< 2 Kings 12 >

1 Ní ọdún keje tí Jehu, Jehoaṣi di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ogójì ọdún. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Sibia: Ó wá láti Beerṣeba.
Na rĩrĩ, mwaka-inĩ wa mũgwanja wa Jehu, Joashu agĩtuĩka mũthamaki, na agĩthamaka arĩ Jerusalemu mĩaka mĩrongo ĩna. Nyina eetagwo Zibia; na oimĩte Birishiba.
2 Jehoaṣi ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú Olúwa ní gbogbo ọdún tí Jehoiada àlùfáà fi àṣẹ fún un.
Joashu nĩekire maũndũ marĩa magĩrĩire maitho-inĩ ma Jehova mĩaka ĩrĩa yothe Jehoiada mũthĩnjĩri-Ngai aamũtaarire.
3 Àwọn ibi gíga, bí ó ti wù kí ó rí, a kò sí wọn ní ìdí, àwọn ènìyàn sì tẹ̀síwájú láti máa rú ẹbọ àti sísun tùràrí níbẹ̀.
No rĩrĩ, kũndũ kũrĩa gũtũũgĩru gwa kũrutĩra magongona gũtieheririo; andũ mathiire na mbere kũrutĩra magongona na gũcinĩra ũbumba kuo.
4 Jehoaṣi sọ fún àwọn àlùfáà pé, “Gba gbogbo owó tí wọ́n mú wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ mímọ́ sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa owó tí a gbà ní ìgbà kíka àwọn ènìyàn ìlú, owó tí a gbà láti ọwọ́ olúkúlùkù bí wọ́n ti ṣe jẹ́ ẹ̀yà àti owó tí ó ti ọkàn olúkúlùkù wá tí a mú wá sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa.
Joashu akĩĩra athĩnjĩri-Ngai atĩrĩ, “Cookanĩrĩriai mbeeca iria ciothe irehagwo irĩ cia maruta marĩa maamũre ma hekarũ ya Jehova, na mbeeca iria irutagwo cia gwĩtara, na mbeeca iria ciamũkagĩrwo kuuma mĩĩhĩtwa-inĩ ya andũ o na mbeeca iria irehagwo hekarũ na ũndũ wa kwĩyendera.
5 Jẹ́ kí gbogbo àlùfáà gba owó náà lọ́wọ́ ọ̀kan nínú àwọn akápò. Kí a sì lò ó fún tuntun ohunkóhun tí ó bá bàjẹ́ nínú ilé tí a kọ́ fún Olúwa ṣe.”
Ĩtĩkĩriai mũthĩnjĩri-Ngai o wothe aamũkagĩre mbeeca kuuma kũrĩ ũmwe wa aigi a kĩgĩĩna, na mũreke ihũthĩrwo na gũcookereria hekarũ kũrĩa guothe ĩngĩkorwo ĩrĩ tharũku.”
6 Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹtàlélógún ọba Jehoaṣi, àwọn àlùfáà kò ì tí ì tún ilé tí a kọ́ fún Olúwa ṣe.
Na rĩrĩ, o na gũkinyĩria mwaka-inĩ wa mĩrongo ĩĩrĩ na ĩtatũ wa Mũthamaki Joashu, athĩnjĩri-Ngai magĩkorwo matiacookereirie hekarũ.
7 Nígbà náà, ọba Jehoaṣi pe Jehoiada àlùfáà àti àwọn àlùfáà yòókù, ó sì bi wọ́n pé, “Kí ni ó dé tí ẹ̀yin kò fi tún ìbàjẹ́ tí a ṣe sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa ṣe? Ẹ má ṣe gba owó mọ́ lọ́wọ́ àwọn afowópamọ́, ṣùgbọ́n ẹ gbé e kalẹ̀ fún títún ilé tí a kọ́ fún Olúwa ṣe.”
Nĩ ũndũ ũcio Mũthamaki Joashu agĩĩta Jehoiada ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai na athĩnjĩri-Ngai arĩa angĩ, akĩmooria atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ mũtaracookereria hekarũ kũrĩa ĩtharũkĩte? Mũtigeetie mbeeca ingĩ kuuma kũrĩ aigi kĩgĩĩna, no cineanei nĩguo icookererie hekarũ kũrĩa ĩtharũkĩte.”
8 Àwọn àlùfáà fi ara mọ́ pé wọn kò nígbà owó kankan mọ́ lọ́wọ́ àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ sì ni, wọn kò sì ní tún ilé tí a kọ́ fún Olúwa ṣe mọ́ fúnra wọn.
Nao athĩnjĩri-Ngai magĩtĩkĩra atĩ matikũngania mbeeca ingĩ kuuma kũrĩ andũ, na atĩ o ene tio megũcookereria hekarũ.
9 Jehoiada àlùfáà mú àpótí kan, ó sì lu ihò sí ìdérí rẹ̀. Ó gbé e sí ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ ní apá ọ̀tún bí ẹnìkan ti wọlé tí a kọ́ fún Olúwa. Àwọn àlùfáà tí ó ṣọ́ ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé fi sínú àpótí náà gbogbo owó tí a mú wá sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa.
Nake Jehoiada ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai akĩoya ithandũkũ na agĩtũra ngunĩko yarĩo irima. Akĩrĩiga mwena wa ũrĩo wa mũndũ agĩtoonya hekarũ ya Jehova. Athĩnjĩri-Ngai arĩa maarangagĩra itoonyero magĩĩkĩra mbeeca ciothe ithandũkũ-inĩ iria ciarehagwo hekarũ-inĩ ya Jehova.
10 Ìgbàkígbà tí wọ́n bá ti rí wí pé owó púpọ̀ wà nínú àpótí, akọ̀wé ọba àti olórí àlùfáà yóò wá, wọ́n á ka owó náà tí wọ́n ti mú wá sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa. Wọn a sì kó o sínú àwọn àpò.
Hĩndĩ ĩrĩa yothe moonaga mbeeca nĩciaingĩha ithandũkũ-inĩ, mwandĩki-marũa wa mũthamaki na mũthĩnjĩri-Ngai ũrĩa mũnene mookaga, magatara mbeeca iria ciakoragwo irehetwo hekarũ-inĩ ya Jehova na magaciĩkĩra mĩhuko.
11 Nígbà tí wọ́n bá ti pinnu iye rẹ̀, wọn a kó owó náà fún àwọn tí a ti yàn láti bojútó iṣẹ́ náà lórí ilé tí a kọ́ fún Olúwa. Pẹ̀lú u rẹ̀, wọ́n sọ fún àwọn tí ó ń ṣiṣẹ́ lórí ilé tí a kọ́ fún Olúwa; àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà àti àwọn olùkọ́lé.
Rĩrĩa mũigana wa mbeeca wahinga, makanengera andũ arĩa maathuurĩtwo matuĩke arori a wĩra wa hekarũ. Mbeeca icio ciarĩhaga aruti a wĩra wa hekarũ ya Jehova na andũ a wĩra wa mbaũ, na aaki,
12 Àwọn ilé ńlá àti àwọn agékúta. Wọ́n ra igi gẹdú àti òkúta tí wọ́n tọ́jú fún tuntun ilé tí a kọ́ fún Olúwa ṣe. Wọ́n tún ohun gbogbo tí wọ́n ná fún títún tẹmpili ṣe.
na arĩa maakaga na mahiga, na aicũhia a mahiga. Maagũraga mbaũ na mahiga maicũhie nĩ ũndũ wa gũcookereria hekarũ ya Jehova kũrĩa yatharũkĩte na makarĩha mahũthĩro mothe ma gũcookereria hekarũ.
13 Owó tí a mú wá sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa kò jẹ́ níná fún ṣíṣe òpó fàdákà, ohun èlò ta fi ń fa ẹnu fìtílà, àwokòtò, ìpè, ohun èlò wúrà tàbí ohun èlò fàdákà kan fún ilé tí a kọ́ fún Olúwa.
Mbeeca iria ciarehagwo hekarũ-inĩ itiahũthagĩrwo na gũthondeka iraĩ cia betha, kana magathĩ ma gũthima ndaambĩ, kana mbakũri cia kũminjaminja, kana tũrumbeta, kana kĩndũ o gĩothe gĩa thahabu kana gĩa betha nĩ ũndũ wa hekarũ ya Jehova.
14 A sì san án fún àwọn ọkùnrin tí ó ń ṣiṣẹ́, tí wọ́n ń tọ́jú ilé tí a kọ́ fún Olúwa.
Mbeeca icio ciarĩhaga aruti a wĩra arĩa maarutaga wĩra wa gũcookereria hekarũ.
15 Wọn kò sì bá àwọn ọkùnrin náà ṣírò, ní ọwọ́ ẹni tí wọ́n fún ní owó láti san fún àwọn òṣìṣẹ́. Torí wọ́n ṣe é pẹ̀lú òdodo tí ó pé.
Matioragia mathabu ma mbeeca kuuma kũrĩ andũ arĩa maanengerete mbeeca marĩhe aruti a wĩra, tondũ andũ acio maarĩ ehokeku biũ.
16 Owó láti ibi ọrẹ ẹ̀bi àti ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ ní a kò mú wá sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa, ó jẹ́ ti àwọn àlùfáà.
Mbeeca cia maruta ma mahĩtia, na maruta ma mehia itiarehagwo hekarũ-inĩ ya Jehova, icio ciarĩ cia athĩnjĩri-Ngai.
17 Ní déédé àkókò yìí, Hasaeli ọba Siria gòkè lọ láti dojúkọ Gati àti láti fi agbára mú un. Nígbà náà, ó yípadà láti dojúkọ Jerusalẹmu.
Ihinda-inĩ o rĩu Hazaeli mũthamaki wa Suriata akĩambata agĩthiĩ agĩtharĩkĩra Gathu na akĩrĩtaha. Ningĩ akĩhũndũka, agĩthiĩ gũtharĩkĩra Jerusalemu.
18 Ṣùgbọ́n Jehoaṣi ọba Juda mú gbogbo ohun mímọ́ tí a gbé ka iwájú tí a yà sọ́tọ̀ nípasẹ̀ baba rẹ̀ Jehoṣafati, Jehoramu àti Ahasiah, àwọn ọba Juda, àti àwọn ẹ̀bùn tí òun tìkára rẹ̀ ti yà sọ́tọ̀ àti gbogbo wúrà, tí ó rí nínú ibi ìfowópamọ́ sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa àti ní ti ààfin ọba, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí Hasaeli; ọba Siria, tí ó sì fà padà kúrò ní Jerusalẹmu.
No rĩrĩ, Joashu mũthamaki wa Juda akĩoya indo ciothe iria ciatheretio ikaamũrwo nĩ maithe make, nao nĩ Jehoshafatu, na Jehoramu na Ahazia, athamaki a Juda o na iheo iria we mwene aamũrĩte, o na thahabu iria ciakoretwo kĩgĩĩna-inĩ kĩa hekarũ ya Jehova, o na iria ciarĩ nyũmba ya ũthamaki, agĩcineana itwarĩrwo Hazaeli mũthamaki wa Suriata, nake agĩthiĩ, agĩtiga gũtharĩkĩra Jerusalemu.
19 Pẹ̀lú ìyókù ìṣe Joaṣi, àti ohun gbogbo tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Juda?
Ha ũhoro wa maũndũ marĩa mangĩ makoniĩ wathani wa Joashu, na ũrĩa wothe eekire-rĩ, githĩ matiandĩkĩtwo ibuku-inĩ rĩa mahinda ma athamaki a Juda?
20 Àwọn oníṣẹ́ rẹ̀ dìtẹ̀ sí i wọ́n sì lù ú pa ní Beti-Milo ní ọ̀nà sí Silla.
Nao anene ake makĩmũciirĩrĩra ndundu mamũũkĩrĩre, makĩmũũragĩra Bethi-Milo, njĩra-inĩ ya gũthiĩ Sila.
21 Àwọn oníṣẹ́ tí ó pa á jẹ́ Josabadi ọmọ Ṣimeati àti Jehosabadi ọmọ Ṣomeri. Ó kú, wọ́n sì sin ín pẹ̀lú baba rẹ̀ ní ìlú ńlá ti Dafidi. Amasiah ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Nao anene arĩa maamũũragire nĩ Jozakaru mũrũ wa Shimeathu, na Jehozabadu mũrũ wa Shomeru. Joashu agĩkua na agĩthikwo hamwe na maithe make itũũra-inĩ rĩa Daudi. Nake mũriũ Amazia agĩtuĩka mũthamaki ithenya rĩake.

< 2 Kings 12 >