< 2 Kings 2 >
1 Nígbà tí Olúwa ń fẹ́ gbé Elijah lọ sí òkè ọ̀run nínú àjà, Elijah àti Eliṣa wà ní ọ̀nà láti Gilgali.
Og det skete, der Herren vilde hente Elias op til Himmelen i en Storm, da gik Elias og Elisa fra Gilgal.
2 Elijah wí fún Eliṣa pé, “Dúró níbí; Olúwa rán mi lọ sí Beteli.” Ṣùgbọ́n Eliṣa wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti dájú pé Olúwa wà láyé àti gẹ́gẹ́ bí ó ti yẹ, èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí Beteli.
Og Elias sagde til Elisa: Kære, bliv her; thi Herren sendte mig til Bethel; men Elisa sagde: Saa vist som Herren lever og din Sjæl lever, jeg forlader dig ikke; og de kom ned til Bethel.
3 Àwọn ọmọ wòlíì ní Beteli jáde wá sí ọ̀dọ̀ Eliṣa wọ́n sì béèrè pé, “Ṣé ìwọ mọ̀ pé Olúwa yóò gba ọ̀gá rẹ kúrò lọ́dọ̀ rẹ lónìí?” “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi mọ̀,” Eliṣa dáhùn, “Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀.”
Da gik Profeternes Børn, som vare i Bethel, ud til Elisa og sagde til ham: Ved du, at Herren i Dag vil tage din Herre fra dit Hoved? og han sagde: Jeg ved det ogsaa, tier!
4 Nígbà náà Elijah sì wí fún un pé, “Dúró níbí, Eliṣa: Olúwa ti rán mi lọ sí Jeriko.” Ó sì dá a lóhùn pé, “Bí ó ti dájú pé Olúwa yè àti tí ìwọ náà yè, èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Wọ́n sì jọ lọ sí Jeriko.
Og Elias sagde til ham: Elisa, kære, bliv her, thi Herren har sendt mig til Jeriko; men han sagde: Saa vist som Herren lever, og din Sjæl lever, jeg forlader dig ikke; og de kom til Jeriko.
5 Àwọn ọmọ wòlíì tí ó wà ní Jeriko sì gòkè tọ Eliṣa wá wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Ṣé ìwọ mọ̀ wí pé Olúwa yóò gba ọ̀gá rẹ kúrò lọ́dọ̀ rẹ lónìí?” “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi mọ̀,” Ó dá wọn lóhùn, “Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe sọ nípa rẹ̀.”
Og Profeternes Børn, som vare i Jeriko, gik frem til Elisa og sagde til ham: Ved du, at Herren i Dag vil tage din Herre fra dit Hoved? og han sagde: Jeg ved det ogsaa, tier!
6 Nígbà náà Elijah wí fún un pé, “Dúró níbí; Olúwa rán mi lọ sí Jordani.” Ó sì dá a lóhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti jẹ́ wí pé, Olúwa yè àti gẹ́gẹ́ bí o ti yè, èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn méjèèjì sì jọ ń lọ.
Og Elias sagde til ham: Kære, bliv her, thi Herren har sendt mig til Jordanen; men han sagde: Saa vist som Herren lever, og din Sjæl lever, jeg forlader dig ikke; og de gik begge sammen.
7 Àádọ́ta àwọn ọkùnrin ọmọ wòlíì sì lọ láti lọ dúró ní ọ̀nà jíjìn, wọ́n sì kọ ojú da ibi tí Elijah àti Eliṣa ti dúró ní Jordani.
Og halvtredsindstyve Mænd af Profeternes Børn gik frem og stode tværs overfor langtfra; men de stode begge ved Jordanen.
8 Elijah sì mú agbádá ó sì ká a sókè ó sì lu omi náà pẹ̀lú rẹ̀. Omi náà sì pín sí ọ̀tún àti sí òsì, àwọn méjèèjì sì rékọjá lórí ilẹ̀ gbígbẹ.
Da tog Elias sin Kappe og svøbte den sammen og slog Vandet, og det skiltes ad til begge Sider, og de gik begge igennem paa det tørre.
9 Nígbà tí wọ́n rékọjá, Elijah sì wí fún Eliṣa pé, “Sọ fún mi, kí ni èmi lè ṣe fún ọ kí ó tó di wí pé wọ́n gbà mí kúrò lọ́dọ̀ rẹ?” “Jẹ́ kí èmi kí ó jogún ìlọ́po méjì ẹ̀mí rẹ.” Ó dá a lóhùn.
Og det skete, der de kom over, da sagde Elias til Elisa: Bed, hvad jeg skal gøre for dig, før jeg tages fra dig; og Elisa sagde: Kære, at der maa være to Dele af din Aand over mig!
10 “Ìwọ ti béèrè ohun tí ó ṣòro,” Elijah wí pé, “Síbẹ̀ tí ìwọ bá rí mi nígbà tí a bá gbà mí kúrò lọ́wọ́ rẹ, yóò jẹ́ tìrẹ bí bẹ́ẹ̀ kọ́ kò ní rí bẹ́ẹ̀.”
Og han sagde: Du har bedet om en svar Ting; dog, dersom du ser mig, naar jeg tages fra dig, skal det ske dig saa, men hvis ikke, da sker det ikke.
11 Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ń rìn lọ tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ pọ̀, lọ́gán kẹ̀kẹ́ iná àti ẹṣin iná yọ sí wọn ó sì ya àwọn méjèèjì nípa, Elijah sì gòkè lọ sí ọ̀run pẹ̀lú àjà.
Og det skete, der de gik videre og talte, se, da kom der en gloende Vogn og gloende Heste, og de gjorde Skilsmisse imellem dem begge, og Elias for op i en Storm til Himmelen.
12 Eliṣa rí èyí ó sì kígbe sókè, “Baba mi! Baba mi! Kẹ̀kẹ́ àti ẹlẹ́ṣin Israẹli!” Eliṣa kò sì rí i mọ́. Ó sì mú aṣọ ara rẹ̀ ó sì fà wọ́n ya sọ́tọ̀.
Og Elisa saa det, og han raabte: Min Fader, min Fader, Israels Vogne og hans Ryttere! og han saa ham ikke ydermere, og han tog fat i sine Klæder og rev dem i to Stykker.
13 Ó sì mú agbádá tí ó ti jábọ́ láti ọ̀dọ̀ Elijah ó sì padà lọ, ó sì dúró lórí bèbè Jordani.
Og han tog Elias's Kappe op, som var falden af ham, og vendte tilbage og stod ved Jordanens Bred.
14 Ó sì mú agbádá náà tí ó jábọ́ láti ọwọ́ rẹ̀, ó sì lu omi pẹ̀lú rẹ̀. “Níbo ni Olúwa Ọlọ́run Elijah wà?” Ó béèrè. Nígbà tí ó lu omi náà, ó sì pín sí apá ọ̀tún àti sí òsì, Eliṣa sì rékọjá.
Og han tog Elias's Kappe, som var falden af ham, og slog Vandet og sagde: Hvor er Herren, Elias's Gud? ja hvor er han? og han slog Vandet, og det skiltes ad til begge Sider, og Elisa gik over.
15 Àwọn ọmọ wòlíì láti Jeriko, tí wọ́n ń wò, wí pé, “Ẹ̀mí Elijah sinmi lé Eliṣa.” Wọ́n sì lọ láti lọ bá a, wọ́n sì dojúbolẹ̀ níwájú rẹ̀.
Og der Profeternes Børn, som vare i Jeriko tværs overfor, saa det, da sagde de: Elias's Aand hviler paa Elisa; og de gik ham i Møde, og de bøjede sig ned for ham imod Jorden.
16 “Wò ó,” wọ́n wí pé, “Àwa ìránṣẹ́ ni àádọ́ta ọkùnrin alágbára. Jẹ́ kí wọ́n lọ láti lọ wá ọ̀gá rẹ wá. Bóyá ẹ̀mí Olúwa ti gbé e sókè, ó sì gbé e kalẹ̀ lórí òkè ńlá tàbí lórí ilẹ̀.” “Rárá,” Eliṣa dá a lóhùn pé, “Má ṣe rán wọn.”
Og de sagde til ham: Kære, se, her er halvtredsindstyve Mænd iblandt dine Tjenere, stærke Folk; lad dem dog gaa og lede efter din Herre, maaske Herrens Aand har optaget ham og kastet ham paa et af Bjergene eller i en af Dalene; men han sagde: Lader dem ikke gaa!
17 Ṣùgbọ́n wọ́n rọ̀ ọ́ títí ojú fi tì í láti gbà. Ó wí pé, “Rán wọn.” Wọ́n sì rán àádọ́ta ènìyàn tí ó wá a fún ọjọ́ mẹ́ta ṣùgbọ́n wọn kò rí i.
Men de nødte ham, indtil han bluedes derved og sagde: Lader dem gaa; og de udsendte halvtredsindstyve Mænd, og de ledte i tre Dage, men de fandt ham ikke.
18 Nígbà tí wọ́n padà dé ọ̀dọ̀ Eliṣa, tí ó dúró ní Jeriko, ó wí fún wọn pé, “Ṣé èmi kò sọ fún un yín kí ẹ má lọ?”
Da kom de tilbage til ham, medens han var bleven i Jeriko; og han sagde til dem: Sagde jeg ej til eder, at I ikke skulde gaa?
19 Àwọn ọkùnrin ìlú wí fún Eliṣa, pé, “Wò ó, olúwa wa, ìtẹ̀dó ìlú yìí dára, gẹ́gẹ́ bí ẹ ti rí i, ṣùgbọ́n omi náà burú, ilẹ̀ náà sì sá.”
Og Mændene i Staden sagde til Elisa: Kære, se, her er godt at bo i Staden, ligesom min Herre ser; men Vandet er slet, og Landet volder utidige Fødsler.
20 Ó sì wí pé, “Mú àwokòtò tuntun fún mi wá, kí o sì mú iyọ̀ sí inú rẹ̀.” Wọ́n sì gbé e wá fún un.
Og han sagde: Henter mig en ny Skaal og lægger Salt derudi; og de hentede det til ham.
21 Nígbà náà ó sì jáde lọ sí ibi orísun omi, ó sì da iyọ̀ sí inú rẹ̀, ó wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Èmi ti wo omi yìí sàn. Kò ní mú ikú wá mọ́ tàbí mú ilẹ̀ náà sá.’”
Da gik han ud til Vandets Udspring, og han kastede Saltet deri og sagde: Saa sagde Herren: Jeg har gjort dette Vand sundt, at der skal ingen Død eller Ufrugtbarhed ydermere komme deraf.
22 Omi náà sì ti dára ni mímu títí di òní, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ tí Eliṣa ti sọ.
Saa blev Vandet sundt indtil denne Dag, efter Elisas Ord, som han talte.
23 Láti ibẹ̀ Eliṣa lọ sókè ní Beteli gẹ́gẹ́ bí ó ti ń rìn lọ lójú ọ̀nà, àwọn ọ̀dọ́ kan jáde wá láti ìlú náà wọ́n sì fi ṣe ẹlẹ́yà. “Máa lọ sókè ìwọ apárí!” Wọ́n wí pé. “Máa lọ sókè ìwọ apárí!”
Og han gik derfra op til Bethel; men der han gik op paa Vejen, da kom der smaa Drenge ud af Staden og spottede ham og sagde til ham: Kom op, du skaldede! kom op, du skaldede!
24 Ó sì yípadà, ó sì wò wọ́n ó sì fi wọ́n bú ní orúkọ Olúwa. Nígbà náà beari méjì sì jáde wá láti inú igbó ó sì lu méjìlélógójì lára àwọn ọ̀dọ́ náà.
Og han vendte sig om, og der han saa dem, da bandede han dem i Herrens Navn; da kom der to Bjørne ud af Skoven og sønderreve af dem to og fyrretyve Børn.
25 Ó sì lọ sí orí òkè Karmeli láti ibẹ̀ ó sì padà sí Samaria.
Og han gik derfra til Bjerget Karmel, og han vendte tilbage derfra til Samaria.