< 2 Kings 19 >

1 Nígbà tí ọba Hesekiah gbọ́ èyí, ó fa aṣọ rẹ̀ ya ó sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀ ó sì lọ sí àgọ́ Olúwa
Ce qu’ayant entendu le roi Ezéchias, il déchira ses vêtements, se couvrit d’un sac, et entra dans la maison du Seigneur.
2 Ó sì rán Eliakimu olùtọ́jú ààfin, Ṣebna akọ̀wé àti olórí àlùfáà gbogbo wọn sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, sí ọ̀dọ̀ wòlíì Isaiah ọmọ Amosi.
Et il envoya Eliacim, intendant de sa maison, Sobna, le scribe, et les anciens d’entre les prêtres, couverts de sacs, à Isaïe, le prophète, fils d’Amos,
3 Wọ́n sì sọ fún ún pé, “Èyí ni ohun tí Hesekiah sọ: ọjọ́ òní yí jẹ́ ọjọ́ ìpọ́njú àti ìbáwí àti ẹ̀gàn, gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí ọmọdé wá sí ojú ìbímọ tí kò sì sí agbára láti fi bí wọn.
Lesquels dirent: Voici ce que dit Ezéchias: C’est un jour de tribulation, de reproche et de blasphème, que ce jour: des enfants sont venus jusqu’à l’enfantement, et celle qui est en travail n’a pas de forces.
4 Ó lè jẹ́ wí pé Olúwa Ọlọ́run yóò gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ olùdarí pápá, ẹni tí ọ̀gá rẹ̀, ọba Asiria, ti rán láti fi Ọlọ́run alààyè ṣẹ̀sín, yóò sì bá a wí fún ọ̀rọ̀ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ ti gbọ́. Nítorí náà gbàdúrà fún ìyókù àwọn tí ó wà láààyè.”
Peut-être que le Seigneur ton Dieu entendra toutes les paroles de Rabsacès, qu’a envoyé le roi des Assyriens, son maître, pour insulter le Dieu vivant, et l’attaquer par les paroles que le Seigneur ton Dieu a entendues: fais donc une prière au Seigneur pour les restes qui ont été retrouvés.
5 Nígbà tí ìránṣẹ́ ọba Hesekiah lọ sí ọ̀dọ̀ Isaiah,
Les serviteurs du roi Ezéchias vinrent donc vers Isaïe.
6 Isaiah wí fún wọn pé, “Sọ fún ọ̀gá rẹ, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa sọ pé: Ẹ má ṣe bẹ̀rù ohun tí ẹ̀yin ti gbọ́—àwọn ọ̀rọ̀ ìhàlẹ̀ pẹ̀lú èyí ti ọba Asiria ti sọ̀rọ̀-òdì sí mi.
Et Isaïe leur répondit: Vous direz à votre maître: Voici ce que dit le Seigneur: Ne crains point à cause des paroles que tu as entendues, par lesquelles m’ont blasphémé les serviteurs du roi des Assyriens.
7 Gbọ́! Èmi yóò rán ẹ̀mí kan sínú rẹ̀ nígbà tí ó bá sì gbọ́ ariwo, yóò sì padà sí ìlú rẹ̀, níbẹ̀ ni èmi yóò sì gbé gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà.’”
Voilà que moi je lui enverrai un esprit, et il apprendra une nouvelle, et il retournera dans sa terre, et je l’abattrai par le glaive dans sa terre.
8 Nígbà tí olùdarí pápá gbọ́ wí pé ọba Asiria ti kúrò ní Lakiṣi ó sì padà ó sì rí ọba níbi ti ó gbé ń bá Libina jà.
Rabsacès s’en retourna donc, et il trouva le roi des Assyriens assiégeant Lobna; car il avait su qu’il s’était retiré de devant Lachis.
9 Nísinsin yìí, Sennakeribu sì gbọ́ ìròyìn wí pé Tirakah, ọba Etiopia ti Ejibiti wá ó sì ń yan jáde lọ láti lọ bá a jagun. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì tún rán oníṣẹ́ sí Hesekiah pẹ̀lú ọ̀rọ̀ yìí pé,
Et lorsque Sennachérib eut entendu, au sujet de Tharaca, roi d’Ethiopie, des gens disant: Voilà qu’il est sorti pour combattre contre vous, et qu’il allait marcher contre ce roi, il envoya des messagers à Ezéchias, en disant:
10 “Sọ fún Hesekiah ọba Juda pé, má ṣe jẹ́ kí òrìṣà tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé kí ó tàn ó jẹ nígbà tí ó wí pé, ‘Jerusalẹmu a kò ní fi lé ọwọ́ ọba Asiria.’
Vous direz ceci à Ezéchias, roi de Juda: Que votre Dieu, en qui vous avez confiance, ne vous séduise pas, et ne dites point: Jérusalem ne sera point livrée aux mains du roi des Assyriens.
11 Lóòótọ́ ìwọ ti gbọ́ gbogbo ohun tí ọba Asiria tí ó ṣe sí gbogbo àwọn ìlú, ó pa wọ́n run pátápátá. Ìwọ yóò sì gbàlà?
Car vous-même, vous avez appris ce que les rois des Assyriens ont fait à tous les pays, comment ils les ont ravagés: est-ce donc que seul vous pourrez échapper?
12 Ṣé àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè tí a ti parun láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá mi gbà wọ́n là: òrìṣà Gosani, Harani Reṣefu àti gbogbo ènìyàn Edeni tí wọ́n wà ní Teli-Assari?
Est-ce que les dieux des nations ont délivré tous ceux qu’ont ravagés mes pères, c’est-à-dire Gozan, Haran, Réseph, et les enfants d’Eden, qui étaient en Thélassar?
13 Níbo ni ọba Hamati wa, ọba Arpadi, ọba ìlú Sefarfaimi, ti Hena, tàbí ti Iffa gbé wà?”
Où est le roi d’Emath, le roi d’Arphad, le roi de la ville de Sépharvaïm, d’Ana et d’Ava?
14 Hesekiah gba lẹ́tà láti ọ̀dọ̀ ìránṣẹ́ ó sì kà á. Nígbà náà ó sì lọ sí òkè ilé tí a kọ́ fún Olúwa ó sì tẹ́ ẹ síwájú Olúwa.
C’est pourquoi, lorsqu’Ezéchias eut reçu la lettre de Sennachérib de la main des messagers, et qu’il l’eut lue, il monta dans le temple, et étendit la lettre devant le Seigneur,
15 Hesekiah gbàdúrà sí Olúwa: “Olúwa Ọlọ́run Israẹli, tí ń gbé ní àárín àwọn kérúbù, ìwọ nìkan ni Ọlọ́run lórí gbogbo ìjọba tí ó wà láyé, ìwọ ti dá ọ̀run àti ayé.
Et il pria en sa présence, disant: Seigneur Dieu d’Israël, qui êtes assis sur les chérubins, c’est vous qui êtes le seul Dieu de tous les rois de la terre; c’est vous qui avez fait le ciel et la terre.
16 Dẹtí sílẹ̀, Olúwa kí o sì gbọ́; la ojú rẹ, Olúwa, kí o sì rí i, gbọ́ ọ̀rọ̀ Sennakeribu tí ó rán láti fi bú Ọlọ́run alààyè.
Inclinez votre oreille et écoutez; ouvrez vos yeux. Seigneur, et voyez: écoutez toutes les paroles de Sennachérib, qui a envoyé pour incriminer devant nous le Dieu vivant.
17 “Òtítọ́ ni, Olúwa, wí pé ọba Asiria ti pa orílẹ̀-èdè wọ̀nyí run àti ilẹ̀ wọn.
Il est vrai, Seigneur, les rois des Assyriens ont détruit les nations et toutes leurs terres,
18 Wọ́n ti ju òrìṣà wọn sínú iná wọn sì ti bà wọ́n jẹ́, nítorí pé wọn kì í ṣe ọlọ́run. Ṣùgbọ́n, wọ́n jẹ́ igi àti òkúta tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú ọwọ́ ènìyàn.
Et ils ont jeté leurs dieux dans le feu; car ce n’étaient point des dieux, mais des ouvrages de mains d’hommes, de bois et de pierre, et ils les ont détruits.
19 Nísinsin yìí Olúwa Ọlọ́run wa, gbà wá kúrò lọ́wọ́ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo àwọn ìjọba lórí ilẹ̀ ayé le mọ̀ pé ìwọ nìkan ṣoṣo ni, Olúwa Ọlọ́run wa.”
Maintenant donc, Seigneur notre Dieu, sauvez-nous de la main de ce roi, afin qu’ils sachent, tous les royaumes de la terre, que c’est vous qui êtes le seul Seigneur Dieu.
20 Nígbà náà Isaiah ọmọ Amosi rán oníṣẹ́ sí Hesekiah pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ: Mo ti gbọ́ àdúrà rẹ nípa ti Sennakeribu ọba Asiria.
Or Isaïe, fils d’Amos, envoya vers Ezéchias, disant: Voici ce que dit le Seigneur Dieu d’Israël: La prière que tu m’as faite touchant Sennachérib, roi des Assyriens, je l’ai entendue.
21 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀, “‘Wúńdíá ọmọbìnrin Sioni kẹ́gàn rẹ ó sì fi ọ́ ṣe ẹlẹ́yà. Ọmọbìnrin Jerusalẹmu mi orí sí ọ gẹ́gẹ́ bí o ti sálọ.
Voici la parole que le Seigneur a dite de lui: Elle t’a méprisé et elle t’a raillé, la vierge, fille de Sion, derrière toi elle a secoué la tête, la fille de Jérusalem.
22 Ta ni ìwọ ti bú tí o sì kẹ́gàn rẹ̀? Lórí ta ni ìwọ ti gbé ohùn rẹ sókè tí ó sì gbé ojú sókè sí ọ ní ìgbéraga? Lórí ẹni mímọ́ ti Israẹli!
Qui as-tu insulté et qui as-tu blasphémé? contre qui as-tu élevé la voix, et porté en haut les yeux? contre le saint d’Israël.
23 Nípa àwọn ìránṣẹ́ rẹ ìwọ ti sọ̀rọ̀ búburú sí Olúwa. Tì wọ sì wí pé, “Pẹ̀lú ọ̀pọ̀ kẹ̀kẹ́ mi ni èmi sì fi dé orí àwọn òkè ńlá, sí ibi gíga jùlọ Lebanoni. Èmi a sì ké igi kedari gíga rẹ̀ lulẹ̀, àti ààyò igi firi rẹ̀. Èmi a sì lọ sí orí òkè ìbùwọ̀ rẹ̀ sínú ibi tí ó dára jù nínú igbó rẹ̀.
Par l’entremise de tes serviteurs tu as insulté le Seigneur, et tu as dit: Avec la multitude de mes quadriges je suis monté sur le haut des montagnes, au sommet du Liban: j’ai coupé par le pied ses hauts cèdres et ses sapins les plus beaux. Je suis même entré jusqu’à l’extrémité de ses limites, et la forêt de son Carmel,
24 Mo ti gbẹ́ kànga ní ilẹ̀ àjèjì, mo sì mu omi níbẹ̀. Pẹ̀lú àtẹ́lẹsẹ̀ mi, èmi ti gbẹ́ gbogbo omi odò tí ó wà ní Ejibiti.”
C’est moi qui l’ai coupée par le pied. Et j’ai bu des eaux étrangères, et j’ai séché par les traces de mes pieds toutes les eaux fermées.
25 “‘Ṣé ìwọ kò tí ì gbọ́? Ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn mo yàn án. Ní ọjọ́ ogbó ni mo ṣètò rẹ̀; nísinsin yìí mo ti mú wá sí ìkọjá pé ìwọ ti yí ìlú olódi padà dí òkìtì àlàpà òkúta.
N’as-tu donc point ouï dire ce que dès le commencement j’ai fait? Dès les jours anciens je l’ai préparé, et c’est maintenant que je l’ai exécuté; et des villes de combattants fortifiées seront comme des collines ruinées.
26 Àwọn ènìyàn wọn ń gbẹ nípa, wọ́n ti dà á láàmú wọ́n sì ti ṣọ́ di ìtìjú. Wọ́n dàbí koríko igbó lórí pápá, gẹ́gẹ́ bí ọkà tí ó rẹ̀ dànù kí ó tó dàgbàsókè, gẹ́gẹ́ bí fífún ọkà tí ó hù jáde.
Et ceux qui y sont dedans, faibles de main, ont tremblé et ont été confondus: ils sont devenus comme le foin d’un champ, comme l’herbe verte des toits et qui sèche avant de venir à maturité.
27 “‘Ṣùgbọ́n èmi mọ ibi tí ìwọ dúró àti ìgbà tí ìwọ bá dé tàbí lọ àti bí ìwọ ṣe ìkáàánú rẹ: sí mi.
Ta demeure, ton entrée, ta sortie, et ton chemin par où tu es venu, je les ai sus d’avance, et même ta fureur contre moi.
28 Ṣùgbọ́n ìkáàánú rẹ sí mi àti ìrora rẹ dé etí mi, Èmi yóò gbé ìwọ̀ mi sí imú rẹ àti ìjánu mi sí ẹnu rẹ, èmi yóò mú ọ padà nípa wíwá rẹ.’
Tu as été furieux contre moi, et ton orgueil est monté à mes oreilles: c’est pourquoi je mettrai un cercle à tes narines et un mors à tes lèvres, et je te ramènerai par la voie par laquelle tu es venu.
29 “Èyí yóò jẹ́ àmì fún ọ, ìwọ Hesekiah: “Ọdún yìí ìwọ yóò jẹ ohun tí ó bá hù fún rara rẹ̀, àti ní ọdún kejì ohun tí ó bá hù jáde láti inú ìyẹn. Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, gbìn kí o sì kórè, gbin ọgbà àjàrà kí o sì jẹ èso rẹ̀.
Mais pour toi, Ezéchias, voici un signe: Mange cette année ce que tu trouveras; en la seconde année, ce qui naîtra de soi-même; mais, en la troisième année, semez et recueillez, plantez des vignes et mangez-en le fruit.
30 Lẹ́ẹ̀kan sí i ìyókù ti ilé Juda yóò sì tún hu gbòǹgbò lábẹ́, yóò sì so èso lókè.
Et tout ce qui sera de reste de la maison de Juda, jettera des racines en bas et fera des fruits en haut.
31 Láti inú Jerusalẹmu ní àwọn ìyókù yóò ti wá àti láti orí òkè Sioni ni ọ̀pọ̀ àwọn tí ó sá àsálà. Ìtara Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò ṣe èyí.
Car de Jérusalem sortiront des restes, et ce qui sera sauvé de la montagne de Sion: le zèle du Seigneur des armées fera cela.
32 “Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa sọ nípa ti ọba Asiria: “Kò ní wọ ìlú yìí tàbí ta ọfà síbí. Kò ní wá níwájú rẹ pẹ̀lú àpáta tàbí kó ìdọ̀tí àgbò sí ọ̀kánkán rẹ.
C’est pourquoi voici ce que dit le Seigneur du roi des Assyriens: Il n’entrera point dans cette ville, il ne lancera point contre elle de flèche; pas un bouclier ne l’occupera, et pas un retranchement ne l’entourera.
33 Nípa ọ̀nà tí ó gbà wá ni yóò padà; kì yóò wọ ìlú ńlá yìí, ni Olúwa wí.
Il retournera par la voie par laquelle il est venu; et il n’entrera point dans cette ville, dit le Seigneur.
34 Èmi yóò dá ààbò bo ìlú ńlá yìí, èmi yóò sì pa á mọ́ fún èmi tìkára mi àti fún Dafidi ìránṣẹ́ mi.”
Je protégerai cette ville, et je la sauverai à cause de moi et à cause de mon serviteur David.
35 Ní alẹ́ ọjọ́ náà, angẹli Olúwa jáde lọ ó sì pa ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án lé ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn ní ibùdó àwọn ará Asiria. Nígbà tí wọ́n sì dìde dúró ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì níbẹ̀ ni gbogbo òkú wà!
Il arriva donc en cette nuit-là qu’il vint un ange du Seigneur, et qu’il tua dans le camp des Assyriens cent quatre-vingt mille hommes. Et lorsqu’au point du jour il se fut levé, il vit tous les corps des morts et, se retirant, il s’en alla.
36 Bẹ́ẹ̀ ni Sennakeribu ọba Asiria wọ àgọ́ ó sì padà, ó sì padà sí Ninefe ó sì dúró níbẹ̀.
Ainsi s’en retourna Sennachérib, roi des Assyriens, et il demeura à Ninive.
37 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí ó sùn nínú ilé òrìṣà Nisroki, ọmọkùnrin rẹ̀ Adrameleki àti Ṣareseri gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà, wọ́n sì sálọ sí ilẹ̀ Ararati Esarhadoni ọmọkùnrin rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Et lorsqu’il adorait dans le temple Nesroch, son dieu, Adramélech et Sarasar, ses fils, le frappèrent du glaive, et s’enfuirent dans la terre des Arméniens, et Asarhaddon, son fils, régna eu sa place.

< 2 Kings 19 >