< 2 Kings 17 >

1 Ní ọdún kejìlá ọba Ahasi ará Juda, Hosea ọmọ Ela jẹ ọba Israẹli ní Samaria, ó sì jẹ fún ọdún mẹ́sàn-án.
Yahuda Kralı Ahaz'ın krallığının on ikinci yılında Ela oğlu Hoşea Samiriye'de İsrail Kralı oldu ve dokuz yıl krallık yaptı.
2 Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe bí i ti ọba Israẹli ẹni tí ó ti wà ṣáájú rẹ̀.
RAB'bin gözünde kötü olanı yaptı, ama kendisinden önceki İsrail kralları kadar kötü değildi.
3 Ṣalamaneseri ọba Asiria wá sókè láti mú Hosea, ẹni tí ó ti jẹ fún Ṣalamaneseri ó sì ti san owó òde fún un.
Asur Kralı Şalmaneser Hoşea'ya savaş açtı. Hoşea teslim olup haraç ödemeye başladı.
4 Ṣùgbọ́n ọba Asiria rí i wí pé Hosea jẹ́ ọlọ́tẹ̀, nítorí ó ti rán oníṣẹ́ sọ́dọ̀ ọba Ejibiti, kò sì san owó òde mọ́ fún ọba Asiria, gẹ́gẹ́ bí o ti máa ń ṣe ní ọdọọdún. Nígbà náà ọba Asiria fi agbára mú ún, ó sì fi sínú túbú.
Ancak Asur Kralı Hoşea'nın hainlik yaptığını öğrendi. Çünkü Hoşea Mısır Firavunu So'nun desteğini sağlamak için ona ulaklar göndermiş, üstelik her yıl ödemesi gereken haraçları da Asur Kralı'na ödememişti. Bunun üzerine Asur Kralı onu yakalayıp cezaevine kapadı.
5 Ọba Asiria gòkè wá sí gbogbo ibi ilé náà, ó sì lọ sí Samaria, ó sì dúró tí ì fún ọdún mẹ́ta.
Asur Kralı İsrail topraklarına saldırdı. Samiriye'yi kuşattı. Kuşatma üç yıl sürdü.
6 Ní ọdún kẹsànán ti Hosea, ọba Asiria mú Samaria ó sì kó Israẹli lọ sí Asiria. Ó sì fi wọ́n sílẹ̀ ní Hala, ní Gosani ní etí odò Habori àti ní ìlú àwọn ará Media.
Hoşea'nın krallığının dokuzuncu yılında Asur Kralı Samiriye'yi ele geçirdi. İsrail halkını Asur'a sürdü. Onları Halah'a, Habur Irmağı kıyısındaki Gozan'a ve Med kentlerine yerleştirdi.
7 Gbogbo eléyìí ṣẹlẹ̀ nítorí àwọn ọmọ Israẹli ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wọn, ẹni tí ó mú wọn jáde ní Ejibiti lábẹ́ agbára Farao ọba Ejibiti. Wọ́n sin ọlọ́run mìíràn,
Bütün bunlar kendilerini Mısır Firavunu'nun boyunduruğundan kurtarıp Mısır'dan çıkaran Tanrıları RAB'be karşı günah işledikleri için İsrailliler'in başına geldi. Çünkü başka ilahlara tapmışlar,
8 wọn si tẹ̀lé ìwà orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti gbá kúrò níwájú wọn gẹ́gẹ́ bí ìwà ti ọba Israẹli tí ó ti paláṣẹ.
RAB'bin İsrail halkının önünden kovmuş olduğu ulusların törelerine ve İsrail krallarının koyduğu kurallara göre yaşamışlardı.
9 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe ohun ìríra sí Olúwa Ọlọ́run wọn kọ́ láti ilé ìṣọ́ sí ìlú tí a dáàbò bò, wọ́n kọ́ ilé gíga fún ara wọn ní gbogbo ìlú wọn.
Tanrıları RAB'bin onaylamadığı bu işleri gizlilik içinde yapmışlar, gözcü kulelerinden surlu kentlere kadar her yerde tapınma yerleri kurmuşlardı.
10 Wọ́n sì gbé àwọn òkúta tí a yà sọ́tọ̀ sókè àti ère òrìṣà Aṣerah lórí gbogbo igi tútù.
Her yüksek tepenin üzerine, bol yapraklı her ağacın altına dikili taşlar, Aşera putları diktiler.
11 Ní gbogbo ibi gíga, wọ́n sun tùràrí gẹ́gẹ́ bí orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti lé jáde níwájú wọn. Wọ́n ṣe ohun búburú tí ó rú ìbínú Olúwa sókè.
RAB'bin onların önünden kovmuş olduğu ulusların yaptığı gibi, bütün tapınma yerlerinde buhur yaktılar. Yaptıkları kötülüklerle RAB'bi öfkelendirdiler.
12 Wọ́n sìn òrìṣà, èyí tí Olúwa ti sọ pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe èyí.”
RAB'bin, “Bunu yapmayacaksınız” demiş olmasına karşın putlara taptılar.
13 Olúwa kìlọ̀ fún Israẹli àti Juda nípa gbogbo àwọn wòlíì wọn àti aríran: “Ẹ yípadà kúrò ní ọ̀nà búburú yín. Kí ẹ ṣe òfin mi àti ìlànà mi, ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo òfin tí Èmi paláṣẹ fún àwọn baba yín láti tẹ̀lé àti èyí tí mo rán sí i yín nípa ìránṣẹ́ àwọn wòlíì mi.”
RAB İsrail ve Yahuda halkını bütün peygamberler ve biliciler aracılığıyla uyarmış, onlara, “Bu kötü yollarınızdan dönün” demişti, “Atalarınıza buyurduğum ve kullarım peygamberler aracılığıyla size gönderdiğim Kutsal Yasa'nın tümüne uyarak buyruklarımı, kurallarımı yerine getirin.”
14 Ṣùgbọ́n wọn kò ní gbọ́, wọ́n sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ọlọ́rùn líle gẹ́gẹ́ bí i ti baba wọn, ẹni tí kò gbà Olúwa Ọlọ́run wọn gbọ́.
Ama dinlemediler, Tanrıları RAB'be güvenmeyen ataları gibi inat ettiler.
15 Wọ́n kọ̀ ìlànà rẹ̀ àti májẹ̀mú tí ó ti ṣe pẹ̀lú baba wọn àti ìkìlọ̀ tí ó ti fi fún wọn. Wọ́n tẹ̀lé òrìṣà aláìníláárí, àwọn fún rara wọn sì jẹ́ aláìníláárí. Wọ́n tẹ̀lé orílẹ̀-èdè tí ó yí wọn ká bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa ti kìlọ̀ fún wọn pé, “Má ṣe ṣe gẹ́gẹ́ bí wọn tí ń ṣe,” wọ́n sì ṣe ohun tí Olúwa ti kà léèwọ̀ fún wọn láti ṣe.
Tanrı'nın kurallarını, uyarılarını ve atalarıyla yaptığı antlaşmayı hiçe sayarak değersiz putların ardınca gittiler, böylece kendi değerlerini de yitirdiler. Çevrelerindeki uluslar gibi yaşamamaları için RAB kendilerine buyruk verdiği halde, ulusların törelerine göre yaşadılar.
16 Wọ́n kọ̀ gbogbo òfin Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, wọ́n sì ṣe òrìṣà méjì fún ara wọn, wọ́n sì gbẹ́ ẹ ọ̀kan ní ère ẹgbọrọ màlúù, àti ọ̀kan ní ère òrìṣà Aṣerah. Wọ́n sì tẹrí wọn ba sí gbogbo ogun ọ̀run, wọ́n sì sin Baali.
Tanrıları RAB'bin bütün buyruklarını terk ettiler. Tapınmak için kendilerine iki dökme buzağı ve Aşera putu yaptırdılar. Gök cisimlerine taptılar. Baal'a kulluk ettiler.
17 Wọ́n sì fi àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn rú ẹbọ nínú iná. Wọ́n sì ń fọ àfọ̀ṣẹ, wọ́n sì ń ṣe àlúpàyídà wọ́n sì ta ara wọn láti ṣe ohun búburú níwájú Olúwa, wọ́n sì mú un bínú.
Oğullarını, kızlarını ateşte kurban ettiler. Falcılık, büyücülük yaptılar. RAB'bin gözünde kötü olanı yaptılar, kendilerini kötülüğe adayarak O'nu öfkelendirdiler.
18 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì bínú gidigidi pẹ̀lú Israẹli ó sì mú wọn kúrò níwájú rẹ̀. Ẹ̀yà Juda nìkan ṣoṣo ni ó kù,
RAB İsrailliler'e çok kızdı, Yahuda oymağı dışında hepsini huzurundan kovdu.
19 àti pẹ̀lú, Juda kò pa òfin Olúwa Ọlọ́run wọn mọ́. Wọ́n tẹ̀lé ìhùwàsí àwọn Israẹli tí wọ́n ṣe.
Yahudalılar bile Tanrıları RAB'bin buyruklarına uymadılar. İsrailliler'in benimsediği törelere göre yaşadılar.
20 Nítorí náà Olúwa kọ gbogbo àwọn ènìyàn Israẹli; ó sì jẹ wọ́n ní yà. Ó sì fi wọ́n lé ọwọ́ àwọn olè títí tí ó fi ta wọ́n nù kúrò níwájú rẹ̀.
Bundan dolayı RAB İsrail soyundan olan herkesi reddetti. Çapulcuların eline teslim ederek onları cezalandırdı. Hepsini huzurundan kovdu.
21 Nígbà tí ó ta Israẹli kúrò láti ìdílé Dafidi, wọ́n sì mú Jeroboamu ọmọ Nebati jẹ ọba wọn. Jeroboamu sì mú kí àwọn ọmọ Israẹli yípadà kúrò ní títẹ̀lé Olúwa, ó sí mú kí wọn dẹ́ṣẹ̀ ńlá.
RAB İsrail'i Davut soyunun elinden aldıktan sonra, İsrailliler Nevat oğlu Yarovam'ı kral yaptılar. Yarovam İsrailliler'i RAB'bin yolundan saptırarak büyük günaha sürükledi.
22 Àwọn ọmọ Israẹli forítì í nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu kò sì yí padà kúrò lọ́dọ̀ wọn,
İsrailliler Yarovam'ın işlediği bütün günahlara katıldılar ve bunlardan ayrılmadılar.
23 títí tí Olúwa fi mú wọn kúrò níwájú rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ó ti paláṣẹ láti ọ̀dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ wòlíì. Bẹ́ẹ̀ ni a kó gbogbo ènìyàn Israẹli kúrò ní ilẹ̀ wọn lọ sí ìgbèkùn ni Asiria, títí di òní yìí.
Sonunda RAB kulları peygamberler aracılığıyla uyarmış olduğu gibi, onları huzurundan kovdu. İsrailliler kendi topraklarından Asur'a sürüldüler. Bugün de orada yaşıyorlar.
24 Ọba Asiria mú àwọn ènìyàn láti Babeli, Kuta, Afa, Hamati àti Sefarfaimi, wọ́n sì fi wọ́n sínú ìlú Samaria láti rọ́pò àwọn ọmọ Israẹli. Wọ́n sì ń gbé ní ìlú náà.
Asur Kralı İsrailliler'in yerine Babil, Kuta, Avva, Hama ve Sefarvayim'den insanlar getirtip Samiriye kentlerine yerleştirdi. Bunlar Samiriye'yi mülk edinip oradaki kentlerde yaşamaya başladılar.
25 Nígbà tí wọ́n gbé bẹ̀ ní àkọ́kọ́, wọn kò sì bẹ̀rù Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni ó rán kìnnìún sí àárín wọn. Wọ́n sì pa nínú wọn.
Oralara ilk yerleştiklerinde RAB'be tapınmadılar. Bu yüzden RAB aslanlar göndererek bazılarını öldürttü.
26 Wọ́n sì sọ fún ọba Asiria pé, “Àwọn ènìyàn tí ìwọ lé kúrò tí o sì fi sínú ìlú Samaria kò mọ ohun tí ọlọ́run ìlú náà béèrè. Ó sì ti rán kìnnìún sí àárín wọn, tí ó sì ń pa wọ́n run, nítorí ènìyàn wọn kò mọ ohun tí ó béèrè.”
Asur Kralı'na, “Sürdüğün ve Samiriye kentlerine yerleştirdiğin uluslar Samiriye ilahının yasasını bilmiyorlar. O da üzerlerine aslanlar gönderiyor” diye haber salındı, “Bu yüzden aslanlara yem oluyorlar. Çünkü ülke ilahının yasasından haberleri yok.”
27 Nígbà náà ọba Asiria pàṣẹ yìí wí pé, “Mú ọ̀kan lára àwọn àlùfáà tí ó mú láti Samaria lọ padà gbé níbẹ̀ kí ó sì kọ́ àwọn ènìyàn ní, ohun tí ọlọ́run ilẹ̀ náà béèrè.”
Bunun üzerine Asur Kralı şu buyruğu verdi: “Samiriye'den sürülen kâhinlerden birini geri gönderin, gidip orada yaşasın ve ülke ilahının yasasını onlara öğretsin.”
28 Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kan lára àwọn àlùfáà tí ó ti kúrò ní Samaria wá gbé ní Beteli ó sì kọ́ wọn bí a ti ń sin Olúwa.
Samiriye'den sürülen kâhinlerden biri gelip Beytel'e yerleşti ve RAB'be nasıl tapınacaklarını onlara öğretmeye başladı.
29 Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, olúkúlùkù orílẹ̀-èdè ṣe òrìṣà tirẹ̀ ní gbogbo ìlú níbi tí wọ́n gbé wà, wọ́n sì gbé wọn nínú ilé òrìṣà àti àwọn ènìyàn Samaria ó sì ṣe wọ́n sí ibi gíga wọ̀n-ọn-nì.
Gelgelelim Samiriye kentlerine yerleşen her ulus kendi ilahlarını yaptı. Samiriyeliler'in yapmış olduğu tapınma yerlerindeki yapılara bu ilahları koydular.
30 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin láti Babeli ṣe àgọ́ àwọn wúńdíá, àwọn ènìyàn Kuti ṣe òrìṣà Nergali, àti àwọn ènìyàn Hamati ṣe ti Aṣima;
Babil halkı Sukkot-Benot, Kuta halkı Nergal, Hama halkı Aşima,
31 àti àwọn ará Afa ṣe Nibhasi àti Tartaki, àti àwọn ará Sefarfaimi sun àwọn ọmọ wọn níná gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sí Adrameleki àti Anameleki, àwọn òrìṣà Sefarfaimi.
Avva halkı ise Nivhaz ve Tartak adındaki ilahlarını yaptılar. Sefarvayim halkı ise oğullarını ilahları Adrammelek ve Anammelek'e yakarak kurban ettiler.
32 Wọ́n sin Olúwa, ṣùgbọ́n wọ́n sì tún yan gbogbo ẹgbẹ́ tí ènìyàn wọn láti ṣe iṣẹ́ oyè fún wọn gẹ́gẹ́ bí àlùfáà ní ibi gíga.
Bir yandan RAB'be tapınıyor, öte yandan tapınma yerlerindeki yapılarda görev yapmak üzere aralarından rasgele kâhinler seçiyorlardı.
33 Wọ́n sin Olúwa ṣùgbọ́n wọ́n sin òrìṣà wọn ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú àṣà orílẹ̀-èdè wọn láti ibi tí wọ́n ti gbé wọn wá.
Böylece hem RAB'be tapınıyorlar, hem de aralarından geldikleri ulusların törelerine göre kendi ilahlarına kulluk ediyorlardı.
34 Láti ìgbà náà wá àwọn àlùfáà wọn ṣe bí ti àtẹ̀yìnwá. Wọn kò sin Olúwa tàbí kí wọ́n fi ara mọ́ ìlànà àti àṣẹ àti òfin tí Olúwa fi fún ìránṣẹ́ Jakọbu, tí wọ́n pe orúkọ rẹ̀ ní Israẹli.
Bugün de eski törelerine göre yaşıyorlar. Ne RAB'be tapınıyorlar, ne de RAB'bin İsrail adını verdiği Yakup'un oğulları için koymuş olduğu kurallara, ilkelere, yasalara, buyruklara uyuyorlar.
35 Nígbà tí Olúwa ṣe májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ó pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ má ṣe sin òrìṣà mìíràn tàbí tẹríba fún wọn, sìn wọ́n tàbí kí ẹ rú ẹbọ sí wọn.
RAB Yakupoğulları'yla antlaşma yapmış ve onlara şöyle buyurmuştu: “Başka ilahlara tapmayacak, önlerinde eğilmeyecek, onlara kulluk etmeyecek, kurban kesmeyeceksiniz.
36 Ṣùgbọ́n Olúwa, ẹni tí ó mú yín gòkè jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú agbára ńlá àti nínà apá, òun ni ẹni náà tí ó yẹ kí ẹ sìn. Òun ni ẹni tí ó yẹ kí ẹ tẹríba fún àti sí òun ni kí ẹ rú ẹbọ fún.
Yalnızca ulu gücüyle her yere erişen eliyle sizleri Mısır'dan çıkaran RAB'be tapınacaksınız. O'nun önünde eğilip O'na kurban keseceksiniz.
37 Ó yẹ kí ẹ̀yin kí ó máa kíyèsi ara yín gidigidi láti pa ìlànà àti àṣẹ, àti òfin tí ó kọ fún un yín mọ́. Ẹ má ṣe sin ọlọ́run mìíràn.
Sizler için yazmış olduğu kuralları, ilkeleri, yasaları, buyrukları her zaman yerine getirmeye özen gösterecek ve başka ilahlara tapmayacaksınız.
38 Ẹ má ṣe gbàgbé májẹ̀mú tí mo ti ṣe pẹ̀lú yín mọ́ àti kí ẹ má sin ọlọ́run mìíràn.
Sizinle yaptığım antlaşmayı unutmayacak ve başka ilahlara tapmayacaksınız.
39 Kúkú sin Olúwa Ọlọ́run rẹ; Òun ni ẹni náà tí yóò gbà yín kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá a yín.”
Yalnız Tanrınız RAB'be tapacaksınız. O sizi bütün düşmanlarınızın elinden kurtaracak.”
40 Wọn kò ní gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni, wọ́n sì ń ṣe iṣẹ́ wọ́n ti àtijọ́.
Ne var ki Samiriye'ye yerleşenler buna kulak asmadılar ve eski törelerine göre yaşamaya devam ettiler.
41 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn wọn sin Olúwa, wọ́n sì ń sin òrìṣà wọn. Títí di ọjọ́ òní ọmọ wọn àti àwọn ọmọ ọmọ wọn sì ń ṣe bí àwọn baba wọn ti ń ṣe.
Bu uluslar aynı zamanda hem RAB'be, hem de putlarına tapıyorlardı. Çocukları ve torunları da bugüne dek ataları gibi yaşıyorlar.

< 2 Kings 17 >