< 2 Kings 18 >

1 Ní ọdún kẹta Hosea ọmọ Ela ọba Israẹli, Hesekiah ọmọ Ahasi ọba Juda bẹ̀rẹ̀ ìjọba.
És Hóseásnak, az Ela fiának, az Izráel királyának harmadik esztendejében kezdett uralkodni Ezékiás, Akháznak, a Júda királyának fia.
2 Ó jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó ti di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Abijah ọmọbìnrin Sekariah.
Huszonöt esztendős volt, mikor uralkodni kezdett, és huszonkilencz esztendeig uralkodott Jeruzsálemben; anyjának neve Abi, a Zakariás leánya.
3 Ó sì ṣe ohun tí ó dára níwájú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí i baba rẹ̀ Dafidi ti ṣe.
És kedves dolgot cselekedék az Úr szemei előtt, a mint az ő atyja, Dávid cselekedett volt.
4 Ó mú ibi gíga náà kúrò, ó sì fọ́ àwọn ère òkúta, ó sì gé àwọn ère Aṣerah lulẹ̀, ó sì fọ́ ejò idẹ tí Mose ti ṣe náà túútúú, títí di ọjọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli ń sun tùràrí sí. (Wọ́n sì pè é ní Nehuṣitani.)
Ő rontotta le a magaslatokat, törte el az oszlopokat, és vágta ki az Aserát, és törte össze az érczkígyót is, a melyet Mózes csinált; mert mind az ideig az Izráel fiai jóillatot tettek annak, és nevezék azt Nékhustánnak.
5 Hesekiah sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run Israẹli. Kò sì ṣí ẹnìkan tí ó dàbí tirẹ̀ lára gbogbo àwọn ọba Juda, bóyá kí ó tó jẹ tàbí lẹ́yìn rẹ̀.
Egyedül az Úrban, Izráel Istenében bízott, és ő utána nem volt hozzá hasonló Júda minden királyai között sem azok között, a kik ő előtte voltak.
6 Ó súnmọ́ Olúwa, kò sì dẹ́kun láti tì í lẹ́yìn: ó sì pa òfin Olúwa mọ́ tí ó ti fi fún Mose.
Mert az Úrhoz ragaszkodott, és el nem hajlott ő tőle, és megőrizte az ő parancsolatait, a melyeket az Úr Mózesnek parancsolt vala.
7 Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀; ó sì ń ṣe rere nínú gbogbo ohun tí ó dáwọ́lé. Ó ṣe ọ̀tẹ̀ sí ọba Asiria kò sì sìn ín.
És vele volt az Úr mindenütt és a hova csak ment, előmenetele volt. És elszakadt Assiria királyától, és nem szolgált néki.
8 Láti ilé ìṣọ́ títí dé ìlú olódi, ó sì pa àwọn ará Filistini run, àti títí dé Gasa àti agbègbè rẹ̀.
Megverte a Filiszteusokat is egész Gázáig és határukat, az őrtornyoktól a kerített városokig.
9 Ní ọdún kẹrin ọba Hesekiah, nígbà tí ó jẹ́ ọdún keje Hosea ọmọ Ela ọba Israẹli. Ṣalamaneseri ọba Asiria yàn lára Samaria ó sì tẹ̀dó tì í.
Ezékiás királynak negyedik esztendejében – a mely Hóseásnak, az Ela fiának, az Izráel királyának hetedik esztendeje – feljött Salmanassár, Assiria királya Samaria ellen, és megszállotta azt;
10 Lẹ́yìn ọdún mẹ́ta Asiria gbé e. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kó Samaria ní ọdún kẹfà Hesekiah tí ó sì jẹ́ ọdún kẹsànán Hosea ọba Israẹli.
És elfoglalta három esztendő mulva, Ezékiás hatodik esztendejében – ez Hóseásnak, az Izráel királyának kilenczedik esztendeje – ekkor vették be Samariát.
11 Ọba Asiria lé Israẹli kúrò ní Asiria, wọ́n sì ṣe àtìpó wọn ní Hala, ní Gosani létí odò Habori àti ní ìlú àwọn ará Media.
És elhurczolta Assiria királya az Izráelt Assiriába, és letelepíté Halába, Háborba, a Gózán folyó mellé, és a Médeusok városaiba;
12 Èyí ṣẹlẹ̀ nítorí wọn kò pa àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wọn mọ́. Ṣùgbọ́n wọ́n ti dà májẹ̀mú rẹ̀ gbogbo èyí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti pàṣẹ. Wọn kò fi etí wọn sílẹ̀ sí òfin wọn kò sì gbé wọn jáde.
Azért, mert nem hallgattak az Úrnak, az ő Istenöknek szavára, hanem megszegték az ő szövetségét, mindazokat, a melyeket Mózes, az Úr szolgája parancsolt vala; sem nem hallgattak rájok, sem nem cselekedték azokat.
13 Ní ọdún kẹrìnlá tí Hesekiah jẹ ọba, Sennakeribu ọba Asiria kọlu gbogbo ìlú olódi ti Juda ó sì pa wọ́n run.
Ezékiás királynak pedig tizennegyedik esztendejében feljött Sénakhérib, Assiria királya Júdának minden kerített városa ellen, és elfoglalta azokat.
14 Bẹ́ẹ̀ ni Hesekiah ọba Juda sì ránṣẹ́ yìí sí ọba Asiria ní Lakiṣi, wí pé, “Mo ti ṣẹ̀, padà lẹ́yìn mi: èmi yóò sì san ohunkóhun tí ìwọ bá béèrè lọ́wọ́ mi.” Ọba Asiria sì bu fún Hesekiah ọba Juda ọ̀ọ́dúnrún tálẹ́ǹtì fàdákà àti ọgbọ̀n tálẹ́ǹtì wúrà.
Akkor elküldött Ezékiás, Júda királya Assiria királyához Lákisba, ezt izenvén: Vétkeztem, térj el én rólam; a mit rám vetsz, elviselem! És Assiria királya Ezékiásra, Júda királyára háromszáz tálentom ezüstöt és harmincz tálentom aranyat vetett ki.
15 Hesekiah fún un ní gbogbo fàdákà tí a rí nínú ilé Olúwa àti nínú ìṣúra ilé ọba.
És Ezékiás oda adott minden ezüstöt, a mely találtatott az Úr házában és a király házának kincsei között.
16 Ní àkókò yìí Hesekiah ọba Juda ké wúrà tí ó wà ní ẹnu ìlẹ̀kùn ilé Olúwa, kúrò àti ti òpó tí Hesekiah ọba Juda ti gbéró ó sì fi fún ọba Asiria.
Ugyanebben az időben fosztotta meg Ezékiás az Úr templomának ajtajait és az ajtók félfáit, a melyeket Ezékiás, Júda királya maga boríttatott be, és oda adta azokat Assiria királyának.
17 Ọba Asiria rán alákòóso gíga jùlọ, ìjòyè pàtàkì àti àwọn adarí pápá pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun tí ó pọ̀, láti Lakiṣi sí ọba Hesekiah ní Jerusalẹmu. Wọ́n wá sí òkè Jerusalẹmu wọ́n sì dúró ní etí ìdarí omi àbàtà òkè, ní ojú ọ̀nà tó lọ sí òpópó pápá alágbàfọ̀.
És Assiria királya mégis oda küldte Thartánt, Rabsárist és Rabsakét Lákisból Ezékiás királyhoz igen nagy haddal Jeruzsálembe, és felmenének és jutának Jeruzsálembe, és feljövén és oda érvén, megállának a felső halastó zsilipjénél, a mely a ruhafestő útja mellett van.
18 Wọ́n sì pe ọba; àti Eliakimu ọmọ Hilkiah ẹni tí í ṣe ilé olùtọ́jú, Ṣebna akọ̀wé, àti Joah ọmọkùnrin Asafu tí ó jẹ́ akọ̀wé ìrántí jáde pẹ̀lú wọn.
És kihívaták a királyt. És kiméne hozzájok Eliákim, a Hilkia fia, ki a király házának gondviselője volt, és Sebna, az íródeák, és Joákh, az Asáf fia, az emlékíró.
19 Olùdarí pápá wí fún wọn pé, “Sọ fún Hesekiah pé, “‘Èyí ni ohun tí ọba ńlá, ọba Asiria sọ: Kí ni ìgbẹ́kẹ̀lé yìí tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé?
És monda nékik Rabsaké: Mondjátok meg Ezékiásnak: Ezt mondja a király, Assiria nagy királya: Micsoda bizodalom ez, a melyben te bizakodtál?
20 Ìwọ wí pé ìwọ ni ìmọ̀ àti agbára láti jagun, ṣùgbọ́n ìwọ sọ̀rọ̀ òfìfo lásán. Ǹjẹ́ ta ni ìwọ gbẹ́kẹ̀ rẹ lé, tí ìwọ fi ń ṣe ọ̀tẹ̀ sí mi?
Azt mondád: csak szóbeszéd; tanács és erő kell a hadakozáshoz; vajjon kihez bíztál, hogy fellázadtál ellenem?
21 Wò ó, nísinsin yìí, ìwọ gbẹ́kẹ̀ rẹ lé Ejibiti, ẹ̀rún ọ̀pá pẹlẹbẹ ìyè fífọ́ yìí, èyí tí yóò wọ inú ọwọ́ ẹni tí ó sì bá fi ara tì í. Bẹ́ẹ̀ ni Farao ọba Ejibiti ṣe rí fún gbogbo àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀ wọn lé e.
Ímé, ebben a törött nádszálban bizakodol, Égyiptomban, melyhez ha ki támaszkodik, bemegy az ő kezébe és általlikasztja? Ilyen a Faraó, Égyiptom királya mindenekhez, a kik ő hozzá bíznak!
22 Tí ìwọ bá sì sọ fún mi pé, “Àwa gbẹ́kẹ̀ wa lé Olúwa Ọlọ́run.” Òun ha kọ́ ní ẹnìkan náà tí ibi gíga àti àwọn pẹpẹ tí Hesekiah mú kúrò, tí ó wí fún Juda àti Jerusalẹmu pé, “O gbọdọ̀ sìn níwájú pẹpẹ yìí ní Jerusalẹmu”?
Vagy azt akarjátok nékem mondani: Mi az Úrban, a mi Istenünkben bízunk; hát nem ez-é az, a kinek magaslatait és oltárait lerontotta Ezékiás, és mind Júdának, mind Jeruzsálemnek megparancsolta: Ez oltár előtt imádkozzatok Jeruzsálemben?
23 “‘Wá nísinsin yìí, ṣe àdéhùn pẹ̀lú ọ̀gá mi, ọba Asiria èmi yóò sì fún ọ ní ẹgbẹ̀rún méjì ẹṣin tí ìwọ bá lè kó àwọn tí yóò gùn ún sí orí rẹ!
Nosza, fogadj hát az én urammal, Assiria királyával: Én néked kétezer lovat adok, ha tudsz reájok adni annyi lovast.
24 Báwo ni ìwọ yóò ha ti ṣe le yí ojú balógun kan tí ó kéré jùlọ padà nínú àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi, tí ìwọ sì gbẹ́kẹ̀ rẹ lé Ejibiti fún àwọn kẹ̀kẹ́ àti ẹlẹ́ṣin?
Hogy verhetnél hát vissza az én uram legkisebb hadnagyai közül csak egyet is, és hogyan bízhatol Égyiptomhoz a szekerek és a lovagok miatt?
25 Síwájú sí i, èmi ti wá láti mú àti láti parun ibí yìí láìsí ọ̀rọ̀ láti ọ̀dọ̀ Olúwa? Olúwa fún rara rẹ̀ sọ fún mi pé kí n yára láti yan lórí ìlú yìí, kí n sì pa á run.’”
Vajjon az Úr tudta nélkül jöttem-é fel e hely ellen, hogy azt elveszessem? Az Úr mondotta nékem: Menj fel e föld ellen, és veszesd el azt!
26 Nígbà náà Eliakimu ọmọ Hilkiah, àti Ṣebna àti Joah sọ fún olùdarí pápá pé, “Jọ̀wọ́ sọ̀rọ̀ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ ní èdè Aramaiki, nítorí ti ó tí yé wa, má ṣe sọ̀rọ̀ fún wa pẹ̀lú èdè Heberu ní etí ìgbọ́ àwọn ènìyàn tí ń bẹ lórí odi.”
És monda Eliákim, a Hilkia fia, és Sebna és Joákh Rabsakénak: Beszélj, kérlek, a te szolgáiddal siriai nyelven, mert jól értjük; és ne beszélj velünk zsidóul e nép füle hallatára, a mely a kőfalon van.
27 Ṣùgbọ́n aláṣẹ dáhùn pé, “Ṣé fún ọ̀gá rẹ àti ìwọ nìkan ní ọ̀gá mi rán mi sí láti sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí kì í sì í ṣe fún àwọn ọkùnrin tí ó jókòó lórí odi ni gẹ́gẹ́ bí ìwọ, ni yóò ní láti jẹ ìgbẹ́ ará wọn kí wọ́n sì mu ìtọ̀ ará wọn?”
És felele nékik Rabsaké: Vajjon a te uradhoz, vagy te hozzád küldött-é engem az én uram, hogy elmondjam e dolgokat, avagy nem inkább e férfiakhoz-é, a kik a kőfalon ülnek, hogy azután veletek együtt egyék meg a saját ganéjokat, és igyák meg a saját vizeletöket?
28 Nígbà náà, aláṣẹ dìde, ó sì pè jáde ní èdè Heberu pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ ọba ńlá, ọba Asiria!
És oda állott Rabsaké, és hangosan kezdett zsidóul beszélni, mondván: Halljátok meg a királynak, Assiria nagy királyának beszédit!
29 Èyí ni ohun tí ọba sọ, má ṣe jẹ́ kí Hesekiah tàn ọ́ jẹ kò le gbà ọ́ kúrò ní ọwọ́ mi.
Azt mondja a király: Meg ne csaljon titeket Ezékiás; mert nem szabadíthat meg titeket az ő kezéből.
30 Ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah mú yín gbẹ́kẹ̀lé Olúwa nípa sísọ pé, ‘Olúwa yóò gbà wá nítòótọ́; ìlú yìí ni wọn kò ní fi lé ọba ìlú Asiria lọ́wọ́.’
És ne biztasson titeket Ezékiás az Úrral, ezt mondván: Kétség nélkül megszabadít minket az Úr, és nem adatik e város az assiria király kezébe.
31 “Má ṣe tẹ́tí sí Hesekiah. Èyí ni ohun tí ọba Asiria wí pé, ‘Fi ẹ̀bùn wá ojúrere mi, kí o sì jáde tọ̀ mí wá.’ Nígbà náà olúkúlùkù yín yóò jẹun láti inú àjàrà rẹ̀ àti igi ọ̀pọ̀tọ́, yóò sì mu omi láti inú àmù rẹ̀,
Ne hallgassatok Ezékiásra; mert így szól Assiria királya: Békéljetek meg velem, és jőjjetek ki hozzám, és kiki egyék az ő szőlőjéből és fügefájáról, és igyék az ő kútjának vizéből;
32 títí tí èmi yóò fi wá mú ọ lọ sí ilé gẹ́gẹ́ bí i tìrẹ, ilẹ̀ ọkà àti ọtí wáìnì, ilẹ̀ oúnjẹ àti ọgbà àjàrà, ilẹ̀ òróró olifi àti ti ilẹ̀ oyin; yàn ìyè má sì ṣe yàn ikú! “Kí ẹ má ṣe gbọ́ tí Hesekiah, nítorí ó ń tàn yín tí ó ba tí wí pé, ‘Olúwa yóò gbà wá?’
Míg eljövök és elviszlek titeket a ti földetekhez hasonló földre, gabonás és boros földre, kenyeres és szőlős földre, olajfás, és mézes földre, hogy élhessetek és meg ne haljatok. Ne higyjetek Ezékiásnak, mert félrevezet benneteket, mikor azt mondja: Az Úr megszabadít minket!
33 Ṣé òrìṣà àwọn orílẹ̀-èdè kankan ti gba ilé rẹ lọ́wọ́ àwọn ọba Asiria?
Vajjon megszabadították-é a pogányok istenei, mindenik a maga földjét Assiria királyának kezéből?
34 Níbo ni àwọn òrìṣà Hamati àti Arpadi gbé wà? Níbo ni àwọn òrìṣà Sefarfaimi, Hena àti Iffa gbé wà? Wọ́n ha gba Samaria kúrò lọ́wọ́ mi bí?
Hol vannak Hámátnak és Arphádnak istenei? Hol Sefárvaimnak, Hénának és Hivvának istenei? És Samariát is megszabadították-é az én kezemből?
35 Ta ni nínú gbogbo àwọn òrìṣà ilẹ̀ yìí tí ó ti gbìyànjú láti gba ilẹ̀ rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi? Báwo ni Olúwa yóò ṣe gba Jerusalẹmu kúrò lọ́wọ́ mi?”
Kicsoda a földön való minden istenek közül, a ki megszabadíthatta volna az ő földjét az én kezemből, hogy az Úr is kiszabadíthatná Jeruzsálemet az én kezemből?
36 Ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ènìyàn náà dákẹ́ síbẹ̀ wọn kò sì sọ ohunkóhun, láti fi fèsì, nítorí ọba ti paláṣẹ, “Ẹ má ṣe dá a lóhùn.”
De a nép csak hallgatott, és nem felelt néki csak egy igét sem; mert a király megparancsolta volt, mondván: Ne feleljetek néki.
37 Nígbà náà Eliakimu ọmọ Hilkiah olùtọ́jú ààfin, Ṣebna akọ̀wé àti Joah ọmọ Asafu akọ̀wé ránṣẹ́ lọ sí ọ̀dọ̀ Hesekiah, pẹ̀lú aṣọ wọn yíya, ó sì wí fún un ohun tí olùdarí pápá ti sọ.
És elment Eliákim, a Hilkia fia, a király házának gondviselője, és Sebna, az íródeák, és Joákh, az Asáf fia, az emlékíró, Ezékiáshoz megszaggatott ruhákban, és elmondák néki Rabsaké beszédit.

< 2 Kings 18 >