< 2 Kings 20 >
1 Ní ayé ìgbà wọ̀n-ọn-nì Hesekiah ṣe àìsàn ó sì wà ní ojú ikú. Wòlíì Isaiah ọmọ Amosi lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: tún ilé rẹ ṣe, ṣùgbọ́n ìwọ yóò kú; o kò ní í gbádùn.”
In those days, Hezekiah was sick unto death. And the prophet Isaiah, the son of Amoz, came and said to him: “Thus says the Lord God: Instruct your house, for you will die, and not live.”
2 Hesekiah yí ojú rẹ̀ padà sí ògiri ó sì gbàdúrà sí Olúwa pé,
And he turned his face to the wall, and he prayed to the Lord, saying:
3 “Rántí, Olúwa mi, bí èmi ṣe rìn níwájú rẹ àti pẹ̀lú bí èmi ṣe jẹ́ olóòtítọ́ àti pẹ̀lú gbogbo ọkàn ìfọkànsìn mi tí èmi sì ti ṣe ohun tí ó dára níwájú rẹ.” Hesekiah sọkún kíkorò.
“I beg you, O Lord, I beseech you, remember how I have walked before you in truth, and with a perfect heart, and how I have done what is pleasing before you.” And then Hezekiah wept with a great weeping.
4 Kí ó tó di wí pé Isaiah jáde kúrò ní àárín àgbàlá ààfin, ọ̀rọ̀ Olúwa wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé:
And before Isaiah departed from the middle part of the atrium, the word of the Lord came to him, saying:
5 “Lọ padà kí o sì sọ fún Hesekiah, olórí àwọn ènìyàn mi pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run baba rẹ Dafidi sọ: Mo ti gbọ́ àdúrà rẹ mo sì ti rí omijé rẹ, Èmi yóò wò ọ́ sàn. Ní ọjọ́ kẹta láti ìsinsin yìí, ìwọ yóò lọ sókè ilé tí a kọ́ fún Olúwa.
“Return and tell Hezekiah, the leader of my people: Thus says the Lord, the God of your father David: I have heard your prayer, and I have seen your tears. And behold, I have healed you. On the third day, you shall ascend to the temple of the Lord.
6 Èmi yóò fi ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún kún ọjọ́ ayé rẹ. Èmi yóò sì gbà ọ́ àti ìlú ńlá yìí láti ọwọ́ ọba Asiria. Èmi yóò sì dáàbò bo ìlú yìí nítorí ti èmi tìkára mi àti nítorí ti Dafidi ìránṣẹ́ mi.’”
And I will add fifteen years to your days. Then too, I will free you and this city from the hand of the king of the Assyrians. And I will protect this city for my own sake, and for the sake of my servant David.”
7 Nígbà náà ni Isaiah wí pé, “Mú odidi ọ̀pọ̀tọ́.” Wọ́n sì mú un, wọ́n sì fi lé oówo náà, ara rẹ̀ sì yá.
And Isaiah said, “Bring me a mass of figs.” And when they had brought it, and they had placed it on his sore, he was healed.
8 Hesekiah sì béèrè lọ́wọ́ Isaiah pé, “Kí ni yóò jẹ́ àmì pé Olúwa yóò wò mí sàn àti wí pé èmi yóò lọ sókè sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa láti ọjọ́ kẹta títí di òní?”
But Hezekiah had said to Isaiah, “What will be the sign that the Lord will heal me, and that I will ascend to the temple of the Lord on the third day?”
9 Isaiah dáhùn pé, “Èyí ni àmì tí Olúwa fún ọ wí pé Olúwa yóò ṣe ohun tí ó ti ṣe ìlérí: kí òjìji lọ síwájú ìgbésẹ̀ mẹ́wàá, tàbí kí ó padà lọ ní ìgbésẹ̀ mẹ́wàá?”
And Isaiah said to him: “This will be the sign from the Lord, that the Lord will do the word that he has spoken: Do you wish that the shadow may ascend ten lines, or that it may turn back for the same number of degrees?”
10 “Ó jẹ́ ohun ìrọ̀rùn fún òjìji láti lọ síwájú ìgbésẹ̀ mẹ́wàá,” Hesekiah wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, jẹ́ kí ó lọ padà ní ìgbésẹ̀ mẹ́wàá.”
And Hezekiah said: “It is easy for the shadow to increase for ten lines. And so I do not wish that this be done. Instead, let it turn back for ten degrees.”
11 Nígbà náà wòlíì Isaiah ké pe Olúwa, Olúwa sì ṣe òjìji padà sí ìgbésẹ̀ mẹ́wàá ó ti sọ̀kalẹ̀ ní òpópó ọ̀nà Ahasi.
And so the prophet Isaiah called upon the Lord. And he led back the shadow, along the lines by which it had already descended on the sundial of Ahaz, in reverse for ten degrees.
12 Ní àkókò náà ni Merodaki-Baladani ọmọ Baladani ọba Babeli ránṣẹ́ ìwé àti ẹ̀bùn sí Hesekiah nítorí tí ó ti gbọ́ nípa àìsàn Hesekiah.
At that time, Merodach-baladan, the son of Baladan, the king of the Babylonians, sent letters and gifts to Hezekiah. For he had heard that Hezekiah had been ill.
13 Hesekiah gba ìránṣẹ́ náà ó sì fihàn wọ́n, gbogbo ohun tí ó wà nínú ilé ìṣúra—sílífà, àti wúrà, àti tùràrí, àti òróró dáradára àti ìhámọ́ra àti gbogbo èyí tí a rí lára ìṣúra rẹ̀. Kò sí nǹkan nínú ààfin rẹ̀ tàbí nínú gbogbo ìjọba rẹ̀ tí Hesekiah kò sì fihàn wọ́n.
Now Hezekiah rejoiced at their arrival, and so he revealed to them the house of aromatic spices, and the gold and silver, and the various pigments and ointments, and the house of his vessels, and all that he was able to have in his treasuries. There was nothing in his house, nor in all his dominions, that Hezekiah did not show to them.
14 Nígbà náà Isaiah wòlíì lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Hesekiah ó sì béèrè pé, “Kí ni àwọn ọkùnrin náà sọ, àti níbo ni wọ́n ti ń bọ̀ wá?” “Láti ìlú jíjìn réré,” Hesekiah dáhùn. “Wọ́n wá láti Babeli.”
Then the prophet Isaiah came to king Hezekiah, and said to him: “What did these men say? And from where did they come to you?” And Hezekiah said to him, “They came to me from Babylon, from a far away land.”
15 Wòlíì náà béèrè pé, “Kí ni wọ́n rí ní ààfin rẹ?” “Wọ́n rí gbogbo nǹkan ní ààfin mi,” Hesekiah wí pé. “Kò sí nǹkan kan lára àwọn ìṣúra tí èmi kò fihàn wọ́n.”
And he responded, “What did they see in your house?” And Hezekiah said: “They saw all things whatsoever that are in my house. There is nothing in my treasuries that I did not show to them.”
16 Nígbà náà Isaiah wí fún Hesekiah pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa,
And so Isaiah said to Hezekiah: “Listen to the word of the Lord.
17 àkókò náà yóò sì dé nítòótọ́ nígbà tí gbogbo ohun tí ó wà ní ààfin àti gbogbo ohun tí baba rẹ̀ ti kó pamọ́ sókè títí di ọjọ́ òní, wọn yí ó gbe lọ sí Babeli, kò sí ohun tí yóò kù, ni Olúwa wí.
Behold, the days are coming when all that is in your house, and all that your fathers have stored up even to this day, will be carried away to Babylon. Nothing at all shall remain, says the Lord.
18 Àti díẹ̀ nínú àwọn ìran rẹ, ẹran-ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀, tí wọn yóò bí fún ọ, ni wọn yóò kó lọ, wọn yóò sì di ìwẹ̀fà ní ààfin ọba Babeli.”
Then too, they will take from your sons, who will go forth from you, whom you will conceive. And they will be eunuchs in the palace of the king of Babylon.”
19 Hesekiah wí fún Isaiah pé. “Rere ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ìwọ sọ.” Nítorí ó rò wí pé, “Kò ha dára àlàáfíà àti òtítọ́ ní ọjọ́ ayé mi?”
Hezekiah said to Isaiah: “The word of the Lord, which you have spoken, is good. Let peace and truth be in my days.”
20 Ní ti àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ tókù nípa ìjọba Hesekiah, gbogbo ohun tí ó ṣe tan àti bí ó ti ṣe adágún omi àti ọ̀nà omi náà nípa èyí tí ó gbé wá omi sínú ìlú ńlá, ṣé wọn kò kọ wọ́n sínú ìwé ìgbésẹ̀ ayé àwọn ọba àwọn Juda?
Now the rest of the words of Hezekiah, and all his strength, and how he made a pool, and an aqueduct, and how he brought waters into the city, have these not been written in the book of the words of the days of the kings of Judah?
21 Hesekiah sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀: Manase ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
And Hezekiah slept with his fathers. And Manasseh, his son, reigned in his place.