< 2 Kings 16 >

1 Ní ọdún kẹtàdínlógún Peka ọmọ Remaliah, Ahasi ọmọ Jotamu ọba Juda bẹ̀rẹ̀ sí i jẹ ọba.
I KA makahiki nmikumamahiku o Peka ke keiki a Remalia, i lilo ai o Ahaza, ke keiki a Iotama, ke alii o ka Iuda, i alii.
2 Ẹni ogún ọdún ni Ahasi nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí jẹ ọba, ó sì jẹ ọba ọdún mẹ́rìndínlógún ní Jerusalẹmu, kò sì ṣe èyí tí ó tọ́ lójú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Dafidi baba rẹ̀.
He iwakalua na makahiki o Ahaza i kona wa i lilo ai i alii, a he umikumamaono na makahiki ana i alii ai ma Ierusalema; aole ia i hana pono imua o Iehova kona Akua, e like me Davida kona kupuna.
3 Ṣùgbọ́n ó rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli, nítòótọ́, ó sì sun ọmọ rẹ̀ nínú iná, gẹ́gẹ́ bí ohun ìríra àwọn orílẹ̀-èdè, tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
Aka, hele no ia ma ka aoao o na'lii o ka Iseraela, a hoohelo aku hoi i kana keiki iloko o ke ahi, e like me na mea hoowahawahaia o na lahuikanaka a Iehova i kipaku ae mai ke alo aku o na mamo a Iseraela.
4 Ó sì rú ẹbọ, ó sì sun tùràrí ní àwọn ibi gíga, àti lórí àwọn òkè kéékèèké àti lábẹ́ gbogbo igi tútù.
A kaumaha aku no hoi a kuni i ka mea ala ma na heiau, a ma na pun, a malalo o na laau uliuli a pau.
5 Nígbà náà ni Resini ọba Siria àti Peka ọmọ Remaliah ọba Israẹli gòkè wá sí Jerusalẹmu láti jagun: wọ́n dó ti Ahasi, ṣùgbọ́n wọn kò lè borí rẹ̀.
Alaila hele mai o Rezina, ke alii o Suria, a me Peka ke keiki a Remalia, ke alii o ka Iseraela, i Ierusalema i ke kaua; a hoopilikia lakou ia Ahaza, aole e hiki ia lakou ke hoopio ia ia.
6 Ní àkókò náà, Resini ọba Siria gba Elati padà fún Siria, ó sì lé àwọn ènìyàn Juda kúrò ní Elati: àwọn ará Siria sì wá sí Elati, wọ́n sì ń gbé ibẹ̀ títí di òní yìí.
Ia manawa, hoihoi aku la o Rezina, ke alii o Suria, ia Elata no Suria, a kipaku aka la i na Iudaio mai Elata aku: a hele mai ko Suria i Elata, a noho ilaila a hiki i keia manawa.
7 Ahasi sì rán oníṣẹ́ sọ́dọ̀ Tiglat-Pileseri ọba Asiria wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ni èmi, àti ọmọ rẹ; gòkè wá, kí o sì gbà mi lọ́wọ́ ọba Siria, àti lọ́wọ́ ọba Israẹli tí ó dìde sí mi.”
A hoouna aku la o Ahaza i na elele ia Tigelatepilesera ke alii o Asuria, i aku la, Owau no kau kauwa, a o kau keiki hoi; e pii mai oe, a e hoopakele ia'u mai ka lima mai o ke alii o Suria, a mai ka lima mai o ke alii o ka Iseraela, e ku e mai ana ia'u.
8 Ahasi sì mú fàdákà àti wúrà tí a rí ní ilé Olúwa, àti nínú ìṣúra ilé ọba, ó sì rán an sí ọba Asiria ní ọrẹ.
A lawe aku la o Ahaza i ke kala a me ke gula i loaa ma ka hale o Iehova, a ma ka waihonakala o ka hale o ke alii, a hoouna aku la i makana no ke alii o Asuria.
9 Ọba Asiria sì gbọ́ tirẹ̀: nítorí ọba Asiria gòkè wá sí Damasku, ó sì kó o, ó sì mú un ní ìgbèkùn lọ sí Kiri, ó sì pa Resini.
A hoolohe mai ke alii o Asuria ia ia; a hele aku la ke alii o Asuria i Damaseko, a hoopio aku la ia, a lawe pio aku la i kolaila ma Kira, a pepehi aku la ia Rezina.
10 Ọba sì lọ sí Damasku láti pàdé Tiglat-Pileseri, ọba Asiria, ó sì rí pẹpẹ kan tí ó wà ní Damasku: Ahasi ọba sì rán àwòrán pẹpẹ náà, àti àpẹẹrẹ rẹ̀ sí Uriah àlùfáà, gẹ́gẹ́ bí gbogbo iṣẹ́ ọ̀nà rẹ̀.
A hele aku la o Ahaza ke alii e halawai me Tigelatepilesera ke alii o Asuria ma Damaseko; a ike aku la ia i kekahi kuahu ma Damaseko; a hoouna aku la o Ahaza ke alii io Uriia la ke kahuna i ke ano o ke kuahu a me kana kii, e like me ka hana'na o ia mea a pau.
11 Uriah àlùfáà sì kọ́ pẹpẹ náà gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí Ahasi ọba fi ránṣẹ́ sí i láti Damasku; bẹ́ẹ̀ ni Uriah àlùfáà ṣe é dé ìpadàbọ̀ Ahasi ọba láti Damasku.
A hana aku la o Uriia ke kahuna i ke kuahu e like me ka mea a pau a Ahaza ke alii i hoouna aku ai mai Damaseko aku; pela o Uriia ke kahuna i hana'i i ka hoi ana mai o Ahaza ke alii mai Damaseko mai.
12 Nígbà tí ọba sì ti Damasku dé, ọba sì rí pẹpẹ náà: ọba sì súnmọ́ pẹpẹ náà, ó sì rú ẹbọ lórí rẹ̀.
A hiki mai ke alii mai Damaseko mai, ike aku la ke alii i ke kuahu, a hele aku la a kokoke i ke kuahu, a kaumaha aku maluna ona.
13 Ó sì sun ẹbọ sísun rẹ̀ àti ọrẹ-jíjẹ rẹ̀, o si ta ohun mímu rẹ̀ sílẹ̀, ó sì wọ́n ẹ̀jẹ̀ ọrẹ àlàáfíà rẹ̀ sí ara pẹpẹ náà.
A puhi aku la i ka mohaikuni, a me kana mohai ai, a ninini iho la i kana mohai inu, a kapipi i ke koko o kana mau mohai hoomalu maluna o ke kuahu.
14 Ṣùgbọ́n ó mú pẹpẹ idẹ tí ó wà níwájú Olúwa kúrò láti iwájú ilé náà, láti àárín méjì pẹpẹ náà, àti ilé Olúwa, ó sì fi í sí apá àríwá pẹpẹ náà.
A lawe mai no hoi ia i ke kuahu keleawe imua o Iehova mai ke alo mai o ka hale, maiwaena mai o ke kuahu a o ka hale o Iehova, a waiho aku la ia mea ma ka aoao akau o ke kuahu.
15 Ahasi ọba sì pàṣẹ fún Uriah àlùfáà, wí pé, “Lórí pẹpẹ ńlá náà ni kó o máa sun ẹbọ sísun òròwúrọ̀ àti ọrẹ-jíjẹ alaalẹ́, àti ẹbọ sísun ti ọba, àti ọrẹ-jíjẹ rẹ̀, pẹ̀lú ẹbọ sísun tí gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, àti ọrẹ-jíjẹ wọn, àti ọrẹ ohun mímu wọn; kí o sì wọ́n gbogbo ẹ̀jẹ̀ ẹbọ sísun náà lórí rẹ̀, àti gbogbo ẹ̀jẹ̀ ẹbọ mìíràn, ṣùgbọ́n ní ti pẹpẹ idẹ náà èmi ó máa gbèrò ohun tí èmi ó fi ṣe.”
A kauoha aku la o Ahaza ke alii ia Uriia ke kahuna, i aku la, Maluna o ke kuahu nui e puhi aku i ka mohaikuni kakahiaka, a me ka mohai ai o ke ahiahi, a me ka mohaikuni a ke alii, a me kana mohai ai, me ka mohaikuni a na kanaka a pau o ka aina, a me ka lakou mohai ai, a me ka lakou mohai inu; a e kapipi maluna ona i ke koko a pau o ka mohaikuni, a me ke koko a pau o ka mohai: a no'u ke kuahu keleawe e ninau aku ai.
16 Báyìí ni Uriah àlùfáà ṣe, gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Ahasi ọba pàṣẹ.
A hana iho la o Uriia ke kahuna e like me na mea a pau a ke alii, a Ahaza i kauoha aku ai.
17 Ahasi ọba sì gé igi-ìpílẹ̀ àwọn àgbédúró náà, ó ṣí agbada náà kúrò lára wọn; ó sì gbé agbada ńlá náà kalẹ̀ kúrò lára àwọn màlúù idẹ tí ń bẹ lábẹ́ rẹ̀, ó sì gbé e ka ilẹ̀ tí a fi òkúta tẹ́.
A oki iho o Ahaza ke alii i na kihi o na kumu, a lawe aku i ka ipu holoi mai o lakou aku; a lawe ae la ia i ka ipu nui mai na bipi keleawe mai malalo iho ona, a kau iho la ia mea maluna o na pohaku i hoonohoia.
18 Ibi ààbò fún ọjọ́ ìsinmi tí a kọ́ nínú ilé náà, àti ọ̀nà ìjáde sí òde ọba, ni ó yípadà kúrò ní ilé Olúwa nítorí ọba Asiria.
A o ka lanai no ka Sabati a lakou i kukulu ai ma ka hale, a o ke keena komo a ke alii mawaho, hoohuli ae la ia mai ka hale o Iehova aku no ke alii o Asuria.
19 Àti ìyókù ìṣe Ahasi tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda?
A o na hana i koe a Ahaza, o na mea ana i hana'i, aole anei i kakauia lakou iloko o ka buke oihanaalii a na'lii o ka Iuda?
20 Ahasi sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú Dafidi: Hesekiah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
A hiamoe iho la o Abaza me kona poe kupuna, a ua kanuia oia me kona poe kupuna ma ke kulanakauhale o Davida: a nobo alii iho la o Hezekia kana keiki ma kona hakahaka.

< 2 Kings 16 >