< 2 Kings 2 >

1 Nígbà tí Olúwa ń fẹ́ gbé Elijah lọ sí òkè ọ̀run nínú àjà, Elijah àti Eliṣa wà ní ọ̀nà láti Gilgali.
Forsothe it was don, whanne the Lord wolde reise Elie bi a whirlewynd in to heuene, Elie and Elisee yeden fro Galgalis.
2 Elijah wí fún Eliṣa pé, “Dúró níbí; Olúwa rán mi lọ sí Beteli.” Ṣùgbọ́n Eliṣa wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti dájú pé Olúwa wà láyé àti gẹ́gẹ́ bí ó ti yẹ, èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí Beteli.
And Elie seide to Elisee, Sitte thou here, for the Lord sente me til into Bethel. To whom Elisee seide, The Lord lyueth and thi soule lyueth, for Y schal not forsake thee. And whanne thei hadden come doun to Bethel,
3 Àwọn ọmọ wòlíì ní Beteli jáde wá sí ọ̀dọ̀ Eliṣa wọ́n sì béèrè pé, “Ṣé ìwọ mọ̀ pé Olúwa yóò gba ọ̀gá rẹ kúrò lọ́dọ̀ rẹ lónìí?” “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi mọ̀,” Eliṣa dáhùn, “Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀.”
the sones of prophetis, that weren in Bethel, yeden out to Elisee, and seiden to hym, Whether thou knowist, that the Lord schal take awey thi lord to dai fro thee? Which answeride, And I knowe; be ye stille.
4 Nígbà náà Elijah sì wí fún un pé, “Dúró níbí, Eliṣa: Olúwa ti rán mi lọ sí Jeriko.” Ó sì dá a lóhùn pé, “Bí ó ti dájú pé Olúwa yè àti tí ìwọ náà yè, èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Wọ́n sì jọ lọ sí Jeriko.
Forsothe Elie seide to Elisee, Sitte thou here, for the Lord sente me into Jerico. And he seide, The Lord lyueth and thi soule lyueth, for Y schal not forsake thee. And whanne thei hadden come to Jerico,
5 Àwọn ọmọ wòlíì tí ó wà ní Jeriko sì gòkè tọ Eliṣa wá wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Ṣé ìwọ mọ̀ wí pé Olúwa yóò gba ọ̀gá rẹ kúrò lọ́dọ̀ rẹ lónìí?” “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi mọ̀,” Ó dá wọn lóhùn, “Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe sọ nípa rẹ̀.”
the sones of prophetis, that weren in Jerico, neiyiden to Elisee, and seiden to hym, Whether thou knowist, that the Lord schal take awei thi lord to dai fro thee? And he seide, Y knowe; be ye stille.
6 Nígbà náà Elijah wí fún un pé, “Dúró níbí; Olúwa rán mi lọ sí Jordani.” Ó sì dá a lóhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti jẹ́ wí pé, Olúwa yè àti gẹ́gẹ́ bí o ti yè, èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn méjèèjì sì jọ ń lọ.
Forsothe Elie seide to Elisee, Sitte thou here, for the Lord sente me `til to Jordan. Which seide, The Lord lyueth and thi soule lyueth, for Y schal not forsake thee. Therfor bothe yeden togidere;
7 Àádọ́ta àwọn ọkùnrin ọmọ wòlíì sì lọ láti lọ dúró ní ọ̀nà jíjìn, wọ́n sì kọ ojú da ibi tí Elijah àti Eliṣa ti dúró ní Jordani.
and fifti men of the sones of prophetis sueden, which also stoden fer euen ayens; sothely thei bothe stoden ouer Jordan.
8 Elijah sì mú agbádá ó sì ká a sókè ó sì lu omi náà pẹ̀lú rẹ̀. Omi náà sì pín sí ọ̀tún àti sí òsì, àwọn méjèèjì sì rékọjá lórí ilẹ̀ gbígbẹ.
And Elie took his mentil, and wlappide it, and smoot the watris; whiche weren departid `into euer ethir part, and bothe yeden bi the drie.
9 Nígbà tí wọ́n rékọjá, Elijah sì wí fún Eliṣa pé, “Sọ fún mi, kí ni èmi lè ṣe fún ọ kí ó tó di wí pé wọ́n gbà mí kúrò lọ́dọ̀ rẹ?” “Jẹ́ kí èmi kí ó jogún ìlọ́po méjì ẹ̀mí rẹ.” Ó dá a lóhùn.
And whanne thei hadden passid, Elie seide to Elisee, Axe thou that, that thou wolt that Y do to thee, bifor that Y be takun awey fro thee. And Elisee seide, Y biseche, that thi double spirit be `maad in me.
10 “Ìwọ ti béèrè ohun tí ó ṣòro,” Elijah wí pé, “Síbẹ̀ tí ìwọ bá rí mi nígbà tí a bá gbà mí kúrò lọ́wọ́ rẹ, yóò jẹ́ tìrẹ bí bẹ́ẹ̀ kọ́ kò ní rí bẹ́ẹ̀.”
Which Elie answeride, Thou axist an hard thing; netheles if thou schalt se me, whanne Y schal be takun awei fro thee, that that thou axidist schal be; sotheli, if thou schalt not se, it schal not be.
11 Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ń rìn lọ tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ pọ̀, lọ́gán kẹ̀kẹ́ iná àti ẹṣin iná yọ sí wọn ó sì ya àwọn méjèèjì nípa, Elijah sì gòkè lọ sí ọ̀run pẹ̀lú àjà.
And whanne thei yeden, and spaken goynge, lo! a chare of fier and horsys of fier departiden euer either; and Elie stiede bi a whirlewynd in to heuene.
12 Eliṣa rí èyí ó sì kígbe sókè, “Baba mi! Baba mi! Kẹ̀kẹ́ àti ẹlẹ́ṣin Israẹli!” Eliṣa kò sì rí i mọ́. Ó sì mú aṣọ ara rẹ̀ ó sì fà wọ́n ya sọ́tọ̀.
Forsothe Elise siy, and criede, My fadir! my fadir! the chare of Israel, and the charietere therof. And he siy no more Elie. And he took hise clothis, and to-rente tho in to twei partis.
13 Ó sì mú agbádá tí ó ti jábọ́ láti ọ̀dọ̀ Elijah ó sì padà lọ, ó sì dúró lórí bèbè Jordani.
And he reiside the mentil of Elie, that felde doun to hym; and he turnede ayen, and stood ouer the ryuer of Jordan.
14 Ó sì mú agbádá náà tí ó jábọ́ láti ọwọ́ rẹ̀, ó sì lu omi pẹ̀lú rẹ̀. “Níbo ni Olúwa Ọlọ́run Elijah wà?” Ó béèrè. Nígbà tí ó lu omi náà, ó sì pín sí apá ọ̀tún àti sí òsì, Eliṣa sì rékọjá.
And with the mentil of Elie, that felde doun to hym, he smoot the watris, whiche weren not departid. And he seide, Where is God of Elie also now? And he smoot the watris, and tho weren departid hidur and thidur; and Elisee passide.
15 Àwọn ọmọ wòlíì láti Jeriko, tí wọ́n ń wò, wí pé, “Ẹ̀mí Elijah sinmi lé Eliṣa.” Wọ́n sì lọ láti lọ bá a, wọ́n sì dojúbolẹ̀ níwájú rẹ̀.
Sotheli the sones of prophetis, that weren in Jerico euene ayens, siyen, and seiden, The spirit of Elie restide on Elisee. And thei camen in to the meetyng of hym, and worschipiden hym lowli to erthe.
16 “Wò ó,” wọ́n wí pé, “Àwa ìránṣẹ́ ni àádọ́ta ọkùnrin alágbára. Jẹ́ kí wọ́n lọ láti lọ wá ọ̀gá rẹ wá. Bóyá ẹ̀mí Olúwa ti gbé e sókè, ó sì gbé e kalẹ̀ lórí òkè ńlá tàbí lórí ilẹ̀.” “Rárá,” Eliṣa dá a lóhùn pé, “Má ṣe rán wọn.”
And thei seiden to hym, Lo! with thi seruauntis ben fifti stronge men, that moun go, and seke thi lord, lest perauenture the Spirit of the Lord hath take hym, and hath cast forth hym in oon of the hillis, ethir in oon of the valeys.
17 Ṣùgbọ́n wọ́n rọ̀ ọ́ títí ojú fi tì í láti gbà. Ó wí pé, “Rán wọn.” Wọ́n sì rán àádọ́ta ènìyàn tí ó wá a fún ọjọ́ mẹ́ta ṣùgbọ́n wọn kò rí i.
Which seide, `Nyle ye sende. And thei constreyneden hym, til he assentide to hem, and seide, Sende ye. And thei senten fifti men; and whanne thei hadden souyt bi thre daies, thei founden not.
18 Nígbà tí wọ́n padà dé ọ̀dọ̀ Eliṣa, tí ó dúró ní Jeriko, ó wí fún wọn pé, “Ṣé èmi kò sọ fún un yín kí ẹ má lọ?”
And thei turneden ayen to hym; and he dwelide in Jerico. And he seide to hem, Whether Y seide not to you, Nyle ye sende?
19 Àwọn ọkùnrin ìlú wí fún Eliṣa, pé, “Wò ó, olúwa wa, ìtẹ̀dó ìlú yìí dára, gẹ́gẹ́ bí ẹ ti rí i, ṣùgbọ́n omi náà burú, ilẹ̀ náà sì sá.”
Therfor the men of the citee seiden to Elisee, Lo! the dwellyng of this cite is ful good, as thou thi silf, lord, seest; but the watris ben ful yuele, and the lond is bareyn.
20 Ó sì wí pé, “Mú àwokòtò tuntun fún mi wá, kí o sì mú iyọ̀ sí inú rẹ̀.” Wọ́n sì gbé e wá fún un.
And he seide, Brynge ye to me a newe vessel, and sende ye salt in to it. And whanne thei hadden brouyt it,
21 Nígbà náà ó sì jáde lọ sí ibi orísun omi, ó sì da iyọ̀ sí inú rẹ̀, ó wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Èmi ti wo omi yìí sàn. Kò ní mú ikú wá mọ́ tàbí mú ilẹ̀ náà sá.’”
he yede out to the welle of watris, and sente salt in to it, and seide, The Lord seith these thingis, Y haue helid these watris, and nethir deeth, nether bareynesse, schal be more in tho.
22 Omi náà sì ti dára ni mímu títí di òní, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ tí Eliṣa ti sọ.
Therfor the watris weren heelid til in to this dai, bi the word of Elisee, which he spak.
23 Láti ibẹ̀ Eliṣa lọ sókè ní Beteli gẹ́gẹ́ bí ó ti ń rìn lọ lójú ọ̀nà, àwọn ọ̀dọ́ kan jáde wá láti ìlú náà wọ́n sì fi ṣe ẹlẹ́yà. “Máa lọ sókè ìwọ apárí!” Wọ́n wí pé. “Máa lọ sókè ìwọ apárí!”
Forsothe Elisee stiede fro thennus in to Bethel; and whanne he stiede bi the weie, litle children yeden out of the citee, and scorneden hym, and seiden, Stie, thou ballard! stie, thou ballard!
24 Ó sì yípadà, ó sì wò wọ́n ó sì fi wọ́n bú ní orúkọ Olúwa. Nígbà náà beari méjì sì jáde wá láti inú igbó ó sì lu méjìlélógójì lára àwọn ọ̀dọ́ náà.
And whanne he hadde biholde, he siy hem, and curside hem in the name of the Lord. And twey beeris yeden out of the forest, and to-rente fourti children of hem.
25 Ó sì lọ sí orí òkè Karmeli láti ibẹ̀ ó sì padà sí Samaria.
Sotheli Elisee wente fro thennus in to the hil of Carmele, and fro thennus he turnede `ayen to Samarie.

< 2 Kings 2 >