< 2 Kings 2 >

1 Nígbà tí Olúwa ń fẹ́ gbé Elijah lọ sí òkè ọ̀run nínú àjà, Elijah àti Eliṣa wà ní ọ̀nà láti Gilgali.
Pǝrwǝrdigar Iliyasni ⱪara ⱪuyunda asmanƣa kɵtürmǝkqi bolƣan waⱪitta Iliyas bilǝn Elixa Gilgaldin qiⱪip ketiwatatti.
2 Elijah wí fún Eliṣa pé, “Dúró níbí; Olúwa rán mi lọ sí Beteli.” Ṣùgbọ́n Eliṣa wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti dájú pé Olúwa wà láyé àti gẹ́gẹ́ bí ó ti yẹ, èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí Beteli.
Iliyas Elixaƣa: — Sǝndin ɵtünimǝn, bu yǝrdǝ ⱪalƣin; qünki Pǝrwǝrdigar meni Bǝyt-Əlgǝ mangƣuzdi. Elixa: Pǝrwǝrdigarning ⱨayati bilǝn, wǝ sening ⱨayating bilǝn ⱪǝsǝm ⱪilimǝnki, seningdin ⱨǝrgiz ayrilmaymǝn! dedi. Xuning bilǝn ular Bǝyt-Əlgǝ qüxüp kǝldi.
3 Àwọn ọmọ wòlíì ní Beteli jáde wá sí ọ̀dọ̀ Eliṣa wọ́n sì béèrè pé, “Ṣé ìwọ mọ̀ pé Olúwa yóò gba ọ̀gá rẹ kúrò lọ́dọ̀ rẹ lónìí?” “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi mọ̀,” Eliṣa dáhùn, “Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀.”
U waⱪitta Bǝyt-Əldiki pǝyƣǝmbǝr xagirtliri Elixaning ⱪexiƣa kelip uningƣa: Bilǝmsǝn, Pǝrwǝrdigar bügün ƣojangni sǝndin elip ketidu? — dedi. U: Bilimǝn; xük turunglar, dedi.
4 Nígbà náà Elijah sì wí fún un pé, “Dúró níbí, Eliṣa: Olúwa ti rán mi lọ sí Jeriko.” Ó sì dá a lóhùn pé, “Bí ó ti dájú pé Olúwa yè àti tí ìwọ náà yè, èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Wọ́n sì jọ lọ sí Jeriko.
Iliyas Elixaƣa: — Sǝndin ɵtünimǝnki, bu yǝrdǝ ⱪalƣin; qünki Pǝrwǝrdigar meni Yerihoƣa mangƣuzdi. Elixa: Pǝrwǝrdigarning ⱨayati bilǝn, wǝ sening ⱨayating bilǝn ⱪǝsǝm ⱪilimǝnki, seningdin ⱨǝrgiz ayrilmaymǝn, dedi. Xuning bilǝn ular ikkisi Yerihoƣa bardi.
5 Àwọn ọmọ wòlíì tí ó wà ní Jeriko sì gòkè tọ Eliṣa wá wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Ṣé ìwọ mọ̀ wí pé Olúwa yóò gba ọ̀gá rẹ kúrò lọ́dọ̀ rẹ lónìí?” “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi mọ̀,” Ó dá wọn lóhùn, “Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe sọ nípa rẹ̀.”
U waⱪitta Yerihodiki pǝyƣǝmbǝr xagirtliri Elixaning ⱪexiƣa kelip uningƣa: Bilǝmsǝn, Pǝrwǝrdigar bügün ƣojangni sǝndin elip ketidu? — dedi. U: Bilimǝn; xük turunglar, dedi.
6 Nígbà náà Elijah wí fún un pé, “Dúró níbí; Olúwa rán mi lọ sí Jordani.” Ó sì dá a lóhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti jẹ́ wí pé, Olúwa yè àti gẹ́gẹ́ bí o ti yè, èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn méjèèjì sì jọ ń lọ.
Iliyas Elixaƣa: — Sǝndin ɵtünimǝnki, bu yǝrdǝ ⱪalƣin; qünki Pǝrwǝrdigar meni Iordan dǝryasiƣa mangƣuzdi, dedi. Elixa: Pǝrwǝrdigarning ⱨayati bilǝn, wǝ sening ⱨayating bilǝn ⱪǝsǝm ⱪilimǝnki, seningdin ⱨǝrgiz ayrilmaymǝn, dedi, xuning bilǝn ular ikkisi mengiwǝrdi.
7 Àádọ́ta àwọn ọkùnrin ọmọ wòlíì sì lọ láti lọ dúró ní ọ̀nà jíjìn, wọ́n sì kọ ojú da ibi tí Elijah àti Eliṣa ti dúró ní Jordani.
Əmdi pǝyƣǝmbǝr xagirtliridin ǝllik kixi berip, ularning udulida yiraⱪtin ⱪarap turatti. Əmma u ikkiylǝn Iordan dǝryasining boyida tohtap turdi.
8 Elijah sì mú agbádá ó sì ká a sókè ó sì lu omi náà pẹ̀lú rẹ̀. Omi náà sì pín sí ọ̀tún àti sí òsì, àwọn méjèèjì sì rékọjá lórí ilẹ̀ gbígbẹ.
Iliyas yepinqisini ⱪatlap, uning bilǝn suni uriwidi, su ikkigǝ bɵlünüp turdi; ular ikkisi ⱪuruⱪ yoldin ɵtti.
9 Nígbà tí wọ́n rékọjá, Elijah sì wí fún Eliṣa pé, “Sọ fún mi, kí ni èmi lè ṣe fún ọ kí ó tó di wí pé wọ́n gbà mí kúrò lọ́dọ̀ rẹ?” “Jẹ́ kí èmi kí ó jogún ìlọ́po méjì ẹ̀mí rẹ.” Ó dá a lóhùn.
Ɵtüp bolƣandin keyin Iliyas Elixaƣa: Mǝn sǝndin ayrilmasta, sening ɵzüng üqün mǝndin nemǝ tiliking bolsa, dǝwǝrgin, dedi. Elixa: Sening üstüngdǝ turƣan Roⱨning ikki ⱨǝssisi üstümgǝ ⱪonsun, — dedi.
10 “Ìwọ ti béèrè ohun tí ó ṣòro,” Elijah wí pé, “Síbẹ̀ tí ìwọ bá rí mi nígbà tí a bá gbà mí kúrò lọ́wọ́ rẹ, yóò jẹ́ tìrẹ bí bẹ́ẹ̀ kọ́ kò ní rí bẹ́ẹ̀.”
U: Bu tilikinggǝ erixmǝk ⱪiyindur; mǝn sǝndin elip ketilgǝn waⱪtimda, meni kɵrüp tursang, sanga xundaⱪ berilidu; bolmisa, berilmǝydu, — dedi.
11 Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ń rìn lọ tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ pọ̀, lọ́gán kẹ̀kẹ́ iná àti ẹṣin iná yọ sí wọn ó sì ya àwọn méjèèjì nípa, Elijah sì gòkè lọ sí ọ̀run pẹ̀lú àjà.
Wǝ xundaⱪ boldiki, ular sɵzlixip mangƣanda, mana, otluⱪ bir jǝng ⱨarwisi bilǝn otluⱪ atlar namayan boldi; ular ikkisini ayriwǝtti wǝ Iliyas ⱪara ⱪuyunda asmanƣa kɵtürülüp kǝtti.
12 Eliṣa rí èyí ó sì kígbe sókè, “Baba mi! Baba mi! Kẹ̀kẹ́ àti ẹlẹ́ṣin Israẹli!” Eliṣa kò sì rí i mọ́. Ó sì mú aṣọ ara rẹ̀ ó sì fà wọ́n ya sọ́tọ̀.
Elixa buni kɵrüp: I atam, i atam, Israilning jǝng ⱨarwisi wǝ atliⱪ ǝskǝrliri! — dǝp warⱪiridi. Andin u uni yǝnǝ kɵrǝlmidi. U ɵz kiyimini tutup, ularni yirtip ikki parqǝ ⱪiliwǝtti.
13 Ó sì mú agbádá tí ó ti jábọ́ láti ọ̀dọ̀ Elijah ó sì padà lọ, ó sì dúró lórí bèbè Jordani.
Andin u Iliyasning uqisidin qüxüp ⱪalƣan yepinqisini yǝrdin elip, Iordan dǝryasining ⱪirƣiⱪiƣa ⱪaytip kǝldi.
14 Ó sì mú agbádá náà tí ó jábọ́ láti ọwọ́ rẹ̀, ó sì lu omi pẹ̀lú rẹ̀. “Níbo ni Olúwa Ọlọ́run Elijah wà?” Ó béèrè. Nígbà tí ó lu omi náà, ó sì pín sí apá ọ̀tún àti sí òsì, Eliṣa sì rékọjá.
U Iliyasning üstidin qüxüp ⱪalƣan yepinqisi bilǝn suni urup: «Iliyasning Hudasi Pǝrwǝrdigar nǝdidur?», dedi. Elixa suni xundaⱪ urƣanda su ikkigǝ bɵlündi; Elixa sudin ɵtüp kǝtti.
15 Àwọn ọmọ wòlíì láti Jeriko, tí wọ́n ń wò, wí pé, “Ẹ̀mí Elijah sinmi lé Eliṣa.” Wọ́n sì lọ láti lọ bá a, wọ́n sì dojúbolẹ̀ níwájú rẹ̀.
Yerihodiki pǝyƣǝmbǝr Xagirtliri ⱪarxi ⱪirƣaⱪta turup uni kɵrdi wǝ: «Iliyasning roⱨi Elixaning üstididur» dǝp uning aldiƣa berip, bax urup tǝzim ⱪildi.
16 “Wò ó,” wọ́n wí pé, “Àwa ìránṣẹ́ ni àádọ́ta ọkùnrin alágbára. Jẹ́ kí wọ́n lọ láti lọ wá ọ̀gá rẹ wá. Bóyá ẹ̀mí Olúwa ti gbé e sókè, ó sì gbé e kalẹ̀ lórí òkè ńlá tàbí lórí ilẹ̀.” “Rárá,” Eliṣa dá a lóhùn pé, “Má ṣe rán wọn.”
Ular uningƣa: Mana sening kǝminiliring arisida ǝllik ǝzimǝt bar; ɵtünimiz, bular ƣojangni izdigili barsun. Pǝrwǝrdigarning Roⱨi bǝlkim uni kɵtürüp taƣlarning bir yeridǝ yaki jilƣilarning bir tǝripidǝ taxlap ⱪoydimiki, dedi. Lekin u: Silǝr ⱨeq adǝmni ǝwǝtmǝnglar, dedi.
17 Ṣùgbọ́n wọ́n rọ̀ ọ́ títí ojú fi tì í láti gbà. Ó wí pé, “Rán wọn.” Wọ́n sì rán àádọ́ta ènìyàn tí ó wá a fún ọjọ́ mẹ́ta ṣùgbọ́n wọn kò rí i.
Əmma ularning uni ⱪistawerixi bilǝn u hijalǝt bolup: Adǝm ǝwǝtinglar, dedi. Xunga ular ǝllik kixini ǝwǝtti; bular üq kün uni izdidi, lekin ⱨeq tapalmidi.
18 Nígbà tí wọ́n padà dé ọ̀dọ̀ Eliṣa, tí ó dúró ní Jeriko, ó wí fún wọn pé, “Ṣé èmi kò sọ fún un yín kí ẹ má lọ?”
Ular Elixaning yeniƣa ⱪaytip kǝlgǝndǝ (u Yerihoda turuwatatti) u ularƣa: Mǝn dǝrwǝⱪǝ silǝrgǝ «Izdǝp barmanglar!» demidimmu? — dedi.
19 Àwọn ọkùnrin ìlú wí fún Eliṣa, pé, “Wò ó, olúwa wa, ìtẹ̀dó ìlú yìí dára, gẹ́gẹ́ bí ẹ ti rí i, ṣùgbọ́n omi náà burú, ilẹ̀ náà sì sá.”
Xǝⱨǝrdiki adǝmlǝr Elixaƣa: Ƣojam kɵrgǝndǝk, xǝⱨǝr ɵzi obdan jaydidur, lekin su naqar wǝ tupraⱪ tuƣmastur, dedi.
20 Ó sì wí pé, “Mú àwokòtò tuntun fún mi wá, kí o sì mú iyọ̀ sí inú rẹ̀.” Wọ́n sì gbé e wá fún un.
U: Yengi bir koza elip kelip, iqigǝ tuz ⱪoyup, manga beringlar, dedi. Ular uni elip kelip uningƣa bǝrdi.
21 Nígbà náà ó sì jáde lọ sí ibi orísun omi, ó sì da iyọ̀ sí inú rẹ̀, ó wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Èmi ti wo omi yìí sàn. Kò ní mú ikú wá mọ́ tàbí mú ilẹ̀ náà sá.’”
U bulaⱪning bexiƣa berip uningƣa tuzni tɵkti wǝ: Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — «Mǝn bu sularni saⱪayttim; ǝmdi ulardin ⱪayta ɵlüm bolmaydu wǝ yǝrning tuƣmasliⱪi bolmaydu» — dedi.
22 Omi náà sì ti dára ni mímu títí di òní, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ tí Eliṣa ti sọ.
Huddi Elixaning eytⱪan bu sɵzidǝk, u su taki bügüngǝ ⱪǝdǝr pak bolup kǝldi.
23 Láti ibẹ̀ Eliṣa lọ sókè ní Beteli gẹ́gẹ́ bí ó ti ń rìn lọ lójú ọ̀nà, àwọn ọ̀dọ́ kan jáde wá láti ìlú náà wọ́n sì fi ṣe ẹlẹ́yà. “Máa lọ sókè ìwọ apárí!” Wọ́n wí pé. “Máa lọ sókè ìwọ apárí!”
Elixa Yerihodin qiⱪip Bǝyt-Əlgǝ bardi. U yolda ketip barƣanda, bǝzi balilar xǝⱨǝrdin qiⱪip uni zangliⱪ ⱪilip: Qiⱪip kǝt, i taⱪir bax! Qiⱪip kǝt, i taⱪir bax! — dǝp warⱪiraxti.
24 Ó sì yípadà, ó sì wò wọ́n ó sì fi wọ́n bú ní orúkọ Olúwa. Nígbà náà beari méjì sì jáde wá láti inú igbó ó sì lu méjìlélógójì lára àwọn ọ̀dọ́ náà.
U burulup ularƣa ⱪarap Pǝrwǝrdigarning nami bilǝn ularƣa lǝnǝt oⱪudi; xuning bilǝn ormanliⱪtin ikki qixi eyiⱪ qiⱪip, balilardin ⱪiriⱪ ikkini yirtiwǝtti.
25 Ó sì lọ sí orí òkè Karmeli láti ibẹ̀ ó sì padà sí Samaria.
U u yǝrdin ketip, Karmǝl teƣiƣa berip, u yǝrdin Samariyǝgǝ yenip bardi.

< 2 Kings 2 >