< 2 Kings 17 >

1 Ní ọdún kejìlá ọba Ahasi ará Juda, Hosea ọmọ Ela jẹ ọba Israẹli ní Samaria, ó sì jẹ fún ọdún mẹ́sàn-án.
Roku dwunastego Achaza, króla Judzkiego, królował Ozeasz, syn Eli, w Samaryi nad Izraelem dziewięć lat.
2 Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe bí i ti ọba Israẹli ẹni tí ó ti wà ṣáájú rẹ̀.
I czynił złe przed oczyma Pańskiemi, wszakże nie tak jak inni królowie Izraelscy, którzy byli przed nim.
3 Ṣalamaneseri ọba Asiria wá sókè láti mú Hosea, ẹni tí ó ti jẹ fún Ṣalamaneseri ó sì ti san owó òde fún un.
Przeciwko niemu wyciągnął Salmanasar, król Assyryjski; i stał się Ozeasz niewolnikiem jego, i dawał mu dań.
4 Ṣùgbọ́n ọba Asiria rí i wí pé Hosea jẹ́ ọlọ́tẹ̀, nítorí ó ti rán oníṣẹ́ sọ́dọ̀ ọba Ejibiti, kò sì san owó òde mọ́ fún ọba Asiria, gẹ́gẹ́ bí o ti máa ń ṣe ní ọdọọdún. Nígbà náà ọba Asiria fi agbára mú ún, ó sì fi sínú túbú.
A gdy obaczył król Assyryjski, iż się Ozeasz buntował przeciw niemu, a iż wyprawił posły do Sua, króla Egipskiego, i nie posyłał dani dorocznej królowi Assyryjskiemu, obległ go król Assyryjski, a związawszy podał go do więzienia.
5 Ọba Asiria gòkè wá sí gbogbo ibi ilé náà, ó sì lọ sí Samaria, ó sì dúró tí ì fún ọdún mẹ́ta.
I ciągnął król Assyryjski przez wszystkę ziemię, aż przyciągnął do Samaryi, pod którą leżał przez trzy lata.
6 Ní ọdún kẹsànán ti Hosea, ọba Asiria mú Samaria ó sì kó Israẹli lọ sí Asiria. Ó sì fi wọ́n sílẹ̀ ní Hala, ní Gosani ní etí odò Habori àti ní ìlú àwọn ará Media.
A roku dziewiątego Ozeasza wziął król Assyryjski Samaryję, i przeniósł Izraela do Assyryi, a osadził je w Hala i w Habor nad rzeką Gozan i w miastach Medskich.
7 Gbogbo eléyìí ṣẹlẹ̀ nítorí àwọn ọmọ Israẹli ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wọn, ẹni tí ó mú wọn jáde ní Ejibiti lábẹ́ agbára Farao ọba Ejibiti. Wọ́n sin ọlọ́run mìíràn,
A to się stało przeto, że grzeszyli synowie Izraelscy przeciw Panu, Bogu swemu, który je wywiódł z ziemi Egipskiej, aby nie byli pod mocą Faraona, króla Egipskiego; a bali się bogów cudzych,
8 wọn si tẹ̀lé ìwà orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti gbá kúrò níwájú wọn gẹ́gẹ́ bí ìwà ti ọba Israẹli tí ó ti paláṣẹ.
Chodząc w ustawach poganów, które był Pan wyrzucił przed obliczem synów Izraelskich, i w ustawach królów Izraelskich, które czynili.
9 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe ohun ìríra sí Olúwa Ọlọ́run wọn kọ́ láti ilé ìṣọ́ sí ìlú tí a dáàbò bò, wọ́n kọ́ ilé gíga fún ara wọn ní gbogbo ìlú wọn.
Obłudnie synowie Izraelscy postępowali, czyniąc co nie było rzeczą dobrą przed Panem, Bogiem swym, i pobudowali sobie wyżyny po wszystkich miastach swych, od wieży strażników aż do miasta obronnego;
10 Wọ́n sì gbé àwọn òkúta tí a yà sọ́tọ̀ sókè àti ère òrìṣà Aṣerah lórí gbogbo igi tútù.
A nastawiali sobie słupów, i gajów na każdym pagórku wyniosłym, pod każdem drzewem gałęzistem,
11 Ní gbogbo ibi gíga, wọ́n sun tùràrí gẹ́gẹ́ bí orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti lé jáde níwájú wọn. Wọ́n ṣe ohun búburú tí ó rú ìbínú Olúwa sókè.
Paląc tam kadzidła po wszystkich górach, jako narody, które wypędził Pan przed obliczem ich; i czynili rzeczy co najgorsze, pobudzając Pana ku gniewu,
12 Wọ́n sìn òrìṣà, èyí tí Olúwa ti sọ pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe èyí.”
A służyli brzydkim bałwanom, o którym im powiedział Pan, aby tego nie czynili.
13 Olúwa kìlọ̀ fún Israẹli àti Juda nípa gbogbo àwọn wòlíì wọn àti aríran: “Ẹ yípadà kúrò ní ọ̀nà búburú yín. Kí ẹ ṣe òfin mi àti ìlànà mi, ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo òfin tí Èmi paláṣẹ fún àwọn baba yín láti tẹ̀lé àti èyí tí mo rán sí i yín nípa ìránṣẹ́ àwọn wòlíì mi.”
I oświadczał się Pan przeciwko Izraelowi, i przeciwko Judzie, przez wszystkie proroki, i przez wszystkie widzące, mówiąc: Nawróćcie się od dróg waszych złych, a strzeżcie rozkazania mego, i wyroków moich według wszystkiego zakonu, którym rozkazał ojcom waszym, a z którymem posłał do was proroki, sługi moje.
14 Ṣùgbọ́n wọn kò ní gbọ́, wọ́n sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ọlọ́rùn líle gẹ́gẹ́ bí i ti baba wọn, ẹni tí kò gbà Olúwa Ọlọ́run wọn gbọ́.
Lecz nie byli posłuszni; ale zatwardzili kark swój według karku ojców swych, którzy nie wierzyli w Pana, Boga swego.
15 Wọ́n kọ̀ ìlànà rẹ̀ àti májẹ̀mú tí ó ti ṣe pẹ̀lú baba wọn àti ìkìlọ̀ tí ó ti fi fún wọn. Wọ́n tẹ̀lé òrìṣà aláìníláárí, àwọn fún rara wọn sì jẹ́ aláìníláárí. Wọ́n tẹ̀lé orílẹ̀-èdè tí ó yí wọn ká bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa ti kìlọ̀ fún wọn pé, “Má ṣe ṣe gẹ́gẹ́ bí wọn tí ń ṣe,” wọ́n sì ṣe ohun tí Olúwa ti kà léèwọ̀ fún wọn láti ṣe.
I wzgardzili wyroki jego, i przymierze jego, które uczynił z ojcami ich, i oświadczenia jego, któremi się oświadczał przeciwko nim, a chodzili za próżnością, i stali się próżnymi, i naśladowali poganów, którzy byli około nich, o których im rozkazał Pan, aby nie czynili jako oni.
16 Wọ́n kọ̀ gbogbo òfin Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, wọ́n sì ṣe òrìṣà méjì fún ara wọn, wọ́n sì gbẹ́ ẹ ọ̀kan ní ère ẹgbọrọ màlúù, àti ọ̀kan ní ère òrìṣà Aṣerah. Wọ́n sì tẹrí wọn ba sí gbogbo ogun ọ̀run, wọ́n sì sin Baali.
I opuściwszy wszystkie rozkazania Pana, Boga swego, poczynili sobie lane bałwany, mianowicie dwóch cielców; poczynili też gaje, a kłaniali się wszystkiemu wojsku niebieskiemu, i służyli Baalowi.
17 Wọ́n sì fi àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn rú ẹbọ nínú iná. Wọ́n sì ń fọ àfọ̀ṣẹ, wọ́n sì ń ṣe àlúpàyídà wọ́n sì ta ara wọn láti ṣe ohun búburú níwájú Olúwa, wọ́n sì mú un bínú.
Przewodzili też syny i córki swe przez ogień, i bawili się wieszczbami i wróżkami, i zaprzedali się, aby czynili złe przed oczyma Pańskiemi, pobudzając go do gniewu.
18 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì bínú gidigidi pẹ̀lú Israẹli ó sì mú wọn kúrò níwájú rẹ̀. Ẹ̀yà Juda nìkan ṣoṣo ni ó kù,
Przetoż się bardzo Pan rozgniewał na Izraela, a odrzucił je od oblicza swego, nic z nich nie zostawując, oprócz samego pokolenia Judy.
19 àti pẹ̀lú, Juda kò pa òfin Olúwa Ọlọ́run wọn mọ́. Wọ́n tẹ̀lé ìhùwàsí àwọn Israẹli tí wọ́n ṣe.
Aleć i Juda nie strzegł przykazań Pana, Boga swego; lecz chodził w ustawach Izaelskich, których naczynili.
20 Nítorí náà Olúwa kọ gbogbo àwọn ènìyàn Israẹli; ó sì jẹ wọ́n ní yà. Ó sì fi wọ́n lé ọwọ́ àwọn olè títí tí ó fi ta wọ́n nù kúrò níwájú rẹ̀.
Przetoż odrzucił Pan wszystko nasienie Izraelskie, i utrapił je, a podał je w rękę łupieżcom, aż je odrzucił od oblicza swego.
21 Nígbà tí ó ta Israẹli kúrò láti ìdílé Dafidi, wọ́n sì mú Jeroboamu ọmọ Nebati jẹ ọba wọn. Jeroboamu sì mú kí àwọn ọmọ Israẹli yípadà kúrò ní títẹ̀lé Olúwa, ó sí mú kí wọn dẹ́ṣẹ̀ ńlá.
Albowiem oderwał się Izrael od domu Dawidowego, a postanowili królem Jeroboama, syna Nabatowego; ale Jeroboam odwiódł Izraela od naśladowania Pana, a przywiódł je do grzeszenia grzechem wielkim.
22 Àwọn ọmọ Israẹli forítì í nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu kò sì yí padà kúrò lọ́dọ̀ wọn,
I chodzili synowie Izraelscy we wszystkich grzechach Jeroboamowych, które on czynił, a nie odstąpili od nich,
23 títí tí Olúwa fi mú wọn kúrò níwájú rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ó ti paláṣẹ láti ọ̀dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ wòlíì. Bẹ́ẹ̀ ni a kó gbogbo ènìyàn Israẹli kúrò ní ilẹ̀ wọn lọ sí ìgbèkùn ni Asiria, títí di òní yìí.
A odrzucił Pan Izraela od oblicza swego, jako powiedział przez wszystkie sługi swe proroki; a tak przeniesiony jest Izrael z ziemi swej do Assyryi, aż do dnia tego.
24 Ọba Asiria mú àwọn ènìyàn láti Babeli, Kuta, Afa, Hamati àti Sefarfaimi, wọ́n sì fi wọ́n sínú ìlú Samaria láti rọ́pò àwọn ọmọ Israẹli. Wọ́n sì ń gbé ní ìlú náà.
Potem przyprowadził król Assyryjski lud z Babilonu, i z Kuta, i z Awa, i z Emat, i z Sefarwaim, a osadził je w miastach Samaryi miasto synów Izraelskch; którzy posiadłszy Samaryję, mieszkali w miastach jej.
25 Nígbà tí wọ́n gbé bẹ̀ ní àkọ́kọ́, wọn kò sì bẹ̀rù Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni ó rán kìnnìún sí àárín wọn. Wọ́n sì pa nínú wọn.
A gdy tam oni mieszkać poczęli a nie bali się Pana, posłał Pan na nie lwy, którzy je zabijali.
26 Wọ́n sì sọ fún ọba Asiria pé, “Àwọn ènìyàn tí ìwọ lé kúrò tí o sì fi sínú ìlú Samaria kò mọ ohun tí ọlọ́run ìlú náà béèrè. Ó sì ti rán kìnnìún sí àárín wọn, tí ó sì ń pa wọ́n run, nítorí ènìyàn wọn kò mọ ohun tí ó béèrè.”
I powiedziano to królowi Assyryjskiemu, mówiąc: Narodowie, któreś przeniósł i osadził w miastach Samaryi, nie wiedzą obyczaju Boga onej ziemi; przetoż posłał na nie lwy, a oto je zabijają, dla tego, iż nie wiedzą obyczaju Boga onej ziemi.
27 Nígbà náà ọba Asiria pàṣẹ yìí wí pé, “Mú ọ̀kan lára àwọn àlùfáà tí ó mú láti Samaria lọ padà gbé níbẹ̀ kí ó sì kọ́ àwọn ènìyàn ní, ohun tí ọlọ́run ilẹ̀ náà béèrè.”
Tedy rozkazał król Assyryjski, mówiąc: Zawiedźcie tam jednego z kapłanów, któreście stamtąd przywiedli, aby poszedłszy mieszkał tam, i nauczał ich obyczaju Boga onej ziemi.
28 Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kan lára àwọn àlùfáà tí ó ti kúrò ní Samaria wá gbé ní Beteli ó sì kọ́ wọn bí a ti ń sin Olúwa.
Przyszedł tedy jeden z kapłanów, których było wzięto z Samryi, i mieszkał w Betel, a nauczał ich, jako się mieli bać Pana.
29 Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, olúkúlùkù orílẹ̀-èdè ṣe òrìṣà tirẹ̀ ní gbogbo ìlú níbi tí wọ́n gbé wà, wọ́n sì gbé wọn nínú ilé òrìṣà àti àwọn ènìyàn Samaria ó sì ṣe wọ́n sí ibi gíga wọ̀n-ọn-nì.
Wszakże naczynili sobie każdy naród bogów swych, i postawili je w domu wyżyn, które byli pobudowali Samaryjczycy, każdy naród w miastach swych, w których mieszkali,
30 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin láti Babeli ṣe àgọ́ àwọn wúńdíá, àwọn ènìyàn Kuti ṣe òrìṣà Nergali, àti àwọn ènìyàn Hamati ṣe ti Aṣima;
Albowiem mężowie Babilońscy uczynili Sukkotbenot, a mężowie Kutscy uczynili Nergiel, a mężowie Ematscy uczynili Asyma.
31 àti àwọn ará Afa ṣe Nibhasi àti Tartaki, àti àwọn ará Sefarfaimi sun àwọn ọmọ wọn níná gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sí Adrameleki àti Anameleki, àwọn òrìṣà Sefarfaimi.
A Hewejczycy uczynili Nebahaz, i Tartak; a Sefarwaiczycy palili syny swe w ogniu Adramelechowi, i Anamelechowi, bogom Sefarwaimskim.
32 Wọ́n sin Olúwa, ṣùgbọ́n wọ́n sì tún yan gbogbo ẹgbẹ́ tí ènìyàn wọn láti ṣe iṣẹ́ oyè fún wọn gẹ́gẹ́ bí àlùfáà ní ibi gíga.
A tak bali się Pana, naczyniwszy sobie z pośrodku siebie kapłanów na wyżynach, którzy im usługiwali w domach wyżyn.
33 Wọ́n sin Olúwa ṣùgbọ́n wọ́n sin òrìṣà wọn ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú àṣà orílẹ̀-èdè wọn láti ibi tí wọ́n ti gbé wọn wá.
A choć się Pana bali, wszakże przecię bogom swoim służyli według zwyczajów onych narodów, skąd byli przeniesieni.
34 Láti ìgbà náà wá àwọn àlùfáà wọn ṣe bí ti àtẹ̀yìnwá. Wọn kò sin Olúwa tàbí kí wọ́n fi ara mọ́ ìlànà àti àṣẹ àti òfin tí Olúwa fi fún ìránṣẹ́ Jakọbu, tí wọ́n pe orúkọ rẹ̀ ní Israẹli.
Ci aż do dnia tego sprawują się według zwyczajów starych, nie boją się Pana, ani czynią według wyroków jego, i według ustaw jego, i według zakonu, i według rozkazania, które przykazał Pan synom Jakóbowym, którego przezwał Izraelem.
35 Nígbà tí Olúwa ṣe májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ó pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ má ṣe sin òrìṣà mìíràn tàbí tẹríba fún wọn, sìn wọ́n tàbí kí ẹ rú ẹbọ sí wọn.
Uczynił też był Pan z nimi przymierze, i rozkazał im, mówiąc: Nie bójcie się bogów cudzych, i nie kłaniajcie się im, ani im służcie, ani im ofiarujcie;
36 Ṣùgbọ́n Olúwa, ẹni tí ó mú yín gòkè jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú agbára ńlá àti nínà apá, òun ni ẹni náà tí ó yẹ kí ẹ sìn. Òun ni ẹni tí ó yẹ kí ẹ tẹríba fún àti sí òun ni kí ẹ rú ẹbọ fún.
Ale Pana, który was wywiódł z ziemi Egipskiej mocą wielką i ramieniem wyciągnionem, tego się bójcie, i jemu się kłaniajcie, i jemu ofiarujcie;
37 Ó yẹ kí ẹ̀yin kí ó máa kíyèsi ara yín gidigidi láti pa ìlànà àti àṣẹ, àti òfin tí ó kọ fún un yín mọ́. Ẹ má ṣe sin ọlọ́run mìíràn.
Także ustaw, i sądów, i zakonu, i przykazań, które wam napisał, strzeżcie, czyniąc je po wszystkie dni, a nie bójcie się bogów cudzych.
38 Ẹ má ṣe gbàgbé májẹ̀mú tí mo ti ṣe pẹ̀lú yín mọ́ àti kí ẹ má sin ọlọ́run mìíràn.
Więc przymierza, którem czynił z wami, nie zapominajcie, ani się bójcie bogów cudzych.
39 Kúkú sin Olúwa Ọlọ́run rẹ; Òun ni ẹni náà tí yóò gbà yín kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá a yín.”
Ale Pana, Boga waszego, się bójcie, a on was wybawi z ręki wszystkich nieprzyjaciół waszych;
40 Wọn kò ní gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni, wọ́n sì ń ṣe iṣẹ́ wọ́n ti àtijọ́.
Lecz nie usłuchali, ale owszem według obyczaju swego dawnego czynili.
41 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn wọn sin Olúwa, wọ́n sì ń sin òrìṣà wọn. Títí di ọjọ́ òní ọmọ wọn àti àwọn ọmọ ọmọ wọn sì ń ṣe bí àwọn baba wọn ti ń ṣe.
A tak narodowie oni bali się Pana, wszakże przecię rytym bałwanom swoim służyli; a synowie ich, i synowie synów ich, według wszystkiego, co czynili ojcowie ich, tak i oni czynią, aż po dziś dzień.

< 2 Kings 17 >