< 2 Kings 19 >

1 Nígbà tí ọba Hesekiah gbọ́ èyí, ó fa aṣọ rẹ̀ ya ó sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀ ó sì lọ sí àgọ́ Olúwa
Xundaⱪ boldiki, Ⱨǝzǝkiya buni angliƣanda, kiyim-keqǝklirini yirtip, ɵzini bɵz bilǝn ⱪaplap Pǝrwǝrdigarning ibadǝthanisiƣa kirdi.
2 Ó sì rán Eliakimu olùtọ́jú ààfin, Ṣebna akọ̀wé àti olórí àlùfáà gbogbo wọn sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, sí ọ̀dọ̀ wòlíì Isaiah ọmọ Amosi.
U Ⱨilⱪiyaning oƣli, ordini baxⱪuridiƣan Eliakim, orda diwanbegi Xǝbna wǝ kaⱨinlarning aⱪsaⱪallirini bɵz ⱪaplanƣan peti Amozning oƣli Yǝxaya pǝyƣǝmbǝrgǝ ǝwǝtti.
3 Wọ́n sì sọ fún ún pé, “Èyí ni ohun tí Hesekiah sọ: ọjọ́ òní yí jẹ́ ọjọ́ ìpọ́njú àti ìbáwí àti ẹ̀gàn, gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí ọmọdé wá sí ojú ìbímọ tí kò sì sí agbára láti fi bí wọn.
Ular uningƣa: — Ⱨǝzǝkiya mundaⱪ dǝydu: — «Balilar tuƣulay dǝp ⱪalƣanda anining tuƣⱪudǝk ⱨali ⱪalmiƣandǝk, muxu kün awariqilik, rǝswa ⱪilinidiƣan, mazaⱪ ⱪilinidiƣan bir künidur.
4 Ó lè jẹ́ wí pé Olúwa Ọlọ́run yóò gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ olùdarí pápá, ẹni tí ọ̀gá rẹ̀, ọba Asiria, ti rán láti fi Ọlọ́run alààyè ṣẹ̀sín, yóò sì bá a wí fún ọ̀rọ̀ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ ti gbọ́. Nítorí náà gbàdúrà fún ìyókù àwọn tí ó wà láààyè.”
Ɵz hojayini bolƣan Asuriyǝ padixaⱨi tirik Hudani mazaⱪ ⱪilixⱪa ǝwǝtkǝn Rab-Xakǝⱨning muxu barliⱪ gǝplirini Pǝrwǝrdigar Hudaying nǝzirigǝ elip tingxisa, bularni angliƣan Pǝrwǝrdigar Hudaying xu gǝplǝr üqün uning dǝkkisini berǝrmikin? Xunga ⱪelip ⱪalƣan ⱪaldisi üqün awazingni kɵtürüp, bir duayingni bǝrsǝng» — dedi.
5 Nígbà tí ìránṣẹ́ ọba Hesekiah lọ sí ọ̀dọ̀ Isaiah,
Xu gǝplǝr bilǝn Ⱨǝzǝkiyaning hizmǝtkarliri Yǝxayaning aldiƣa kǝldi.
6 Isaiah wí fún wọn pé, “Sọ fún ọ̀gá rẹ, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa sọ pé: Ẹ má ṣe bẹ̀rù ohun tí ẹ̀yin ti gbọ́—àwọn ọ̀rọ̀ ìhàlẹ̀ pẹ̀lú èyí ti ọba Asiria ti sọ̀rọ̀-òdì sí mi.
Yǝxaya ularƣa: — «Hojayininglarƣa: — Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dedi: — «Asuriyǝ padixaⱨining qaparmǝnlirining sǝn angliƣan axu Manga kupurluⱪ ⱪilƣuqi gǝpliridin ⱪorⱪma;
7 Gbọ́! Èmi yóò rán ẹ̀mí kan sínú rẹ̀ nígbà tí ó bá sì gbọ́ ariwo, yóò sì padà sí ìlú rẹ̀, níbẹ̀ ni èmi yóò sì gbé gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà.’”
Mana, Mǝn uningƣa bir roⱨni kirgüzimǝn; xuning bilǝn u bir iƣwani anglap, ɵz yurtiƣa ⱪaytidu. Mǝn uni ɵz zeminida turƣuzup ⱪiliq bilǝn ɵltürgüzimǝn» — dǝnglar» — dedi.
8 Nígbà tí olùdarí pápá gbọ́ wí pé ọba Asiria ti kúrò ní Lakiṣi ó sì padà ó sì rí ọba níbi ti ó gbé ń bá Libina jà.
Rab-Xakǝⱨ ɵzi kǝlgǝn yoli bilǝn ⱪaytip mangƣanda, Asuriyǝ padixaⱨining Laⱪix xǝⱨiridin qekingǝnlikini anglap, Libnaⱨ xǝⱨirigǝ ⱪarxi jǝng ⱪiliwatⱪan padixaⱨning yeniƣa kǝldi.
9 Nísinsin yìí, Sennakeribu sì gbọ́ ìròyìn wí pé Tirakah, ọba Etiopia ti Ejibiti wá ó sì ń yan jáde lọ láti lọ bá a jagun. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì tún rán oníṣẹ́ sí Hesekiah pẹ̀lú ọ̀rọ̀ yìí pé,
Qünki padixaⱨ: «Mana, Efiopiyǝ padixaⱨi Tirⱨakaⱨ sizgǝ ⱪarxi jǝng ⱪilmaⱪqi bolup yolƣa qiⱪti» degǝn hǝwǝrni angliƣanidi. Lekin u yǝnǝ Ⱨǝzǝkiyaƣa ǝlqilǝrni mundaⱪ hǝt bilǝn ǝwǝtti: —
10 “Sọ fún Hesekiah ọba Juda pé, má ṣe jẹ́ kí òrìṣà tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé kí ó tàn ó jẹ nígbà tí ó wí pé, ‘Jerusalẹmu a kò ní fi lé ọwọ́ ọba Asiria.’
«Silǝr Yǝⱨuda padixaⱨi Ⱨǝzǝkiyaƣa mundaⱪ dǝngarisaldilar: — «Sǝn tayinidiƣan Hudayingning sanga: «Yerusalem Asuriyǝ padixaⱨining ⱪoliƣa tapxurulmaydu» deginigǝ aldanma;
11 Lóòótọ́ ìwọ ti gbọ́ gbogbo ohun tí ọba Asiria tí ó ṣe sí gbogbo àwọn ìlú, ó pa wọ́n run pátápátá. Ìwọ yóò sì gbàlà?
mana, sǝn Asuriyǝ padixaⱨlirining ⱨǝmmǝ ǝl-yurtlarni nemǝ ⱪilƣanlirini, ularni ɵz ilaⱨ-butliriƣa atap ⱨalak ⱪilƣanliⱪini angliƣansǝn; ǝmdi ɵzüng ⱪutⱪuzulamsǝn?
12 Ṣé àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè tí a ti parun láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá mi gbà wọ́n là: òrìṣà Gosani, Harani Reṣefu àti gbogbo ènìyàn Edeni tí wọ́n wà ní Teli-Assari?
Ata-bowilirim ⱨalak ⱪilƣan ǝllǝrning ɵz ilaⱨ-butliri ularni ⱪutⱪuzƣanmu? Gozan, Ⱨaran, Rǝzǝf xǝⱨiridikilǝrniqu, Telassarda turƣan Edǝnlǝrniqu?
13 Níbo ni ọba Hamati wa, ọba Arpadi, ọba ìlú Sefarfaimi, ti Hena, tàbí ti Iffa gbé wà?”
Hamat padixaⱨi, Arpad padixaⱨi, Sǝfarwaim, Hena ⱨǝm Iwwaⱨ xǝⱨǝrlirining padixaⱨliri ⱪeni?»».
14 Hesekiah gba lẹ́tà láti ọ̀dọ̀ ìránṣẹ́ ó sì kà á. Nígbà náà ó sì lọ sí òkè ilé tí a kọ́ fún Olúwa ó sì tẹ́ ẹ síwájú Olúwa.
Xuning bilǝn Ⱨǝzǝkiya hǝtni ǝkǝlgüqilǝrning ⱪolidin elip oⱪup qiⱪti. Andin u Pǝrwǝrdigarning ɵyigǝ kirip, Pǝrwǝrdigarning aldiƣa hǝtni yeyip ⱪoydi.
15 Hesekiah gbàdúrà sí Olúwa: “Olúwa Ọlọ́run Israẹli, tí ń gbé ní àárín àwọn kérúbù, ìwọ nìkan ni Ọlọ́run lórí gbogbo ìjọba tí ó wà láyé, ìwọ ti dá ọ̀run àti ayé.
Wǝ Ⱨǝzǝkiya Pǝrwǝrdigarƣa dua ⱪilip mundaⱪ dedi: — «I kerublar otturisida turƣan Pǝrwǝrdigar, Israilning Hudasi: — Sǝn Ɵzüngdursǝn, jaⱨandiki barliⱪ ǝl-yurtlarning üstidiki Huda pǝⱪǝt Ɵzüngdursǝn; asman-zeminni Yaratⱪuqisǝn.
16 Dẹtí sílẹ̀, Olúwa kí o sì gbọ́; la ojú rẹ, Olúwa, kí o sì rí i, gbọ́ ọ̀rọ̀ Sennakeribu tí ó rán láti fi bú Ọlọ́run alààyè.
I Pǝrwǝrdigar, ⱪuliⱪingni tɵwǝn ⱪilip angliƣaysǝn; kɵzüngni aqⱪaysǝn, i Pǝrwǝrdigar, kɵrgǝysǝn; Sǝnnaheribning adǝm ǝwǝtip mǝnggü ⱨayat Hudani ⱨaⱪarǝtlǝp eytⱪan gǝplirini angliƣaysǝn!
17 “Òtítọ́ ni, Olúwa, wí pé ọba Asiria ti pa orílẹ̀-èdè wọ̀nyí run àti ilẹ̀ wọn.
I Pǝrwǝrdigar, Asuriyǝ padixaⱨliri ⱨǝⱪiⱪǝtǝn ⱨǝmmǝ yurtlarni, xularƣa beⱪindi bolƣan yurtlarnimu harabǝ ⱪilip,
18 Wọ́n ti ju òrìṣà wọn sínú iná wọn sì ti bà wọ́n jẹ́, nítorí pé wọn kì í ṣe ọlọ́run. Ṣùgbọ́n, wọ́n jẹ́ igi àti òkúta tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú ọwọ́ ènìyàn.
ularning ilaⱨ-butlirini otⱪa taxliwǝtkǝn; qünki ularning ilaⱨliri ilaⱨ ǝmǝs, bǝlki insan ⱪoli bilǝn yasalƣanliri, yaƣaq wǝ tax, halas; xunga asuriylar ularni ⱨalak ⱪildi.
19 Nísinsin yìí Olúwa Ọlọ́run wa, gbà wá kúrò lọ́wọ́ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo àwọn ìjọba lórí ilẹ̀ ayé le mọ̀ pé ìwọ nìkan ṣoṣo ni, Olúwa Ọlọ́run wa.”
Əmdi, i Pǝrwǝrdigar Hudayimiz, jaⱨandiki barliⱪ ǝl-yurtlarƣa Sening, pǝⱪǝt Seningla Pǝrwǝrdigar ikǝnlikingni bildürüx üqün, bizni uning ⱪolidin ⱪutⱪuzƣaysǝn!».
20 Nígbà náà Isaiah ọmọ Amosi rán oníṣẹ́ sí Hesekiah pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ: Mo ti gbọ́ àdúrà rẹ nípa ti Sennakeribu ọba Asiria.
Xuning bilǝn Amozning oƣli Yǝxaya Ⱨǝzǝkiyaƣa sɵz ǝwǝtip mundaⱪ dedi: — — Israilning Hudasi Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — «Sening Manga Sǝnnaherib toƣruluⱪ ⱪilƣan duayingni anglidim.
21 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀, “‘Wúńdíá ọmọbìnrin Sioni kẹ́gàn rẹ ó sì fi ọ́ ṣe ẹlẹ́yà. Ọmọbìnrin Jerusalẹmu mi orí sí ọ gẹ́gẹ́ bí o ti sálọ.
Pǝrwǝrdigarning uningƣa ⱪarita degǝn sɵzi xudurki: — «Pak ⱪiz, yǝni Zionning ⱪizi seni kǝmsitidu, Seni mazaⱪ ⱪilip külidu; Yerusalemning ⱪizi kǝyninggǝ ⱪarap bexini qayⱪaydu;
22 Ta ni ìwọ ti bú tí o sì kẹ́gàn rẹ̀? Lórí ta ni ìwọ ti gbé ohùn rẹ sókè tí ó sì gbé ojú sókè sí ọ ní ìgbéraga? Lórí ẹni mímọ́ ti Israẹli!
sǝn kimni mazaⱪ ⱪilip kupurluⱪ ⱪilding? Sǝn kimgǝ ⱪarxi awazingni kɵtürüp, Nǝziringni üstün ⱪilding? Israildiki Muⱪǝddǝs Bolƣuqiƣa ⱪarxi!
23 Nípa àwọn ìránṣẹ́ rẹ ìwọ ti sọ̀rọ̀ búburú sí Olúwa. Tì wọ sì wí pé, “Pẹ̀lú ọ̀pọ̀ kẹ̀kẹ́ mi ni èmi sì fi dé orí àwọn òkè ńlá, sí ibi gíga jùlọ Lebanoni. Èmi a sì ké igi kedari gíga rẹ̀ lulẹ̀, àti ààyò igi firi rẹ̀. Èmi a sì lọ sí orí òkè ìbùwọ̀ rẹ̀ sínú ibi tí ó dára jù nínú igbó rẹ̀.
Əlqiliring arⱪiliⱪ sǝn Rǝbni mazaⱪ ⱪilip; — «Mǝn nurƣunliƣan jǝng ⱨarwilirim bilǝn taƣ qoⱪⱪisiƣa, Liwan taƣ baƣriliriƣa yetip kǝldimki, Uning egiz kedir dǝrǝhlirini, esil ⱪariƣaylirini kesiwetimǝn; Mǝn uning ǝng qǝt turalƣusiƣa, Uning ǝng bük-baraⱪsan ormanzarliⱪiƣa kirip yetimǝn.
24 Mo ti gbẹ́ kànga ní ilẹ̀ àjèjì, mo sì mu omi níbẹ̀. Pẹ̀lú àtẹ́lẹsẹ̀ mi, èmi ti gbẹ́ gbogbo omi odò tí ó wà ní Ejibiti.”
Ɵzüm ⱪuduⱪ kolap yaⱪa yurtning süyini iqtim; Putumning uqidila mǝn Misirning barliⱪ dǝrya-ɵstǝnglirini ⱪurutiwǝttim — deding.
25 “‘Ṣé ìwọ kò tí ì gbọ́? Ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn mo yàn án. Ní ọjọ́ ogbó ni mo ṣètò rẹ̀; nísinsin yìí mo ti mú wá sí ìkọjá pé ìwọ ti yí ìlú olódi padà dí òkìtì àlàpà òkúta.
— Sǝn xuni anglap baⱪmiƣanmiding? Uzundin buyan Mǝn xuni bekitkǝnmǝnki, Ⱪǝdimdin tartip xǝkillǝndürgǝnmǝnki, Ⱨazir uni ǝmǝlgǝ axurdumki, Mana, sǝn ⱪǝl’ǝ-ⱪorƣanliⱪ xǝⱨǝrlǝrni harabilǝrgǝ aylandurdung;
26 Àwọn ènìyàn wọn ń gbẹ nípa, wọ́n ti dà á láàmú wọ́n sì ti ṣọ́ di ìtìjú. Wọ́n dàbí koríko igbó lórí pápá, gẹ́gẹ́ bí ọkà tí ó rẹ̀ dànù kí ó tó dàgbàsókè, gẹ́gẹ́ bí fífún ọkà tí ó hù jáde.
Xuning bilǝn u yǝrdǝ turuwatⱪanlar küqsizlinip, Yǝrgǝ ⱪaritip ⱪoyuldi, xǝrmǝndǝ ⱪilindi; Ular ɵsiwatⱪan ot-qɵptǝk, Yumran kɵk qɵplǝrdǝk, Ɵgzidiki ot-qɵplǝr ɵsmǝy ⱪurup kǝtkǝndǝk boldi.
27 “‘Ṣùgbọ́n èmi mọ ibi tí ìwọ dúró àti ìgbà tí ìwọ bá dé tàbí lọ àti bí ìwọ ṣe ìkáàánú rẹ: sí mi.
Biraⱪ sening olturƣiningni, ornungdin turƣiningni, qiⱪip-kirginingni wǝ Manga ⱪarxi ƣaljirlixip kǝtkiningni bilimǝn;
28 Ṣùgbọ́n ìkáàánú rẹ sí mi àti ìrora rẹ dé etí mi, Èmi yóò gbé ìwọ̀ mi sí imú rẹ àti ìjánu mi sí ẹnu rẹ, èmi yóò mú ọ padà nípa wíwá rẹ.’
Sening Manga ⱪarxi ƣaljirlixip kǝtkǝnlikingning, ⱨakawurlixip kǝtkǝnlikingning ⱪuliⱪimƣa yǝtkǝnliki tüpǝylidin, Mǝn ⱪarmiⱪimni burningdin ɵtküzimǝn, Yüginimni aƣzingƣa salimǝn, Wǝ ɵzüng kǝlgǝn yol bilǝn seni ⱪayturimǝn.
29 “Èyí yóò jẹ́ àmì fún ọ, ìwọ Hesekiah: “Ọdún yìí ìwọ yóò jẹ ohun tí ó bá hù fún rara rẹ̀, àti ní ọdún kejì ohun tí ó bá hù jáde láti inú ìyẹn. Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, gbìn kí o sì kórè, gbin ọgbà àjàrà kí o sì jẹ èso rẹ̀.
I [Ⱨǝzǝkiya], xu ix sanga alamǝt bexarǝt boliduki, Muxu yili ɵzlükidin ɵskǝn, Ikkinqi yili xulardin qiⱪⱪanlarmu silǝrning rizⱪinglar bolidu; Üqinqi yili bolsa teriysilǝr, orisilǝr, üzüm kɵqǝtlirini tikisilǝr; Ulardin qiⱪⱪan mewilǝrni yǝysilǝr.
30 Lẹ́ẹ̀kan sí i ìyókù ti ilé Juda yóò sì tún hu gbòǹgbò lábẹ́, yóò sì so èso lókè.
Yǝⱨuda jǝmǝtining ⱪeqip ⱪutulƣan ⱪaldisi bolsa yǝnǝ tɵwǝngǝ ⱪarap yiltiz tartidu, Yuⱪiriƣa ⱪarap mewǝ beridu;
31 Láti inú Jerusalẹmu ní àwọn ìyókù yóò ti wá àti láti orí òkè Sioni ni ọ̀pọ̀ àwọn tí ó sá àsálà. Ìtara Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò ṣe èyí.
Qünki Yerusalemdin bir ⱪaldisi, Zion teƣidin ⱪeqip ⱪutulƣanlar qiⱪidu; Samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Pǝrwǝrdigarning otluⱪ muⱨǝbbiti muxuni ada ⱪilidu.
32 “Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa sọ nípa ti ọba Asiria: “Kò ní wọ ìlú yìí tàbí ta ọfà síbí. Kò ní wá níwájú rẹ pẹ̀lú àpáta tàbí kó ìdọ̀tí àgbò sí ọ̀kánkán rẹ.
Xunga, Pǝrwǝrdigar Asuriyǝ padixaⱨi toƣruluⱪ mundaⱪ dǝydu: — U nǝ muxu xǝⱨǝrgǝ yetip kǝlmǝydu, Nǝ uningƣa bir tal oⱪmu atmaydu; Nǝ ⱪalⱪanni kɵtürüp aldiƣa kǝlmǝydu, Nǝ uningƣa ⱪarita ⱪaxalarnimu yasimaydu.
33 Nípa ọ̀nà tí ó gbà wá ni yóò padà; kì yóò wọ ìlú ńlá yìí, ni Olúwa wí.
U ⱪaysi yol bilǝn kǝlgǝn bolsa, U yol bilǝn ⱪaytidu wǝ muxu xǝⱨǝrgǝ kǝlmǝydu — dǝydu Pǝrwǝrdigar,
34 Èmi yóò dá ààbò bo ìlú ńlá yìí, èmi yóò sì pa á mọ́ fún èmi tìkára mi àti fún Dafidi ìránṣẹ́ mi.”
— Qünki Ɵzüm üqün wǝ Mening ⱪulum Dawut üqün uni ǝtrapidiki sepildǝk ⱪoƣdap ⱪutⱪuzimǝn».
35 Ní alẹ́ ọjọ́ náà, angẹli Olúwa jáde lọ ó sì pa ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án lé ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn ní ibùdó àwọn ará Asiria. Nígbà tí wọ́n sì dìde dúró ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì níbẹ̀ ni gbogbo òkú wà!
Xu keqǝ xundaⱪ boldiki, Pǝrwǝrdigarning Pǝrixtisi qiⱪip, Asuriyǝliklǝrning bargaⱨida bir yüz sǝksǝn bǝx ming ǝskǝrni urdi; mana, kixilǝr ǝtigǝndǝ ornidin turƣanda, ularning ⱨǝmmisining ɵlgǝnlikini kɵrdi!
36 Bẹ́ẹ̀ ni Sennakeribu ọba Asiria wọ àgọ́ ó sì padà, ó sì padà sí Ninefe ó sì dúró níbẹ̀.
Xunga Asuriyǝ padixaⱨi Sǝnnaherib qekinip, yolƣa qiⱪip, Ninǝwǝ xǝⱨirigǝ ⱪaytip turdi.
37 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí ó sùn nínú ilé òrìṣà Nisroki, ọmọkùnrin rẹ̀ Adrameleki àti Ṣareseri gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà, wọ́n sì sálọ sí ilẹ̀ Ararati Esarhadoni ọmọkùnrin rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Wǝ xundaⱪ boldiki, u ɵz buti Nisroⱪning buthanisida uningƣa qoⱪunuwatⱪanda, oƣulliri Adrammǝlǝk ⱨǝm Xarezǝr uni ⱪiliqlap ɵltürüwǝtti; andin ular bolsa Ararat degǝn yurtⱪa ⱪeqip kǝtti. Uning oƣli Esarⱨaddon uning ornida padixaⱨ boldi.

< 2 Kings 19 >