< 2 Kings 11 >
1 Nígbà tí Ataliah ìyá Ahasiah rí i wí pé ọmọ rẹ̀ ti kú, ó tẹ̀síwájú láti pa gbogbo ìdílé ọba náà run.
Rĩrĩa Athalia nyina wa Ahazia onire atĩ mũriũ nĩakua-rĩ, agĩthiĩ na mbere kũũraga andũ othe a nyũmba yothe ya ũthamaki.
2 Ṣùgbọ́n Jehoṣeba ọmọbìnrin ọba Jehoramu àti arábìnrin Ahasiah, mú Joaṣi ọmọ Ahasiah, ó sì jí i lọ kúrò láàrín àwọn ọmọ-aládébìnrin ti ọba náà, tí ó kù díẹ̀ kí a pa. Ó gbé òhun àti olùtọ́jú rẹ̀ sínú ìyẹ̀wù láti fi pamọ́ kúrò fún Ataliah; bẹ́ẹ̀ ni a kò pa á.
No rĩrĩ, Jehosheba, mwarĩ wa Mũthamaki Jehoramu na mwarĩ wa nyina na Ahazia, akĩoya Joashu mũrũ wa Ahazia akĩmweheria kuuma kũrĩ ariũ a mũthamaki arĩa maakirie kũũragwo. Akĩmũiga hamwe na mũreri wake kanyũmba ga gũkoma, akĩmũhitha kuuma kũrĩ Athalia; nĩ ũndũ ũcio Joashu ndaigana kũũragwo.
3 Ó wà ní ìpamọ́ pẹ̀lú olùtọ́jú ní ilé tí a kọ́ fún Olúwa fún ọdún mẹ́fà nígbà tí Ataliah fi jẹ ọba lórí ilẹ̀ náà.
Aikarire ahithĩtwo hamwe na mũreri wake thĩinĩ wa hekarũ ya Jehova mĩaka ĩtandatũ ĩrĩa Athalia aathamakire bũrũri ũcio.
4 Ní ọdún keje, Jehoiada ránṣẹ́ ó sí mú àwọn olórí lórí ọ̀rọ̀ọ̀rún, pẹ̀lú àwọn balógun àti àwọn olùṣọ́, ó sì mú wọn wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ nínú ilé tí a kọ́ fún Olúwa. Ó ṣe májẹ̀mú pẹ̀lú wọn, ó sì fi wọ́n sí abẹ́ ìbúra nínú ilé tí a kọ́ fún Olúwa. Níbẹ̀ ni ó fi ọmọkùnrin ọba hàn wọ́n.
Mwaka-inĩ wa mũgwanja, Jehoiada agĩtũmanĩra anene a ikundi arĩa maathaga thigari igana rĩmwe, thĩinĩ wa andũ arĩa meetagwo Akari, na arangĩri nao magĩũka kũrĩ we kũu hekarũ-inĩ ya Jehova. Nake akĩgĩa kĩrĩkanĩro nao na akĩmehĩtithĩria kũu hekarũ-inĩ ya Jehova. Agĩcooka akĩmoonia mũriũ wa mũthamaki.
5 Ó pàṣẹ fún wọn, wí pé, “Ìwọ tí ó wà nínú àwọn ẹgbẹ́ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta tí ó ń lọ fún iṣẹ́ ìsìn ní ọjọ́ ìsinmi—ìdámẹ́ta yín fún ṣíṣọ́ ààfin ọba.
Akĩmaatha akĩmeera atĩrĩ, “Mũgwĩka ũũ: Inyuĩ arĩa othe mũgaakorwo mũrĩ wĩra mũthenya wa thabatũ-rĩ, gĩcunjĩ kĩmwe kĩanyu gĩa ithatũ gĩkaarangĩra nyũmba ya ũthamaki,
6 Ìdámẹ́ta ní ẹnu ìlẹ̀kùn huri, àti ìdámẹ́ta ní ẹnu ìlẹ̀kùn ní ẹ̀yìn olùṣọ́, tí ó yípadà ní ṣíṣọ́ ilé tí a kọ́,
nakĩo gĩcunjĩ gĩa ithatũ kĩrangĩre Kĩhingo gĩa Suri, ningĩ gĩcunjĩ gĩa ithatũ gĩkorwo kĩhingo-inĩ kĩrĩa kĩrĩ thuutha wa arangĩri arĩa mateithanagia kũrangĩra hekarũ,
7 àti ẹ̀yin tí ó wà ní ẹgbẹ́ kejì yòókù tí kì í lọ ibi iṣẹ́ ìsìn ní ọjọ́ ìsinmi gbogbo ni kí ó ṣọ́ ilé tí a kọ́ fún Olúwa fún ọba.
na inyuĩ andũ arĩa makoragwo thĩinĩ wa ikundi icio ingĩ igĩrĩ, arĩa matakoragwo wĩra mũthenya wa thabatũ-rĩ, othe makaarangĩra hekarũ nĩ ũndũ wa mũthamaki.
8 Ẹ mú ibùjókòó yín yí ọba ká, olúkúlùkù ọkùnrin pẹ̀lú ohun ìjà rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀. Ẹnikẹ́ni tí ó bá súnmọ́ ọgbà yìí gbọdọ̀ kú. Ẹ dúró súnmọ́ ọba ní ibikíbi tí ó bá lọ.”
Mũikare mũthiũrũrũkĩirie mũthamaki, o mũndũ anyiitĩte indo ciake cia mbaara na guoko. Mũndũ o na ũrĩkũ angĩkaamũkuhĩrĩria no nginya ooragwo. Mũikare hakuhĩ na mũthamaki o harĩa hothe angĩthiĩ.”
9 Olórí àwọn ọ̀rọ̀ọ̀rún ṣe gẹ́gẹ́ bí Jehoiada àlùfáà ti pa á láṣẹ. Olúkúlùkù mú àwọn ọkùnrin rẹ̀ àwọn tí ó ń lọ sí iṣẹ́ ìsìn ní ọjọ́ ìsinmi àti àwọn tí wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Jehoiada àlùfáà.
Nao anene a ita arĩa maathaga ikundi cia andũ igana rĩmwe magĩĩka o ta ũrĩa Jehoiada, mũthĩnjĩri-Ngai aathanĩte. O mũnene akĩoya andũ ake, arĩa maathiiaga wĩra mũthenya ũcio wa thabatũ na arĩa moimagĩra wĩra hĩndĩ ĩyo, othe magĩũka kũrĩ Jehoiada mũthĩnjĩri-Ngai.
10 Nígbà náà, ó fún àwọn olórí ní àwọn ọ̀kọ̀ àti àwọn àpáta tí ó ti jẹ́ ti ọba Dafidi tí ó sì wà nínú ilé tí a kọ́ fún Olúwa.
Nake akĩhe anene acio matimũ na ngo iria ciarĩ cia Mũthamaki Daudi, iria ciakoragwo hekarũ-inĩ ya Jehova.
11 Àwọn olùṣọ́, olúkúlùkù pẹ̀lú ohun ìjà rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀, wọ́n sì dúró ṣinṣin yìí ọba ká—lẹ́bàá pẹpẹ àti ilé ìhà gúúsù sí ìhà àríwá ilé tí a kọ́ fun Olúwa náà.
Nao arangĩri, o mũndũ arĩ na indo ciake cia mbaara, magĩthiũrũrũkĩria mũthamaki hau hakuhĩ na kĩgongona, na magĩthiũrũrũkĩria hekarũ kuuma mwena wa gũthini nginya mwena wa gathigathini wayo.
12 Jehoiada mú ọmọkùnrin ọba jáde, ó sì gbé adé náà lé e: ó fún un ní ẹ̀dà májẹ̀mú, wọ́n sì kéde ọba rẹ̀. Wọ́n fi àmì òróró yàn án, àwọn ènìyàn pa àtẹ́wọ́, wọ́n sì kígbe, “Kí ẹ̀mí ọba kí ó gùn.”
Jehoiada akĩrehe mũrũ wa mũthamaki akĩmwĩkĩra thũmbĩ, akĩmũnengera Ibuku rĩa Kĩrĩkanĩro, na akĩmwanĩrĩra atĩ nĩwe mũthamaki. Makĩmũitĩrĩria maguta, nao andũ makĩhũũra hĩ na makĩanĩrĩra makiugaga atĩrĩ, “Mũthamaki arotũũra nginya tene!”
13 Nígbà tí Ataliah gbọ́ ariwo tí àwọn olùṣọ́ àti àwọn ènìyàn ń pa, ó lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn nínú ilé tí a kọ́ fún Olúwa.
Rĩrĩa Athalia aaiguire inegene rĩa andũ na arangĩri, agĩthiĩ kũrĩ andũ hekarũ-inĩ ya Jehova.
14 Ó wò ó, níbẹ̀ ni ọba, tí ó dúró lẹ́bàá òpó, gẹ́gẹ́ bí àṣà ti rí. Àwọn balógun àti àwọn afùnpè wà ní ẹ̀bá ọba, gbogbo àwọn ènìyàn ilé náà sì ń yọ̀, wọ́n sì ń fun ìpè pẹ̀lú. Nígbà náà Ataliah fa aṣọ ìgúnwà rẹ̀ ya. Ó sì kégbe pé, “Ọ̀tẹ̀! Ọ̀tẹ̀!”
Agĩcũthĩrĩria na akĩona mũthamaki arũgamĩte gĩtugĩ-inĩ o ta ũrĩa mũtugo warĩ. Nao anene na ahuhi tũrumbeta maarũgamĩte hakuhĩ na mũthamaki, nao andũ othe a bũrũri magakena makĩhuhaga tũrumbeta. Nake Athalia agĩtembũranga nguo ciake cia igũrũ, na akĩanĩrĩra, akiuga atĩrĩ, “Ungumania! Ungumania!”
15 Jehoiada àlùfáà pàṣẹ fún olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún, ta ni ó wà ní ìkáwọ́ ọ̀wọ́ ogun: “Mú u jáde láàrín àwọn ẹgbẹ́ ogun yìí kí o sì fi sí ipa idà ẹnikẹ́ni tí ó bá tẹ̀lé.” Nítorí àlùfáà ti sọ, “A kò gbọdọ̀ pa á nínú ilé tí a kọ́ fún Olúwa.”
Jehoiada mũthĩnjĩri-Ngai agĩatha anene a ita a thigari igana igana arĩa maarĩ arũgamĩrĩri a mbũtũ, akĩmeera atĩrĩ, “Mũrutũrũrei, mũmũrehe arĩ gatagatĩ ga thigari, na mũndũ o wothe ũngĩmuuma thuutha, ooragwo.” Nĩgũkorwo mũthĩnjĩri-Ngai nĩoigĩte atĩrĩ, “Ndakooragĩrwo hekarũ-inĩ ya Jehova.”
16 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n fi agbára mú un bí ó ti dé ibi tí àwọn ẹṣin tí ń wọ ilẹ̀ ààfin ọba àti níbẹ̀ ni a ti pa á.
Nĩ ũndũ ũcio makĩmũnyiitĩra harĩa mbarathi ciatoonyagĩra igĩthiĩ nja cia nyũmba ya ũthamaki, makĩmũũragĩra hau.
17 Nígbà náà ni Jehoiada dá májẹ̀mú láàrín Olúwa àti ọba àti àwọn ènìyàn tí yóò jẹ́ ènìyàn Olúwa. Ó dá májẹ̀mú láàrín ọba àti àwọn ènìyàn pẹ̀lú.
Nake Jehoiada akĩgĩa na kĩrĩkanĩro gatagatĩ ka Jehova, na mũthamaki, o na andũ, atĩ o nĩmegũtuĩka andũ a Jehova. Ningĩ agĩcooka agĩthondeka kĩrĩkanĩro gatagatĩ ka mũthamaki na andũ.
18 Gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà lọ sí ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali wọ́n sì ya á bolẹ̀. Wọ́n fọ́ àwọn pẹpẹ àti òrìṣà sí wẹ́wẹ́. Wọ́n sì pa Mattani àlùfáà Baali níwájú àwọn pẹpẹ. Nígbà náà, Jehoiada àlùfáà náà sì yan àwọn olùṣọ́ sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa.
Nao andũ othe a bũrũri magĩthiĩ hekarũ-inĩ ya Baali na makĩmĩtharia. Makiunanga igongona na mĩhianano, na makĩũragĩra Matani ũrĩa warĩ mũthĩnjĩri-ngai wa Baali hau mbere ya igongona icio. Ningĩ Jehoiada mũthĩnjĩri-Ngai akĩiga arangĩri hau hekarũ-inĩ ya Jehova.
19 Ó mú pẹ̀lú u rẹ̀ àwọn olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún àti gbogbo balógun àti àwọn olùṣọ́ àti gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà àti lápapọ̀, wọ́n mú ọba sọ̀kalẹ̀ wá láti ilé tí a kọ́ fún Olúwa. Wọ́n sì wọ inú ààfin lọ, wọ́n sì wọlé nípa ìlẹ̀kùn ti àwọn olùṣọ́. Ọba sì mú ààyè rẹ̀ ní orí ìtẹ́ ọba.
Nake agĩthiĩ na anene a ita arĩa maarũgamagĩrĩra ikundi cia thigari igana igana, na Akari, na arangĩri, o hamwe na andũ othe a bũrũri, na marĩ hamwe makĩruta mũthamaki hekarũ-inĩ ya Jehova makĩmũtwara nyũmba ya ũthamaki matoonyeire kĩhingo-inĩ kĩa arangĩri. Hĩndĩ ĩyo mũthamaki agĩikarĩra gĩtĩ gĩake kĩa ũnene kũu nyũmba-inĩ ya ũthamaki.
20 Gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà sì yọ̀, ìlú náà sì dákẹ́ jẹ́ẹ́. Nítorí a pa Ataliah pẹ̀lú idà náà ní ààfin ọba.
Nao andũ othe a bũrũri magĩkena. Narĩo itũũra rĩkĩhoorera, tondũ Athalia nĩarĩkĩtie kũũragwo na rũhiũ rwa njora nyũmba-inĩ ya ũthamaki.
21 Joaṣi jẹ́ ọmọ ọdún méje nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ ìjọba rẹ̀.
Joashu aarĩ wa mĩaka mũgwanja rĩrĩa aambĩrĩirie gwathana.