< 2 Kings 18 >

1 Ní ọdún kẹta Hosea ọmọ Ela ọba Israẹli, Hesekiah ọmọ Ahasi ọba Juda bẹ̀rẹ̀ ìjọba.
És volt harmadik évében Hoséának, Éla fiának, Izraél királyának, király lett Chizkíja, Ácház fia, Jehúda királya.
2 Ó jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó ti di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Abijah ọmọbìnrin Sekariah.
Huszonöt éves volt, mikor király lett és huszonkilenc évig uralkodott Jeruzsálemben; anyjának neve pedig Abí, Zakarja leánya.
3 Ó sì ṣe ohun tí ó dára níwájú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí i baba rẹ̀ Dafidi ti ṣe.
És tette azt, a mi helyes az Örökkévaló szemeiben egészen a szerint, mint tette őse Dávid.
4 Ó mú ibi gíga náà kúrò, ó sì fọ́ àwọn ère òkúta, ó sì gé àwọn ère Aṣerah lulẹ̀, ó sì fọ́ ejò idẹ tí Mose ti ṣe náà túútúú, títí di ọjọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli ń sun tùràrí sí. (Wọ́n sì pè é ní Nehuṣitani.)
Ő távolította el a magaslatokat, összetörte az oszlopokat és kivágta az asérát; és szétzúzta a rézkígyót, melyet készített Mózes – mert egészen ama napokig füstölögtettek neki Izraél fiai – és melyet Nechustánnak neveztek.
5 Hesekiah sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run Israẹli. Kò sì ṣí ẹnìkan tí ó dàbí tirẹ̀ lára gbogbo àwọn ọba Juda, bóyá kí ó tó jẹ tàbí lẹ́yìn rẹ̀.
Az Örökkévalóban, Izraél Istenében bízott; ő utána pedig nem volt olyan, mint ő, mind a Jehúda királyai között, azok közt sem, kik előtte voltak.
6 Ó súnmọ́ Olúwa, kò sì dẹ́kun láti tì í lẹ́yìn: ó sì pa òfin Olúwa mọ́ tí ó ti fi fún Mose.
Ragaszkodott az Örökkévalóhoz, nem tért el tőle, hanem megőrizte parancsolatjait, melyeket az Örökkévaló parancsolt Mózesnek.
7 Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀; ó sì ń ṣe rere nínú gbogbo ohun tí ó dáwọ́lé. Ó ṣe ọ̀tẹ̀ sí ọba Asiria kò sì sìn ín.
Volt is vele az Örökkévaló, bármiért vonult ki, szerencsés volt; és fellázadt Assúr királya ellen és nem szolgálta.
8 Láti ilé ìṣọ́ títí dé ìlú olódi, ó sì pa àwọn ará Filistini run, àti títí dé Gasa àti agbègbè rẹ̀.
Ő verte meg a filiszteusokat egészen Azzáig, meg annak határait, őrtoronytól erősített városig.
9 Ní ọdún kẹrin ọba Hesekiah, nígbà tí ó jẹ́ ọdún keje Hosea ọmọ Ela ọba Israẹli. Ṣalamaneseri ọba Asiria yàn lára Samaria ó sì tẹ̀dó tì í.
Volt pedig Chizkíjáhú király negyedik évében, az hetedik éve Hóséának, Éla fiának, Izraél királyának, feljött Salmanéezer, Assúr királya Sómrón ellen és ostrom alá vette;
10 Lẹ́yìn ọdún mẹ́ta Asiria gbé e. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kó Samaria ní ọdún kẹfà Hesekiah tí ó sì jẹ́ ọdún kẹsànán Hosea ọba Israẹli.
És bevette három év múltán; Chizkíja hatodik évében, az kilencedik éve Hóséának, Izraél királyának, vétetett be Sómrón.
11 Ọba Asiria lé Israẹli kúrò ní Asiria, wọ́n sì ṣe àtìpó wọn ní Hala, ní Gosani létí odò Habori àti ní ìlú àwọn ará Media.
És számkivetette Assúr királya Izraélt Assúrba és Chaláchba és vitte őket a Chábórhoz, Gózán folyójához és Média városaiba;
12 Èyí ṣẹlẹ̀ nítorí wọn kò pa àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wọn mọ́. Ṣùgbọ́n wọ́n ti dà májẹ̀mú rẹ̀ gbogbo èyí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti pàṣẹ. Wọn kò fi etí wọn sílẹ̀ sí òfin wọn kò sì gbé wọn jáde.
mivelhogy nem hallgattak az Örökkévalónak, az ő Istenüknek szavára és megszegték szövetségét, mindazt, amit parancsolt Mózes, az Örökkévaló szolgája, sem nem hallgattak rá, sem nem tették.
13 Ní ọdún kẹrìnlá tí Hesekiah jẹ ọba, Sennakeribu ọba Asiria kọlu gbogbo ìlú olódi ti Juda ó sì pa wọ́n run.
Chizkíjáhú király tizennegyedik évében pedig fölment Szanchérib, Assúr királya, mind a Jehúda erősített városai ellen és elfoglalta azokat.
14 Bẹ́ẹ̀ ni Hesekiah ọba Juda sì ránṣẹ́ yìí sí ọba Asiria ní Lakiṣi, wí pé, “Mo ti ṣẹ̀, padà lẹ́yìn mi: èmi yóò sì san ohunkóhun tí ìwọ bá béèrè lọ́wọ́ mi.” Ọba Asiria sì bu fún Hesekiah ọba Juda ọ̀ọ́dúnrún tálẹ́ǹtì fàdákà àti ọgbọ̀n tálẹ́ǹtì wúrà.
Erre küldött Chizkíja, Jehúda királya Assúr királyához Lákhísba, mondván: Vétkeztem, vonulj el tőlem, a mit kivetsz reám, viselem. És rávetett Assúr királya Chizkíjára, Jehúda királyára háromszáz kikkár ezüstöt és harminc kikkár aranyat.
15 Hesekiah fún un ní gbogbo fàdákà tí a rí nínú ilé Olúwa àti nínú ìṣúra ilé ọba.
És odaadta Chizkija mind az ezüstöt, a mi találtatott az Örökkévaló házában és a király házának kincstáraiban.
16 Ní àkókò yìí Hesekiah ọba Juda ké wúrà tí ó wà ní ẹnu ìlẹ̀kùn ilé Olúwa, kúrò àti ti òpó tí Hesekiah ọba Juda ti gbéró ó sì fi fún ọba Asiria.
Abban az időben törte le Chizkíja az Örökkévaló templomának ajtóit és a pilléreket, melyeket beborított volt maga Chizkíja, Jehúda királya, és odaadta Assúr királyának.
17 Ọba Asiria rán alákòóso gíga jùlọ, ìjòyè pàtàkì àti àwọn adarí pápá pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun tí ó pọ̀, láti Lakiṣi sí ọba Hesekiah ní Jerusalẹmu. Wọ́n wá sí òkè Jerusalẹmu wọ́n sì dúró ní etí ìdarí omi àbàtà òkè, ní ojú ọ̀nà tó lọ sí òpópó pápá alágbàfọ̀.
Ekkor küldte Assúr királya Tartánt, Rab-Száríszt és Rabságét hatalmas sereggel Lákhísból Chizkíjáhú királyhoz Jeruzsálembe. Fölmentek tehát és érkeztek Jeruzsálembe; fölmentek és eljöttek és megálltak a felső tónak vízvezetékénél, mely a mosómező útján van.
18 Wọ́n sì pe ọba; àti Eliakimu ọmọ Hilkiah ẹni tí í ṣe ilé olùtọ́jú, Ṣebna akọ̀wé, àti Joah ọmọkùnrin Asafu tí ó jẹ́ akọ̀wé ìrántí jáde pẹ̀lú wọn.
És szólították a királyt; erre kiment hozzájuk Eljákim, Chizkíjáhú fia, a ki a ház fölött volt, meg Sebna az író, és Jóách, Ászáf fia, a kancellár.
19 Olùdarí pápá wí fún wọn pé, “Sọ fún Hesekiah pé, “‘Èyí ni ohun tí ọba ńlá, ọba Asiria sọ: Kí ni ìgbẹ́kẹ̀lé yìí tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé?
És szólt hozzájuk Rabsáké: Szóljatok csak Chizkíjáhúnak: így szól a nagy király, Assúr királya, micsoda bizalom az, mellyel bíztál?
20 Ìwọ wí pé ìwọ ni ìmọ̀ àti agbára láti jagun, ṣùgbọ́n ìwọ sọ̀rọ̀ òfìfo lásán. Ǹjẹ́ ta ni ìwọ gbẹ́kẹ̀ rẹ lé, tí ìwọ fi ń ṣe ọ̀tẹ̀ sí mi?
Azt mondtad, csak szóbeszéd, hogy tanács és hatalom kell a háborúhoz! Most kiben bíztál, hogy föllázadtál ellenem?
21 Wò ó, nísinsin yìí, ìwọ gbẹ́kẹ̀ rẹ lé Ejibiti, ẹ̀rún ọ̀pá pẹlẹbẹ ìyè fífọ́ yìí, èyí tí yóò wọ inú ọwọ́ ẹni tí ó sì bá fi ara tì í. Bẹ́ẹ̀ ni Farao ọba Ejibiti ṣe rí fún gbogbo àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀ wọn lé e.
Most íme bíztad magad erre a törött nádpálcára, Egyiptomra, amelyre ha valaki támaszkodik, bemegy a tenyerébe és átfúrja azt! Ilyen Fáraó, Egyiptom királya mindazoknak, kik benne bíznak.
22 Tí ìwọ bá sì sọ fún mi pé, “Àwa gbẹ́kẹ̀ wa lé Olúwa Ọlọ́run.” Òun ha kọ́ ní ẹnìkan náà tí ibi gíga àti àwọn pẹpẹ tí Hesekiah mú kúrò, tí ó wí fún Juda àti Jerusalẹmu pé, “O gbọdọ̀ sìn níwájú pẹpẹ yìí ní Jerusalẹmu”?
De ha így szóltok hozzám: az Örökkévalóban, a mi Istenünkben bíztunk – hiszen ő az, akinek eltávolította Chizkíjáhu magaslatait és oltárait és azt mondta Jehúdának és Jeruzsálemnek: ezen oltár előtt boruljatok le Jeruzsálemben!
23 “‘Wá nísinsin yìí, ṣe àdéhùn pẹ̀lú ọ̀gá mi, ọba Asiria èmi yóò sì fún ọ ní ẹgbẹ̀rún méjì ẹṣin tí ìwọ bá lè kó àwọn tí yóò gùn ún sí orí rẹ!
Most tehát állj csak fogadásba urammal, Assúr királyával: hadd adok neked kétezer lovat, vajon tudsz-e te lovasokat adni rájuk?
24 Báwo ni ìwọ yóò ha ti ṣe le yí ojú balógun kan tí ó kéré jùlọ padà nínú àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi, tí ìwọ sì gbẹ́kẹ̀ rẹ lé Ejibiti fún àwọn kẹ̀kẹ́ àti ẹlẹ́ṣin?
Hogy vernél hát vissza csak egy helytartót is uramnak legkisebb szolgái közül? És te bíztad magadat Egyiptomra szekérhad és lovasok dolgában!
25 Síwájú sí i, èmi ti wá láti mú àti láti parun ibí yìí láìsí ọ̀rọ̀ láti ọ̀dọ̀ Olúwa? Olúwa fún rara rẹ̀ sọ fún mi pé kí n yára láti yan lórí ìlú yìí, kí n sì pa á run.’”
Ám, vajon az Örökkévaló nélkül jöttem-e föl e hely ellen, hogy elpusztítsam? Az Örökkévaló mondta nekem: menj föl ez ország ellen és pusztítsd el!
26 Nígbà náà Eliakimu ọmọ Hilkiah, àti Ṣebna àti Joah sọ fún olùdarí pápá pé, “Jọ̀wọ́ sọ̀rọ̀ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ ní èdè Aramaiki, nítorí ti ó tí yé wa, má ṣe sọ̀rọ̀ fún wa pẹ̀lú èdè Heberu ní etí ìgbọ́ àwọn ènìyàn tí ń bẹ lórí odi.”
Erre szólt Eljákim, Chilkíjáhú fia, meg Sebna és Jóách Rabsákéhoz: Beszélj, kérlek, szolgáidhoz arámul, mert mi értjük; s ne beszélj velünk zsidóul azon nép fülei hallatára, mely a falon van.
27 Ṣùgbọ́n aláṣẹ dáhùn pé, “Ṣé fún ọ̀gá rẹ àti ìwọ nìkan ní ọ̀gá mi rán mi sí láti sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí kì í sì í ṣe fún àwọn ọkùnrin tí ó jókòó lórí odi ni gẹ́gẹ́ bí ìwọ, ni yóò ní láti jẹ ìgbẹ́ ará wọn kí wọ́n sì mu ìtọ̀ ará wọn?”
De szólt hozzájuk Rabsáké: Vajon uradhoz és tehozzád küldött-e engem uram, hogy elmondjam e szavakat? Nemde inkább azon emberekhez, kik a falon ülnek, hogy egyék a ganajukat és igyák a vizeletüket veletek együtt!
28 Nígbà náà, aláṣẹ dìde, ó sì pè jáde ní èdè Heberu pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ ọba ńlá, ọba Asiria!
Erre odaállt Rabsáké és fennhangon kiáltott zsidóul, beszélt és mondta: Halljátok a nagy királynak, Assúr királyának szavát!
29 Èyí ni ohun tí ọba sọ, má ṣe jẹ́ kí Hesekiah tàn ọ́ jẹ kò le gbà ọ́ kúrò ní ọwọ́ mi.
Így szól a király: ne ámítson benneteket Chizkíjáhú, mert nem menthet meg titeket az ő kezéből.
30 Ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah mú yín gbẹ́kẹ̀lé Olúwa nípa sísọ pé, ‘Olúwa yóò gbà wá nítòótọ́; ìlú yìí ni wọn kò ní fi lé ọba ìlú Asiria lọ́wọ́.’
És ne biztasson benneteket Chizkíjáhú az Örökkévalóval, mondván: meg fog menteni minket az Örökkévaló és nem adatik e város Assúr királyának kezébe.
31 “Má ṣe tẹ́tí sí Hesekiah. Èyí ni ohun tí ọba Asiria wí pé, ‘Fi ẹ̀bùn wá ojúrere mi, kí o sì jáde tọ̀ mí wá.’ Nígbà náà olúkúlùkù yín yóò jẹun láti inú àjàrà rẹ̀ àti igi ọ̀pọ̀tọ́, yóò sì mu omi láti inú àmù rẹ̀,
Ne hallgassatok Chizkíjáhúra! Mert így szól Assúr királya: csináljatok velem békét és jertek ki hozzám, hogy ehessétek ki-ki az ő szőlőtőjét és ki-ki az ő fügefáját és hogy ihassátok ki-ki kútja vizét.
32 títí tí èmi yóò fi wá mú ọ lọ sí ilé gẹ́gẹ́ bí i tìrẹ, ilẹ̀ ọkà àti ọtí wáìnì, ilẹ̀ oúnjẹ àti ọgbà àjàrà, ilẹ̀ òróró olifi àti ti ilẹ̀ oyin; yàn ìyè má sì ṣe yàn ikú! “Kí ẹ má ṣe gbọ́ tí Hesekiah, nítorí ó ń tàn yín tí ó ba tí wí pé, ‘Olúwa yóò gbà wá?’
A míg eljövök és elviszlek benneteket egy országba, mely olyan, mint a ti országotok: gabona és must országába, kenyér és szőlők országába, olajfa és méz országába, hogy éljetek és meg ne haljatok. Ne hallgassatok hát Chizkíjáhúra, midőn csábítgat titeket, mondván: az Örökkévaló majd megment bennünket.
33 Ṣé òrìṣà àwọn orílẹ̀-èdè kankan ti gba ilé rẹ lọ́wọ́ àwọn ọba Asiria?
Hát megmentették-e a nemzetek istenei ki-ki az ő országát Assúr királyának kezéből?
34 Níbo ni àwọn òrìṣà Hamati àti Arpadi gbé wà? Níbo ni àwọn òrìṣà Sefarfaimi, Hena àti Iffa gbé wà? Wọ́n ha gba Samaria kúrò lọ́wọ́ mi bí?
Hol vannak Chamát és Arpád istenei, hol Szefarvájim, Héná és Ivva istenei, hogy megmentették volna Sómrónt kezemből?
35 Ta ni nínú gbogbo àwọn òrìṣà ilẹ̀ yìí tí ó ti gbìyànjú láti gba ilẹ̀ rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi? Báwo ni Olúwa yóò ṣe gba Jerusalẹmu kúrò lọ́wọ́ mi?”
Kik azok az országok minden istenei közül, a kik megmentették az ő országukat kezemből, hogy az Örökkévaló megmentené Jeruzsálemet kezemből?
36 Ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ènìyàn náà dákẹ́ síbẹ̀ wọn kò sì sọ ohunkóhun, láti fi fèsì, nítorí ọba ti paláṣẹ, “Ẹ má ṣe dá a lóhùn.”
Hallgatott a nép és nem feleltek neki semmit, mert parancsa volt az a királynak, mondván: ne feleljetek neki!
37 Nígbà náà Eliakimu ọmọ Hilkiah olùtọ́jú ààfin, Ṣebna akọ̀wé àti Joah ọmọ Asafu akọ̀wé ránṣẹ́ lọ sí ọ̀dọ̀ Hesekiah, pẹ̀lú aṣọ wọn yíya, ó sì wí fún un ohun tí olùdarí pápá ti sọ.
Erre bement Eljákím, Chilkíja fia, aki a ház fölött volt, meg Sebna az író és Jóách, Ászáf fia, a kancellár Chizkíjáhúhoz megszaggatott ruhákkal és jelentették neki Rabsáké szavait.

< 2 Kings 18 >