< 2 Kings 14 >

1 Ní ọdún kejì tí Jehoaṣi ọmọ Joahasi ọba Israẹli, Amasiah ọmọ Joaṣi ọba Juda bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba.
W drugim roku Joasza, syna Jehoachaza, króla Izraela, zaczął królować Amazjasz, syn Joasza, króla Judy.
2 Ó jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jehoadani; ó wá láti Jerusalẹmu.
Miał dwadzieścia pięć lat, kiedy zaczął królować, i królował dwadzieścia dziewięć lat w Jerozolimie. Jego matka [miała] na imię Jehoaddan, [była] z Jerozolimy.
3 Ó ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe bí i Dafidi baba a rẹ̀ tí ṣe. Nínú ohun gbogbo, ó tẹ̀lé àpẹẹrẹ baba a rẹ̀ Joaṣi.
Czynił on to, co słuszne w oczach PANA, ale nie tak jak Dawid, jego ojciec. Czynił wszystko tak, jak czynił Joasz, jego ojciec.
4 Àwọn ibi gíga bí ó ti wù kí ó rí, a kò sí i kúrò, àwọn ènìyàn sì tẹ̀síwájú láti rú ẹbọ àti sun tùràrí níbẹ̀.
Wyżyn jednak nie zniesiono i lud jeszcze składał ofiary, i palił kadzidło na tych wyżynach.
5 Lẹ́yìn tí ó ti fi ọwọ́ gbá ìjọba rẹ̀ mú gbọingbọin, ó pa àwọn oníṣẹ́ tí wọ́n ti pa baba a rẹ̀ ọba.
A gdy królestwo umocniło się w jego ręku, zabił tych spośród swoich sług, którzy zabili króla, jego ojca.
6 Síbẹ̀ kò pa ọmọ àwọn apànìyàn náà. Ní ìbámu pẹ̀lú ohun tí a kọ sínú ìwé òfin Mose níbi tí Olúwa ti paláṣẹ pé, “A kì yóò pa baba nítorí àwọn ọmọ, tàbí àwọn ọmọ nítorí àwọn baba; olúkúlùkù ni kí ó kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.”
Lecz synów morderców nie zabił zgodnie z tym, co jest napisane w księdze Prawa Mojżesza, gdzie PAN rozkazał: Ojcowie nie poniosą śmierci za synów ani synowie nie poniosą śmierci za ojców, ale każdy poniesie śmierć za swój grzech.
7 Òun ni ẹni tí ó ṣẹ́gun ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ará Edomu ní àfonífojì iyọ̀, ó sì fi agbára mú Sela nínú ogun, tí ó ń pè é ní Jokteeli, orúkọ tí ó ní títí di òní.
On też pobił dziesięć tysięcy Edomitów w Dolinie Soli i zdobył w walce Selę, i nadał jej nazwę Jokteel, [i tak nazywa się] aż do dziś.
8 Nígbà náà, Amasiah rán àwọn ìránṣẹ́ sí Jehoaṣi ọmọ Jehoahasi ọmọ Jehu ọba Israẹli pẹ̀lú ìpèníjà: “Wá, jẹ́ kí á wo ara wa ní ojú.”
Wtedy Amazjasz wysłał posłańców do Jehoasza, syna Jehoachaza, syna Jehu, króla Izraela, ze słowami: Chodź, spójrzmy sobie w twarze.
9 Ṣùgbọ́n Jehoaṣi ọba Israẹli fèsì sí Amasiah ọba Juda: “Òṣùṣú kan ní Lebanoni rán iṣẹ́ sí kedari ní Lebanoni, ‘Fi ọmọbìnrin rẹ fún ọmọkùnrin mi ní ìgbéyàwó.’ Nígbà náà ẹranko ẹlẹ́sẹ̀ mẹ́rin tinú igbó ní Lebanoni wá pẹ̀lú ó sì fi ẹsẹ̀ tẹ òṣùṣú náà mọ́lẹ̀.
Jehoasz zaś, król Izraela, wysłał do Amazjasza, króla Judy, taką odpowiedź: Oset w Libanie posłał do cedru w Libanie prośbę: Daj swoją córkę mojemu synowi za żonę. Lecz dziki zwierz w Libanie przeszedł i podeptał oset.
10 Ìwọ ti ṣẹ́gun Edomu pẹ̀lú, ṣùgbọ́n, nísinsin yìí ìwọ ṣe ìgbéraga. Ògo nínú ìṣẹ́gun rẹ, ṣùgbọ́n dúró nílé! Kí ni ó dé tí o fi ń wá wàhálà tí o sì fa ìṣubú rẹ àti ti Juda pẹ̀lú?”
Rzeczywiście, pobiłeś Edomitów i twoje serce uniosło się pychą. Chwal się [tym] i siedź w domu. Po co masz wdawać się w nieszczęście, abyś upadł ty i Juda z tobą?
11 Bí ó ti wù kí ó rí Amasiah kò ní tẹ́tí, bẹ́ẹ̀ ni Jehoaṣi ọba Israẹli sì dojúkọ ọ́. Òun àti Amasiah ọba Juda kọjú sí ara wọn ní Beti-Ṣemeṣi ní Juda.
Lecz Amazjasz nie posłuchał. Wyruszył więc Jehoasz, król Izraela, i spojrzeli sobie w twarze, on i Amazjasz, król Judy, w Bet-Szemesz, które należy do Judy.
12 A kó ipa ọ̀nà Juda nípasẹ̀ Israẹli, gbogbo àwọn ọkùnrin sì sálọ sí ilé e rẹ̀.
I Juda został pobity przez Izraela, i uciekł – każdy do swego namiotu.
13 Jehoaṣi ọba Israẹli fi agbára mú Amasiah ọba Juda, ọmọ Jehoaṣi, ọmọ Ahasiah ní Beti-Ṣemeṣi. Nígbà náà, Jehoaṣi lọ sí Jerusalẹmu, ó sì lọ wó odi Jerusalẹmu lulẹ̀ láti ìlẹ̀kùn Efraimu sí ibi igun ìlẹ̀kùn. Ìpín kan tí ó fẹ́rẹ̀ jẹ́ irinwó ìgbọ̀nwọ́.
A Jehoasz, król Izraela, pojmał Amazjasza, króla Judy, syna Jehoasza, syna Achazjasza, w Bet-Szemesz, przyszedł do Jerozolimy i zburzył mur Jerozolimy od Bramy Efraim aż do Bramy Narożnej, na czterysta łokci.
14 Ó mú gbogbo wúrà àti fàdákà àti gbogbo ohun tí ó rí nínú ilé tí a kọ́ fún Olúwa àti níbi ìfowópamọ́ sí nínú ààfin ọba. Ó mú àwọn ògo, ó sì dá wọn padà sí Samaria.
I zabrał całe złoto i srebro oraz wszystkie naczynia, które znajdowały się w domu PANA i w skarbcach domu królewskiego, a także zakładników, po czym wrócił do Samarii.
15 Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Jehoaṣi, gbogbo ohun tí ó ṣe pẹ̀lú àṣeyọrí rẹ̀, pẹ̀lú ogun rẹ̀ sí Amasiah ọba Juda, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli?
A pozostałe dzieje Jehoasza, które czynił, i jego potęga, i [to], jak walczył z Amazjaszem, królem Judy, czy nie są zapisane w księdze kronik królów Izraela?
16 Jehoaṣi sì sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín sí Samaria pẹ̀lú àwọn ọba Israẹli. Jeroboamu ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
I Jehoasz zasnął ze swymi ojcami, i został pogrzebany w Samarii wraz z królami Izraela, a jego syn Jeroboam królował w jego miejsce.
17 Amasiah ọmọ Joaṣi ọba Juda gbé fún ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún lẹ́yìn ikú Jehoaṣi ọmọ Jehoahasi ọba Israẹli.
Amazjasz zaś, syn Joasza, król Judy, żył piętnaście lat po śmierci Jehoasza, syna Jehoachaza, króla Izraela.
18 Fún ti ìyókù iṣẹ́ rẹ̀ nígbà ìjọba Amasiah, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Juda?
A pozostałe dzieje Amazjasza – czy nie są zapisane w księdze kronik królów Judy?
19 Wọ́n dìtẹ̀ sí i ní Jerusalẹmu, ó sì sálọ sí Lakiṣi, ṣùgbọ́n wọ́n rán àwọn ọkùnrin tẹ̀lé e sí Lakiṣi, wọ́n sì pa á síbẹ̀.
Potem uknuto przeciwko niemu spisek w Jerozolimie. Uciekł do Lakisz, lecz posłano za nim do Lakisz i tam go zabito.
20 Wọ́n gbé e padà pẹ̀lú ẹṣin, a sì sin ín sí Jerusalẹmu pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, ní ìlú ńlá ti Dafidi.
Przywieziono go na koniach i został pogrzebany w Jerozolimie ze swymi ojcami, w mieście Dawida.
21 Nígbà náà, gbogbo àwọn ènìyàn Juda mú Asariah tí ó jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́rìndínlógún. Wọ́n sì ṣe é ní ọba ní ìrọ́pò baba rẹ̀ Amasiah.
Cały lud Judy wziął Azariasza, który miał szesnaście lat, i ustanowili go królem po jego ojcu Amazjaszu.
22 Òun ni ẹni tí ó tún Elati kọ́, ó sì dá a padà sí Juda lẹ́yìn tí Amasiah ti sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀.
On odbudował Elat i przywrócił je Judzie, po tym jak król zasnął ze swymi ojcami.
23 Ní ọdún kẹ́ẹ̀dógún tí Amasiah ọmọ Joaṣi ọba Juda, Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi ọba Israẹli di ọba ní Samaria, ó sì jẹ ọba fún ọ̀kànlélógójì ọdún.
W piętnastym roku Amazjasza, syna Joasza, króla Judy, Jeroboam, syn Joasza, króla Izraela, [zaczął] królować w Samarii i [królował] czterdzieści jeden lat.
24 Ó ṣe búburú ní ojú Olúwa kò sì yípadà kúrò nínú ọ̀kankan nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati. Èyí tí ó ti fa Israẹli láti dá.
Czynił on to, co złe w oczach PANA. Nie odstąpił od żadnego z grzechów Jeroboama, syna Nebata, który przywiódł Izraela do grzechu.
25 Òun ni ẹni tí ó ti dá àwọn ààlà Israẹli padà láti Lebo-Hamati sí òkú aginjù. Ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run Israẹli, tí ó sọ nípasẹ̀ ìránṣẹ́ Jona ọmọ Amittai, wòlíì láti Gati-Heferi.
On przywrócił granice Izraela od wejścia do Chamat aż do Morza Stepowego, według słowa PANA, Boga Izraela, które wypowiedział przez swego sługę Jonasza, syna Amittaja, proroka z Gat-ha-Chefer.
26 Olúwa ti rí ìpọ́njú Israẹli pé, ó korò gidigidi, nítorí kò sí ẹrú tàbí òmìnira tàbí olùrànlọ́wọ́ kan fún Israẹli.
PAN bowiem widział gorzkie utrapienie Izraela. Nie było ani więźnia, ani opuszczonego, ani kogokolwiek, kto by pomógł Izraelowi.
27 Láti ìgbà tí Olúwa kò ti wí pé òhun yóò bu àbùkù lu orúkọ Israẹli láti abẹ́ ọ̀run. Ó gbà wọ́n là, lọ́wọ́ Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi.
A PAN nie powiedział, że miał wymazać imię Izraela spod niebios. Wybawił ich więc przez rękę Jeroboama, syna Joasza.
28 Fún ti ìyókù iṣẹ́ ìjọba Jeroboamu, gbogbo ohun tí ó ṣe àti gbogbo àwọn agbára rẹ, bí ó ti jagun sí, àti bí ó ti gba Damasku àti Hamati, tí í ṣe ti Juda, padà fún Israẹli, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli?
A pozostałe dzieje Jeroboama i wszystko, co czynił, oraz jego potęga, [to], jak walczył i jak przywrócił Izraelowi Damaszek i Chamat judzkie – czy nie są zapisane w księdze kronik królów Izraela?
29 Jeroboamu sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, àwọn ọba Israẹli Sekariah ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
I Jeroboam zasnął ze swymi ojcami, z królami Izraela, a Zachariasz, jego syn, królował w jego miejsce.

< 2 Kings 14 >