< 2 Kings 17 >
1 Ní ọdún kejìlá ọba Ahasi ará Juda, Hosea ọmọ Ela jẹ ọba Israẹli ní Samaria, ó sì jẹ fún ọdún mẹ́sàn-án.
La douzième année d’Achaz, roi de Juda, Osée, fils d’Éla, commença de régner à Samarie sur Israël; [il régna] neuf ans.
2 Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe bí i ti ọba Israẹli ẹni tí ó ti wà ṣáájú rẹ̀.
Et il fit ce qui est mauvais aux yeux de l’Éternel, non pas toutefois comme les rois d’Israël qui avaient été avant lui.
3 Ṣalamaneseri ọba Asiria wá sókè láti mú Hosea, ẹni tí ó ti jẹ fún Ṣalamaneseri ó sì ti san owó òde fún un.
Shalmanéser, roi d’Assyrie, monta contre lui, et Osée devint son serviteur, et lui envoya des présents.
4 Ṣùgbọ́n ọba Asiria rí i wí pé Hosea jẹ́ ọlọ́tẹ̀, nítorí ó ti rán oníṣẹ́ sọ́dọ̀ ọba Ejibiti, kò sì san owó òde mọ́ fún ọba Asiria, gẹ́gẹ́ bí o ti máa ń ṣe ní ọdọọdún. Nígbà náà ọba Asiria fi agbára mú ún, ó sì fi sínú túbú.
Et le roi d’Assyrie découvrit qu’Osée conspirait; car [Osée] avait envoyé des messagers à Sô, roi d’Égypte, et il n’envoyait pas de présents au roi d’Assyrie comme [il avait fait] d’année en année; et le roi d’Assyrie l’enferma dans une prison et le lia.
5 Ọba Asiria gòkè wá sí gbogbo ibi ilé náà, ó sì lọ sí Samaria, ó sì dúró tí ì fún ọdún mẹ́ta.
Et le roi d’Assyrie monta par tout le pays, et monta à Samarie, et l’assiégea trois ans.
6 Ní ọdún kẹsànán ti Hosea, ọba Asiria mú Samaria ó sì kó Israẹli lọ sí Asiria. Ó sì fi wọ́n sílẹ̀ ní Hala, ní Gosani ní etí odò Habori àti ní ìlú àwọn ará Media.
La neuvième année d’Osée, le roi d’Assyrie prit Samarie, et il transporta Israël en Assyrie, et les fit habiter à Khalakh, et sur le Khabor, fleuve de Gozan, et dans les villes des Mèdes.
7 Gbogbo eléyìí ṣẹlẹ̀ nítorí àwọn ọmọ Israẹli ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wọn, ẹni tí ó mú wọn jáde ní Ejibiti lábẹ́ agbára Farao ọba Ejibiti. Wọ́n sin ọlọ́run mìíràn,
Et il était arrivé que les fils d’Israël avaient péché contre l’Éternel, leur Dieu, qui les avait fait monter du pays d’Égypte, de dessous la main du Pharaon, roi d’Égypte, et qu’ils avaient révéré d’autres dieux.
8 wọn si tẹ̀lé ìwà orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti gbá kúrò níwájú wọn gẹ́gẹ́ bí ìwà ti ọba Israẹli tí ó ti paláṣẹ.
Et ils marchèrent dans les statuts des nations que l’Éternel avait dépossédées devant les fils d’Israël, et [dans ceux] que les rois d’Israël avaient établis.
9 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe ohun ìríra sí Olúwa Ọlọ́run wọn kọ́ láti ilé ìṣọ́ sí ìlú tí a dáàbò bò, wọ́n kọ́ ilé gíga fún ara wọn ní gbogbo ìlú wọn.
Et les fils d’Israël firent en secret contre l’Éternel, leur Dieu, des choses qui ne sont pas droites; et ils se bâtirent des hauts lieux dans toutes leurs villes, depuis la tour des gardes jusqu’à la ville forte;
10 Wọ́n sì gbé àwọn òkúta tí a yà sọ́tọ̀ sókè àti ère òrìṣà Aṣerah lórí gbogbo igi tútù.
et ils se dressèrent des statues et des ashères sur toute haute colline et sous tout arbre vert,
11 Ní gbogbo ibi gíga, wọ́n sun tùràrí gẹ́gẹ́ bí orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti lé jáde níwájú wọn. Wọ́n ṣe ohun búburú tí ó rú ìbínú Olúwa sókè.
et firent fumer là de l’encens sur tous les hauts lieux, comme les nations que l’Éternel avait transportées de devant eux; et ils firent des choses mauvaises, pour provoquer à colère l’Éternel;
12 Wọ́n sìn òrìṣà, èyí tí Olúwa ti sọ pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe èyí.”
et ils servirent les idoles, au sujet desquelles l’Éternel leur avait dit: Vous ne ferez point cela.
13 Olúwa kìlọ̀ fún Israẹli àti Juda nípa gbogbo àwọn wòlíì wọn àti aríran: “Ẹ yípadà kúrò ní ọ̀nà búburú yín. Kí ẹ ṣe òfin mi àti ìlànà mi, ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo òfin tí Èmi paláṣẹ fún àwọn baba yín láti tẹ̀lé àti èyí tí mo rán sí i yín nípa ìránṣẹ́ àwọn wòlíì mi.”
Et l’Éternel rendit témoignage contre Israël et contre Juda par tous les prophètes, tous les voyants, disant: Détournez-vous de vos mauvaises voies; et gardez mes commandements, mes statuts, selon toute la loi que j’ai commandée à vos pères et que je vous ai envoyée par mes serviteurs les prophètes.
14 Ṣùgbọ́n wọn kò ní gbọ́, wọ́n sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ọlọ́rùn líle gẹ́gẹ́ bí i ti baba wọn, ẹni tí kò gbà Olúwa Ọlọ́run wọn gbọ́.
Et ils n’écoutèrent pas, et roidirent leur cou comme le cou de leurs pères, qui n’avaient pas cru l’Éternel, leur Dieu.
15 Wọ́n kọ̀ ìlànà rẹ̀ àti májẹ̀mú tí ó ti ṣe pẹ̀lú baba wọn àti ìkìlọ̀ tí ó ti fi fún wọn. Wọ́n tẹ̀lé òrìṣà aláìníláárí, àwọn fún rara wọn sì jẹ́ aláìníláárí. Wọ́n tẹ̀lé orílẹ̀-èdè tí ó yí wọn ká bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa ti kìlọ̀ fún wọn pé, “Má ṣe ṣe gẹ́gẹ́ bí wọn tí ń ṣe,” wọ́n sì ṣe ohun tí Olúwa ti kà léèwọ̀ fún wọn láti ṣe.
Et ils rejetèrent ses statuts, et son alliance qu’il avait faite avec leurs pères, et ses témoignages qu’il leur avait donnés, et ils marchèrent après la vanité, et agirent vainement, et en suivant les nations qui étaient autour d’eux, touchant lesquelles l’Éternel leur avait commandé de ne pas faire comme elles.
16 Wọ́n kọ̀ gbogbo òfin Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, wọ́n sì ṣe òrìṣà méjì fún ara wọn, wọ́n sì gbẹ́ ẹ ọ̀kan ní ère ẹgbọrọ màlúù, àti ọ̀kan ní ère òrìṣà Aṣerah. Wọ́n sì tẹrí wọn ba sí gbogbo ogun ọ̀run, wọ́n sì sin Baali.
Et ils abandonnèrent tous les commandements de l’Éternel, leur Dieu, et se firent des images de fonte, deux veaux, et se firent des ashères, et se prosternèrent devant toute l’armée des cieux, et servirent Baal.
17 Wọ́n sì fi àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn rú ẹbọ nínú iná. Wọ́n sì ń fọ àfọ̀ṣẹ, wọ́n sì ń ṣe àlúpàyídà wọ́n sì ta ara wọn láti ṣe ohun búburú níwájú Olúwa, wọ́n sì mú un bínú.
Et ils firent passer leurs fils et leurs filles par le feu, et pratiquèrent la divination et s’adonnèrent aux enchantements, et se vendirent pour faire ce qui est mauvais aux yeux de l’Éternel, pour le provoquer à colère.
18 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì bínú gidigidi pẹ̀lú Israẹli ó sì mú wọn kúrò níwájú rẹ̀. Ẹ̀yà Juda nìkan ṣoṣo ni ó kù,
Et l’Éternel fut très irrité contre Israël, et les ôta de devant sa face; il n’en resta que la seule tribu de Juda.
19 àti pẹ̀lú, Juda kò pa òfin Olúwa Ọlọ́run wọn mọ́. Wọ́n tẹ̀lé ìhùwàsí àwọn Israẹli tí wọ́n ṣe.
Et Juda non plus ne garda pas les commandements de l’Éternel, son Dieu; et ils marchèrent dans les statuts qu’Israël avait établis.
20 Nítorí náà Olúwa kọ gbogbo àwọn ènìyàn Israẹli; ó sì jẹ wọ́n ní yà. Ó sì fi wọ́n lé ọwọ́ àwọn olè títí tí ó fi ta wọ́n nù kúrò níwájú rẹ̀.
Et l’Éternel rejeta toute la semence d’Israël, et il les affligea, et les livra en la main des pillards, jusqu’à ce qu’il les ait rejetés de devant sa face.
21 Nígbà tí ó ta Israẹli kúrò láti ìdílé Dafidi, wọ́n sì mú Jeroboamu ọmọ Nebati jẹ ọba wọn. Jeroboamu sì mú kí àwọn ọmọ Israẹli yípadà kúrò ní títẹ̀lé Olúwa, ó sí mú kí wọn dẹ́ṣẹ̀ ńlá.
Car Israël s’était séparé de la maison de David, et avait fait roi Jéroboam, fils de Nebath; et Jéroboam avait détourné violemment Israël de suivre l’Éternel, et les avait fait commettre un grand péché.
22 Àwọn ọmọ Israẹli forítì í nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu kò sì yí padà kúrò lọ́dọ̀ wọn,
Et les fils d’Israël marchèrent dans tous les péchés que Jéroboam avait commis; ils ne s’en détournèrent point,
23 títí tí Olúwa fi mú wọn kúrò níwájú rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ó ti paláṣẹ láti ọ̀dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ wòlíì. Bẹ́ẹ̀ ni a kó gbogbo ènìyàn Israẹli kúrò ní ilẹ̀ wọn lọ sí ìgbèkùn ni Asiria, títí di òní yìí.
jusqu’à ce que l’Éternel ôta Israël de devant sa face, comme il avait dit par tous ses serviteurs les prophètes; et Israël fut transporté de dessus sa terre en Assyrie, [où il est] jusqu’à ce jour.
24 Ọba Asiria mú àwọn ènìyàn láti Babeli, Kuta, Afa, Hamati àti Sefarfaimi, wọ́n sì fi wọ́n sínú ìlú Samaria láti rọ́pò àwọn ọmọ Israẹli. Wọ́n sì ń gbé ní ìlú náà.
Et le roi d’Assyrie fit venir [des gens] de Babel, et de Cuth, et d’Avva, et de Hamath, et de Sepharvaïm, et [les] fit habiter dans les villes de la Samarie, à la place des fils d’Israël; et ils possédèrent la Samarie, et habitèrent dans ses villes.
25 Nígbà tí wọ́n gbé bẹ̀ ní àkọ́kọ́, wọn kò sì bẹ̀rù Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni ó rán kìnnìún sí àárín wọn. Wọ́n sì pa nínú wọn.
Et il arriva, quand ils commencèrent d’y habiter, qu’ils ne craignaient pas l’Éternel, et l’Éternel envoya contre eux des lions qui les tuaient.
26 Wọ́n sì sọ fún ọba Asiria pé, “Àwọn ènìyàn tí ìwọ lé kúrò tí o sì fi sínú ìlú Samaria kò mọ ohun tí ọlọ́run ìlú náà béèrè. Ó sì ti rán kìnnìún sí àárín wọn, tí ó sì ń pa wọ́n run, nítorí ènìyàn wọn kò mọ ohun tí ó béèrè.”
Et on parla au roi d’Assyrie, disant: Les nations que tu as transportées et que tu as fait habiter dans les villes de Samarie ne connaissent pas la coutume du dieu du pays, et il a envoyé contre elles des lions, et voici, [ces lions] les font mourir, parce qu’elles ne connaissent pas la coutume du dieu du pays.
27 Nígbà náà ọba Asiria pàṣẹ yìí wí pé, “Mú ọ̀kan lára àwọn àlùfáà tí ó mú láti Samaria lọ padà gbé níbẹ̀ kí ó sì kọ́ àwọn ènìyàn ní, ohun tí ọlọ́run ilẹ̀ náà béèrè.”
Et le roi d’Assyrie commanda, disant: Faites aller là quelqu’un des sacrificateurs que vous en avez transportés; et qu’il aille et qu’il demeure là, et qu’il leur enseigne la coutume du dieu du pays.
28 Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kan lára àwọn àlùfáà tí ó ti kúrò ní Samaria wá gbé ní Beteli ó sì kọ́ wọn bí a ti ń sin Olúwa.
Et un des sacrificateurs qu’on avait transportés de Samarie, vint et habita à Béthel, et il leur enseignait comment ils devaient craindre l’Éternel.
29 Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, olúkúlùkù orílẹ̀-èdè ṣe òrìṣà tirẹ̀ ní gbogbo ìlú níbi tí wọ́n gbé wà, wọ́n sì gbé wọn nínú ilé òrìṣà àti àwọn ènìyàn Samaria ó sì ṣe wọ́n sí ibi gíga wọ̀n-ọn-nì.
Et chaque nation se fit ses dieux, et elles les placèrent dans les maisons des hauts lieux que les Samaritains avaient faites, chaque nation dans ses villes où elle habitait.
30 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin láti Babeli ṣe àgọ́ àwọn wúńdíá, àwọn ènìyàn Kuti ṣe òrìṣà Nergali, àti àwọn ènìyàn Hamati ṣe ti Aṣima;
Et les hommes de Babel firent Succoth-Benoth; et les hommes de Cuth firent Nergal; et les hommes de Hamath firent Ashima;
31 àti àwọn ará Afa ṣe Nibhasi àti Tartaki, àti àwọn ará Sefarfaimi sun àwọn ọmọ wọn níná gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sí Adrameleki àti Anameleki, àwọn òrìṣà Sefarfaimi.
et les Avviens firent Nibkhaz et Tharthak; et les Sepharviens brûlaient au feu leurs fils à Adrammélec et à Anammélec, les dieux de Sepharvaïm.
32 Wọ́n sin Olúwa, ṣùgbọ́n wọ́n sì tún yan gbogbo ẹgbẹ́ tí ènìyàn wọn láti ṣe iṣẹ́ oyè fún wọn gẹ́gẹ́ bí àlùfáà ní ibi gíga.
Et ils craignaient l’Éternel, et se firent d’entre toutes les classes [du peuple] des sacrificateurs des hauts lieux, qui offraient [des sacrifices] pour eux dans les maisons des hauts lieux:
33 Wọ́n sin Olúwa ṣùgbọ́n wọ́n sin òrìṣà wọn ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú àṣà orílẹ̀-èdè wọn láti ibi tí wọ́n ti gbé wọn wá.
ils craignaient l’Éternel, et ils servaient leurs dieux selon la coutume des nations d’où ils avaient été transportés.
34 Láti ìgbà náà wá àwọn àlùfáà wọn ṣe bí ti àtẹ̀yìnwá. Wọn kò sin Olúwa tàbí kí wọ́n fi ara mọ́ ìlànà àti àṣẹ àti òfin tí Olúwa fi fún ìránṣẹ́ Jakọbu, tí wọ́n pe orúkọ rẹ̀ ní Israẹli.
Jusqu’à ce jour ils font selon leurs premières coutumes: ils ne craignent pas l’Éternel, et ils ne font pas selon leurs statuts et selon leurs coutumes, ni selon la loi et selon le commandement que l’Éternel avait commandés aux fils de Jacob, qu’il nomma Israël.
35 Nígbà tí Olúwa ṣe májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ó pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ má ṣe sin òrìṣà mìíràn tàbí tẹríba fún wọn, sìn wọ́n tàbí kí ẹ rú ẹbọ sí wọn.
Et l’Éternel avait fait alliance avec eux, et il leur avait commandé, disant: Vous ne craindrez point d’autres dieux, et vous ne vous prosternerez point devant eux; et vous ne les servirez point, et ne leur sacrifierez point.
36 Ṣùgbọ́n Olúwa, ẹni tí ó mú yín gòkè jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú agbára ńlá àti nínà apá, òun ni ẹni náà tí ó yẹ kí ẹ sìn. Òun ni ẹni tí ó yẹ kí ẹ tẹríba fún àti sí òun ni kí ẹ rú ẹbọ fún.
Mais l’Éternel seul, qui vous a fait monter du pays d’Égypte par une grande force et à bras étendu, lui, vous le craindrez, et vous vous prosternerez devant lui, et à lui vous sacrifierez.
37 Ó yẹ kí ẹ̀yin kí ó máa kíyèsi ara yín gidigidi láti pa ìlànà àti àṣẹ, àti òfin tí ó kọ fún un yín mọ́. Ẹ má ṣe sin ọlọ́run mìíràn.
Et les statuts, et les ordonnances, et la loi, et le commandement, qu’il a écrits pour vous, vous prendrez garde à les pratiquer tous les jours; et vous ne craindrez pas d’autres dieux.
38 Ẹ má ṣe gbàgbé májẹ̀mú tí mo ti ṣe pẹ̀lú yín mọ́ àti kí ẹ má sin ọlọ́run mìíràn.
Et vous n’oublierez pas l’alliance que j’ai faite avec vous, et vous ne craindrez pas d’autres dieux;
39 Kúkú sin Olúwa Ọlọ́run rẹ; Òun ni ẹni náà tí yóò gbà yín kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá a yín.”
mais vous craindrez l’Éternel, votre Dieu, et lui vous délivrera de la main de tous vos ennemis.
40 Wọn kò ní gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni, wọ́n sì ń ṣe iṣẹ́ wọ́n ti àtijọ́.
Et ils n’écoutèrent pas, mais ils firent selon leur première coutume.
41 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn wọn sin Olúwa, wọ́n sì ń sin òrìṣà wọn. Títí di ọjọ́ òní ọmọ wọn àti àwọn ọmọ ọmọ wọn sì ń ṣe bí àwọn baba wọn ti ń ṣe.
Et ces nations-là craignaient l’Éternel, et servaient leurs images; leurs fils aussi, et les fils de leurs fils, font jusqu’à ce jour comme leurs pères ont fait.