< 2 Kings 19 >

1 Nígbà tí ọba Hesekiah gbọ́ èyí, ó fa aṣọ rẹ̀ ya ó sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀ ó sì lọ sí àgọ́ Olúwa
Și s-a întâmplat, când împăratul Ezechia a auzit aceasta, că și-a sfâșiat hainele și s-a acoperit cu pânză de sac și a intrat în casa DOMNULUI.
2 Ó sì rán Eliakimu olùtọ́jú ààfin, Ṣebna akọ̀wé àti olórí àlùfáà gbogbo wọn sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, sí ọ̀dọ̀ wòlíì Isaiah ọmọ Amosi.
Și a trimis pe Eliachim, care era peste casă și pe Șebna, scribul, și pe bătrânii preoților, acoperiți cu pânză de sac, la profetul Isaia, fiul lui Amoț.
3 Wọ́n sì sọ fún ún pé, “Èyí ni ohun tí Hesekiah sọ: ọjọ́ òní yí jẹ́ ọjọ́ ìpọ́njú àti ìbáwí àti ẹ̀gàn, gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí ọmọdé wá sí ojú ìbímọ tí kò sì sí agbára láti fi bí wọn.
Și ei i-au zis: Astfel spune Ezechia: Această zi este o zi de necaz și de mustrare și de blasfemie; deoarece copiii au ajuns la naștere și nu este putere pentru a naște.
4 Ó lè jẹ́ wí pé Olúwa Ọlọ́run yóò gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ olùdarí pápá, ẹni tí ọ̀gá rẹ̀, ọba Asiria, ti rán láti fi Ọlọ́run alààyè ṣẹ̀sín, yóò sì bá a wí fún ọ̀rọ̀ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ ti gbọ́. Nítorí náà gbàdúrà fún ìyókù àwọn tí ó wà láààyè.”
Poate că DOMNUL Dumnezeul tău va auzi toate cuvintele lui Rabșache, pe care l-a trimis împăratul Asiriei, stăpânul său, să ocărască pe Dumnezeul cel viu; și va mustra cuvintele pe care DOMNUL Dumnezeul tău le-a auzit; de aceea înalță rugăciunea ta pentru rămășița care a rămas.
5 Nígbà tí ìránṣẹ́ ọba Hesekiah lọ sí ọ̀dọ̀ Isaiah,
Astfel servitorii împăratului Ezechia au venit la Isaia.
6 Isaiah wí fún wọn pé, “Sọ fún ọ̀gá rẹ, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa sọ pé: Ẹ má ṣe bẹ̀rù ohun tí ẹ̀yin ti gbọ́—àwọn ọ̀rọ̀ ìhàlẹ̀ pẹ̀lú èyí ti ọba Asiria ti sọ̀rọ̀-òdì sí mi.
Și Isaia le-a zis: Astfel să spuneți stăpânului vostru: Astfel spune DOMNUL: Nu te teme de cuvintele pe care le-ai auzit, cu care servitorii împăratului Asiriei m-au blasfemiat.
7 Gbọ́! Èmi yóò rán ẹ̀mí kan sínú rẹ̀ nígbà tí ó bá sì gbọ́ ariwo, yóò sì padà sí ìlú rẹ̀, níbẹ̀ ni èmi yóò sì gbé gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà.’”
Iată, voi trimite o pufnire peste el și va auzi un zvon și se va întoarce în țara sa; și îl voi face să cadă prin sabie în țara sa.
8 Nígbà tí olùdarí pápá gbọ́ wí pé ọba Asiria ti kúrò ní Lakiṣi ó sì padà ó sì rí ọba níbi ti ó gbé ń bá Libina jà.
Astfel, Rabșache s-a întors și l-a găsit pe împăratul Asiriei războindu-se împotriva Libnei, pentru că auzise că plecase din Lachis.
9 Nísinsin yìí, Sennakeribu sì gbọ́ ìròyìn wí pé Tirakah, ọba Etiopia ti Ejibiti wá ó sì ń yan jáde lọ láti lọ bá a jagun. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì tún rán oníṣẹ́ sí Hesekiah pẹ̀lú ọ̀rọ̀ yìí pé,
Și după ce a auzit spunându-se despre Tirhaca, împăratul Etiopiei: Iată, el a ieșit să lupte împotriva ta; el a trimis din nou mesageri la Ezechia, zicând:
10 “Sọ fún Hesekiah ọba Juda pé, má ṣe jẹ́ kí òrìṣà tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé kí ó tàn ó jẹ nígbà tí ó wí pé, ‘Jerusalẹmu a kò ní fi lé ọwọ́ ọba Asiria.’
Astfel să vorbiți lui Ezechia, împăratul lui Iuda, spunând: Să nu te înșele Dumnezeul tău în care te încrezi, zicând: Ierusalimul nu va fi dat în mâna împăratului Asiriei.
11 Lóòótọ́ ìwọ ti gbọ́ gbogbo ohun tí ọba Asiria tí ó ṣe sí gbogbo àwọn ìlú, ó pa wọ́n run pátápátá. Ìwọ yóò sì gbàlà?
Iată, ai auzit ce au făcut împărații Asiriei tuturor țărilor, distrugându-le complet; și vei fi tu scăpat?
12 Ṣé àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè tí a ti parun láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá mi gbà wọ́n là: òrìṣà Gosani, Harani Reṣefu àti gbogbo ènìyàn Edeni tí wọ́n wà ní Teli-Assari?
I-au scăpat dumnezeii națiunilor pe cei pe care i-au nimicit părinții mei, precum: Gozanul și Haranul și Rețeful și pe copiii Edenului care erau în Telasar?
13 Níbo ni ọba Hamati wa, ọba Arpadi, ọba ìlú Sefarfaimi, ti Hena, tàbí ti Iffa gbé wà?”
Unde este împăratul Hamatului, și împăratul Arpadului, și împăratul cetății Sefarvaimului, Henei și Ivei?
14 Hesekiah gba lẹ́tà láti ọ̀dọ̀ ìránṣẹ́ ó sì kà á. Nígbà náà ó sì lọ sí òkè ilé tí a kọ́ fún Olúwa ó sì tẹ́ ẹ síwájú Olúwa.
Și Ezechia a primit scrisoarea din mâna mesagerilor și a citit-o; și Ezechia s-a urcat în casa DOMNULUI și a întins-o înaintea DOMNULUI.
15 Hesekiah gbàdúrà sí Olúwa: “Olúwa Ọlọ́run Israẹli, tí ń gbé ní àárín àwọn kérúbù, ìwọ nìkan ni Ọlọ́run lórí gbogbo ìjọba tí ó wà láyé, ìwọ ti dá ọ̀run àti ayé.
Și Ezechia s-a rugat înaintea DOMNULUI și a spus: DOAMNE Dumnezeul lui Israel, tu care locuiești între heruvimi, tu, numai tu, ești Dumnezeul tuturor împărățiilor pământului; tu ai făcut cerul și pământul.
16 Dẹtí sílẹ̀, Olúwa kí o sì gbọ́; la ojú rẹ, Olúwa, kí o sì rí i, gbọ́ ọ̀rọ̀ Sennakeribu tí ó rán láti fi bú Ọlọ́run alààyè.
Doamne, pleacă-ți urechea și ascultă; deschide, Doamne, ochii tăi și vezi; și ascultă cuvintele lui Sanherib cu care l-a trimis să ocărască pe Dumnezeul cel viu.
17 “Òtítọ́ ni, Olúwa, wí pé ọba Asiria ti pa orílẹ̀-èdè wọ̀nyí run àti ilẹ̀ wọn.
În adevăr, DOAMNE, împărații Asiriei au nimicit națiunile și țările lor,
18 Wọ́n ti ju òrìṣà wọn sínú iná wọn sì ti bà wọ́n jẹ́, nítorí pé wọn kì í ṣe ọlọ́run. Ṣùgbọ́n, wọ́n jẹ́ igi àti òkúta tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú ọwọ́ ènìyàn.
Și au aruncat pe dumnezeii lor în foc, pentru că ei nu erau dumnezei, ci lucrarea mâinilor oamenilor, lemn și piatră: de aceea i-au nimicit.
19 Nísinsin yìí Olúwa Ọlọ́run wa, gbà wá kúrò lọ́wọ́ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo àwọn ìjọba lórí ilẹ̀ ayé le mọ̀ pé ìwọ nìkan ṣoṣo ni, Olúwa Ọlọ́run wa.”
Și acum, DOAMNE Dumnezeul nostru, te implor, salvează-ne din mâna lui, ca toate împărățiile pământului să știe că tu, numai tu, ești DOMNUL Dumnezeu.
20 Nígbà náà Isaiah ọmọ Amosi rán oníṣẹ́ sí Hesekiah pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ: Mo ti gbọ́ àdúrà rẹ nípa ti Sennakeribu ọba Asiria.
Atunci Isaia, fiul lui Amoț, a trimis la Ezechia, spunând: Astfel spune DOMNUL Dumnezeul lui Israel: Am auzit ce mi te-ai rugat referitor la Sanherib, împăratul Asiriei.
21 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀, “‘Wúńdíá ọmọbìnrin Sioni kẹ́gàn rẹ ó sì fi ọ́ ṣe ẹlẹ́yà. Ọmọbìnrin Jerusalẹmu mi orí sí ọ gẹ́gẹ́ bí o ti sálọ.
Acesta este cuvântul pe care DOMNUL l-a spus referitor la el: Fecioara, fiica Sionului, te-a disprețuit și a râs de tine în batjocură; fiica Ierusalimului și-a scuturat capul spre tine.
22 Ta ni ìwọ ti bú tí o sì kẹ́gàn rẹ̀? Lórí ta ni ìwọ ti gbé ohùn rẹ sókè tí ó sì gbé ojú sókè sí ọ ní ìgbéraga? Lórí ẹni mímọ́ ti Israẹli!
Pe cine ai ocărât și ai blasfemiat tu? Și împotriva cui ți-ai înălțat tu vocea și ți-ai ridicat ochii în înalt? Împotriva Celui Sfânt al lui Israel.
23 Nípa àwọn ìránṣẹ́ rẹ ìwọ ti sọ̀rọ̀ búburú sí Olúwa. Tì wọ sì wí pé, “Pẹ̀lú ọ̀pọ̀ kẹ̀kẹ́ mi ni èmi sì fi dé orí àwọn òkè ńlá, sí ibi gíga jùlọ Lebanoni. Èmi a sì ké igi kedari gíga rẹ̀ lulẹ̀, àti ààyò igi firi rẹ̀. Èmi a sì lọ sí orí òkè ìbùwọ̀ rẹ̀ sínú ibi tí ó dára jù nínú igbó rẹ̀.
Prin mesagerii tăi tu ai ocărât pe DOMNUL și ai spus: Prin mulțimea carelor mele m-am urcat pe înălțimea munților, pe coastele Libanului, și voi tăia cedrii înalți ai acestuia și brazii săi cei aleși; și voi intra până la locuințele granițelor lui și în pădurea Carmelului său.
24 Mo ti gbẹ́ kànga ní ilẹ̀ àjèjì, mo sì mu omi níbẹ̀. Pẹ̀lú àtẹ́lẹsẹ̀ mi, èmi ti gbẹ́ gbogbo omi odò tí ó wà ní Ejibiti.”
Am săpat și am băut ape străine și cu talpa picioarelor mele am secat toate râurile locurilor asediate.
25 “‘Ṣé ìwọ kò tí ì gbọ́? Ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn mo yàn án. Ní ọjọ́ ogbó ni mo ṣètò rẹ̀; nísinsin yìí mo ti mú wá sí ìkọjá pé ìwọ ti yí ìlú olódi padà dí òkìtì àlàpà òkúta.
Nu ai auzit tu, că de demult am făcut aceasta; și că din timpuri vechi am întocmit-o? Acum eu am împlinit-o, ca tu să prefaci cetăți întărite în mormane de ruine.
26 Àwọn ènìyàn wọn ń gbẹ nípa, wọ́n ti dà á láàmú wọ́n sì ti ṣọ́ di ìtìjú. Wọ́n dàbí koríko igbó lórí pápá, gẹ́gẹ́ bí ọkà tí ó rẹ̀ dànù kí ó tó dàgbàsókè, gẹ́gẹ́ bí fífún ọkà tí ó hù jáde.
De aceea locuitorii lor au avut mică putere, au fost descurajați și încurcați, au fost ca iarba câmpului și ca planta verde, ca iarba de pe acoperișurile caselor și ca grâne prăjite înainte să fi crescut.
27 “‘Ṣùgbọ́n èmi mọ ibi tí ìwọ dúró àti ìgbà tí ìwọ bá dé tàbí lọ àti bí ìwọ ṣe ìkáàánú rẹ: sí mi.
Dar eu cunosc locuința ta și ieșirea ta și intrarea ta și furia ta împotriva mea.
28 Ṣùgbọ́n ìkáàánú rẹ sí mi àti ìrora rẹ dé etí mi, Èmi yóò gbé ìwọ̀ mi sí imú rẹ àti ìjánu mi sí ẹnu rẹ, èmi yóò mú ọ padà nípa wíwá rẹ.’
Deoarece furia ta împotriva mea și fala ta s-au ridicat la urechile mele, de aceea voi pune veriga mea în nasul tău și frâul meu în buzele tale și te voi întoarce pe calea pe care ai venit.
29 “Èyí yóò jẹ́ àmì fún ọ, ìwọ Hesekiah: “Ọdún yìí ìwọ yóò jẹ ohun tí ó bá hù fún rara rẹ̀, àti ní ọdún kejì ohun tí ó bá hù jáde láti inú ìyẹn. Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, gbìn kí o sì kórè, gbin ọgbà àjàrà kí o sì jẹ èso rẹ̀.
Și acesta îți va fi semn: Veți mânca în acest an ceea ce crește de la sine; și în al doilea an ceea ce răsare din acestea, și în al treilea an să semănați și să secerați și să sădiți vii și să mâncați din rodul lor.
30 Lẹ́ẹ̀kan sí i ìyókù ti ilé Juda yóò sì tún hu gbòǹgbò lábẹ́, yóò sì so èso lókè.
Și rămășița care a scăpat din casa lui Iuda va prinde din nou rădăcină în jos și va avea rod în sus.
31 Láti inú Jerusalẹmu ní àwọn ìyókù yóò ti wá àti láti orí òkè Sioni ni ọ̀pọ̀ àwọn tí ó sá àsálà. Ìtara Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò ṣe èyí.
Fiindcă din Ierusalim va ieși o rămășiță și din muntele Sionului cei care vor scăpa; zelul Domnului oștirilor va face aceasta.
32 “Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa sọ nípa ti ọba Asiria: “Kò ní wọ ìlú yìí tàbí ta ọfà síbí. Kò ní wá níwájú rẹ pẹ̀lú àpáta tàbí kó ìdọ̀tí àgbò sí ọ̀kánkán rẹ.
De aceea astfel spune DOMNUL referitor la împăratul Asiriei: El nu va intra în această cetate, nici nu va trage vreo săgeată acolo, nici nu va veni înaintea ei cu scutul, nici nu va ridica întăritură împotriva ei.
33 Nípa ọ̀nà tí ó gbà wá ni yóò padà; kì yóò wọ ìlú ńlá yìí, ni Olúwa wí.
Pe calea pe care a venit, pe aceeași se va întoarce și nu va intra în această cetate, spune DOMNUL.
34 Èmi yóò dá ààbò bo ìlú ńlá yìí, èmi yóò sì pa á mọ́ fún èmi tìkára mi àti fún Dafidi ìránṣẹ́ mi.”
Fiindcă eu voi apăra această cetate pentru a o salva de dragul meu și de dragul servitorului meu, David.
35 Ní alẹ́ ọjọ́ náà, angẹli Olúwa jáde lọ ó sì pa ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án lé ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn ní ibùdó àwọn ará Asiria. Nígbà tí wọ́n sì dìde dúró ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì níbẹ̀ ni gbogbo òkú wà!
Și s-a întâmplat, în acea noapte, că îngerul Domnului a ieșit și a lovit în tabăra asirienilor o sută optzeci și cinci de mii; și când s-au sculat devreme dimineața, iată, ei toți erau trupuri moarte.
36 Bẹ́ẹ̀ ni Sennakeribu ọba Asiria wọ àgọ́ ó sì padà, ó sì padà sí Ninefe ó sì dúró níbẹ̀.
Astfel Sanherib, împăratul Asiriei, a plecat și a mers și s-a întors și a locuit la Ninive.
37 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí ó sùn nínú ilé òrìṣà Nisroki, ọmọkùnrin rẹ̀ Adrameleki àti Ṣareseri gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà, wọ́n sì sálọ sí ilẹ̀ Ararati Esarhadoni ọmọkùnrin rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Și s-a întâmplat, pe când el se închina în casa lui Nisroc, dumnezeul său, că Adramelec și Șarețer, fiii săi, l-au lovit cu sabia; și au scăpat în țara Armenia. Și Esar-Hadon, fiul său, a domnit în locul său.

< 2 Kings 19 >