< 2 Kings 18 >

1 Ní ọdún kẹta Hosea ọmọ Ela ọba Israẹli, Hesekiah ọmọ Ahasi ọba Juda bẹ̀rẹ̀ ìjọba.
Roku trzeciego Ozeasza, syna Eli, króla Izraelskiego, królował Ezechyjasz, syn Achaza, króla Judzkiego.
2 Ó jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó ti di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Abijah ọmọbìnrin Sekariah.
Dwadzieścia i pięć lat mu było, gdy począł królować, a dwadzieścia i dziewięć lat królował w Jeruzalemie. Imię matki jego było Abi, córka Zacharyjaszowa.
3 Ó sì ṣe ohun tí ó dára níwájú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí i baba rẹ̀ Dafidi ti ṣe.
I czynił co było dobrego przed oczyma Pańskiemi, według wszystkiego, jako czynił Dawid, ojciec jego.
4 Ó mú ibi gíga náà kúrò, ó sì fọ́ àwọn ère òkúta, ó sì gé àwọn ère Aṣerah lulẹ̀, ó sì fọ́ ejò idẹ tí Mose ti ṣe náà túútúú, títí di ọjọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli ń sun tùràrí sí. (Wọ́n sì pè é ní Nehuṣitani.)
On zniósł wyżyny, i skruszył bałwany, i powycinał gaje, a pokruszył węża miedzianego, którego był uczynił Mojżesz; bo aż do onych dni Izraelczycy kadzili mu, i nazwał go Nehustan.
5 Hesekiah sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run Israẹli. Kò sì ṣí ẹnìkan tí ó dàbí tirẹ̀ lára gbogbo àwọn ọba Juda, bóyá kí ó tó jẹ tàbí lẹ́yìn rẹ̀.
W Panu Bogu Izraelskim ufał; a po nim nie był żaden podobny jemu między wszystkimi królami Judzkimi, i którzy byli przed nim.
6 Ó súnmọ́ Olúwa, kò sì dẹ́kun láti tì í lẹ́yìn: ó sì pa òfin Olúwa mọ́ tí ó ti fi fún Mose.
Bo się trzymał Pana, nie odstępując od niego, a strzegąc przykazania jego, które był przykazał Pan Mojżeszowi.
7 Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀; ó sì ń ṣe rere nínú gbogbo ohun tí ó dáwọ́lé. Ó ṣe ọ̀tẹ̀ sí ọba Asiria kò sì sìn ín.
A Pan był z nim; i we wszystkiem, do czego się obrócił, szczęściło mu się. Wybił się też z mocy królowi Assyryjskiemu, i nie służył mu.
8 Láti ilé ìṣọ́ títí dé ìlú olódi, ó sì pa àwọn ará Filistini run, àti títí dé Gasa àti agbègbè rẹ̀.
Tenże poraził Filistyny aż do Gazy i granic jego, od wieży strażników aż do miasta obronnego.
9 Ní ọdún kẹrin ọba Hesekiah, nígbà tí ó jẹ́ ọdún keje Hosea ọmọ Ela ọba Israẹli. Ṣalamaneseri ọba Asiria yàn lára Samaria ó sì tẹ̀dó tì í.
Roku czwartego króla Ezechyjasza, (który był rok siódmy Ozeasza, syna Eli, króla Izraelskiego) wyciągnął Salmanaser, król Assyryjski, przeciwko Samaryi, i obległ ją.
10 Lẹ́yìn ọdún mẹ́ta Asiria gbé e. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kó Samaria ní ọdún kẹfà Hesekiah tí ó sì jẹ́ ọdún kẹsànán Hosea ọba Israẹli.
A wziął ją przy dokończeniu trzeciego roku; roku szóstego Ezechyjasza, (który był rok dziewiąty Ozeasza, króla Izraelskiego) wzięta jest Samaryja.
11 Ọba Asiria lé Israẹli kúrò ní Asiria, wọ́n sì ṣe àtìpó wọn ní Hala, ní Gosani létí odò Habori àti ní ìlú àwọn ará Media.
Tedy przeniósł król Assyryjski Izraela do Assyryi, i osadził nimi Halach i Habor u rzeki Gazan, i miasta Medskie.
12 Èyí ṣẹlẹ̀ nítorí wọn kò pa àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wọn mọ́. Ṣùgbọ́n wọ́n ti dà májẹ̀mú rẹ̀ gbogbo èyí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti pàṣẹ. Wọn kò fi etí wọn sílẹ̀ sí òfin wọn kò sì gbé wọn jáde.
Przeto, iż nie posłuchali głosu Pana Boga swego, ale przestępowali przymierze jego, i tego wszystkiego, co rozkazał Mojżesz, sługa Pański, nie słuchali i nie czynili.
13 Ní ọdún kẹrìnlá tí Hesekiah jẹ ọba, Sennakeribu ọba Asiria kọlu gbogbo ìlú olódi ti Juda ó sì pa wọ́n run.
Potem czternastego roku króla Ezechyjasza ruszył się Sennacheryb, król Assyryjski, przeciw wszystkim miastom Judzkim obronnym, i wziął je.
14 Bẹ́ẹ̀ ni Hesekiah ọba Juda sì ránṣẹ́ yìí sí ọba Asiria ní Lakiṣi, wí pé, “Mo ti ṣẹ̀, padà lẹ́yìn mi: èmi yóò sì san ohunkóhun tí ìwọ bá béèrè lọ́wọ́ mi.” Ọba Asiria sì bu fún Hesekiah ọba Juda ọ̀ọ́dúnrún tálẹ́ǹtì fàdákà àti ọgbọ̀n tálẹ́ǹtì wúrà.
A tak posłał Ezechyjasz, król Judzki, do króla Assyryjskiego, do Lachys, mówiąc: Zgrzeszyłem; odciągnij odemnie, cokolwiek na mię włożysz, poniosę. Tedy włożył król Assyryjski na Ezechyjasza, króla Judzkiego, dań trzy sta talentów srebra, i trzydzieści talentów złota.
15 Hesekiah fún un ní gbogbo fàdákà tí a rí nínú ilé Olúwa àti nínú ìṣúra ilé ọba.
I dał Ezechyjasz wszystko srebro, które się znalazło w domu Pańskim i w skarbach domu królewskiego.
16 Ní àkókò yìí Hesekiah ọba Juda ké wúrà tí ó wà ní ẹnu ìlẹ̀kùn ilé Olúwa, kúrò àti ti òpó tí Hesekiah ọba Juda ti gbéró ó sì fi fún ọba Asiria.
Onegoż czasu obłupił Ezechyjasz drzwi domu Pańskiego, i słupy, które samże Ezechyjasz, król Judzki, był obył, a dał je królowi Assyryjskiemu.
17 Ọba Asiria rán alákòóso gíga jùlọ, ìjòyè pàtàkì àti àwọn adarí pápá pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun tí ó pọ̀, láti Lakiṣi sí ọba Hesekiah ní Jerusalẹmu. Wọ́n wá sí òkè Jerusalẹmu wọ́n sì dúró ní etí ìdarí omi àbàtà òkè, ní ojú ọ̀nà tó lọ sí òpópó pápá alágbàfọ̀.
Wszakże posłał król Assyryjski Tartana, i Rabsarysa, i Rabsacesa z Lachys do króla Ezechyjasza z wielkiem wojskiem do Jeruzalemu. Którzy wyciągnąwszy przyjechali ku Jeruzalemowi, a przyciągnąwszy przyszli i położyli się u rur sadzawki wyższej, która jest podle drogi brukowanej na polu blecharzowem.
18 Wọ́n sì pe ọba; àti Eliakimu ọmọ Hilkiah ẹni tí í ṣe ilé olùtọ́jú, Ṣebna akọ̀wé, àti Joah ọmọkùnrin Asafu tí ó jẹ́ akọ̀wé ìrántí jáde pẹ̀lú wọn.
A gdy wołali na króla, wyszedł do nich Elijakim, syn Helkijaszowy, przełożony nad domem, i Sobna pisarz, i Joach syn Asafowy, kanclerz.
19 Olùdarí pápá wí fún wọn pé, “Sọ fún Hesekiah pé, “‘Èyí ni ohun tí ọba ńlá, ọba Asiria sọ: Kí ni ìgbẹ́kẹ̀lé yìí tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé?
I rzekł do nich Rabsaces: Proszę powiedzcie Ezechyjaszowi: Tak mówi król wielki, król Assyryjski: Co to za ufność, na której się wspierasz?
20 Ìwọ wí pé ìwọ ni ìmọ̀ àti agbára láti jagun, ṣùgbọ́n ìwọ sọ̀rọ̀ òfìfo lásán. Ǹjẹ́ ta ni ìwọ gbẹ́kẹ̀ rẹ lé, tí ìwọ fi ń ṣe ọ̀tẹ̀ sí mi?
Mówiłeś: (aleć to słowa daremne) Rady i mocy mam dosyć do wojny. A teraz w kimże ufasz, żeś mi się sprzeciwił?
21 Wò ó, nísinsin yìí, ìwọ gbẹ́kẹ̀ rẹ lé Ejibiti, ẹ̀rún ọ̀pá pẹlẹbẹ ìyè fífọ́ yìí, èyí tí yóò wọ inú ọwọ́ ẹni tí ó sì bá fi ara tì í. Bẹ́ẹ̀ ni Farao ọba Ejibiti ṣe rí fún gbogbo àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀ wọn lé e.
Oto teraz spolegasz na Egipcie, jako na lasce trzcinnej, i to nałamanej, którą jeźliby się kto podpierał, tedy wnijdzie w rękę jego i przekole ją. Takić jest Farao, król Egipski, wszystkim, co w nim ufają.
22 Tí ìwọ bá sì sọ fún mi pé, “Àwa gbẹ́kẹ̀ wa lé Olúwa Ọlọ́run.” Òun ha kọ́ ní ẹnìkan náà tí ibi gíga àti àwọn pẹpẹ tí Hesekiah mú kúrò, tí ó wí fún Juda àti Jerusalẹmu pé, “O gbọdọ̀ sìn níwájú pẹpẹ yìí ní Jerusalẹmu”?
A jeźli mi rzeczecie: W Panu Bogu naszym ufność mamy: azaż nie ten jest, którego zniósł Ezechyjasz wyżyny i ołtarze? i rozkazał Judzie i Jeruzalemowi, mówiąc: Przed tym ołtarzem kłaniać się będziecie w Jeruzalemie.
23 “‘Wá nísinsin yìí, ṣe àdéhùn pẹ̀lú ọ̀gá mi, ọba Asiria èmi yóò sì fún ọ ní ẹgbẹ̀rún méjì ẹṣin tí ìwọ bá lè kó àwọn tí yóò gùn ún sí orí rẹ!
Przetoż teraz zaręcz się królowi Assyryjskiemu, panu memu, a dam ci dwa tysiące koni; będzieszli mógł mieć jezdnych tak wiele do dnich?
24 Báwo ni ìwọ yóò ha ti ṣe le yí ojú balógun kan tí ó kéré jùlọ padà nínú àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi, tí ìwọ sì gbẹ́kẹ̀ rẹ lé Ejibiti fún àwọn kẹ̀kẹ́ àti ẹlẹ́ṣin?
I jakoż się ty możesz oprzeć hetmanowi jednemu najmniejszemu z sług pana mego? choć pokładasz nadzieję w Egipcie dla wozów i jezdnych.
25 Síwájú sí i, èmi ti wá láti mú àti láti parun ibí yìí láìsí ọ̀rọ̀ láti ọ̀dọ̀ Olúwa? Olúwa fún rara rẹ̀ sọ fún mi pé kí n yára láti yan lórí ìlú yìí, kí n sì pa á run.’”
Nadto, czy bez woli Pańskiej przyciągnąłem przeciw temu miejscu, abym je zburzył? Pan mówi do mnie: Idź do tej ziemi, a spustosz ją.
26 Nígbà náà Eliakimu ọmọ Hilkiah, àti Ṣebna àti Joah sọ fún olùdarí pápá pé, “Jọ̀wọ́ sọ̀rọ̀ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ ní èdè Aramaiki, nítorí ti ó tí yé wa, má ṣe sọ̀rọ̀ fún wa pẹ̀lú èdè Heberu ní etí ìgbọ́ àwọn ènìyàn tí ń bẹ lórí odi.”
Tedy rzekł Elijakim, syn Helkijaszowy, i Sobna, i Joach do Rabsacesa: Proszę mów do sług twoich po syryjsku, boć rozumiemy; a nie mów z nami po żydowsku, gdzie słyszy lud, który jest na murze.
27 Ṣùgbọ́n aláṣẹ dáhùn pé, “Ṣé fún ọ̀gá rẹ àti ìwọ nìkan ní ọ̀gá mi rán mi sí láti sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí kì í sì í ṣe fún àwọn ọkùnrin tí ó jókòó lórí odi ni gẹ́gẹ́ bí ìwọ, ni yóò ní láti jẹ ìgbẹ́ ará wọn kí wọ́n sì mu ìtọ̀ ará wọn?”
Którym odpowiedział Rabsaces: Azaż mię do pana twego, albo do ciebie przysłał Pan mój, abym te słowa mówił? Azaż nie do tych mężów, którzy siedzą na murze, aby jedli łajna swoje, i pili mocz swój z wami.
28 Nígbà náà, aláṣẹ dìde, ó sì pè jáde ní èdè Heberu pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ ọba ńlá, ọba Asiria!
A tak stanąwszy Rabsaces wołał głosem wielkim po żydowsku, a mówiąc rzekł: Słuchajcie słów króla wielkiego, króla Assyryjskiego.
29 Èyí ni ohun tí ọba sọ, má ṣe jẹ́ kí Hesekiah tàn ọ́ jẹ kò le gbà ọ́ kúrò ní ọwọ́ mi.
Tak mówi król: Niech was nie zwodzi Ezechyjasz; bo was nie będzie mógł wyrwać z ręki mojej.
30 Ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah mú yín gbẹ́kẹ̀lé Olúwa nípa sísọ pé, ‘Olúwa yóò gbà wá nítòótọ́; ìlú yìí ni wọn kò ní fi lé ọba ìlú Asiria lọ́wọ́.’
A niech wam nie rozkazuje ufać Ezechyjasz w Panu, mówiąc: Pewnie nas wyrwie Pan, a nie będzie podane to miasto w ręce króla Assyryjskiego.
31 “Má ṣe tẹ́tí sí Hesekiah. Èyí ni ohun tí ọba Asiria wí pé, ‘Fi ẹ̀bùn wá ojúrere mi, kí o sì jáde tọ̀ mí wá.’ Nígbà náà olúkúlùkù yín yóò jẹun láti inú àjàrà rẹ̀ àti igi ọ̀pọ̀tọ́, yóò sì mu omi láti inú àmù rẹ̀,
Nie słuchajcie Ezechyjasza. Albowiem tak mówi król Assyryjski: Uczyńcie ze mną przymierze, a wynijdźcie do mnie, a jedzcie każdy z winnicy swojej i każdy z figi swojej, i pijcie każdy wodę z studnicy swojej,
32 títí tí èmi yóò fi wá mú ọ lọ sí ilé gẹ́gẹ́ bí i tìrẹ, ilẹ̀ ọkà àti ọtí wáìnì, ilẹ̀ oúnjẹ àti ọgbà àjàrà, ilẹ̀ òróró olifi àti ti ilẹ̀ oyin; yàn ìyè má sì ṣe yàn ikú! “Kí ẹ má ṣe gbọ́ tí Hesekiah, nítorí ó ń tàn yín tí ó ba tí wí pé, ‘Olúwa yóò gbà wá?’
Aż przyjdę a pobiorę was do ziemi podobnej ziemi waszej, do ziemi żyznej i obfitującej winem, do ziemi chleba i winnic, do ziemi drzew oliwnych, i oliwy, i miodu; i będziecie żyli, a nie pomrzecie. Nie słuchajcież Ezechyjasza; bo was zwodzi, mó wiąc: Pan was wybawi.
33 Ṣé òrìṣà àwọn orílẹ̀-èdè kankan ti gba ilé rẹ lọ́wọ́ àwọn ọba Asiria?
Izaż mogli bogowie narodów wybawić każdy ziemię swoję, z ręki króla Assyryjskiego?
34 Níbo ni àwọn òrìṣà Hamati àti Arpadi gbé wà? Níbo ni àwọn òrìṣà Sefarfaimi, Hena àti Iffa gbé wà? Wọ́n ha gba Samaria kúrò lọ́wọ́ mi bí?
Gdzież jest bóg Emat i Arfad? gdzież jest bóg Sefarwaim, Ana i Awa? izali wyrwali Samaryję z rąk moich?
35 Ta ni nínú gbogbo àwọn òrìṣà ilẹ̀ yìí tí ó ti gbìyànjú láti gba ilẹ̀ rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi? Báwo ni Olúwa yóò ṣe gba Jerusalẹmu kúrò lọ́wọ́ mi?”
Któryż jest między wszystkimi bogi tych ziem, któryby wyrwał ziemię swoję z ręki mojej? A miałby Pan wyrwać Jeruzalem z ręki mojej?
36 Ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ènìyàn náà dákẹ́ síbẹ̀ wọn kò sì sọ ohunkóhun, láti fi fèsì, nítorí ọba ti paláṣẹ, “Ẹ má ṣe dá a lóhùn.”
Ale milczał lud, i nie odpowiedzieli mu słowa; bo takie było rozkazanie królewskie, mówiąc: Nie odpowiadajcie mu.
37 Nígbà náà Eliakimu ọmọ Hilkiah olùtọ́jú ààfin, Ṣebna akọ̀wé àti Joah ọmọ Asafu akọ̀wé ránṣẹ́ lọ sí ọ̀dọ̀ Hesekiah, pẹ̀lú aṣọ wọn yíya, ó sì wí fún un ohun tí olùdarí pápá ti sọ.
Przyszedł tedy Elijakim, syn Helkijaszowy, przełożony domu, i Sobna pisarz, i Joach, syn Asafowy, kanclerz, do Ezechyjasza, rozdarłszy szaty swe, i oznajmili mu słowa Rabsacesowe.

< 2 Kings 18 >