< 2 Kings 18 >

1 Ní ọdún kẹta Hosea ọmọ Ela ọba Israẹli, Hesekiah ọmọ Ahasi ọba Juda bẹ̀rẹ̀ ìjọba.
En la troisième année d’Osée, fils d’Ela, roi d’Israël, régna Ezéchias, fils d’Achaz, roi de Juda.
2 Ó jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó ti di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Abijah ọmọbìnrin Sekariah.
Il avait vingt-cinq ans lorsqu’il commença à régner, et il régna vingt-neuf ans dans Jérusalem: le nom de sa mère était Abi, fille de Zacharie.
3 Ó sì ṣe ohun tí ó dára níwájú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí i baba rẹ̀ Dafidi ti ṣe.
Et il fit ce qui était bon devant le Seigneur, selon tout ce qu’avait fait David son père.
4 Ó mú ibi gíga náà kúrò, ó sì fọ́ àwọn ère òkúta, ó sì gé àwọn ère Aṣerah lulẹ̀, ó sì fọ́ ejò idẹ tí Mose ti ṣe náà túútúú, títí di ọjọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli ń sun tùràrí sí. (Wọ́n sì pè é ní Nehuṣitani.)
C’est lui qui détruisit les hauts lieux, renversa les statues, coupa les bois sacrés, et brisa le serpent d’airain qu’avait fait Moïse, parce que jusqu’à ce temps-là les enfants d’Israël lui brûlaient de l’encens, et il l’appela du nom de Nohestan.
5 Hesekiah sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run Israẹli. Kò sì ṣí ẹnìkan tí ó dàbí tirẹ̀ lára gbogbo àwọn ọba Juda, bóyá kí ó tó jẹ tàbí lẹ́yìn rẹ̀.
C’est dans le Seigneur Dieu d’Israël qu’il espéra: aussi après lui il n’y eut pas de semblable à lui entre tous les rois de Juda, ni même parmi ceux qui furent avant lui;
6 Ó súnmọ́ Olúwa, kò sì dẹ́kun láti tì í lẹ́yìn: ó sì pa òfin Olúwa mọ́ tí ó ti fi fún Mose.
Et il s’attacha au Seigneur, et il ne s’écarta pas de ses traces, et il pratiqua ses commandements qu’avait prescrits le Seigneur à Moïse.
7 Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀; ó sì ń ṣe rere nínú gbogbo ohun tí ó dáwọ́lé. Ó ṣe ọ̀tẹ̀ sí ọba Asiria kò sì sìn ín.
C’est pourquoi le Seigneur était même avec lui, et dans toutes les choses qu’il entreprenait il se conduisait sagement. Il secoua aussi le joug du roi des Assyriens, et ne lui fut pas asservi.
8 Láti ilé ìṣọ́ títí dé ìlú olódi, ó sì pa àwọn ará Filistini run, àti títí dé Gasa àti agbègbè rẹ̀.
C’est lui qui frappa les Philistins jusqu’à Gaza, et tous leurs confins, depuis la Tour des gardes jusqu’à la Cité fortifiée.
9 Ní ọdún kẹrin ọba Hesekiah, nígbà tí ó jẹ́ ọdún keje Hosea ọmọ Ela ọba Israẹli. Ṣalamaneseri ọba Asiria yàn lára Samaria ó sì tẹ̀dó tì í.
La quatrième année du roi Ezéchias, qui était la septième année d’Osée, fils d’Ela, roi d’Israël, Salmanasar, roi des Assyriens, monta à Samarie, l’assiégea,
10 Lẹ́yìn ọdún mẹ́ta Asiria gbé e. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kó Samaria ní ọdún kẹfà Hesekiah tí ó sì jẹ́ ọdún kẹsànán Hosea ọba Israẹli.
Et la prit. Or c’est après trois ans, en la sixième année du roi Ezéchias, c’est-à-dire la neuvième année d’Osée, roi d’Israël, que Samarie fut prise;
11 Ọba Asiria lé Israẹli kúrò ní Asiria, wọ́n sì ṣe àtìpó wọn ní Hala, ní Gosani létí odò Habori àti ní ìlú àwọn ará Media.
Et le roi des Assyriens transféra Israël chez les Assyriens, et les établit en Hala et en Habor, fleuves de Gozan, dans les villes des Mèdes,
12 Èyí ṣẹlẹ̀ nítorí wọn kò pa àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wọn mọ́. Ṣùgbọ́n wọ́n ti dà májẹ̀mú rẹ̀ gbogbo èyí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti pàṣẹ. Wọn kò fi etí wọn sílẹ̀ sí òfin wọn kò sì gbé wọn jáde.
Parce qu’ils n’écoutèrent point la voix du Seigneur leur Dieu, qu’ils transgressèrent son alliance: tout ce qu’avait ordonné Moïse, serviteur du Seigneur, ils ne l’écoutèrent point ni ne le suivirent.
13 Ní ọdún kẹrìnlá tí Hesekiah jẹ ọba, Sennakeribu ọba Asiria kọlu gbogbo ìlú olódi ti Juda ó sì pa wọ́n run.
La quatorzième aimée du roi Ezéchias, Sennachérib, roi des Assyriens, monta vers toutes les villes de Juda fortifiées, et les prit.
14 Bẹ́ẹ̀ ni Hesekiah ọba Juda sì ránṣẹ́ yìí sí ọba Asiria ní Lakiṣi, wí pé, “Mo ti ṣẹ̀, padà lẹ́yìn mi: èmi yóò sì san ohunkóhun tí ìwọ bá béèrè lọ́wọ́ mi.” Ọba Asiria sì bu fún Hesekiah ọba Juda ọ̀ọ́dúnrún tálẹ́ǹtì fàdákà àti ọgbọ̀n tálẹ́ǹtì wúrà.
Alors Ezéchias, roi de Juda, envoya des messagers au roi des Assyriens, à Lachis, disant: J’ai péché, retirez-vous loin de moi, et tout ce que vous m’imposerez, je le supporterai. C’est pourquoi le roi des Assyriens imposa à Ezéchias, roi de Juda, trois cents talents d’argent et trente talents d’or.
15 Hesekiah fún un ní gbogbo fàdákà tí a rí nínú ilé Olúwa àti nínú ìṣúra ilé ọba.
Et Ezéchias donna tout l’argent qui avait été trouvé dans la maison du Seigneur et dans les trésors du roi.
16 Ní àkókò yìí Hesekiah ọba Juda ké wúrà tí ó wà ní ẹnu ìlẹ̀kùn ilé Olúwa, kúrò àti ti òpó tí Hesekiah ọba Juda ti gbéró ó sì fi fún ọba Asiria.
En ce temps-là Ezéchias rompit les battants des portes du temple du Seigneur, et les lames d’or que lui-même y avait attachées, et il les donna au roi des Assyriens.
17 Ọba Asiria rán alákòóso gíga jùlọ, ìjòyè pàtàkì àti àwọn adarí pápá pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun tí ó pọ̀, láti Lakiṣi sí ọba Hesekiah ní Jerusalẹmu. Wọ́n wá sí òkè Jerusalẹmu wọ́n sì dúró ní etí ìdarí omi àbàtà òkè, ní ojú ọ̀nà tó lọ sí òpópó pápá alágbàfọ̀.
Or le roi des Assyriens envoya ensuite Tharthan, Rabsaris et Rabsacès, de Lachis à Jérusalem, vers le roi Ezéchias, avec une forte armée; et lorsqu’ils eurent monté, ils vinrent à Jérusalem, ils s’arrêtèrent près de l’aqueduc de la piscine supérieure, qui est sur la voie de Champ de Foulon.
18 Wọ́n sì pe ọba; àti Eliakimu ọmọ Hilkiah ẹni tí í ṣe ilé olùtọ́jú, Ṣebna akọ̀wé, àti Joah ọmọkùnrin Asafu tí ó jẹ́ akọ̀wé ìrántí jáde pẹ̀lú wọn.
Et ils demandèrent le roi: or sortirent vers eux, Eliacim, fils d’Helcias, intendant de la maison du roi, Sobna, le scribe, et Joahé, fils d’Asaph, qui tenait les registres.
19 Olùdarí pápá wí fún wọn pé, “Sọ fún Hesekiah pé, “‘Èyí ni ohun tí ọba ńlá, ọba Asiria sọ: Kí ni ìgbẹ́kẹ̀lé yìí tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé?
Et Rabsacès leur dit: Dites à Ezéchias: Voici ce que dit le grand roi, le roi des Assyriens: Quelle est cette confiance qui vous soutient?
20 Ìwọ wí pé ìwọ ni ìmọ̀ àti agbára láti jagun, ṣùgbọ́n ìwọ sọ̀rọ̀ òfìfo lásán. Ǹjẹ́ ta ni ìwọ gbẹ́kẹ̀ rẹ lé, tí ìwọ fi ń ṣe ọ̀tẹ̀ sí mi?
Peut-être que vous avez formé le dessein de vous préparer au combat. En qui mettez-vous votre confiance, pour que vous osiez vous révolter?
21 Wò ó, nísinsin yìí, ìwọ gbẹ́kẹ̀ rẹ lé Ejibiti, ẹ̀rún ọ̀pá pẹlẹbẹ ìyè fífọ́ yìí, èyí tí yóò wọ inú ọwọ́ ẹni tí ó sì bá fi ara tì í. Bẹ́ẹ̀ ni Farao ọba Ejibiti ṣe rí fún gbogbo àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀ wọn lé e.
Espérez-vous en ce bâton de roseau et cassé, l’Egypte: bâton qui, si un homme s’appuie dessus, étant brisé, entrera dans sa main et la percera? Ainsi est Pharaon, roi d’Egypte, pour tous ceux qui se confient en lui.
22 Tí ìwọ bá sì sọ fún mi pé, “Àwa gbẹ́kẹ̀ wa lé Olúwa Ọlọ́run.” Òun ha kọ́ ní ẹnìkan náà tí ibi gíga àti àwọn pẹpẹ tí Hesekiah mú kúrò, tí ó wí fún Juda àti Jerusalẹmu pé, “O gbọdọ̀ sìn níwájú pẹpẹ yìí ní Jerusalẹmu”?
Que si vous me dites: C’est dans le Seigneur notre Dieu que nous avons confiance, n’est-ce pas celui dont Ezéchias a détruit les autels et les hauts lieux, et a ordonné à Juda et à Jérusalem: C’est devant cet autel que vous adorerez dans Jérusalem?
23 “‘Wá nísinsin yìí, ṣe àdéhùn pẹ̀lú ọ̀gá mi, ọba Asiria èmi yóò sì fún ọ ní ẹgbẹ̀rún méjì ẹṣin tí ìwọ bá lè kó àwọn tí yóò gùn ún sí orí rẹ!
Maintenant donc passez vers mon seigneur, le roi des Assyriens, et je vous donnerai deux mille chevaux, et voyez si vous trouverez des cavaliers pour eux.
24 Báwo ni ìwọ yóò ha ti ṣe le yí ojú balógun kan tí ó kéré jùlọ padà nínú àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi, tí ìwọ sì gbẹ́kẹ̀ rẹ lé Ejibiti fún àwọn kẹ̀kẹ́ àti ẹlẹ́ṣin?
Et comment pourriez-vous résister devant un seul satrape des derniers serviteurs de mon maître? Est-ce que vous avez confiance dans l’Egypte, à cause de ses chars et de ses cavaliers?
25 Síwájú sí i, èmi ti wá láti mú àti láti parun ibí yìí láìsí ọ̀rọ̀ láti ọ̀dọ̀ Olúwa? Olúwa fún rara rẹ̀ sọ fún mi pé kí n yára láti yan lórí ìlú yìí, kí n sì pa á run.’”
Mais est-ce donc sans la volonté du Seigneur que je suis monté en ce lieu pour le détruire? Le Seigneur m’a dit: Monte dans cette terre et ravage-la.
26 Nígbà náà Eliakimu ọmọ Hilkiah, àti Ṣebna àti Joah sọ fún olùdarí pápá pé, “Jọ̀wọ́ sọ̀rọ̀ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ ní èdè Aramaiki, nítorí ti ó tí yé wa, má ṣe sọ̀rọ̀ fún wa pẹ̀lú èdè Heberu ní etí ìgbọ́ àwọn ènìyàn tí ń bẹ lórí odi.”
Or Eliacim, fils d’Helcias, Sobna et Joahé, dirent à Rabsacès: Nous vous prions de parler à vos serviteurs en syriaque, parce que nous entendons cette langue, et de ne pas nous parler en hébreu, le peuple, qui est sur le mur, écoutant.
27 Ṣùgbọ́n aláṣẹ dáhùn pé, “Ṣé fún ọ̀gá rẹ àti ìwọ nìkan ní ọ̀gá mi rán mi sí láti sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí kì í sì í ṣe fún àwọn ọkùnrin tí ó jókòó lórí odi ni gẹ́gẹ́ bí ìwọ, ni yóò ní láti jẹ ìgbẹ́ ará wọn kí wọ́n sì mu ìtọ̀ ará wọn?”
Et Rabsacès leur répondit: Est-ce donc vers ton maître et vers toi que mon maître m’a envoyé pour dire ces paroles, et non pas plutôt vers les hommes qui sont sur le mur, pour qu’ils mangent leurs excréments et boivent leur urine avec vous?
28 Nígbà náà, aláṣẹ dìde, ó sì pè jáde ní èdè Heberu pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ ọba ńlá, ọba Asiria!
C’est pourquoi Rabsacès se tint debout et cria d’une voix forte en langue judaïque: Ecoutez les paroles du grand roi, du roi des Assyriens.
29 Èyí ni ohun tí ọba sọ, má ṣe jẹ́ kí Hesekiah tàn ọ́ jẹ kò le gbà ọ́ kúrò ní ọwọ́ mi.
Voici ce que dit le roi: Qu’Ezéchias ne vous séduise point: car il ne pourra pas vous arracher à ma main.
30 Ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah mú yín gbẹ́kẹ̀lé Olúwa nípa sísọ pé, ‘Olúwa yóò gbà wá nítòótọ́; ìlú yìí ni wọn kò ní fi lé ọba ìlú Asiria lọ́wọ́.’
Et qu’il ne vous donne point de confiance dans le Seigneur, disant: Le Seigneur nous délivrera certainement, et cette ville ne sera point livrée à la main du roi des Assyriens.
31 “Má ṣe tẹ́tí sí Hesekiah. Èyí ni ohun tí ọba Asiria wí pé, ‘Fi ẹ̀bùn wá ojúrere mi, kí o sì jáde tọ̀ mí wá.’ Nígbà náà olúkúlùkù yín yóò jẹun láti inú àjàrà rẹ̀ àti igi ọ̀pọ̀tọ́, yóò sì mu omi láti inú àmù rẹ̀,
N’écoutez point Ezéchias; car voici ce que dit le roi des Assyriens: Faites avec moi ce qui vous est utile: sortez vers moi, et chacun mangera de sa vigne et de son figuier, et vous boirez des eaux de vos citernes,
32 títí tí èmi yóò fi wá mú ọ lọ sí ilé gẹ́gẹ́ bí i tìrẹ, ilẹ̀ ọkà àti ọtí wáìnì, ilẹ̀ oúnjẹ àti ọgbà àjàrà, ilẹ̀ òróró olifi àti ti ilẹ̀ oyin; yàn ìyè má sì ṣe yàn ikú! “Kí ẹ má ṣe gbọ́ tí Hesekiah, nítorí ó ń tàn yín tí ó ba tí wí pé, ‘Olúwa yóò gbà wá?’
Jusqu’à ce que je vienne et que je vous transfère dans une terre qui est semblable à votre terre, dans une terre qui porte du fruit, et fertile en vin, une terre de pain et de vignes, une terre d’oliviers, d’huile et de miel, et vous vivrez, et vous ne mourrez point. N’écoutez point Ezéchias, qui vous trompe, disant: Le Seigneur nous délivrera.
33 Ṣé òrìṣà àwọn orílẹ̀-èdè kankan ti gba ilé rẹ lọ́wọ́ àwọn ọba Asiria?
Est-ce que les dieux des nations ont délivré leur terre de la main du roi des Assyriens?
34 Níbo ni àwọn òrìṣà Hamati àti Arpadi gbé wà? Níbo ni àwọn òrìṣà Sefarfaimi, Hena àti Iffa gbé wà? Wọ́n ha gba Samaria kúrò lọ́wọ́ mi bí?
Où est le dieu d’Emath et d’Arphad? où est le dieu de Sépharvaïm, d’Ana et d’Ava? Est-ce qu’ils ont délivré Samarie de ma main?
35 Ta ni nínú gbogbo àwọn òrìṣà ilẹ̀ yìí tí ó ti gbìyànjú láti gba ilẹ̀ rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi? Báwo ni Olúwa yóò ṣe gba Jerusalẹmu kúrò lọ́wọ́ mi?”
Quels sont ceux, parmi tous les dieux des nations, qui ont arraché leur pays à ma main, pour que le Seigneur puisse arracher Jérusalem à ma main?
36 Ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ènìyàn náà dákẹ́ síbẹ̀ wọn kò sì sọ ohunkóhun, láti fi fèsì, nítorí ọba ti paláṣẹ, “Ẹ má ṣe dá a lóhùn.”
C’est pourquoi le peuple se tut, et ne lui répondit rien; car il avait reçu ordre du roi de ne pas lui répondre.
37 Nígbà náà Eliakimu ọmọ Hilkiah olùtọ́jú ààfin, Ṣebna akọ̀wé àti Joah ọmọ Asafu akọ̀wé ránṣẹ́ lọ sí ọ̀dọ̀ Hesekiah, pẹ̀lú aṣọ wọn yíya, ó sì wí fún un ohun tí olùdarí pápá ti sọ.
Et Eliacim, fils d’Helcias, intendant de la maison, Sobna, le scribe, et Joahé, fils d’Asaph, qui tenait les registres, vinrent vers Ezéchias, leurs vêtements déchirés, et ils lui rapportèrent les paroles de Rabsacès.

< 2 Kings 18 >