< 2 Kings 18 >

1 Ní ọdún kẹta Hosea ọmọ Ela ọba Israẹli, Hesekiah ọmọ Ahasi ọba Juda bẹ̀rẹ̀ ìjọba.
Pripetilo se je torej v tretjem letu Hošéa, Elájevega sina, Izraelovega kralja, da je začel kraljevati Ezekíja, Aházov sin, Judov kralj.
2 Ó jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó ti di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Abijah ọmọbìnrin Sekariah.
Petindvajset let je bil star, ko je začel kraljevati in v Jeruzalemu je kraljeval devetindvajset let. Ime njegove matere je bilo Abí, Zaharijeva hči.
3 Ó sì ṣe ohun tí ó dára níwájú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí i baba rẹ̀ Dafidi ti ṣe.
Delal je to, kar je bilo pravilno v Gospodovih očeh, glede na vse, kar je storil njegov oče David.
4 Ó mú ibi gíga náà kúrò, ó sì fọ́ àwọn ère òkúta, ó sì gé àwọn ère Aṣerah lulẹ̀, ó sì fọ́ ejò idẹ tí Mose ti ṣe náà túútúú, títí di ọjọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli ń sun tùràrí sí. (Wọ́n sì pè é ní Nehuṣitani.)
Odstranil je visoke kraje, zlomil podobe, posekal ašere in na koščke zdrobil bronasto kačo, ki jo je naredil Mojzes, kajti v tistih dneh so ji Izraelovi otroci zažigali kadilo in jo imenoval Nehuštán.
5 Hesekiah sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run Israẹli. Kò sì ṣí ẹnìkan tí ó dàbí tirẹ̀ lára gbogbo àwọn ọba Juda, bóyá kí ó tó jẹ tàbí lẹ́yìn rẹ̀.
Zaupal je v Gospoda, Izraelovega Boga, tako da za njim ni bilo nikogar podobnega njemu med vsemi Judovimi kralji niti nikogar, ki bi bil pred njim.
6 Ó súnmọ́ Olúwa, kò sì dẹ́kun láti tì í lẹ́yìn: ó sì pa òfin Olúwa mọ́ tí ó ti fi fún Mose.
Kajti pridružil se je h Gospodu in se ni oddvojil od sledenju njemu, temveč se je držal njegovih zapovedi, ki jih je Gospod zapovedal Mojzesu.
7 Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀; ó sì ń ṣe rere nínú gbogbo ohun tí ó dáwọ́lé. Ó ṣe ọ̀tẹ̀ sí ọba Asiria kò sì sìn ín.
Gospod je bil z njim in uspeval je kamorkoli je odšel in uprl se je zoper asirskega kralja in mu ni služil.
8 Láti ilé ìṣọ́ títí dé ìlú olódi, ó sì pa àwọn ará Filistini run, àti títí dé Gasa àti agbègbè rẹ̀.
Udaril je Filistejce, celó do Gaze in njenih meja, od stražarskega stolpa, do utrjenega mesta.
9 Ní ọdún kẹrin ọba Hesekiah, nígbà tí ó jẹ́ ọdún keje Hosea ọmọ Ela ọba Israẹli. Ṣalamaneseri ọba Asiria yàn lára Samaria ó sì tẹ̀dó tì í.
Pripetilo se je v četrtem letu kralja Ezekíja, kar je bilo sedmo leto Hošéa, Elájevega sina, Izraelovega kralja, da je asirski kralj Salmanasar prišel gor zoper Samarijo in jo oblegal.
10 Lẹ́yìn ọdún mẹ́ta Asiria gbé e. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kó Samaria ní ọdún kẹfà Hesekiah tí ó sì jẹ́ ọdún kẹsànán Hosea ọba Israẹli.
Ob koncu treh let so jo zavzeli, torej v šestem letu Ezekíja, to je v devetem letu Izraelovega kralja Hošéa je bila Samarija zavzeta.
11 Ọba Asiria lé Israẹli kúrò ní Asiria, wọ́n sì ṣe àtìpó wọn ní Hala, ní Gosani létí odò Habori àti ní ìlú àwọn ará Media.
Asirski kralj je Izraela odvedel v Asirijo in jih naselil v Haláhu in Habórju, pri reki Gozán in v mestih Medijcev,
12 Èyí ṣẹlẹ̀ nítorí wọn kò pa àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wọn mọ́. Ṣùgbọ́n wọ́n ti dà májẹ̀mú rẹ̀ gbogbo èyí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti pàṣẹ. Wọn kò fi etí wọn sílẹ̀ sí òfin wọn kò sì gbé wọn jáde.
ker niso ubogali glasu Gospoda, svojega Boga, temveč so prestopili njegovo zavezo in vse, kar je zapovedal Gospodov služabnik Mojzes, pa jih niso hoteli slišati niti jih izpolnjevati.
13 Ní ọdún kẹrìnlá tí Hesekiah jẹ ọba, Sennakeribu ọba Asiria kọlu gbogbo ìlú olódi ti Juda ó sì pa wọ́n run.
Torej v štirinajstem letu kralja Ezekíja je asirski kralj Senaherib prišel gor zoper vsa utrjena Judova mesta in jih zavzel.
14 Bẹ́ẹ̀ ni Hesekiah ọba Juda sì ránṣẹ́ yìí sí ọba Asiria ní Lakiṣi, wí pé, “Mo ti ṣẹ̀, padà lẹ́yìn mi: èmi yóò sì san ohunkóhun tí ìwọ bá béèrè lọ́wọ́ mi.” Ọba Asiria sì bu fún Hesekiah ọba Juda ọ̀ọ́dúnrún tálẹ́ǹtì fàdákà àti ọgbọ̀n tálẹ́ǹtì wúrà.
Judov kralj Ezekíja je poslal k asirskemu kralju v Lahíš, rekoč: »Grešil sem, obrni se od mene. To, kar polagaš name, bom nosil.« Asirski kralj je Judovemu kralju Ezekíju določil tristo talentov srebra in trideset talentov zlata.
15 Hesekiah fún un ní gbogbo fàdákà tí a rí nínú ilé Olúwa àti nínú ìṣúra ilé ọba.
Ezekíja mu je dal vse srebro, ki je bilo najdeno v Gospodovi hiši in v zakladnicah kraljeve hiše.
16 Ní àkókò yìí Hesekiah ọba Juda ké wúrà tí ó wà ní ẹnu ìlẹ̀kùn ilé Olúwa, kúrò àti ti òpó tí Hesekiah ọba Juda ti gbéró ó sì fi fún ọba Asiria.
Ob tistem času je Ezekíja odluščil zlato iz vrat Gospodovega templja in iz stebrov, ki jih je prevlekel Judov kralj Ezekíja in to dal kralju Asirije.
17 Ọba Asiria rán alákòóso gíga jùlọ, ìjòyè pàtàkì àti àwọn adarí pápá pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun tí ó pọ̀, láti Lakiṣi sí ọba Hesekiah ní Jerusalẹmu. Wọ́n wá sí òkè Jerusalẹmu wọ́n sì dúró ní etí ìdarí omi àbàtà òkè, ní ojú ọ̀nà tó lọ sí òpópó pápá alágbàfọ̀.
Kralj Asirije je iz Lahíša poslal Tartana, Rabsarísa in Rabšakéja h kralju Ezekíju z veliko vojsko zoper Jeruzalem. Odšli so gor in prišli k Jeruzalemu. In ko so prišli gor, so prišli in obstali pri cevi gornjega ribnika, ki je na glavni cesti pralčevega polja.
18 Wọ́n sì pe ọba; àti Eliakimu ọmọ Hilkiah ẹni tí í ṣe ilé olùtọ́jú, Ṣebna akọ̀wé, àti Joah ọmọkùnrin Asafu tí ó jẹ́ akọ̀wé ìrántí jáde pẹ̀lú wọn.
Ko so zaklicali h kralju, je ven k njim prišel Hilkijájev sin Eljakím, ki je bil nad družino, pisar Šebná in Asáfov sin Joáh, letopisec.
19 Olùdarí pápá wí fún wọn pé, “Sọ fún Hesekiah pé, “‘Èyí ni ohun tí ọba ńlá, ọba Asiria sọ: Kí ni ìgbẹ́kẹ̀lé yìí tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé?
Rabšaké jim je rekel: »Govorite torej Ezekíju: ›Tako govori veliki kralj, kralj Asirije: ›Kakšno zaupanje je to, v katero zaupaš?
20 Ìwọ wí pé ìwọ ni ìmọ̀ àti agbára láti jagun, ṣùgbọ́n ìwọ sọ̀rọ̀ òfìfo lásán. Ǹjẹ́ ta ni ìwọ gbẹ́kẹ̀ rẹ lé, tí ìwọ fi ń ṣe ọ̀tẹ̀ sí mi?
Ti praviš (toda to so samo prazne besede): › Imam nasvet in moč za vojno. Komu odslej zaupaš, da si se uprl zoper mene?
21 Wò ó, nísinsin yìí, ìwọ gbẹ́kẹ̀ rẹ lé Ejibiti, ẹ̀rún ọ̀pá pẹlẹbẹ ìyè fífọ́ yìí, èyí tí yóò wọ inú ọwọ́ ẹni tí ó sì bá fi ara tì í. Bẹ́ẹ̀ ni Farao ọba Ejibiti ṣe rí fún gbogbo àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀ wọn lé e.
Torej glej, ti zaupaš v palico iz poškodovanega trsta, v Egipt, na katerega, če se človek nasloni, se bo ta zadrl v njegovo roko in jo prebodel. Tako je faraon, egiptovski kralj, vsem tem, ki zaupajo vanj.
22 Tí ìwọ bá sì sọ fún mi pé, “Àwa gbẹ́kẹ̀ wa lé Olúwa Ọlọ́run.” Òun ha kọ́ ní ẹnìkan náà tí ibi gíga àti àwọn pẹpẹ tí Hesekiah mú kúrò, tí ó wí fún Juda àti Jerusalẹmu pé, “O gbọdọ̀ sìn níwájú pẹpẹ yìí ní Jerusalẹmu”?
Toda če mi rečete: ›Zaupamo v Gospoda, svojega Boga, ‹ mar ni to on, katerega visoke kraje in katerega oltarje je Ezekíja odstranil ter rekel Judu in Jeruzalemu: ›Pred tem oltarjem boste oboževali v Jeruzalemu.‹
23 “‘Wá nísinsin yìí, ṣe àdéhùn pẹ̀lú ọ̀gá mi, ọba Asiria èmi yóò sì fún ọ ní ẹgbẹ̀rún méjì ẹṣin tí ìwọ bá lè kó àwọn tí yóò gùn ún sí orí rẹ!
Zdaj torej, prosim te, daj jamstva mojemu gospodu, asirskemu kralju, jaz pa ti bom izročil dva tisoč konjev, če boš na svoji strani zmožen nanje postaviti jezdece.
24 Báwo ni ìwọ yóò ha ti ṣe le yí ojú balógun kan tí ó kéré jùlọ padà nínú àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi, tí ìwọ sì gbẹ́kẹ̀ rẹ lé Ejibiti fún àwọn kẹ̀kẹ́ àti ẹlẹ́ṣin?
Kako potem hočeš odvrniti obraz enega poveljnika izmed najmanjših služabnikov mojega gospodarja in svoje zaupanje položiti v Egipt zaradi bojnih vozov in konjenikov?
25 Síwájú sí i, èmi ti wá láti mú àti láti parun ibí yìí láìsí ọ̀rọ̀ láti ọ̀dọ̀ Olúwa? Olúwa fún rara rẹ̀ sọ fún mi pé kí n yára láti yan lórí ìlú yìí, kí n sì pa á run.’”
Sem mar brez Gospoda prišel gor zoper ta kraj, da ga uničim? Gospod mi je rekel: ›Pojdi gor zoper to deželo in jo uniči.‹«
26 Nígbà náà Eliakimu ọmọ Hilkiah, àti Ṣebna àti Joah sọ fún olùdarí pápá pé, “Jọ̀wọ́ sọ̀rọ̀ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ ní èdè Aramaiki, nítorí ti ó tí yé wa, má ṣe sọ̀rọ̀ fún wa pẹ̀lú èdè Heberu ní etí ìgbọ́ àwọn ènìyàn tí ń bẹ lórí odi.”
Potem so Hilkijájev sin Eljakím, Šebná in Joáh rekli Rabšakéju: »Govori, prosimo te, tvojim služabnikom v sirskem jeziku, kajti mi ga razumemo in ne govori z nami v judovskem jeziku v ušesa ljudstva, ki so na obzidju.«
27 Ṣùgbọ́n aláṣẹ dáhùn pé, “Ṣé fún ọ̀gá rẹ àti ìwọ nìkan ní ọ̀gá mi rán mi sí láti sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí kì í sì í ṣe fún àwọn ọkùnrin tí ó jókòó lórí odi ni gẹ́gẹ́ bí ìwọ, ni yóò ní láti jẹ ìgbẹ́ ará wọn kí wọ́n sì mu ìtọ̀ ará wọn?”
Toda Rabšaké jim je rekel: »Ali me ni moj gospodar poslal k tvojemu gospodarju in k tebi, da govorim te besede? Ali me ni poslal k možem, ki sedijo na obzidju, da bodo lahko s teboj jedli svoj iztrebek in pili svoj seč?«
28 Nígbà náà, aláṣẹ dìde, ó sì pè jáde ní èdè Heberu pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ ọba ńlá, ọba Asiria!
Potem je Rabšaké vstal, z močnim glasom zaklical v hebrejskem jeziku in spregovoril, rekoč: »Poslušajte besedo velikega kralja, kralja Asirije,
29 Èyí ni ohun tí ọba sọ, má ṣe jẹ́ kí Hesekiah tàn ọ́ jẹ kò le gbà ọ́ kúrò ní ọwọ́ mi.
tako govori kralj: ›Ne dopustite, da vas Ezekíja zavede, kajti ne bo sposoben, da vas osvobodi iz njegove roke,
30 Ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah mú yín gbẹ́kẹ̀lé Olúwa nípa sísọ pé, ‘Olúwa yóò gbà wá nítòótọ́; ìlú yìí ni wọn kò ní fi lé ọba ìlú Asiria lọ́wọ́.’
niti naj vam Ezekíja ne da zaupati v Gospoda, rekoč: › Gospod nas bo zagotovo osvobodil in to mesto ne bo izročeno v roko asirskega kralja.‹
31 “Má ṣe tẹ́tí sí Hesekiah. Èyí ni ohun tí ọba Asiria wí pé, ‘Fi ẹ̀bùn wá ojúrere mi, kí o sì jáde tọ̀ mí wá.’ Nígbà náà olúkúlùkù yín yóò jẹun láti inú àjàrà rẹ̀ àti igi ọ̀pọ̀tọ́, yóò sì mu omi láti inú àmù rẹ̀,
Ne prisluhnite Ezekíju, kajti tako govori kralj Asirije: ›Sklenite dogovor z menoj z darilom in pridite ven k meni in potem jejte vsak mož od svoje lastne trte in vsak mož od svojega figovega drevesa in vsak naj pije vodo iz svojega vodnega zbiralnika,
32 títí tí èmi yóò fi wá mú ọ lọ sí ilé gẹ́gẹ́ bí i tìrẹ, ilẹ̀ ọkà àti ọtí wáìnì, ilẹ̀ oúnjẹ àti ọgbà àjàrà, ilẹ̀ òróró olifi àti ti ilẹ̀ oyin; yàn ìyè má sì ṣe yàn ikú! “Kí ẹ má ṣe gbọ́ tí Hesekiah, nítorí ó ń tàn yín tí ó ba tí wí pé, ‘Olúwa yóò gbà wá?’
dokler ne pridem in vas vzamem proč v deželo, podobno vaši lastni deželi, deželo žita in vina, deželo kruha in vinogradov, deželo olivnega olja in medu, da boste lahko živeli in ne umrli in ne prisluhnite Ezekíju, ko vas pregovarja, rekoč: › Gospod nas bo osvobodil.‹
33 Ṣé òrìṣà àwọn orílẹ̀-èdè kankan ti gba ilé rẹ lọ́wọ́ àwọn ọba Asiria?
Mar so katerikoli izmed bogov narodov mogli svojo deželo rešiti iz roke asirskega kralja?
34 Níbo ni àwọn òrìṣà Hamati àti Arpadi gbé wà? Níbo ni àwọn òrìṣà Sefarfaimi, Hena àti Iffa gbé wà? Wọ́n ha gba Samaria kúrò lọ́wọ́ mi bí?
Kje so bogovi Hamáta in Arpáda? Kje so bogovi Sefarvájima, Hene in Avája? Mar so Samarijo osvobodili iz moje roke?
35 Ta ni nínú gbogbo àwọn òrìṣà ilẹ̀ yìí tí ó ti gbìyànjú láti gba ilẹ̀ rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi? Báwo ni Olúwa yóò ṣe gba Jerusalẹmu kúrò lọ́wọ́ mi?”
Kdo so tisti izmed vseh bogov dežel, ki so svojo deželo rešili iz moje roke, da bi Gospod rešil Jeruzalem iz moje roke?‹«
36 Ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ènìyàn náà dákẹ́ síbẹ̀ wọn kò sì sọ ohunkóhun, láti fi fèsì, nítorí ọba ti paláṣẹ, “Ẹ má ṣe dá a lóhùn.”
Toda ljudstvo je molčalo in mu ni odgovorilo [niti] besede, kajti kraljeva zapoved je bila, rekoč: »Ne odgovarjajte mu.«
37 Nígbà náà Eliakimu ọmọ Hilkiah olùtọ́jú ààfin, Ṣebna akọ̀wé àti Joah ọmọ Asafu akọ̀wé ránṣẹ́ lọ sí ọ̀dọ̀ Hesekiah, pẹ̀lú aṣọ wọn yíya, ó sì wí fún un ohun tí olùdarí pápá ti sọ.
Potem so prišli Hilkijájev sin Eljakím, ki je bil nad družino, pisar Šebná in Asáfov sin Joáh, letopisec, k Ezekíju s svojimi pretrganimi oblačili in mu povedali Rabšakéjeve besede.

< 2 Kings 18 >