< 2 Kings 2 >

1 Nígbà tí Olúwa ń fẹ́ gbé Elijah lọ sí òkè ọ̀run nínú àjà, Elijah àti Eliṣa wà ní ọ̀nà láti Gilgali.
Angraeng mah Elijah to takhi kamhae hoi van ah lak tom naah, Elijah loe Elisha hoi nawnto Gilgal ah caeh.
2 Elijah wí fún Eliṣa pé, “Dúró níbí; Olúwa rán mi lọ sí Beteli.” Ṣùgbọ́n Eliṣa wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti dájú pé Olúwa wà láyé àti gẹ́gẹ́ bí ó ti yẹ, èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí Beteli.
Elijah mah Elisha khaeah, Angraeng mah Bethel ah ang patoeh pongah, Nang loe hae ah om ah, tiah a naa. Toe Elisha mah, Angraeng loe hing moe, nang na hing pongah, nang hae kang caehtaak mak ai, tiah a naa. To pongah nihnik loe Bethel ah nawnto caeh hoi tathuk.
3 Àwọn ọmọ wòlíì ní Beteli jáde wá sí ọ̀dọ̀ Eliṣa wọ́n sì béèrè pé, “Ṣé ìwọ mọ̀ pé Olúwa yóò gba ọ̀gá rẹ kúrò lọ́dọ̀ rẹ lónìí?” “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi mọ̀,” Eliṣa dáhùn, “Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀.”
Bethel vangpui ah kaom tahmaa ih caanawk mah Elisha khaeah caeh o moe, anih khaeah, Vaihniah Angraeng mah nang khae hoiah na angraeng to la ving tih boeh, tito na panoek maw? tiah a naa o. Elisha mah, Ue, ka panoek; toe kamongah om oh, tiah a naa.
4 Nígbà náà Elijah sì wí fún un pé, “Dúró níbí, Eliṣa: Olúwa ti rán mi lọ sí Jeriko.” Ó sì dá a lóhùn pé, “Bí ó ti dájú pé Olúwa yè àti tí ìwọ náà yè, èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Wọ́n sì jọ lọ sí Jeriko.
Elijah mah anih khaeah, Angraeng mah Jeriko vangpui ah ang patoeh pongah, nang loe hae ah om ah, tiah a naa. To naah anih mah, Angraeng loe hing moe, nang doeh na hing pongah, nang hae kang caehtaak mak ai, tiah a naa. To pongah nihnik loe Jeriko vangpui ah nawnto caeh hoi.
5 Àwọn ọmọ wòlíì tí ó wà ní Jeriko sì gòkè tọ Eliṣa wá wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Ṣé ìwọ mọ̀ wí pé Olúwa yóò gba ọ̀gá rẹ kúrò lọ́dọ̀ rẹ lónìí?” “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi mọ̀,” Ó dá wọn lóhùn, “Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe sọ nípa rẹ̀.”
Jeriko vangpui ah kaom tahmaa ih caanawk loe Elisha khaeah caeh o moe, Vaihniah nang khae hoiah Angraeng mah na angraeng to la ving tih boeh, tito na panoek maw? tiah a naa o. Anih mah, Ue, ka panoek; toe kamongah om oh, tiah a naa.
6 Nígbà náà Elijah wí fún un pé, “Dúró níbí; Olúwa rán mi lọ sí Jordani.” Ó sì dá a lóhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti jẹ́ wí pé, Olúwa yè àti gẹ́gẹ́ bí o ti yè, èmi kò ní fi ọ́ sílẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn méjèèjì sì jọ ń lọ.
Elijah mah anih khaeah, Angraeng mah Jordan ah ang patoeh pongah, nang loe hae ah om ah, tiah a naa. Anih mah tahmaa khaeah, Angraeng loe hing moe, nang doeh na hing pongah, nang hae kang caehtaak mak ai, tiah a naa. Nihnik loe nawnto caeh hoi.
7 Àádọ́ta àwọn ọkùnrin ọmọ wòlíì sì lọ láti lọ dúró ní ọ̀nà jíjìn, wọ́n sì kọ ojú da ibi tí Elijah àti Eliṣa ti dúró ní Jordani.
Tahmaa ih caa quipangatonawk loe caeh o moe, kangthla hoiah khet hanah angdoet o; Elijah hoi Elisha loe Jordan vapui taengah angdoet hoi.
8 Elijah sì mú agbádá ó sì ká a sókè ó sì lu omi náà pẹ̀lú rẹ̀. Omi náà sì pín sí ọ̀tún àti sí òsì, àwọn méjèèjì sì rékọjá lórí ilẹ̀ gbígbẹ.
Elijah mah kahni to lak moe, zaeng pacoengah, tui to a boh; to naah tui to banqoi bantang amkhoih; to pacoengah nihnik loe saoeng ah caeh baktiah caeh hoi.
9 Nígbà tí wọ́n rékọjá, Elijah sì wí fún Eliṣa pé, “Sọ fún mi, kí ni èmi lè ṣe fún ọ kí ó tó di wí pé wọ́n gbà mí kúrò lọ́dọ̀ rẹ?” “Jẹ́ kí èmi kí ó jogún ìlọ́po méjì ẹ̀mí rẹ.” Ó dá a lóhùn.
Tui angkaat hoi pacoengah Elijah mah Elisha khaeah, Angraeng mah nang khae hoi kai na la ving ai naah, timaw kang sak pae han, tiah a dueng. To naah Elisha mah, na pakhra alet hnetto ka nuiah om nasoe, tiah a naa.
10 “Ìwọ ti béèrè ohun tí ó ṣòro,” Elijah wí pé, “Síbẹ̀ tí ìwọ bá rí mi nígbà tí a bá gbà mí kúrò lọ́wọ́ rẹ, yóò jẹ́ tìrẹ bí bẹ́ẹ̀ kọ́ kò ní rí bẹ́ẹ̀.”
Elijah mah, Nang loe karai parai hmuen ni nang hnik; toe nang khae hoi kai lak nathuem ah kai nang hnuk nahaeloe, na hak tih; nang hnuh ai nahaeloe na hak mak ai, tiah a naa.
11 Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ń rìn lọ tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ pọ̀, lọ́gán kẹ̀kẹ́ iná àti ẹṣin iná yọ sí wọn ó sì ya àwọn méjèèjì nípa, Elijah sì gòkè lọ sí ọ̀run pẹ̀lú àjà.
Nihnik loe caeh hoi moe, lok apaeh hoi li naah, khenah, hmai hrang lakok hoi hmai hrang to poek ai pui hoiah amtueng moe, nihnik to tapraek ving; Elijah loe takhi kamhae hoiah van ah caeh tahang.
12 Eliṣa rí èyí ó sì kígbe sókè, “Baba mi! Baba mi! Kẹ̀kẹ́ àti ẹlẹ́ṣin Israẹli!” Eliṣa kò sì rí i mọ́. Ó sì mú aṣọ ara rẹ̀ ó sì fà wọ́n ya sọ́tọ̀.
Elisha mah hnuk naah, Kampa, kampa, Israelnawk ih hrang lakok hoi hrang angthueng kaminawk, tiah a hangh. To pacoeng hoi loe Elijah to hnu let ai boeh; to naah angmah ih kahni to lak moe, hnetto ah asih.
13 Ó sì mú agbádá tí ó ti jábọ́ láti ọ̀dọ̀ Elijah ó sì padà lọ, ó sì dúró lórí bèbè Jordani.
Elijah khae hoi kakrah kahni to anih mah lak moe, amlaem let pacoengah, Jordan vapui taengah angdoet;
14 Ó sì mú agbádá náà tí ó jábọ́ láti ọwọ́ rẹ̀, ó sì lu omi pẹ̀lú rẹ̀. “Níbo ni Olúwa Ọlọ́run Elijah wà?” Ó béèrè. Nígbà tí ó lu omi náà, ó sì pín sí apá ọ̀tún àti sí òsì, Eliṣa sì rékọjá.
Elijah khae hoi kakrah kahni to anih mah lak moe, tui to a boh pacoengah, Elijah ih Angraeng Sithaw naa ah maw na oh? tiah thuih. Tui to a boh naah, banqoi bantang amkhoih, to pacoengah anih loe caeh.
15 Àwọn ọmọ wòlíì láti Jeriko, tí wọ́n ń wò, wí pé, “Ẹ̀mí Elijah sinmi lé Eliṣa.” Wọ́n sì lọ láti lọ bá a, wọ́n sì dojúbolẹ̀ níwájú rẹ̀.
Anih toepkung Jeriko vangpui ah kaom tahmaa caanawk mah anih to hnuk o naah, Elisha nuiah Elijah ih pakhra oh boeh, tiah thuih o. Nihcae loe anih to hnuk hanah caeh o moe, a hmaa ah long ah akuep o.
16 “Wò ó,” wọ́n wí pé, “Àwa ìránṣẹ́ ni àádọ́ta ọkùnrin alágbára. Jẹ́ kí wọ́n lọ láti lọ wá ọ̀gá rẹ wá. Bóyá ẹ̀mí Olúwa ti gbé e sókè, ó sì gbé e kalẹ̀ lórí òkè ńlá tàbí lórí ilẹ̀.” “Rárá,” Eliṣa dá a lóhùn pé, “Má ṣe rán wọn.”
Nihcae mah Elisha khaeah, Khenah, na tamna kaicae loe thacak kami quipangato ka tawnh o; nihcae loe caeh o nasoe loe na angraeng to pakrong o nasoe; Angraeng ih Muithla mah anih to lak moe, mae nuiah maw, to tih ai boeh loe azawn ah maw suem khoe doeh om tih, tiah a naa o. Elisha mah, Patoeh o hmah, tiah a naa.
17 Ṣùgbọ́n wọ́n rọ̀ ọ́ títí ojú fi tì í láti gbà. Ó wí pé, “Rán wọn.” Wọ́n sì rán àádọ́ta ènìyàn tí ó wá a fún ọjọ́ mẹ́ta ṣùgbọ́n wọn kò rí i.
Toe to kaminawk mah angaek thai han ai ah hnik o khruek pongah, anih mah, Patoeh oh, tiah a naa. To pongah nihcae mah kami quipangato patoeh o; nihcae mah ni thumto thung pakrong o, toe hnu o ai.
18 Nígbà tí wọ́n padà dé ọ̀dọ̀ Eliṣa, tí ó dúró ní Jeriko, ó wí fún wọn pé, “Ṣé èmi kò sọ fún un yín kí ẹ má lọ?”
Nihcae Jeriko vangpui ah Elisha khaeah amlaem o let naah, anih mah nihcae khaeah, Caeh o hmah, tiah kang thuih o na ai maw, tiah a naa.
19 Àwọn ọkùnrin ìlú wí fún Eliṣa, pé, “Wò ó, olúwa wa, ìtẹ̀dó ìlú yìí dára, gẹ́gẹ́ bí ẹ ti rí i, ṣùgbọ́n omi náà burú, ilẹ̀ náà sì sá.”
Avang thung kaom kaminawk mah Elisha khaeah, Khenah, ka angraeng nang mah na hnuk baktih toengah, hae vangpui loe khosak hanah hoih parai; toe tui hoih ai pongah, long doeh hoih thai ai, tiah a naa o.
20 Ó sì wí pé, “Mú àwokòtò tuntun fún mi wá, kí o sì mú iyọ̀ sí inú rẹ̀.” Wọ́n sì gbé e wá fún un.
Anih mah, Boengloeng khangtha thungah paloi to thaeng oh loe, kai khaeah na sin oh, tiah a naa. To pongah nihcae mah anih hanah sinh pae o.
21 Nígbà náà ó sì jáde lọ sí ibi orísun omi, ó sì da iyọ̀ sí inú rẹ̀, ó wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Èmi ti wo omi yìí sàn. Kò ní mú ikú wá mọ́ tàbí mú ilẹ̀ náà sá.’”
Anih loe vacong ohhaih bangah caeh moe, paloi to a haeh, to pacoengah loe Angraeng mah, Hae tui hae caak han ka hoisak boeh, vaihi hoi kamtong kami dueh mak ai ueloe, long doeh hoih ai ah om mak ai boeh, tiah a naa.
22 Omi náà sì ti dára ni mímu títí di òní, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ tí Eliṣa ti sọ.
To pongah Elisha mah thuih ih lok baktih toengah, vaihni ni khoek to tui to caak hanah hoih boeh.
23 Láti ibẹ̀ Eliṣa lọ sókè ní Beteli gẹ́gẹ́ bí ó ti ń rìn lọ lójú ọ̀nà, àwọn ọ̀dọ́ kan jáde wá láti ìlú náà wọ́n sì fi ṣe ẹlẹ́yà. “Máa lọ sókè ìwọ apárí!” Wọ́n wí pé. “Máa lọ sókè ìwọ apárí!”
Elisha loe to ahmuen hoi Bethel ah caeh tahang, loklam caeh li naah, thendoengnawk vangpui thung hoiah angzoh o moe, anih hanah, Lu angmuilum kami, caeh tahang ah, lu angmuilum kami, caeh tahang ah, tiah pahnui o thuih.
24 Ó sì yípadà, ó sì wò wọ́n ó sì fi wọ́n bú ní orúkọ Olúwa. Nígbà náà beari méjì sì jáde wá láti inú igbó ó sì lu méjìlélógójì lára àwọn ọ̀dọ́ náà.
Anih loe hnukbangah angqoi moe, nihcae to khet pacoengah, Angraeng ih ahmin hoiah to kaminawk to tangoeng thuih; to naah taw ih taqom amno hnetto angzoh moe, thendoeng quipalito pacoeng, hnetto kaek boih.
25 Ó sì lọ sí orí òkè Karmeli láti ibẹ̀ ó sì padà sí Samaria.
Anih loe to ahmuen hoiah Karmel mae ah caeh tahang poe moe, to ahmuen hoiah Samaria vangpui ah amlaem let.

< 2 Kings 2 >