< 2 Kings 2 >

1 Nígbà tí Olúwa ń fẹ́ gbé Elijah lọ sí òkè ọ̀run nínú àjà, Elijah àti Eliṣa wà ní ọ̀nà láti Gilgali.
Történt, midőn az Örökkévaló fölvitte Élijáhút viharban az égbe, elment Élijáhú meg Elísá Gilgálból.
2 Elijah wí fún Eliṣa pé, “Dúró níbí; Olúwa rán mi lọ sí Beteli.” Ṣùgbọ́n Eliṣa wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti dájú pé Olúwa wà láyé àti gẹ́gẹ́ bí ó ti yẹ, èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí Beteli.
És szólt Élijáhú Elísához: Maradj csak itt, mert az Örökkévaló Bét-Élbe küldött engem. Mondta Elísá: Él az Örökkévaló és lelked életére, nem hagylak el. Lementek hát Bét-Élbe.
3 Àwọn ọmọ wòlíì ní Beteli jáde wá sí ọ̀dọ̀ Eliṣa wọ́n sì béèrè pé, “Ṣé ìwọ mọ̀ pé Olúwa yóò gba ọ̀gá rẹ kúrò lọ́dọ̀ rẹ lónìí?” “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi mọ̀,” Eliṣa dáhùn, “Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀.”
És kimentek a prófétafiak, kik Bét-Élben voltak, Elísához és szóltak hozzá: Tudod-e, hogy ma el akarja venni az Örökkévaló a te uradat fejedről? Mondta: Én is tudom, hallgassatok!
4 Nígbà náà Elijah sì wí fún un pé, “Dúró níbí, Eliṣa: Olúwa ti rán mi lọ sí Jeriko.” Ó sì dá a lóhùn pé, “Bí ó ti dájú pé Olúwa yè àti tí ìwọ náà yè, èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Wọ́n sì jọ lọ sí Jeriko.
És mondta neki Élijáhú: Elísá, maradj csak itt, mert az Örökkévaló Jerichóba küldött engem. Mondta: Él az Örökkévaló és lelked életére nem hagylak el. Oda mentek tehát Jeríchóba.
5 Àwọn ọmọ wòlíì tí ó wà ní Jeriko sì gòkè tọ Eliṣa wá wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Ṣé ìwọ mọ̀ wí pé Olúwa yóò gba ọ̀gá rẹ kúrò lọ́dọ̀ rẹ lónìí?” “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi mọ̀,” Ó dá wọn lóhùn, “Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe sọ nípa rẹ̀.”
És oda léptek a prófétafiak, kik Jeríchóban voltak, Elísához és szóltak hozzá: Tudod-e, hogy ma el akarja venni az Örökkévaló a te uradat fejedről? Mondta: Én is tudom, hallgassatok!
6 Nígbà náà Elijah wí fún un pé, “Dúró níbí; Olúwa rán mi lọ sí Jordani.” Ó sì dá a lóhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti jẹ́ wí pé, Olúwa yè àti gẹ́gẹ́ bí o ti yè, èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn méjèèjì sì jọ ń lọ.
És mondta neki Elijáhú: Maradj csak itt, mert az Örökkévaló a Jordánhoz küldött engem. Mondta: Él az Örökkévaló és lelked életére, nem hagylak el. Elmentek tehát mindketten.
7 Àádọ́ta àwọn ọkùnrin ọmọ wòlíì sì lọ láti lọ dúró ní ọ̀nà jíjìn, wọ́n sì kọ ojú da ibi tí Elijah àti Eliṣa ti dúró ní Jordani.
De ötven ember a prófétafiak közül ment, és megálltak átellenben messziről; ők ketten pedig megálltak a Jordán mellett.
8 Elijah sì mú agbádá ó sì ká a sókè ó sì lu omi náà pẹ̀lú rẹ̀. Omi náà sì pín sí ọ̀tún àti sí òsì, àwọn méjèèjì sì rékọjá lórí ilẹ̀ gbígbẹ.
Ekkor vette Élijáhú a köpenyét, összesodorta, ráütött a vízre, ez kétfelé vált, ide és oda; és átkeltek mindketten szárazon.
9 Nígbà tí wọ́n rékọjá, Elijah sì wí fún Eliṣa pé, “Sọ fún mi, kí ni èmi lè ṣe fún ọ kí ó tó di wí pé wọ́n gbà mí kúrò lọ́dọ̀ rẹ?” “Jẹ́ kí èmi kí ó jogún ìlọ́po méjì ẹ̀mí rẹ.” Ó dá a lóhùn.
Volt pedig, amint átkeltek, szólt Élijáhú Elísához: Kérj, mit tegyek számodra, mielőtt elvétetném tőled. Mondta Elísá: Legyen tehát szellemedből kétszeresen rajtam.
10 “Ìwọ ti béèrè ohun tí ó ṣòro,” Elijah wí pé, “Síbẹ̀ tí ìwọ bá rí mi nígbà tí a bá gbà mí kúrò lọ́wọ́ rẹ, yóò jẹ́ tìrẹ bí bẹ́ẹ̀ kọ́ kò ní rí bẹ́ẹ̀.”
És mondta: Nehezet kértél! Ha majd látsz engem elvétetve tőled, legyen neked úgy ha pedig nem, nem leszen.
11 Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ń rìn lọ tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ pọ̀, lọ́gán kẹ̀kẹ́ iná àti ẹṣin iná yọ sí wọn ó sì ya àwọn méjèèjì nípa, Elijah sì gòkè lọ sí ọ̀run pẹ̀lú àjà.
És volt, a mint folyton mennek és beszélgetnek, íme tüzes szekerek és tüzes lovak, melyek elválasztották őket egymástól; így fölszállt Élijáhú viharban az égbe.
12 Eliṣa rí èyí ó sì kígbe sókè, “Baba mi! Baba mi! Kẹ̀kẹ́ àti ẹlẹ́ṣin Israẹli!” Eliṣa kò sì rí i mọ́. Ó sì mú aṣọ ara rẹ̀ ó sì fà wọ́n ya sọ́tọ̀.
És Elísá látja és így kiált föl: Atyám, atyám, Izraél szekerei ég lovasai! És nem látta őt többé. Ekkor megragadta a ruháit és szétszakította két darabra.
13 Ó sì mú agbádá tí ó ti jábọ́ láti ọ̀dọ̀ Elijah ó sì padà lọ, ó sì dúró lórí bèbè Jordani.
És fölvette Élijáhú köpenyét, mely leesett róla; arra visszatért és megállott a Jordán partján.
14 Ó sì mú agbádá náà tí ó jábọ́ láti ọwọ́ rẹ̀, ó sì lu omi pẹ̀lú rẹ̀. “Níbo ni Olúwa Ọlọ́run Elijah wà?” Ó béèrè. Nígbà tí ó lu omi náà, ó sì pín sí apá ọ̀tún àti sí òsì, Eliṣa sì rékọjá.
Vette Élijáhú köpenyét, mely leesett róla, ráütött a vízre és mondta: Hol az Örökkévaló, Élijáhú Istene? Ő is ráütött a vízre, az kétfelé vált, ide és oda, és átkelt Elísá.
15 Àwọn ọmọ wòlíì láti Jeriko, tí wọ́n ń wò, wí pé, “Ẹ̀mí Elijah sinmi lé Eliṣa.” Wọ́n sì lọ láti lọ bá a, wọ́n sì dojúbolẹ̀ níwájú rẹ̀.
És látták őt a prófétafiak, kik átellenben Jeríchóban voltak, és mondták: rajta nyugszik Elijáhú szelleme Elísán. Elejébe mentek és földre borultak előtte.
16 “Wò ó,” wọ́n wí pé, “Àwa ìránṣẹ́ ni àádọ́ta ọkùnrin alágbára. Jẹ́ kí wọ́n lọ láti lọ wá ọ̀gá rẹ wá. Bóyá ẹ̀mí Olúwa ti gbé e sókè, ó sì gbé e kalẹ̀ lórí òkè ńlá tàbí lórí ilẹ̀.” “Rárá,” Eliṣa dá a lóhùn pé, “Má ṣe rán wọn.”
És szóltak hozzá: Íme, kérlek, van szolgáidnál ötven derék ember; hadd menjenek és keressék uradat, hátha elvitte őt az Örökkévaló szelleme és vetette őt a hegyek egyikére vagy a völgyek egyikébe. De mondta: Ne küldjetek.
17 Ṣùgbọ́n wọ́n rọ̀ ọ́ títí ojú fi tì í láti gbà. Ó wí pé, “Rán wọn.” Wọ́n sì rán àádọ́ta ènìyàn tí ó wá a fún ọjọ́ mẹ́ta ṣùgbọ́n wọn kò rí i.
De midőn unszolták, amíg megszégyelték, mondta: Küldjetek! Küldtek tehát ötven embert, keresték három napig, de nem találták.
18 Nígbà tí wọ́n padà dé ọ̀dọ̀ Eliṣa, tí ó dúró ní Jeriko, ó wí fún wọn pé, “Ṣé èmi kò sọ fún un yín kí ẹ má lọ?”
Midőn visszatértek hozzá, ő ugyanis Jeríchóban maradt, szólt hozzájuk: Nemde mondtam nektek, ne menjetek?
19 Àwọn ọkùnrin ìlú wí fún Eliṣa, pé, “Wò ó, olúwa wa, ìtẹ̀dó ìlú yìí dára, gẹ́gẹ́ bí ẹ ti rí i, ṣùgbọ́n omi náà burú, ilẹ̀ náà sì sá.”
És szóltak a város emberei Elísához: Íme, kérlek, a város fekvése jó, amint uram látja, de a víz rossz és a föld emberpusztító.
20 Ó sì wí pé, “Mú àwokòtò tuntun fún mi wá, kí o sì mú iyọ̀ sí inú rẹ̀.” Wọ́n sì gbé e wá fún un.
Erre mondta: Hozzatok nekem új csészét és tegyetek bele sót. És hoztak neki.
21 Nígbà náà ó sì jáde lọ sí ibi orísun omi, ó sì da iyọ̀ sí inú rẹ̀, ó wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Èmi ti wo omi yìí sàn. Kò ní mú ikú wá mọ́ tàbí mú ilẹ̀ náà sá.’”
Kiment a víz forrásához és belevetett sót; mondta: Így szól az Örökkévaló: Meggyógyítottam e vizet, nem lesz többé onnan halál s emberpusztítás.
22 Omi náà sì ti dára ni mímu títí di òní, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ tí Eliṣa ti sọ.
S meggyógyult a víz mind e mai napig, Elísá szava szerint, melyet szólt.
23 Láti ibẹ̀ Eliṣa lọ sókè ní Beteli gẹ́gẹ́ bí ó ti ń rìn lọ lójú ọ̀nà, àwọn ọ̀dọ́ kan jáde wá láti ìlú náà wọ́n sì fi ṣe ẹlẹ́yà. “Máa lọ sókè ìwọ apárí!” Wọ́n wí pé. “Máa lọ sókè ìwọ apárí!”
Fölment onnan Bét-Élbe; a mint pedig fölment az úton, kis fiúk jöttek ki a városból, kicsúfolták őt és mondták neki: Jöjj föl, kopasz, jöjj föl kopasz!
24 Ó sì yípadà, ó sì wò wọ́n ó sì fi wọ́n bú ní orúkọ Olúwa. Nígbà náà beari méjì sì jáde wá láti inú igbó ó sì lu méjìlélógójì lára àwọn ọ̀dọ́ náà.
Ekkor hátrafordult, látta őket és megátkozta, az Örökkévaló nevében; erre kijött az erdőből két nőstény medve, és széthasított közülök negyvenkét gyermeket.
25 Ó sì lọ sí orí òkè Karmeli láti ibẹ̀ ó sì padà sí Samaria.
És elment onnan a Karmel hegyére; onnan pedig visszatért Sómrónba.

< 2 Kings 2 >