< 2 Kings 21 >

1 Manase jẹ́ ẹni ọdún méjìlá nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ìjọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún márùndínlọ́gọ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Hẹfisiba.
Ve dvanácti letech byl Manasses, když počal kralovati, a kraloval padesáte a pět let v Jeruzalémě. Jméno matky jeho bylo Chefziba.
2 Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa, ó sì tẹ̀lé iṣẹ́ ìríra tí àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
I činil to, což jest zlého před očima Hospodinovýma, vedlé ohavností těch národů, kteréž Hospodin vyplénil před syny Izraelskými.
3 Ó sì tún ibi gíga tí baba rẹ̀ Hesekiah tí ó parun kọ́. Ó sì tún gbé pẹpẹ Baali dìde, ó sì ṣe ère òrìṣà Aṣerah, gẹ́gẹ́ bí Ahabu ọba Israẹli ti ṣe. Ó sì tẹríba sí gbogbo ogun ọ̀run, ó sì ń sìn wọ́n.
Nebo převrátiv se, vzdělal zase výsosti, kteréž byl zkazil Ezechiáš otec jeho, a vystavěl oltáře Bálovi, a vysadil háj, tak jako byl učinil Achab král Izraelský. A klaněje se všemu vojsku nebeskému, ctil je.
4 Ó sì kọ́ pẹpẹ nínú ilé tí a kọ́ fún Olúwa, èyí tí Olúwa ti sọ pé, “Ní Jerusalẹmu ni èmi yóò kọ orúkọ mi sí.”
Vzdělal také oltáře v domě Hospodinově, o němž byl řekl Hospodin: V Jeruzalémě položím jméno své.
5 Ní àgbàlá méjèèjì ilé Olúwa, ó sì kọ́ pẹpẹ fún gbogbo àwọn ìrúbọ nínú ilé, ṣe iṣẹ́ àkíyèsí àfọ̀ṣẹ, ó sì béèrè lọ́wọ́ àwọn òkú àti àwọn oṣó. Ó sì ṣe ọ̀pọ̀ búburú ní ojú Olúwa, ó sì mú un bínú.
Nadto nadělal oltářů všemu vojsku nebeskému, v obou síních domu Hospodinova.
6 Ó fi àwọn ọmọ ara rẹ̀ rú ẹbọ nínú iná, ó ń ṣe àkíyèsí àfọ̀ṣẹ, ó sì ń lo àlúpàyídà, ó sì ń bá àwọn òku àti oṣó lò. Ó ṣe ọ̀pọ̀ ohun búburú ní ojú Olúwa láti mú un bínú.
Syna také svého provedl skrze oheň, a šetřil časů, s hadačstvím zacházel, zaklinače a čarodějníky zřídil, a velmi mnoho zlého činil před očima Hospodinovýma, popouzeje ho.
7 Ó sì gbé ère fínfín òrìṣà Aṣerah tí ó ti ṣe, ó sì gbé e sínú ilé Olúwa, èyí tí Olúwa ti sọ fún Dafidi àti sí ọmọ rẹ̀ Solomoni, “Nínú ilé Olúwa yìí àti ní Jerusalẹmu, tí èmi ti yàn jáde lára gbogbo ẹ̀yà Israẹli, èmi yóò kọ orúkọ mi títí láéláé.
Postavil také rytinu háje, kterouž byl udělal v domě, o kterémž byl řekl Hospodin k Davidovi a Šalomounovi synu jeho: V domě tomto a v Jeruzalémě, kterýž jsem vyvolil ze všech pokolení Izraelských, položím jméno své na věky,
8 Èmi kò ní jẹ́ kí ẹsẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli yẹ̀ kúrò láti ilẹ̀ tí èmi fi fún àwọn baba ńlá wọn tí ó bá jẹ́ wí pé wọn yóò ṣe àkíyèsí láti ṣe gbogbo ohun tí èmi ti paláṣẹ fún wọn kí wọn sì pa gbogbo òfin tí ìránṣẹ́ mi Mose fi fún wọn mọ́.”
Aniž více dopustím, aby se pohnula noha Izraele z země, kterouž jsem dal otcům jejich, jen toliko budou-li skutečně ostříhati všeho, což jsem jim přikázal, a všeho zákona, kterýž jim vydal Mojžíš služebník můj.
9 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà kò tẹ́tí. Manase tàn wọ́n síwájú, bẹ́ẹ̀ ni kí wọ́n lè ṣe búburú ju gbogbo orílẹ̀-èdè tí Olúwa tí parun níwájú àwọn ọmọ Israẹli lọ.
Ale neuposlechli; nebo je svedl Manasses, tak že činili horší věci, nežli ti národové, kteréž vyplénil Hospodin od tváři synů Izraelských,
10 Olúwa sì wí nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ wòlíì pé,
Ačkoli mluvíval Hospodin skrze služebníky své proroky, řka:
11 “Manase ọba Juda ti ṣe ẹ̀ṣẹ̀ ohun ìríra. Ó ti ṣe ohun búburú jùlọ ju àwọn ará Amori lọ ẹni tí ó ti wà ṣáájú rẹ̀ tí ó sì ti ṣáájú Juda sínú ẹ̀ṣẹ̀ pẹ̀lú àwọn ère rẹ̀.
Proto že činil Manasses král Judský ohavnosti tyto, a páchal horší věci nad všecko, což činili Amorejští, kteříž byli před ním, a že přivedl i Judu k hřešení skrze ukydané bohy své,
12 Nítorí náà èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, wí, Èmi le è lọ mú irú ibi báyìí wá sórí Jerusalẹmu àti Juda kí gbogbo etí olúkúlùkù tí ó gbọ́ nípa rẹ̀ le è hó.
Protož řekl Hospodin Bůh Izraelský: Aj, já uvedu zlé věci na Jeruzalém a na Judu, aby každému slyšícímu o tom znělo v obou uších jeho.
13 Èmi yóò sì nà okùn ìwọ̀n kan tí a lò lórí Jerusalẹmu àti lórí Samaria àti òjé ìdiwọ̀n ti a lò lórí ilé Ahabu. Èmi yóò sì nu Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí ọkàn tí ń nu àwokòtò nù tí o ń nù un tí o sì ń dorí rẹ̀ kodò.
Nebo vztáhnu na Jeruzalém šňůru Samařskou, a závaží domu Achabova, a vytru Jeruzalém, jako vytírá někdo misku, a vytra, poklopí ji.
14 Èmi yóò sì kọ ìyókù àwọn ìní mi sílẹ̀ èmi yóò sì kó wọn lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́. Wọn yóò sì di ìkógun àti ìjẹ fún gbogbo àwọn ọ̀tá wọn,
A opustím ostatky dědictví svého, a vydám je v ruku nepřátel jejich, i budou v loupež a v rozchvátání všechněm nepřátelům svým,
15 nítorí pé wọ́n ti ṣe búburú ní ojú mi, wọ́n sì ti mú mi bínú láti ọjọ́ tí baba ńlá wọn ti jáde wá láti Ejibiti títí di òní yìí.”
Proto že činili to, což jest zlého před očima mýma, a popouzeli mne od toho dne, jakž vyšli otcové jejich z Egypta, až do dnešního dne.
16 Pẹ̀lúpẹ̀lú, Manase pẹ̀lú ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ púpọ̀ tí ó kún Jerusalẹmu láti ìkangun dé ìkangun ní ẹ̀gbẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ti mú Juda ṣẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni, kí wọ́n lè ṣe ohun búburú ní ojú Olúwa.
Ano i krve nevinné vylil Manasses velmi mnoho, tak že naplnil Jeruzalém od jednoho konce k druhému, kromě hříchu svého, kterýmž přivedl k hřešení Judu, aby činili, což zlého jest před očima Hospodinovýma.
17 Ní ti iṣẹ́ ìyókù ti ìjọba Manase, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, àti fún ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀, ṣé wọ́n kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn àwọn ọba Juda?
O jiných pak činech Manassesových, a cožkoli činil, i hřích jeho, kterýmž zhřešil, zapsáno jest v knize o králích Judských.
18 Manase sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ wọ́n sì sin ín nínú ọgbà ààfin rẹ̀, ọgbà Ussa. Amoni ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
I usnul Manasses s otci svými, a pohřben jest v zahradě domu svého, v zahradě Uzy, a kraloval Amon syn jeho místo něho.
19 Amoni jẹ́ ẹni ọdún méjìlélógún nígbà tí ó jẹ ọba. Orúkọ màmá rẹ̀ a sì máa jẹ́ Meṣulemeti ọmọbìnrin Harusi: ó wá láti Jotba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún méjì.
Ve dvamecítma letech byl Amon, když počal kralovati, a kraloval dvě létě v Jeruzalémě. Jméno matky jeho bylo Mesullemet, dcera Charus z Jateba.
20 Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa àti gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ Manase ti ṣe.
I ten činil to, což jest zlého před očima Hospodinovýma, jako činil Manasses otec jeho.
21 Ó rìn ní gbogbo ọ̀nà baba rẹ̀: Ó sì ń sin àwọn ère tí baba rẹ̀ ń sìn, ó sì ń tẹrí rẹ̀ ba fún wọn.
A chodil po vší cestě, po níž chodil otec jeho. Sloužil také ukydaným bohům, jimž sloužíval otec jeho, a klaněl se jim,
22 Ó sì kọ Olúwa Ọlọ́run baba rẹ̀ sílẹ̀ kò sì rìn ní ọ̀nà ti Olúwa.
Opustiv Hospodina Boha otců svých, aniž chodil po cestě Hospodinově.
23 Àwọn ìránṣẹ́ Amoni dìtẹ̀ lórí rẹ̀ wọ́n sì lu ọba pa ní àárín ilé rẹ̀.
Spuntovali se pak služebníci Amonovi proti němu, a zamordovali jej v domě jeho.
24 Nígbà náà àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà pa gbogbo àwọn tí ó dìtẹ̀ sí ọba Amoni, wọ́n sì fi Josiah ọmọ rẹ̀ jẹ ọba ní ààyè rẹ̀.
Tedy pobil lid země všecky ty, kteříž se byli spuntovali proti králi Amonovi, a ustanovil lid země krále Joziáše syna jeho místo něho.
25 Àti gẹ́gẹ́ bí ìyókù iṣẹ́ ti ìjọba Amoni àti ohun tí ó ṣe, ṣé wọn kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn àwọn ọba Juda?
O jiných pak činech Amonových, kteréž činil, zapsáno jest v knize o králích Judských.
26 Wọ́n sì sin ín sínú isà òkú nínú ọgbà Ussa. Josiah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
I pochoval ho lid v hrobě jeho v zahradě Uzy, a kraloval Joziáš syn jeho místo něho.

< 2 Kings 21 >