< 2 Kings 20 >

1 Ní ayé ìgbà wọ̀n-ọn-nì Hesekiah ṣe àìsàn ó sì wà ní ojú ikú. Wòlíì Isaiah ọmọ Amosi lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: tún ilé rẹ ṣe, ṣùgbọ́n ìwọ yóò kú; o kò ní í gbádùn.”
Matukũ-inĩ macio Hezekia akĩrwara, na aarĩ hakuhĩ gũkua. Mũnabii Isaia mũrũ wa Amozu agĩthiĩ kũrĩ we, akĩmwĩra atĩrĩ, “Jehova ekuuga ũũ: Thondeka maũndũ ma mũciĩ waku, tondũ nĩũgũkua, ndũkũhona.”
2 Hesekiah yí ojú rẹ̀ padà sí ògiri ó sì gbàdúrà sí Olúwa pé,
Hezekia akĩhũgũra ũthiũ wake, akĩrora rũthingo-inĩ, na akĩhooya Jehova, akiuga atĩrĩ,
3 “Rántí, Olúwa mi, bí èmi ṣe rìn níwájú rẹ àti pẹ̀lú bí èmi ṣe jẹ́ olóòtítọ́ àti pẹ̀lú gbogbo ọkàn ìfọkànsìn mi tí èmi sì ti ṣe ohun tí ó dára níwájú rẹ.” Hesekiah sọkún kíkorò.
“Wee Jehova, ririkana ũrĩa ngoretwo ngĩthiĩ na mĩthiĩre ya kwĩhokeka mbere yaku, na ngeheana na ngoro yakwa yothe, na ngeeka ũrĩa kwagĩrĩire maitho-inĩ maku.” Nake Hezekia akĩrĩra mũno.
4 Kí ó tó di wí pé Isaiah jáde kúrò ní àárín àgbàlá ààfin, ọ̀rọ̀ Olúwa wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé:
Isaia atanakinya nja ya gatagatĩ-rĩ, kiugo kĩa Jehova gĩkĩmũkinyĩra, akĩĩrwo atĩrĩ:
5 “Lọ padà kí o sì sọ fún Hesekiah, olórí àwọn ènìyàn mi pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run baba rẹ Dafidi sọ: Mo ti gbọ́ àdúrà rẹ mo sì ti rí omijé rẹ, Èmi yóò wò ọ́ sàn. Ní ọjọ́ kẹta láti ìsinsin yìí, ìwọ yóò lọ sókè ilé tí a kọ́ fún Olúwa.
“Cooka, ũkeere Hezekia mũtongoria wa andũ akwa atĩrĩ, ‘Jehova Ngai wa thoguo Daudi ekuuga ũũ: Nĩnjiguĩte ihooya rĩaku, na ngoona maithori maku; nĩngũkũhonia. Mũthenya wa ĩtatũ kuuma rĩu nĩũkambata ũthiĩ hekarũ-inĩ ya Jehova.
6 Èmi yóò fi ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún kún ọjọ́ ayé rẹ. Èmi yóò sì gbà ọ́ àti ìlú ńlá yìí láti ọwọ́ ọba Asiria. Èmi yóò sì dáàbò bo ìlú yìí nítorí ti èmi tìkára mi àti nítorí ti Dafidi ìránṣẹ́ mi.’”
Nĩngũkuongerera mĩaka ikũmi na ĩtano ya gũtũũra muoyo. Na nĩngũkũhonokia hamwe na itũũra rĩĩrĩ inene kuuma guoko-inĩ kwa mũthamaki wa Ashuri. Nĩngũgitĩra itũũra rĩĩrĩ inene nĩ ũndũ wakwa, na nĩ ũndũ wa Daudi ndungata yakwa.’”
7 Nígbà náà ni Isaiah wí pé, “Mú odidi ọ̀pọ̀tọ́.” Wọ́n sì mú un, wọ́n sì fi lé oówo náà, ara rẹ̀ sì yá.
Ningĩ Isaia akiuga atĩrĩ, “Thondekai gĩkũmba kĩa ngũyũ.” Nao magĩĩka o ũguo, na magĩkĩigĩrĩra ihũha-inĩ rĩu, nake Hezekia akĩhona.
8 Hesekiah sì béèrè lọ́wọ́ Isaiah pé, “Kí ni yóò jẹ́ àmì pé Olúwa yóò wò mí sàn àti wí pé èmi yóò lọ sókè sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa láti ọjọ́ kẹta títí di òní?”
Hezekia nĩoorĩtie Isaia atĩrĩ, “Kĩmenyithia gĩgaakorwo kĩrĩ kĩrĩkũ kĩa atĩ Jehova nĩekũũhonia, na atĩ nĩngambata thiĩ hekarũ-inĩ ya Jehova mũthenya wa gatatũ kuuma ũmũthĩ?”
9 Isaiah dáhùn pé, “Èyí ni àmì tí Olúwa fún ọ wí pé Olúwa yóò ṣe ohun tí ó ti ṣe ìlérí: kí òjìji lọ síwájú ìgbésẹ̀ mẹ́wàá, tàbí kí ó padà lọ ní ìgbésẹ̀ mẹ́wàá?”
Nake Isaia akĩmũcookeria atĩrĩ, “Gĩkĩ nĩkĩo kĩmenyithia kĩrĩa Jehova egũkũhe, kĩa atĩ Jehova nĩegwĩka ũndũ ũcio akwĩrĩire: Ũkwenda kĩĩruru gĩthiĩ mbere makinya ikũmi, kana gĩcooke thuutha makinya ikũmi?”
10 “Ó jẹ́ ohun ìrọ̀rùn fún òjìji láti lọ síwájú ìgbésẹ̀ mẹ́wàá,” Hesekiah wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, jẹ́ kí ó lọ padà ní ìgbésẹ̀ mẹ́wàá.”
Nake Hezekia akiuga atĩrĩ, “Kĩĩruru gũthiĩ na mbere makinya ikũmi nĩ ũndũ mũhũthũ, nĩ kaba kĩĩruru gĩcooke na thuutha makinya ikũmi.”
11 Nígbà náà wòlíì Isaiah ké pe Olúwa, Olúwa sì ṣe òjìji padà sí ìgbésẹ̀ mẹ́wàá ó ti sọ̀kalẹ̀ ní òpópó ọ̀nà Ahasi.
Nake mũnabii Isaia agĩkaĩra Jehova, nake Jehova agĩtũma kĩĩruru gĩcooke na thuutha makinya macio ikũmi marĩa gĩaikũrũkĩte ngathĩ-inĩ ya Ahazu.
12 Ní àkókò náà ni Merodaki-Baladani ọmọ Baladani ọba Babeli ránṣẹ́ ìwé àti ẹ̀bùn sí Hesekiah nítorí tí ó ti gbọ́ nípa àìsàn Hesekiah.
Ihinda-inĩ rĩu-rĩ, Merodaki-Baladani mũrũ wa Baladani mũthamaki wa Babuloni nĩatũmĩire Hezekia marũa na kĩheo, tondũ nĩaiguĩte ũhoro wa ndwari ya Hezekia.
13 Hesekiah gba ìránṣẹ́ náà ó sì fihàn wọ́n, gbogbo ohun tí ó wà nínú ilé ìṣúra—sílífà, àti wúrà, àti tùràrí, àti òróró dáradára àti ìhámọ́ra àti gbogbo èyí tí a rí lára ìṣúra rẹ̀. Kò sí nǹkan nínú ààfin rẹ̀ tàbí nínú gbogbo ìjọba rẹ̀ tí Hesekiah kò sì fihàn wọ́n.
Hezekia akĩamũkĩra andũ arĩa maatũmĩtwo, na akĩmoonia indo ciothe iria aigĩte makũmbĩ make, akĩmoonia betha, na thahabu, na mahuti marĩa manungi wega, na maguta marĩa mega mũno, na indo ciake cia mbaara, na indo ciothe iria ciarĩ igĩĩna-inĩ ciake. Gũtirĩ kĩndũ o na kĩmwe thĩinĩ wa nyũmba ya ũthamaki kana kĩarĩ ũthamaki-inĩ wake wothe Hezekia ataamoonirie.
14 Nígbà náà Isaiah wòlíì lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Hesekiah ó sì béèrè pé, “Kí ni àwọn ọkùnrin náà sọ, àti níbo ni wọ́n ti ń bọ̀ wá?” “Láti ìlú jíjìn réré,” Hesekiah dáhùn. “Wọ́n wá láti Babeli.”
Hĩndĩ ĩyo mũnabii Isaia agĩthiĩ kũrĩ Mũthamaki Hezekia akĩmũũria atĩrĩ, “Andũ acio moiga atĩa, na mekuumĩte kũ?” Nake Hezekia agĩcookia atĩrĩ, “Moimĩte bũrũri wa kũraya, megũkĩte kuuma bũrũri wa Babuloni.”
15 Wòlíì náà béèrè pé, “Kí ni wọ́n rí ní ààfin rẹ?” “Wọ́n rí gbogbo nǹkan ní ààfin mi,” Hesekiah wí pé. “Kò sí nǹkan kan lára àwọn ìṣúra tí èmi kò fihàn wọ́n.”
Nake mũnabii akĩũria atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ monire nyũmba-inĩ yaku ya ũthamaki?” Nake Hezekia agĩcookia atĩrĩ, “Monire indo ciothe nyũmba-inĩ yakwa ya ũthamaki. Gũtirĩ kĩndũ o na kĩmwe kĩrĩ igĩĩna-inĩ ciakwa itanamonia.”
16 Nígbà náà Isaiah wí fún Hesekiah pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa,
Nake Isaia akĩĩra Hezekia atĩrĩ, “Ta igua kiugo kĩa Jehova:
17 àkókò náà yóò sì dé nítòótọ́ nígbà tí gbogbo ohun tí ó wà ní ààfin àti gbogbo ohun tí baba rẹ̀ ti kó pamọ́ sókè títí di ọjọ́ òní, wọn yí ó gbe lọ sí Babeli, kò sí ohun tí yóò kù, ni Olúwa wí.
Ti-itherũ ihinda nĩrĩgakinya, rĩrĩa indo ciothe iria irĩ thĩinĩ wa nyũmba yaku ya ũthamaki, na indo iria ciothe maithe maku matũire maigĩte nginya ũmũthĩ, ĩgaakuuo itwarwo Babuloni. Gũtirĩ o na kĩmwe gĩgaatigara, ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
18 Àti díẹ̀ nínú àwọn ìran rẹ, ẹran-ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀, tí wọn yóò bí fún ọ, ni wọn yóò kó lọ, wọn yóò sì di ìwẹ̀fà ní ààfin ọba Babeli.”
Na andũ amwe a rũciaro rwaku, o arĩa moimĩte mũthiimo-inĩ na thakame-inĩ yaku, o arĩa wee ũgũciara, nĩmagathaamio, na nĩmakaahakũrwo nĩguo matungatage nyũmba-inĩ ya mũthamaki wa Babuloni.”
19 Hesekiah wí fún Isaiah pé. “Rere ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ìwọ sọ.” Nítorí ó rò wí pé, “Kò ha dára àlàáfíà àti òtítọ́ ní ọjọ́ ayé mi?”
Nake Hezekia agĩcookia atĩrĩ, “Kiugo kĩa Jehova kĩrĩa waria nĩ kĩega,” Tondũ eeciiririe atĩrĩ, “Githĩ gũtigũkorwo na thayũ na ũgitĩri matukũ-inĩ mothe ma muoyo wakwa?”
20 Ní ti àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ tókù nípa ìjọba Hesekiah, gbogbo ohun tí ó ṣe tan àti bí ó ti ṣe adágún omi àti ọ̀nà omi náà nípa èyí tí ó gbé wá omi sínú ìlú ńlá, ṣé wọn kò kọ wọ́n sínú ìwé ìgbésẹ̀ ayé àwọn ọba àwọn Juda?
Ha ũhoro wa maũndũ marĩa mangĩ makoniĩ wathani wa Hezekia, na marĩa mothe eekire, na ũrĩa aathondekire Karia, o na mũtaro wa kũrehe maaĩ itũũra-inĩ, githĩ matiandĩkĩtwo ibuku-inĩ rĩa mahinda ma athamaki a Juda?
21 Hesekiah sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀: Manase ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Nake Hezekia akĩhurũka hamwe na maithe make. Nake mũriũ Manase agĩtuĩka mũthamaki ithenya rĩake.

< 2 Kings 20 >