< 2 Kings 17 >

1 Ní ọdún kejìlá ọba Ahasi ará Juda, Hosea ọmọ Ela jẹ ọba Israẹli ní Samaria, ó sì jẹ fún ọdún mẹ́sàn-án.
Judah siangpahrang Ahaz, a bawinae kum 12 navah, Elah capa, Hosi teh Isarelnaw koe Samaria vah siangpahrang lah ao teh kum 9 touh a uk.
2 Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe bí i ti ọba Israẹli ẹni tí ó ti wà ṣáájú rẹ̀.
BAWIPA mithmu vah thoenae ouk a sak. Hatei a yon e Isarel siangpahrangnaw ma patetlah teh sak hoeh.
3 Ṣalamaneseri ọba Asiria wá sókè láti mú Hosea, ẹni tí ó ti jẹ fún Ṣalamaneseri ó sì ti san owó òde fún un.
Assiria siangpahrang Shalmaneser ni a tuk teh, Hosi teh Salmaneser e san lah ao teh kum tangkuem tamuk a poe.
4 Ṣùgbọ́n ọba Asiria rí i wí pé Hosea jẹ́ ọlọ́tẹ̀, nítorí ó ti rán oníṣẹ́ sọ́dọ̀ ọba Ejibiti, kò sì san owó òde mọ́ fún ọba Asiria, gẹ́gẹ́ bí o ti máa ń ṣe ní ọdọọdún. Nígbà náà ọba Asiria fi agbára mú ún, ó sì fi sínú túbú.
Hathnukkhu hoi kum tangkuem a poe e tamuk hah poe hoeh. Izip siangpahrang So koevah patounenaw a patoun teh, ahnimouh youk hanelah pouknae hah, Assiria siangpahrang ni a panue dawkvah, Hosi teh a man awh teh thawng pabo awh.
5 Ọba Asiria gòkè wá sí gbogbo ibi ilé náà, ó sì lọ sí Samaria, ó sì dúró tí ì fún ọdún mẹ́ta.
Assiria siangpahrang Shalmaneser ni, Isarel ram a tuk teh Samaria khopui kum thum touh thung koung a kalup.
6 Ní ọdún kẹsànán ti Hosea, ọba Asiria mú Samaria ó sì kó Israẹli lọ sí Asiria. Ó sì fi wọ́n sílẹ̀ ní Hala, ní Gosani ní etí odò Habori àti ní ìlú àwọn ará Media.
Hosi a bawinae kum 9 navah, Assiria siangpahrang ni Samaria hah a la. Isarelnaw teh Assiria vah a ceikhai awh teh Halah ram hoi Gozan ram, Harbor palang teng Midiannaw e kho dawk ao sak awh.
7 Gbogbo eléyìí ṣẹlẹ̀ nítorí àwọn ọmọ Israẹli ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wọn, ẹni tí ó mú wọn jáde ní Ejibiti lábẹ́ agbára Farao ọba Ejibiti. Wọ́n sin ọlọ́run mìíràn,
Hot patetlah a onae teh, Isarelnaw ni Izip siangpahrang Faro kut dawk hoi Izip ram hoi katâcawtkhaikung Jehovah Cathut koevah yonnae a sak awh teh alouke cathut hah alawkpui lah a pouk awh dawk doeh.
8 wọn si tẹ̀lé ìwà orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti gbá kúrò níwájú wọn gẹ́gẹ́ bí ìwà ti ọba Israẹli tí ó ti paláṣẹ.
BAWIPA ni, Isarelnaw hmalah a pâlei pouh e miphunnaw e phunglawk hah, Isarel siangpahrang ni a tarawi dawkvah hote phunglam patetlah kho a sak awh dawk doeh.
9 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe ohun ìríra sí Olúwa Ọlọ́run wọn kọ́ láti ilé ìṣọ́ sí ìlú tí a dáàbò bò, wọ́n kọ́ ilé gíga fún ara wọn ní gbogbo ìlú wọn.
Isarelnaw ni BAWIPA Cathut koe thoenae hah, arulahoi meng a sak awh dawkvah a khonaw pueng dawk ramveng imrasang koehoi kamtawng teh rapan ka tawn e kho totouh hmuenrasang a sak awh.
10 Wọ́n sì gbé àwọn òkúta tí a yà sọ́tọ̀ sókè àti ère òrìṣà Aṣerah lórí gbogbo igi tútù.
Mon karasang pueng hoi thingkung tâhlip vah talung a ung awh teh thing dawk meikaphawk hah a sak awh.
11 Ní gbogbo ibi gíga, wọ́n sun tùràrí gẹ́gẹ́ bí orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti lé jáde níwájú wọn. Wọ́n ṣe ohun búburú tí ó rú ìbínú Olúwa sókè.
Hahoi hmuenrasang pueng koe, BAWIPA ni a hmalah a pâlei e miphunnaw ni a sak awh e patetlah hmuitui hah hmai hoi a sawi awh teh, BAWIPA lungphuen sak hanelah thoenae a sak awh.
12 Wọ́n sìn òrìṣà, èyí tí Olúwa ti sọ pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe èyí.”
Bangkongtetpawiteh, BAWIPA ni ahnimouh koe hete hno heh na sak awh mahoeh ati e meikaphawk thaw na tawk awh.
13 Olúwa kìlọ̀ fún Israẹli àti Juda nípa gbogbo àwọn wòlíì wọn àti aríran: “Ẹ yípadà kúrò ní ọ̀nà búburú yín. Kí ẹ ṣe òfin mi àti ìlànà mi, ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo òfin tí Èmi paláṣẹ fún àwọn baba yín láti tẹ̀lé àti èyí tí mo rán sí i yín nípa ìránṣẹ́ àwọn wòlíì mi.”
Hot um hoi hai BAWIPA ni na yonnae kamlang takhai awh. Na mintoenaw ka poe e kâpoelawknaw hoi phunglawknaw pueng ka san profet ka patoun e naw ni a dei awh patetlah a profetnaw hoi kahmawtkungnaw hno lahoi a panue sak awh.
14 Ṣùgbọ́n wọn kò ní gbọ́, wọ́n sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ọlọ́rùn líle gẹ́gẹ́ bí i ti baba wọn, ẹni tí kò gbà Olúwa Ọlọ́run wọn gbọ́.
Hatei, ngai pouh hoeh teh, a na mintoenaw ni, BAWIPA Cathut yuem ngai laipalah, a lunglen awh e patetlah a lungpata sak awh.
15 Wọ́n kọ̀ ìlànà rẹ̀ àti májẹ̀mú tí ó ti ṣe pẹ̀lú baba wọn àti ìkìlọ̀ tí ó ti fi fún wọn. Wọ́n tẹ̀lé òrìṣà aláìníláárí, àwọn fún rara wọn sì jẹ́ aláìníláárí. Wọ́n tẹ̀lé orílẹ̀-èdè tí ó yí wọn ká bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa ti kìlọ̀ fún wọn pé, “Má ṣe ṣe gẹ́gẹ́ bí wọn tí ń ṣe,” wọ́n sì ṣe ohun tí Olúwa ti kà léèwọ̀ fún wọn láti ṣe.
A phunglam hoi a na mintoenaw koe a lawkkam ahnimouh koe a panue sak e lawk hah, banglahai noutna awh hoeh teh cungkeihoehnaw a panki awh teh, banglahai yah tho kalawn hoeh. Ahnimouh kong dawk BAWIPA ni hot patetlah sak van awh hanh telah a dei tangcoung e hah, a teng kaawm e miphunnaw ni a sak awh e patetlah a kamtu awh.
16 Wọ́n kọ̀ gbogbo òfin Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, wọ́n sì ṣe òrìṣà méjì fún ara wọn, wọ́n sì gbẹ́ ẹ ọ̀kan ní ère ẹgbọrọ màlúù, àti ọ̀kan ní ère òrìṣà Aṣerah. Wọ́n sì tẹrí wọn ba sí gbogbo ogun ọ̀run, wọ́n sì sin Baali.
BAWIPA Cathut e kâpoelawknaw pueng hah, a hnamthun takhai awh teh, maitoca meikaphawk kahni touh a sak awh. Kalvan e kaawmnaw pueng hah a bawk awh. Baal thaw a tawk awh.
17 Wọ́n sì fi àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn rú ẹbọ nínú iná. Wọ́n sì ń fọ àfọ̀ṣẹ, wọ́n sì ń ṣe àlúpàyídà wọ́n sì ta ara wọn láti ṣe ohun búburú níwájú Olúwa, wọ́n sì mú un bínú.
A lungphuennae a kâan sak nahanelah, a canu a capanaw hah, hmai hoi thuengnae a sak awh. Camthoumnae hoi taân a sin awh teh, BAWIPA mithmu thoenae sak hanelah ka yo awh.
18 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì bínú gidigidi pẹ̀lú Israẹli ó sì mú wọn kúrò níwájú rẹ̀. Ẹ̀yà Juda nìkan ṣoṣo ni ó kù,
Hatdawkvah, BAWIPA teh Isarelnaw koe a lungphuen poung teh a hmaitung hoi a takhoe awh. Bangkongtetpawiteh, Judah miphun hloilah kacawie awm hoeh toe.
19 àti pẹ̀lú, Juda kò pa òfin Olúwa Ọlọ́run wọn mọ́. Wọ́n tẹ̀lé ìhùwàsí àwọn Israẹli tí wọ́n ṣe.
Judahnaw ni hai BAWIPA Cathut e kâpoelawknaw a tarawi awh hoeh teh Isarel phunglam hah a dawn awh.
20 Nítorí náà Olúwa kọ gbogbo àwọn ènìyàn Israẹli; ó sì jẹ wọ́n ní yà. Ó sì fi wọ́n lé ọwọ́ àwọn olè títí tí ó fi ta wọ́n nù kúrò níwájú rẹ̀.
BAWIPA ni Isarel catounnaw hah a pahnawt teh a mithmu vah he kahmat lah a puen hoehroukrak a rek teh ahni katuknaw kut dawk a poe.
21 Nígbà tí ó ta Israẹli kúrò láti ìdílé Dafidi, wọ́n sì mú Jeroboamu ọmọ Nebati jẹ ọba wọn. Jeroboamu sì mú kí àwọn ọmọ Israẹli yípadà kúrò ní títẹ̀lé Olúwa, ó sí mú kí wọn dẹ́ṣẹ̀ ńlá.
Isarel teh Devit imthung dawk hoi a phen teh hahoi Nebat capa Jeroboam hah siangpahrang lah a la awh. Jeroboam ni Isarelnaw e BAWIPA lam a dawn e hah lam a phen sak teh kalenpounge yonnae hah a sak sak awh.
22 Àwọn ọmọ Israẹli forítì í nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu kò sì yí padà kúrò lọ́dọ̀ wọn,
Isarel catounnaw ni Jeroboam ni a sak e yonnae hah a sak awh. Hote hnonaw pueng teh, BAWIPA ni a profetnaw hno lahoi a dei pouh tangcoung patetlah a hmuhoehnae hmuen koe he a takhoe hoehroukrak cettakhai hoeh toe.
23 títí tí Olúwa fi mú wọn kúrò níwájú rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ó ti paláṣẹ láti ọ̀dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ wòlíì. Bẹ́ẹ̀ ni a kó gbogbo ènìyàn Israẹli kúrò ní ilẹ̀ wọn lọ sí ìgbèkùn ni Asiria, títí di òní yìí.
Hahoi Isarelnaw teh, amamouh ram koehoi Assiria ram vah a hrawi teh atu totouh ao awh.
24 Ọba Asiria mú àwọn ènìyàn láti Babeli, Kuta, Afa, Hamati àti Sefarfaimi, wọ́n sì fi wọ́n sínú ìlú Samaria láti rọ́pò àwọn ọmọ Israẹli. Wọ́n sì ń gbé ní ìlú náà.
Assiria siangpahrang ni, Babilon Kuthah, Ivvah, Hamath, Sepharvaim, hoiyah khocanaw a thokhai teh, Samaria khopui dawkvah, Isarel catoun yueng lah a lawp sak. Hottelah hoi Samaria vah kho a sak awh, a khopui a lawp awh.
25 Nígbà tí wọ́n gbé bẹ̀ ní àkọ́kọ́, wọn kò sì bẹ̀rù Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni ó rán kìnnìún sí àárín wọn. Wọ́n sì pa nínú wọn.
Hote kho dawk ao pasuek nah, BAWIPA barilawa tawn awh hoeh. BAWIPA ni ahnimouh koe sendek a tha pouh teh tami tangawn koung a kei.
26 Wọ́n sì sọ fún ọba Asiria pé, “Àwọn ènìyàn tí ìwọ lé kúrò tí o sì fi sínú ìlú Samaria kò mọ ohun tí ọlọ́run ìlú náà béèrè. Ó sì ti rán kìnnìún sí àárín wọn, tí ó sì ń pa wọ́n run, nítorí ènìyàn wọn kò mọ ohun tí ó béèrè.”
Hahoi Assiria siangpahrang koevah na takhoe awh e miphun Samaria khopui na khawng sak e naw ni hete ram dawk e cathut bawknae nuencang panuek awh hoeh. Hatdawkvah, ahnimouh koe sendek a tha sin teh khenhaw! het ram cathut bawknae nuencang a panue awh hoeh kecu dawk koung a kei telah a dei awh.
27 Nígbà náà ọba Asiria pàṣẹ yìí wí pé, “Mú ọ̀kan lára àwọn àlùfáà tí ó mú láti Samaria lọ padà gbé níbẹ̀ kí ó sì kọ́ àwọn ènìyàn ní, ohun tí ọlọ́run ilẹ̀ náà béèrè.”
Assiria siangpahrang ni, haw e san lah a la e naw koehoi vaihma buet touh ban sak nateh Cathut bawknae nuencang pâtu naseh telah kâ a poe.
28 Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kan lára àwọn àlùfáà tí ó ti kúrò ní Samaria wá gbé ní Beteli ó sì kọ́ wọn bí a ti ń sin Olúwa.
Hahoi Samaria ram hoi a ceikhai e naw thung dawk hoi vaihma buet touh hah, Bethel kho vah ao teh BAWIPA barilawa awh thai nahan a pâtu awh.
29 Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, olúkúlùkù orílẹ̀-èdè ṣe òrìṣà tirẹ̀ ní gbogbo ìlú níbi tí wọ́n gbé wà, wọ́n sì gbé wọn nínú ilé òrìṣà àti àwọn ènìyàn Samaria ó sì ṣe wọ́n sí ibi gíga wọ̀n-ọn-nì.
Hatei miphun tangkuem ni, amamae cathut lengkaleng a sak awh, Samarianaw ni hmuenrasang a sak awh e hah, miphun tangkuem ni amamouh onae kho tangkuem vah a ta awh.
30 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin láti Babeli ṣe àgọ́ àwọn wúńdíá, àwọn ènìyàn Kuti ṣe òrìṣà Nergali, àti àwọn ènìyàn Hamati ṣe ti Aṣima;
Babilonnaw ni Sukkothbenoth a sak awh teh Kuthahnaw ni, Nergal a sak awh. Hamathnaw ni Ashima a sak awh teh,
31 àti àwọn ará Afa ṣe Nibhasi àti Tartaki, àti àwọn ará Sefarfaimi sun àwọn ọmọ wọn níná gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sí Adrameleki àti Anameleki, àwọn òrìṣà Sefarfaimi.
Avvitnaw ni Nibbaz hoi Tartak a sak awh. Hahoi Sepharvaim ni Sepharvaim e cathut Adrammelek hoi Anamalek vah a canaw hah hmai a sawi awh.
32 Wọ́n sin Olúwa, ṣùgbọ́n wọ́n sì tún yan gbogbo ẹgbẹ́ tí ènìyàn wọn láti ṣe iṣẹ́ oyè fún wọn gẹ́gẹ́ bí àlùfáà ní ibi gíga.
BAWIPA teh barilawa a tâ awh teh, amamouh thung dawk hoi hmuenrasang vaihma hah a sak awh teh ayânaw hanlah, thuengnae a sak pouh awh.
33 Wọ́n sin Olúwa ṣùgbọ́n wọ́n sin òrìṣà wọn ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú àṣà orílẹ̀-èdè wọn láti ibi tí wọ́n ti gbé wọn wá.
BAWIPA teh a taki awh ngoun eiteh, a tâcotakhai awh e, amamae ram e phunglam, a cathut thaw hah ouk a tawk awh.
34 Láti ìgbà náà wá àwọn àlùfáà wọn ṣe bí ti àtẹ̀yìnwá. Wọn kò sin Olúwa tàbí kí wọ́n fi ara mọ́ ìlànà àti àṣẹ àti òfin tí Olúwa fi fún ìránṣẹ́ Jakọbu, tí wọ́n pe orúkọ rẹ̀ ní Israẹli.
Ha hoehnahlan e ouk a sak awh, e patetlah atu totouh a sak awh rah. BAWIPA teh taket awh hoeh. BAWIPA ni, Jakop catounnaw, Isarel telah a phung e naw koe,
35 Nígbà tí Olúwa ṣe májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ó pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ má ṣe sin òrìṣà mìíràn tàbí tẹríba fún wọn, sìn wọ́n tàbí kí ẹ rú ẹbọ sí wọn.
Cathut alouke taket hanh awh. Ahnimouh teh bawk hanh awh, a thaw hai tawk pouh hanh awh. Ahnimouh koe thuengnae sak hanh awh.
36 Ṣùgbọ́n Olúwa, ẹni tí ó mú yín gòkè jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú agbára ńlá àti nínà apá, òun ni ẹni náà tí ó yẹ kí ẹ sìn. Òun ni ẹni tí ó yẹ kí ẹ tẹríba fún àti sí òun ni kí ẹ rú ẹbọ fún.
BAWIPA ni a lentoenae hnosakthainae hoi a dâw e kut hoi Izip ram hoi na ka hrawi e BAWIPA hah taket awh nateh bawk awh thuengnae poe awh.
37 Ó yẹ kí ẹ̀yin kí ó máa kíyèsi ara yín gidigidi láti pa ìlànà àti àṣẹ, àti òfin tí ó kọ fún un yín mọ́. Ẹ má ṣe sin ọlọ́run mìíràn.
Phunglawk, kâlawk, kâpoelawk yungyoe na hringkhai awh hanelah, ama ni na thut pouh e doeh. Alouke cathutnaw hah taket han awh.
38 Ẹ má ṣe gbàgbé májẹ̀mú tí mo ti ṣe pẹ̀lú yín mọ́ àti kí ẹ má sin ọlọ́run mìíràn.
Nangmouh koe ka kam e lawkkam hah na pahnim awh mahoeh. Cathut alouke hah na taket awh mahoeh.
39 Kúkú sin Olúwa Ọlọ́run rẹ; Òun ni ẹni náà tí yóò gbà yín kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá a yín.”
BAWIPA Cathut na taki awh han, hahoi na tarannaw e kut dawk hoi na rungngang han telah a ti.
40 Wọn kò ní gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni, wọ́n sì ń ṣe iṣẹ́ wọ́n ti àtijọ́.
Hatei ahnimouh ni tarawi han ngai awh hoeh, yampa e a sak e patetlah pou a sak awh.
41 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn wọn sin Olúwa, wọ́n sì ń sin òrìṣà wọn. Títí di ọjọ́ òní ọmọ wọn àti àwọn ọmọ ọmọ wọn sì ń ṣe bí àwọn baba wọn ti ń ṣe.
Hot patetlah, hete miphunnaw ni BAWIPA teh a taki awh. Hatei a sak awh e meikaphawk thaw hai a tawk awh. A catounnaw totouh, a na mintoenaw ni a sak awh e patetlah sahnin totouh pou a sak awh rah.

< 2 Kings 17 >