l.
14 Èmi yóò sì kọ ìyókù àwọn ìní mi sílẹ̀ èmi yóò sì kó wọn lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́. Wọn yóò sì di ìkógun àti ìjẹ fún gbogbo àwọn ọ̀tá wọn,
Și voi părăsi rămășița moștenirii mele și îi voi da în mâna dușmanilor lor; și ei vor deveni un vânat și o pradă pentru dușmanii lor;
15 nítorí pé wọ́n ti ṣe búburú ní ojú mi, wọ́n sì ti mú mi bínú láti ọjọ́ tí baba ńlá wọn ti jáde wá láti Ejibiti títí di òní yìí.”
Pentru că au făcut ce este rău înaintea ochilor mei și m-au provocat la mânie, din ziua în care părinții lor au ieșit din Egipt, până în această zi.
16 Pẹ̀lúpẹ̀lú, Manase pẹ̀lú ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ púpọ̀ tí ó kún Jerusalẹmu láti ìkangun dé ìkangun ní ẹ̀gbẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ti mú Juda ṣẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni, kí wọ́n lè ṣe ohun búburú ní ojú Olúwa.
Mai mult, Manase a vărsat foarte mult sânge nevinovat, până ar fi umplut Ierusalimul de la o margine la cealaltă, în afară de păcatul său cu care a făcut pe Iuda să păcătuiască, făcând ce este rău înaintea ochilor DOMNULUI.
17 Ní ti iṣẹ́ ìyókù ti ìjọba Manase, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, àti fún ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀, ṣé wọ́n kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn àwọn ọba Juda?
Și restul faptelor lui Manase și tot ce a făcut și păcatul său cu care a păcătuit, nu sunt ele scrise în cartea cronicilor împăraților lui Iuda?
18 Manase sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ wọ́n sì sin ín nínú ọgbà ààfin rẹ̀, ọgbà Ussa. Amoni ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Și Manase a adormit cu părinții săi și a fost îngropat în grădina casei lui, în grădina lui Uza; și Amon, fiul său, a domnit în locul său.
19 Amoni jẹ́ ẹni ọdún méjìlélógún nígbà tí ó jẹ ọba. Orúkọ màmá rẹ̀ a sì máa jẹ́ Meṣulemeti ọmọbìnrin Harusi: ó wá láti Jotba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún méjì.
Amon era în vârstă de douăzeci și doi de ani când a început să domnească și a domnit doi ani în Ierusalim. Și numele mamei lui era Meșulemet, fiica lui Haruț, din Iotba.
20 Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa àti gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ Manase ti ṣe.
Și el a făcut ce este rău înaintea ochilor DOMNULUI, precum făcuse tatăl său, Manase.
21 Ó rìn ní gbogbo ọ̀nà baba rẹ̀: Ó sì ń sin àwọn ère tí baba rẹ̀ ń sìn, ó sì ń tẹrí rẹ̀ ba fún wọn.
Și a umblat în toată calea în care tatăl său a umblat și a servit idolilor cărora tatăl său servise și s-a închinat înaintea lor;
22 Ó sì kọ Olúwa Ọlọ́run baba rẹ̀ sílẹ̀ kò sì rìn ní ọ̀nà ti Olúwa.
Și a părăsit pe DOMNUL Dumnezeul părinților săi și nu a umblat în calea DOMNULUI.
23 Àwọn ìránṣẹ́ Amoni dìtẹ̀ lórí rẹ̀ wọ́n sì lu ọba pa ní àárín ilé rẹ̀.
Și servitorii lui Amon au uneltit împotriva lui și l-au ucis pe împărat în casa lui.
24 Nígbà náà àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà pa gbogbo àwọn tí ó dìtẹ̀ sí ọba Amoni, wọ́n sì fi Josiah ọmọ rẹ̀ jẹ ọba ní ààyè rẹ̀.
Și poporul țării a ucis pe toți cei care uneltiseră împotriva împăratului Amon; și poporul țării l-a făcut pe Iosia, fiul său, împărat în locul său.
25 Àti gẹ́gẹ́ bí ìyókù iṣẹ́ ti ìjọba Amoni àti ohun tí ó ṣe, ṣé wọn kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn àwọn ọba Juda?
Și restul faptelor lui Amon, pe care le-a făcut, nu sunt ele scrise în cartea cronicilor împăraților lui Iuda?
26 Wọ́n sì sin ín sínú isà òkú nínú ọgbà Ussa. Josiah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Și el a fost îngropat în mormântul său în grădina lui Uza; și Iosia, fiul său, a domnit în locul său.

< 2 Kings 21 >