< 2 Kings 12 >

1 Ní ọdún keje tí Jehu, Jehoaṣi di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ogójì ọdún. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Sibia: Ó wá láti Beerṣeba.
La septième année de Jéhu, Joas commença de régner; et il régna 40 ans à Jérusalem; et le nom de sa mère était Tsibia, de Beër-Shéba.
2 Jehoaṣi ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú Olúwa ní gbogbo ọdún tí Jehoiada àlùfáà fi àṣẹ fún un.
Et Joas fit ce qui est droit aux yeux de l’Éternel, tous les jours que Jehoïada, le sacrificateur, l’instruisit.
3 Àwọn ibi gíga, bí ó ti wù kí ó rí, a kò sí wọn ní ìdí, àwọn ènìyàn sì tẹ̀síwájú láti máa rú ẹbọ àti sísun tùràrí níbẹ̀.
Seulement les hauts lieux ne furent pas ôtés; le peuple sacrifiait encore et faisait fumer de l’encens sur les hauts lieux.
4 Jehoaṣi sọ fún àwọn àlùfáà pé, “Gba gbogbo owó tí wọ́n mú wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ mímọ́ sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa owó tí a gbà ní ìgbà kíka àwọn ènìyàn ìlú, owó tí a gbà láti ọwọ́ olúkúlùkù bí wọ́n ti ṣe jẹ́ ẹ̀yà àti owó tí ó ti ọkàn olúkúlùkù wá tí a mú wá sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa.
Et Joas dit aux sacrificateurs: Tout l’argent des choses saintes qui est apporté dans la maison de l’Éternel, l’argent de tout homme qui passe [par le dénombrement], l’argent des âmes selon l’estimation de chacun, tout argent qu’il monte au cœur de chacun d’apporter dans la maison de l’Éternel,
5 Jẹ́ kí gbogbo àlùfáà gba owó náà lọ́wọ́ ọ̀kan nínú àwọn akápò. Kí a sì lò ó fún tuntun ohunkóhun tí ó bá bàjẹ́ nínú ilé tí a kọ́ fún Olúwa ṣe.”
que les sacrificateurs le prennent, chacun de la part [des gens] de sa connaissance, et qu’ils réparent les brèches de la maison, partout où il se trouvera des brèches.
6 Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹtàlélógún ọba Jehoaṣi, àwọn àlùfáà kò ì tí ì tún ilé tí a kọ́ fún Olúwa ṣe.
Et il arriva, la vingt -troisième année du roi Joas, que les sacrificateurs n’avaient point réparé les brèches de la maison.
7 Nígbà náà, ọba Jehoaṣi pe Jehoiada àlùfáà àti àwọn àlùfáà yòókù, ó sì bi wọ́n pé, “Kí ni ó dé tí ẹ̀yin kò fi tún ìbàjẹ́ tí a ṣe sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa ṣe? Ẹ má ṣe gba owó mọ́ lọ́wọ́ àwọn afowópamọ́, ṣùgbọ́n ẹ gbé e kalẹ̀ fún títún ilé tí a kọ́ fún Olúwa ṣe.”
Et le roi Joas appela Jehoïada, le sacrificateur, et les [autres] sacrificateurs, et il leur dit: Pourquoi n’avez-vous pas réparé les brèches de la maison? Et maintenant, ne prenez pas d’argent de vos connaissances, mais vous le donnerez pour les brèches de la maison.
8 Àwọn àlùfáà fi ara mọ́ pé wọn kò nígbà owó kankan mọ́ lọ́wọ́ àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ sì ni, wọn kò sì ní tún ilé tí a kọ́ fún Olúwa ṣe mọ́ fúnra wọn.
Et les sacrificateurs consentirent à ne plus prendre d’argent de la part du peuple, et que seulement on répare les brèches de la maison.
9 Jehoiada àlùfáà mú àpótí kan, ó sì lu ihò sí ìdérí rẹ̀. Ó gbé e sí ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ ní apá ọ̀tún bí ẹnìkan ti wọlé tí a kọ́ fún Olúwa. Àwọn àlùfáà tí ó ṣọ́ ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé fi sínú àpótí náà gbogbo owó tí a mú wá sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa.
Et Jehoïada, le sacrificateur, prit un coffre et fit un trou dans son couvercle, et le mit à côté de l’autel, à droite quand on entre dans la maison de l’Éternel; et les sacrificateurs qui gardaient le seuil mettaient là tout l’argent qui était apporté à la maison de l’Éternel.
10 Ìgbàkígbà tí wọ́n bá ti rí wí pé owó púpọ̀ wà nínú àpótí, akọ̀wé ọba àti olórí àlùfáà yóò wá, wọ́n á ka owó náà tí wọ́n ti mú wá sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa. Wọn a sì kó o sínú àwọn àpò.
Et il arrivait que, lorsqu’ils voyaient qu’il y avait beaucoup d’argent dans le coffre, le secrétaire du roi montait, et le grand sacrificateur, et ils serraient et comptaient l’argent qui était trouvé dans la maison de l’Éternel;
11 Nígbà tí wọ́n bá ti pinnu iye rẹ̀, wọn a kó owó náà fún àwọn tí a ti yàn láti bojútó iṣẹ́ náà lórí ilé tí a kọ́ fún Olúwa. Pẹ̀lú u rẹ̀, wọ́n sọ fún àwọn tí ó ń ṣiṣẹ́ lórí ilé tí a kọ́ fún Olúwa; àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà àti àwọn olùkọ́lé.
et ils remettaient l’argent pesé entre les mains de ceux qui faisaient l’ouvrage, qui étaient établis sur la maison de l’Éternel, et ceux-ci le livraient aux charpentiers et aux constructeurs qui travaillaient à la maison de l’Éternel,
12 Àwọn ilé ńlá àti àwọn agékúta. Wọ́n ra igi gẹdú àti òkúta tí wọ́n tọ́jú fún tuntun ilé tí a kọ́ fún Olúwa ṣe. Wọ́n tún ohun gbogbo tí wọ́n ná fún títún tẹmpili ṣe.
et aux maçons, et aux tailleurs de pierres, pour acheter des bois et des pierres de taille, afin de réparer les brèches de la maison de l’Éternel, et pour tout ce qui se dépensait pour la maison afin de la réparer.
13 Owó tí a mú wá sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa kò jẹ́ níná fún ṣíṣe òpó fàdákà, ohun èlò ta fi ń fa ẹnu fìtílà, àwokòtò, ìpè, ohun èlò wúrà tàbí ohun èlò fàdákà kan fún ilé tí a kọ́ fún Olúwa.
Toutefois on ne fit pas pour la maison de l’Éternel des écuelles d’argent, des couteaux, des bassins, des trompettes, ni aucun ustensile d’or ou ustensile d’argent, avec l’argent qu’on apportait dans la maison de l’Éternel;
14 A sì san án fún àwọn ọkùnrin tí ó ń ṣiṣẹ́, tí wọ́n ń tọ́jú ilé tí a kọ́ fún Olúwa.
mais on le donnait à ceux qui faisaient l’ouvrage, et ils l’employaient à réparer la maison de l’Éternel.
15 Wọn kò sì bá àwọn ọkùnrin náà ṣírò, ní ọwọ́ ẹni tí wọ́n fún ní owó láti san fún àwọn òṣìṣẹ́. Torí wọ́n ṣe é pẹ̀lú òdodo tí ó pé.
Et on ne comptait pas avec les hommes entre les mains desquels on remettait l’argent pour le donner à ceux qui faisaient l’ouvrage, car ils agissaient fidèlement.
16 Owó láti ibi ọrẹ ẹ̀bi àti ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ ní a kò mú wá sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa, ó jẹ́ ti àwọn àlùfáà.
L’argent des sacrifices pour le délit et l’argent des sacrifices pour le péché n’était point apporté dans la maison de l’Éternel; il était pour les sacrificateurs.
17 Ní déédé àkókò yìí, Hasaeli ọba Siria gòkè lọ láti dojúkọ Gati àti láti fi agbára mú un. Nígbà náà, ó yípadà láti dojúkọ Jerusalẹmu.
Alors Hazaël, roi de Syrie, monta, et fit la guerre contre Gath, et la prit; et Hazaël tourna sa face pour monter contre Jérusalem.
18 Ṣùgbọ́n Jehoaṣi ọba Juda mú gbogbo ohun mímọ́ tí a gbé ka iwájú tí a yà sọ́tọ̀ nípasẹ̀ baba rẹ̀ Jehoṣafati, Jehoramu àti Ahasiah, àwọn ọba Juda, àti àwọn ẹ̀bùn tí òun tìkára rẹ̀ ti yà sọ́tọ̀ àti gbogbo wúrà, tí ó rí nínú ibi ìfowópamọ́ sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa àti ní ti ààfin ọba, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí Hasaeli; ọba Siria, tí ó sì fà padà kúrò ní Jerusalẹmu.
Et Joas, roi de Juda, prit toutes les choses saintes, que Josaphat, et Joram, et Achazia, ses pères, rois de Juda, avaient consacrées, et celles qu’il avait lui-même consacrées, et tout l’or qui se trouvait dans les trésors de la maison de l’Éternel et de la maison du roi, et les envoya à Hazaël, roi de Syrie: et il se retira de devant Jérusalem.
19 Pẹ̀lú ìyókù ìṣe Joaṣi, àti ohun gbogbo tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Juda?
Et le reste des actes de Joas, et tout ce qu’il fit, cela n’est-il pas écrit au livre des chroniques des rois de Juda?
20 Àwọn oníṣẹ́ rẹ̀ dìtẹ̀ sí i wọ́n sì lù ú pa ní Beti-Milo ní ọ̀nà sí Silla.
Et ses serviteurs se levèrent et firent une conspiration, et frappèrent Joas dans la maison de Millo, à la descente de Silla.
21 Àwọn oníṣẹ́ tí ó pa á jẹ́ Josabadi ọmọ Ṣimeati àti Jehosabadi ọmọ Ṣomeri. Ó kú, wọ́n sì sin ín pẹ̀lú baba rẹ̀ ní ìlú ńlá ti Dafidi. Amasiah ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Et Jozacar, fils de Shimhath, et Jozabad, fils de Shomer, ses serviteurs, le frappèrent, et il mourut; et on l’enterra avec ses pères dans la ville de David. Et Amatsia, son fils, régna à sa place.

< 2 Kings 12 >