< 2 Kings 15 >

1 Ní ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n tí Jeroboamu ọba Israẹli, Asariah ọmọ Amasiah ọba Juda sì bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba.
La vingt-septième année de Jéroboam, roi d'Israël, Azaria, fils d'Amatsia, roi de Juda, commença à régner.
2 Ó jẹ́ ẹni ọdún mẹ́rìndínlógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún méjìléláàádọ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jekoliah; ó wá láti Jerusalẹmu.
Il avait seize ans lorsqu'il devint roi, et il régna cinquante-deux ans à Jérusalem. Le nom de sa mère était Jecolia, de Jérusalem.
3 Ó ṣe ohun tí ó dára lójú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ Amasiah ti ṣe.
Il fit ce qui est droit aux yeux de l'Éternel, selon tout ce qu'avait fait son père Amatsia.
4 Àwọn ibi gíga, bí ó ti wù kí ó rí, a kò ṣí wọn kúrò, àwọn ènìyàn náà tẹ̀síwájú láti máa rú ẹbọ àti sun tùràrí níbẹ̀.
Cependant, les hauts lieux ne furent pas supprimés. Le peuple continuait à offrir des sacrifices et à brûler des parfums sur les hauts lieux.
5 Olúwa sì kọlu ọba náà pẹ̀lú ẹ̀tẹ̀, títí di ọjọ́ tí ó kú, ó sì ń gbé ní ilé ọ̀tọ̀. Jotamu, ọmọ ọba sì tọ́jú ààfin, ó sì ń darí àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà.
Yahvé frappa le roi, de sorte qu'il fut lépreux jusqu'au jour de sa mort et qu'il vécut dans une maison séparée. Jotham, fils du roi, était à la tête de la maison et jugeait le peuple du pays.
6 Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Asariah, pẹ̀lú gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Juda.
Le reste des actes d'Azaria et tout ce qu'il a fait, n'est-ce pas écrit dans le livre des Chroniques des rois de Juda?
7 Asariah sinmi pẹ̀lú àwọn baba a rẹ̀. A sì sin ín sí ẹ̀bá wọn ní ìlú ńlá ti Dafidi. Jotamu ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Azaria se coucha avec ses pères, et on l'enterra avec ses pères dans la ville de David; et Jotham, son fils, régna à sa place.
8 Ní ọdún kejìdínlógójì Asariah ọba Juda. Sekariah ọmọ Jeroboamu di ọba Israẹli ní Samaria, ó sì jẹ ọba fún oṣù mẹ́fà.
La trente-huitième année d'Azaria, roi de Juda, Zacharie, fils de Jéroboam, régna sur Israël à Samarie pendant six mois.
9 Ó ṣe búburú lójú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí àwọn baba rẹ̀ tí ṣe. Kò sì yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, èyí tí ó ti fa Israẹli láti dá.
Il fit ce qui est mal aux yeux de Yahvé, comme avaient fait ses pères. Il ne se détourna pas des péchés de Jéroboam, fils de Nebath, par lesquels il avait fait pécher Israël.
10 Ṣallumu ọmọ Jabesi dìtẹ̀ sí Sekariah. Ó dojúkọ ọ́ níwájú àwọn ènìyàn, ó sì pa á, ó sì jẹ ọba dípò rẹ̀.
Shallum, fils de Jabesh, conspira contre lui, le frappa devant le peuple, le tua, et régna à sa place.
11 Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Sekariah. Wọ́n kọ ọ́ sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli.
Le reste des actes de Zacharie, voici, ils sont écrits dans le livre des chroniques des rois d'Israël.
12 Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí a sọ fún Jehu jẹ́ ìmúṣẹ: “Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli títí dé ìran kẹrin.”
Telle fut la parole que Yahvé adressa à Jéhu, en disant: « Tes fils jusqu'à la quatrième génération s'assiéront sur le trône d'Israël. » Ainsi s'accomplit ce qui suit.
13 Ṣallumu ọmọ Jabesi di ọba ní ọdún kọkàndínlógójì Ussiah ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní Samaria fún oṣù kan.
Schallum, fils de Jabesh, régna la trente-neuvième année d'Ozias, roi de Juda, et il régna un mois à Samarie.
14 Nígbà náà Menahemu ọmọ Gadi lọ láti Tirsa sí Samaria. Ó dojúkọ Ṣallumu ọmọ Jabesi ní Samaria, ó pa á ó sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Menahem, fils de Gadi, monta de Thirtsa, vint à Samarie, frappa Shallum, fils de Jabesh, à Samarie, le tua, et régna à sa place.
15 Fún ti ìyókù iṣẹ́ ìjọba Ṣallumu, àti ìdìtẹ̀ tí ó dì, a kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli.
Le reste des actes de Shallum, et la conspiration qu'il a formée, sont écrits dans le livre des Chroniques des rois d'Israël.
16 Ní ìgbà tí Menahemu ń jáde bọ̀ láti Tirsa, ó dojúkọ Tifisa àti gbogbo ènìyàn tí ó wà ní ìlú ńlá àti agbègbè rẹ̀, nítorí wọn kọ̀ láti sí ẹnu ibodè. Ó yọ Tifisa kúrò lẹ́nu iṣẹ́, ó sì la inú gbogbo àwọn obìnrin aboyún.
Alors Menahem attaqua Tiphsah et tous ceux qui s'y trouvaient, ainsi que les régions limitrophes, depuis Tirza. Il l'attaqua parce qu'ils ne lui avaient pas ouvert leurs portes, et il déchira toutes leurs femmes enceintes.
17 Ní ọdún kọkàndínlógójì ti Asariah ọba Juda, Menahemu ọmọ Gadi di ọba Israẹli, ó sì jẹ ọba ní Samaria fún ọdún mẹ́wàá.
La trente-neuvième année d'Azaria, roi de Juda, Menahem, fils de Gadi, régna sur Israël pendant dix ans à Samarie.
18 Ó ṣe búburú lójú Olúwa, ní gbogbo ìjọba rẹ̀. Kò sì yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, èyí tí ó ti fa Israẹli láti dá.
Il fit ce qui est mal aux yeux de l'Éternel. Il ne se détourna pas pendant toute sa vie des péchés de Jéroboam, fils de Nebat, par lesquels il avait fait pécher Israël.
19 Nígbà náà, Pulu ọba Asiria, gbógun ti ilẹ̀ náà, Menahemu sì fún un ní ẹgbẹ̀rin tálẹ́ǹtì fàdákà láti fi gba àtìlẹ́yìn rẹ̀ àti láti fún ìdúró tirẹ̀ lágbára lórí ìjọba.
Pul, roi d'Assyrie, vint contre le pays, et Menahem donna à Pul mille talents d'argent, afin que sa main soit avec lui pour confirmer le royaume entre ses mains.
20 Menahemu fi agbára gba owó náà lọ́wọ́ Israẹli. Gbogbo ọkùnrin ọlọ́lá ní láti dá àádọ́ta ṣékélì fàdákà láti fún ọba Asiria. Bẹ́ẹ̀ ni ọba Asiria padà sẹ́yìn, kò sì dúró ní ilẹ̀ náà mọ́.
Menahem exigea d'Israël, de tous les hommes riches et puissants, cinquante sicles d'argent chacun, pour les donner au roi d'Assyrie. Et le roi d'Assyrie s'en retourna, et ne resta pas dans le pays.
21 Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Menahemu, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé ọba Israẹli?
Le reste des actes de Menahem, et tout ce qu'il a fait, n'est-ce pas écrit dans le livre des Chroniques des rois d'Israël?
22 Menahemu sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. Pekahiah ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Menahem se coucha avec ses pères, et Pekahiah, son fils, régna à sa place.
23 Ní ọdún kẹ́ẹ̀dógún Asariah ọba Juda, Pekahiah ọmọ Menahemu di ọba Israẹli ní Samaria, ó sì jẹ ọba fún ọdún méjì.
La cinquantième année d'Azaria, roi de Juda, Pekahia, fils de Menahem, régna sur Israël à Samarie pendant deux ans.
24 Pekahiah ṣe búburú lójú Olúwa. Kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, èyí tí ó fa Israẹli láti dá.
Il fit ce qui est mal aux yeux de l'Éternel. Il ne se détourna pas des péchés de Jéroboam, fils de Nebat, par lesquels il avait fait pécher Israël.
25 Ọ̀kan lára àwọn olórí ìjòyè rẹ̀ Peka ọmọ Remaliah, dìtẹ̀ sí i. Ó mú àádọ́ta àwọn ọkùnrin ti àwọn ará Gileadi pẹ̀lú u rẹ̀. Ó pa Pekahiah pẹ̀lú Argobu àti Arie ní odi ààfin ọba ní Samaria. Bẹ́ẹ̀ ni Peka pa Pekahiah, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Pékah, fils de Remalia, son chef, conspira contre lui et l'attaqua à Samarie, dans la forteresse de la maison du roi, avec Argob et Arieh; il avait avec lui cinquante hommes des Galaadites. Il le tua, et régna à sa place.
26 Fún ti ìyókù iṣẹ́ ìjọba Pekahiah, gbogbo ohun tí ó ṣe, ni a kọ sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli.
Le reste des actes de Pékahia, et tout ce qu'il a fait, voici, cela est écrit dans le livre des chroniques des rois d'Israël.
27 Ní ọdún kejìléláàádọ́ta Asariah ọba Juda, Peka ọmọ Remaliah di ọba Israẹli ní Samaria. Ó sì jẹ ọba fún ogún ọdún.
La cinquante-deuxième année d'Azaria, roi de Juda, Pékah, fils de Remalia, régna sur Israël à Samarie pendant vingt ans.
28 Ó sì ṣe búburú lójú Olúwa, kò sì yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, èyí tí ó fa Israẹli láti dá.
Il fit ce qui est mal aux yeux de Yahvé. Il ne se détourna pas des péchés de Jéroboam, fils de Nebat, par lesquels il avait fait pécher Israël.
29 Ní ìgbà Peka ọba Israẹli, Tiglat-Pileseri ọba Asiria wá, ó sì mú Ijoni, Abeli-Beti-Maaka, Janoa, Kedeṣi àti Hasori. Ó gba Gileadi àti Galili pẹ̀lú gbogbo ilẹ̀ Naftali. Ó sì kó àwọn ènìyàn ní ìgbèkùn lọ sí Asiria.
Du temps de Pékah, roi d'Israël, Tiglath Pileser, roi d'Assyrie, vint et prit Ijon, Abel Beth Maaca, Janoah, Kedesh, Hatsor, Galaad et Galilée, tout le pays de Nephtali, et il les emmena captifs en Assyrie.
30 Nígbà náà, Hosea ọmọ Ela, dìtẹ̀ sí Peka ọmọ Remaliah. Ó dojúkọ ọ́, ó sì pa á, ó sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba ní ogún ọdún Jotamu ọmọ Ussiah.
Hosée, fils d'Éla, forma une conspiration contre Pékah, fils de Remalia, l'attaqua, le tua et régna à sa place, la vingtième année de Jotham, fils d'Ozias.
31 Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Peka, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli?
Le reste des actes de Pékach, et tout ce qu'il a fait, est écrit dans le livre des Chroniques des rois d'Israël.
32 Ní ọdún keje Peka ọmọ Remaliah ọba Israẹli, Jotamu ọmọ Ussiah ọba Juda bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba.
La deuxième année de Pékah, fils de Remalia, roi d'Israël, Jotham, fils d'Ozias, roi de Juda, commença à régner.
33 Ó jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́rìndínlógún. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jeruṣa ọmọbìnrin Sadoku.
Il avait vingt-cinq ans lorsqu'il devint roi, et il régna seize ans à Jérusalem. Le nom de sa mère était Jérusha, fille de Tsadok.
34 Ó ṣe ohun tí ó tọ́ lójú Olúwa gẹ́gẹ́ bí baba a rẹ̀ Ussiah ti ṣe.
Il fit ce qui est droit aux yeux de l'Éternel. Il fit tout ce que son père Ozias avait fait.
35 Àwọn ibi gíga, bí ó ti wù kí ó rí, a kò ṣí wọn kúrò àwọn ènìyàn tẹ̀síwájú láti rú ẹbọ àti láti sun tùràrí níbẹ̀: Jotamu tún ìlẹ̀kùn gíga tó ń kọ́ ní ti ilé tí a kọ́ fún Olúwa ṣe.
Cependant, les hauts lieux ne furent pas supprimés. Le peuple continuait à offrir des sacrifices et à brûler des parfums sur les hauts lieux. Il construisit la porte supérieure de la maison de Yahvé.
36 Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Jotamu, àti ohun tí ó ṣe, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Juda?
Le reste des actes de Jotham, et tout ce qu'il a fait, n'est-il pas écrit dans le livre des chroniques des rois de Juda?
37 (Ní ayé ìgbàanì, Olúwa bẹ̀rẹ̀ sí ní rán Resini ọba Siria àti Peka ọmọ Remaliah láti dojúkọ Juda).
En ces jours-là, Yahvé commença à envoyer contre Juda Rezin, roi de Syrie, et Pékah, fils de Remalia.
38 Jotamu sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. A sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú ńlá Dafidi, ìlú ńlá ti baba rẹ̀. Ahasi ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Jotham se coucha avec ses pères et fut enterré avec ses pères dans la ville de David, son père, et Achaz, son fils, régna à sa place.

< 2 Kings 15 >