< 2 Kings 17 >

1 Ní ọdún kejìlá ọba Ahasi ará Juda, Hosea ọmọ Ela jẹ ọba Israẹli ní Samaria, ó sì jẹ fún ọdún mẹ́sàn-án.
În al doisprezecelea an al lui Ahaz, împăratul lui Iuda, a început Osea, fiul lui Ela, să domnească în Samaria peste Israel; și a domnit nouă ani.
2 Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe bí i ti ọba Israẹli ẹni tí ó ti wà ṣáájú rẹ̀.
Și a făcut ce este rău înaintea ochilor DOMNULUI, dar nu ca împărații lui Israel care fuseseră înaintea lui.
3 Ṣalamaneseri ọba Asiria wá sókè láti mú Hosea, ẹni tí ó ti jẹ fún Ṣalamaneseri ó sì ti san owó òde fún un.
Împotriva lui s-a urcat Salmanasar, împăratul Asiriei; și Osea a devenit servitorul lui și i-a dăruit daruri.
4 Ṣùgbọ́n ọba Asiria rí i wí pé Hosea jẹ́ ọlọ́tẹ̀, nítorí ó ti rán oníṣẹ́ sọ́dọ̀ ọba Ejibiti, kò sì san owó òde mọ́ fún ọba Asiria, gẹ́gẹ́ bí o ti máa ń ṣe ní ọdọọdún. Nígbà náà ọba Asiria fi agbára mú ún, ó sì fi sínú túbú.
Și împăratul Asiriei a aflat de o uneltire a lui Osea, pentru că trimisese mesageri la So, împăratul Egiptului, și nu adusese niciun dar împăratului Asiriei, precum făcuse an de an; de aceea împăratul Asiriei l-a închis și l-a legat în închisoare.
5 Ọba Asiria gòkè wá sí gbogbo ibi ilé náà, ó sì lọ sí Samaria, ó sì dúró tí ì fún ọdún mẹ́ta.
Atunci împăratul Asiriei a venit în toată țara și s-a urcat la Samaria și a asediat-o trei ani.
6 Ní ọdún kẹsànán ti Hosea, ọba Asiria mú Samaria ó sì kó Israẹli lọ sí Asiria. Ó sì fi wọ́n sílẹ̀ ní Hala, ní Gosani ní etí odò Habori àti ní ìlú àwọn ará Media.
În anul al nouălea al lui Osea, împăratul Asiriei a luat Samaria și a dus pe Israel în Asiria, și i-a pus în Halah și în Habor lângă râul Gozan și în cetățile mezilor.
7 Gbogbo eléyìí ṣẹlẹ̀ nítorí àwọn ọmọ Israẹli ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wọn, ẹni tí ó mú wọn jáde ní Ejibiti lábẹ́ agbára Farao ọba Ejibiti. Wọ́n sin ọlọ́run mìíràn,
Și a fost astfel, deoarece copiii lui Israel păcătuiseră împotriva DOMNULUI Dumnezeul lor, care îi scosese din țara Egiptului, de sub mâna lui Faraon împăratul Egiptului, și s-au temut de alți dumnezei,
8 wọn si tẹ̀lé ìwà orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti gbá kúrò níwájú wọn gẹ́gẹ́ bí ìwà ti ọba Israẹli tí ó ti paláṣẹ.
Și au umblat în statutele păgânilor, pe care DOMNUL îi alungase dinaintea copiilor lui Israel, și în ale împăraților lui Israel, pe care ei le făcuseră.
9 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe ohun ìríra sí Olúwa Ọlọ́run wọn kọ́ láti ilé ìṣọ́ sí ìlú tí a dáàbò bò, wọ́n kọ́ ilé gíga fún ara wọn ní gbogbo ìlú wọn.
Și copiii lui Israel au făcut în ascuns acele lucruri care nu erau drepte, împotriva DOMNULUI Dumnezeul lor, și și-au zidit înălțimi în toate cetățile lor, de la turnul paznicilor până la cetatea întărită.
10 Wọ́n sì gbé àwọn òkúta tí a yà sọ́tọ̀ sókè àti ère òrìṣà Aṣerah lórí gbogbo igi tútù.
Și și-au înălțat chipuri și dumbrăvi pe fiecare deal înalt și sub fiecare copac verde;
11 Ní gbogbo ibi gíga, wọ́n sun tùràrí gẹ́gẹ́ bí orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti lé jáde níwájú wọn. Wọ́n ṣe ohun búburú tí ó rú ìbínú Olúwa sókè.
Și acolo au ars tămâie pe toate înălțimile, precum au făcut păgânii pe care DOMNUL îi îndepărtase dinaintea lor; și au lucrat lucruri stricate pentru a-l provoca pe DOMNUL la mânie;
12 Wọ́n sìn òrìṣà, èyí tí Olúwa ti sọ pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe èyí.”
Fiindcă au servit idolilor, despre care DOMNUL le spusese: Să nu faceți acest lucru.
13 Olúwa kìlọ̀ fún Israẹli àti Juda nípa gbogbo àwọn wòlíì wọn àti aríran: “Ẹ yípadà kúrò ní ọ̀nà búburú yín. Kí ẹ ṣe òfin mi àti ìlànà mi, ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo òfin tí Èmi paláṣẹ fún àwọn baba yín láti tẹ̀lé àti èyí tí mo rán sí i yín nípa ìránṣẹ́ àwọn wòlíì mi.”
Totuși, DOMNUL a mărturisit împotriva lui Israel și împotriva lui Iuda prin toți profeții și prin toți văzătorii, spunând: Întoarceți-vă de la căile voastre rele și țineți poruncile mele și statutele mele, conform cu toată legea pe care am poruncit-o părinților voștri și pe care v-am trimis-o prin servitorii mei, profeții.
14 Ṣùgbọ́n wọn kò ní gbọ́, wọ́n sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ọlọ́rùn líle gẹ́gẹ́ bí i ti baba wọn, ẹni tí kò gbà Olúwa Ọlọ́run wọn gbọ́.
Cu toate acestea ei au refuzat să asculte și și-au împietrit gâturile, ca gâtul părinților lor, care nu au crezut în DOMNUL Dumnezeul lor.
15 Wọ́n kọ̀ ìlànà rẹ̀ àti májẹ̀mú tí ó ti ṣe pẹ̀lú baba wọn àti ìkìlọ̀ tí ó ti fi fún wọn. Wọ́n tẹ̀lé òrìṣà aláìníláárí, àwọn fún rara wọn sì jẹ́ aláìníláárí. Wọ́n tẹ̀lé orílẹ̀-èdè tí ó yí wọn ká bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa ti kìlọ̀ fún wọn pé, “Má ṣe ṣe gẹ́gẹ́ bí wọn tí ń ṣe,” wọ́n sì ṣe ohun tí Olúwa ti kà léèwọ̀ fún wọn láti ṣe.
Și au respins statutele lui și legământul lui pe care îl făcuse cu părinții lor și mărturiile lui pe care el le-a mărturisit împotriva lor; și au urmărit deșertăciune și au devenit deșertăciune și au mers după păgânii care erau de jur împrejurul lor, referitor la care DOMNUL le poruncise să nu facă asemenea lor.
16 Wọ́n kọ̀ gbogbo òfin Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, wọ́n sì ṣe òrìṣà méjì fún ara wọn, wọ́n sì gbẹ́ ẹ ọ̀kan ní ère ẹgbọrọ màlúù, àti ọ̀kan ní ère òrìṣà Aṣerah. Wọ́n sì tẹrí wọn ba sí gbogbo ogun ọ̀run, wọ́n sì sin Baali.
Și au părăsit toate poruncile DOMNULUI Dumnezeul lor și și-au făcut chipuri turnate, doi viței, și au făcut o dumbravă și s-au închinat la toată oștirea cerului și i-au servit lui Baal.
17 Wọ́n sì fi àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn rú ẹbọ nínú iná. Wọ́n sì ń fọ àfọ̀ṣẹ, wọ́n sì ń ṣe àlúpàyídà wọ́n sì ta ara wọn láti ṣe ohun búburú níwájú Olúwa, wọ́n sì mú un bínú.
Și au făcut pe fiii și pe fiicele lor să treacă prin foc și au folosit ghicire și descântare și s-au vândut pentru a face rău înaintea ochilor DOMNULUI, ca să îl provoace la mânie.
18 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì bínú gidigidi pẹ̀lú Israẹli ó sì mú wọn kúrò níwájú rẹ̀. Ẹ̀yà Juda nìkan ṣoṣo ni ó kù,
De aceea DOMNUL s-a mâniat foarte tare pe Israel și i-a îndepărtat dinaintea vederii sale; a rămas numai tribul lui Iuda.
19 àti pẹ̀lú, Juda kò pa òfin Olúwa Ọlọ́run wọn mọ́. Wọ́n tẹ̀lé ìhùwàsí àwọn Israẹli tí wọ́n ṣe.
Și nici Iuda nu a ținut poruncile DOMNULUI Dumnezeul lor, ci au umblat în statutele lui Israel pe care ei le făcuseră.
20 Nítorí náà Olúwa kọ gbogbo àwọn ènìyàn Israẹli; ó sì jẹ wọ́n ní yà. Ó sì fi wọ́n lé ọwọ́ àwọn olè títí tí ó fi ta wọ́n nù kúrò níwájú rẹ̀.
Și DOMNUL a respins toată sămânța lui Israel și i-a chinuit și i-a dat în mâna prădătorilor, până i-a aruncat dinaintea feței sale.
21 Nígbà tí ó ta Israẹli kúrò láti ìdílé Dafidi, wọ́n sì mú Jeroboamu ọmọ Nebati jẹ ọba wọn. Jeroboamu sì mú kí àwọn ọmọ Israẹli yípadà kúrò ní títẹ̀lé Olúwa, ó sí mú kí wọn dẹ́ṣẹ̀ ńlá.
Pentru că a rupt pe Israel de la casa lui David; și ei l-au făcut pe Ieroboam, fiul lui Nebat, împărat; și Ieroboam a mânat pe Israel de la a-l urma pe DOMNUL și i-a făcut să păcătuiască un mare păcat.
22 Àwọn ọmọ Israẹli forítì í nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu kò sì yí padà kúrò lọ́dọ̀ wọn,
Deoarece copiii lui Israel au umblat în toate păcatele pe care Ieroboam le-a făcut; ei nu s-au depărtat de ele;
23 títí tí Olúwa fi mú wọn kúrò níwájú rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ó ti paláṣẹ láti ọ̀dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ wòlíì. Bẹ́ẹ̀ ni a kó gbogbo ènìyàn Israẹli kúrò ní ilẹ̀ wọn lọ sí ìgbèkùn ni Asiria, títí di òní yìí.
Până când DOMNUL a îndepărtat pe Israel dinaintea feței sale, precum spusese prin toți servitorii săi, profeții. Astfel a fost Israel dus din propria lor țară în Asiria până în această zi.
24 Ọba Asiria mú àwọn ènìyàn láti Babeli, Kuta, Afa, Hamati àti Sefarfaimi, wọ́n sì fi wọ́n sínú ìlú Samaria láti rọ́pò àwọn ọmọ Israẹli. Wọ́n sì ń gbé ní ìlú náà.
Și împăratul Asiriei a adus oameni din Babilon și de la Cuta și de la Ava și de la Hamat și de la Sefarvaim și i-a pus în cetățile Samariei, în locul copiilor lui Israel; și ei au stăpânit Samaria și au locuit în cetățile ei.
25 Nígbà tí wọ́n gbé bẹ̀ ní àkọ́kọ́, wọn kò sì bẹ̀rù Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni ó rán kìnnìún sí àárín wọn. Wọ́n sì pa nínú wọn.
Și astfel a fost la începutul locuirii lor acolo, că ei nu se temeau de DOMNUL; de aceea DOMNUL a trimis lei printre ei, care au omorât pe unii dintre ei.
26 Wọ́n sì sọ fún ọba Asiria pé, “Àwọn ènìyàn tí ìwọ lé kúrò tí o sì fi sínú ìlú Samaria kò mọ ohun tí ọlọ́run ìlú náà béèrè. Ó sì ti rán kìnnìún sí àárín wọn, tí ó sì ń pa wọ́n run, nítorí ènìyàn wọn kò mọ ohun tí ó béèrè.”
Pentru aceea i-au vorbit împăratului Asiriei, spunând: Națiunile pe care le-ai îndepărtat și le-ai pus în cetățile Samariei, nu cunosc obiceiul Dumnezeului țării; de aceea el a trimis lei printre ei și, iată, îi ucid, pentru că nu cunosc obiceiul Dumnezeului țării.
27 Nígbà náà ọba Asiria pàṣẹ yìí wí pé, “Mú ọ̀kan lára àwọn àlùfáà tí ó mú láti Samaria lọ padà gbé níbẹ̀ kí ó sì kọ́ àwọn ènìyàn ní, ohun tí ọlọ́run ilẹ̀ náà béèrè.”
Atunci împăratul Asiriei a poruncit, spunând: Duceți acolo pe unul dintre preoții pe care i-ați adus de acolo; și ei să meargă și să locuiască acolo și el să îi învețe obiceiul Dumnezeului țării.
28 Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kan lára àwọn àlùfáà tí ó ti kúrò ní Samaria wá gbé ní Beteli ó sì kọ́ wọn bí a ti ń sin Olúwa.
Atunci unul dintre preoții pe care îi duseseră din Samaria a venit și a locuit în Betel și i-a învățat cum să se teamă de DOMNUL.
29 Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, olúkúlùkù orílẹ̀-èdè ṣe òrìṣà tirẹ̀ ní gbogbo ìlú níbi tí wọ́n gbé wà, wọ́n sì gbé wọn nínú ilé òrìṣà àti àwọn ènìyàn Samaria ó sì ṣe wọ́n sí ibi gíga wọ̀n-ọn-nì.
Totuși, fiecare națiune și-a făcut dumnezeii săi și i-a pus în casele înălțimilor pe care samaritenii le făcuseră, fiecare națiune în cetățile unde locuia.
30 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin láti Babeli ṣe àgọ́ àwọn wúńdíá, àwọn ènìyàn Kuti ṣe òrìṣà Nergali, àti àwọn ènìyàn Hamati ṣe ti Aṣima;
Și oamenii din Babilon au făcut pe Sucot-Benot, și oamenii din Cut au făcut pe Nergal, și oamenii din Hamat au făcut pe Așima,
31 àti àwọn ará Afa ṣe Nibhasi àti Tartaki, àti àwọn ará Sefarfaimi sun àwọn ọmọ wọn níná gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sí Adrameleki àti Anameleki, àwọn òrìṣà Sefarfaimi.
Și aviții au făcut pe Nibhaz și pe Tartac, și sefarviții au ars pe copiii lor în foc lui Adramelec și lui Anamelec, dumnezeii sefarviților.
32 Wọ́n sin Olúwa, ṣùgbọ́n wọ́n sì tún yan gbogbo ẹgbẹ́ tí ènìyàn wọn láti ṣe iṣẹ́ oyè fún wọn gẹ́gẹ́ bí àlùfáà ní ibi gíga.
Astfel, ei s-au temut de DOMNUL și și-au făcut din oamenii cei mai de jos preoți ai înălțimilor, care sacrificau pentru ei în casele înălțimilor.
33 Wọ́n sin Olúwa ṣùgbọ́n wọ́n sin òrìṣà wọn ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú àṣà orílẹ̀-èdè wọn láti ibi tí wọ́n ti gbé wọn wá.
S-au temut de DOMNUL și au servit propriilor lor dumnezei, după obiceiul națiunilor pe care le duseseră de aici.
34 Láti ìgbà náà wá àwọn àlùfáà wọn ṣe bí ti àtẹ̀yìnwá. Wọn kò sin Olúwa tàbí kí wọ́n fi ara mọ́ ìlànà àti àṣẹ àti òfin tí Olúwa fi fún ìránṣẹ́ Jakọbu, tí wọ́n pe orúkọ rẹ̀ ní Israẹli.
Până în această zi ei fac după obiceiurile dinainte; nu se tem de DOMNUL, nici nu fac după statutele lor, sau după rânduielile lor, sau după legea și porunca pe care DOMNUL a poruncit-o copiilor lui Iacob, pe care l-a numit Israel.
35 Nígbà tí Olúwa ṣe májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ó pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ má ṣe sin òrìṣà mìíràn tàbí tẹríba fún wọn, sìn wọ́n tàbí kí ẹ rú ẹbọ sí wọn.
Cu care DOMNUL făcuse un legământ și le poruncise, spunând: Să nu vă temeți de alți dumnezei și să nu vă prosternați lor, nici să nu le serviți, nici să nu le sacrificați;
36 Ṣùgbọ́n Olúwa, ẹni tí ó mú yín gòkè jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú agbára ńlá àti nínà apá, òun ni ẹni náà tí ó yẹ kí ẹ sìn. Òun ni ẹni tí ó yẹ kí ẹ tẹríba fún àti sí òun ni kí ẹ rú ẹbọ fún.
Ci de DOMNUL, care v-a scos din țara Egiptului cu putere mare și cu un braț întins, de el să vă temeți și lui să vă închinați și lui să îi sacrificați.
37 Ó yẹ kí ẹ̀yin kí ó máa kíyèsi ara yín gidigidi láti pa ìlànà àti àṣẹ, àti òfin tí ó kọ fún un yín mọ́. Ẹ má ṣe sin ọlọ́run mìíràn.
Și statutele și rânduielile și legea și porunca pe care el le-a scris pentru voi să le țineți pentru a le face pentru totdeauna; și să nu vă temeți de alți dumnezei.
38 Ẹ má ṣe gbàgbé májẹ̀mú tí mo ti ṣe pẹ̀lú yín mọ́ àti kí ẹ má sin ọlọ́run mìíràn.
Și legământul pe care l-am făcut cu voi să nu îl uitați; nici să nu vă temeți de alți dumnezei.
39 Kúkú sin Olúwa Ọlọ́run rẹ; Òun ni ẹni náà tí yóò gbà yín kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá a yín.”
Ci de DOMNUL Dumnezeul vostru să vă temeți; și el vă va elibera din mâna tuturor dușmanilor voștri.
40 Wọn kò ní gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni, wọ́n sì ń ṣe iṣẹ́ wọ́n ti àtijọ́.
Totuși ei nu au dat ascultare, ci au făcut după obiceiul lor de dinainte.
41 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn wọn sin Olúwa, wọ́n sì ń sin òrìṣà wọn. Títí di ọjọ́ òní ọmọ wọn àti àwọn ọmọ ọmọ wọn sì ń ṣe bí àwọn baba wọn ti ń ṣe.
Astfel, aceste națiuni se temeau și de DOMNUL și serveau și chipurilor lor cioplite, deopotrivă copiii lor și copiii copiilor lor; precum au făcut părinții lor, astfel fac ei până în această zi.

< 2 Kings 17 >