< 2 Kings 10 >

1 Nísinsin yìí, Ahabu ṣì ní àádọ́rin ọmọkùnrin ní ìdílé rẹ̀ ní Samaria. Bẹ́ẹ̀ ni, Jehu kọ lẹ́tà, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí Samaria: sí àwọn oníṣẹ́ Jesreeli, sí àwọn àgbàgbà àti sí àwọn olùtọ́jú àwọn ọmọ Ahabu. Ó wí pé,
Și Ahab avea șaptezeci de fii în Samaria. Și Iehu a scris scrisori și le-a trimis în Samaria la conducătorii din Izreel, la bătrâni și la cei ce crescuseră pe copiii lui Ahab, spunând:
2 “Ní kété tí lẹ́tà bá ti dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí àwọn ọmọ ọ̀gá rẹ wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ sì ní àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹṣin, ìlú olódi kan pẹ̀lú ohun ìjà,
Și imediat ce această scrisoare ajunge la voi, văzând că fiii stăpânului vostru sunt cu voi și aveți cu voi care și cai și o cetate întărită și arme,
3 yan èyí tí ó dára àti èyí tí ó níye jùlọ nínú àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ, kí o sì gbé e lé orí ìtẹ́ baba a rẹ̀. Nígbà náà, kí o sì jà fún ilé ọ̀gá à rẹ.”
Alegeți pe cel mai bun și mai potrivit dintre fiii stăpânului vostru și puneți-l pe tronul tatălui său și luptați pentru casa stăpânului vostru.
4 Ṣùgbọ́n ẹ̀rù bà wọ́n, wọ́n sì wí pé, “Tí ọba méjì kò bá le kojú ìjà sí i, báwo ni a ṣẹ le è ṣe é?”
Dar ei erau înfricoșați peste măsură și au spus: Iată, doi împărați nu au putut sta înaintea lui, cum atunci vom sta noi?
5 Bẹ́ẹ̀ ẹni tí ń ṣe olórí ilé, ẹni tí ń ṣe olórí ìlú ńlá, àwọn àgbàgbà àti àwọn olùtọ́jú náà rán iṣẹ́ yìí sí Jehu, pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ni àwa jẹ́ pẹ̀lú, àwa yóò ṣe ohunkóhun tí o bá sọ. Àwa kì yóò yan ẹnikẹ́ni gẹ́gẹ́ bí ọba; ìwọ ṣe ohunkóhun tí o rò pé ó dára jù lójú rẹ.”
Și cel care era peste casă și cel care era peste cetate, bătrânii de asemenea și cei care i-au crescut pe copii, au trimis la Iehu, spunând: Noi suntem servitorii tăi și vom face orice ne vei porunci; nu vom face pe nimeni împărat; fă ce este bine în ochii tăi.
6 Nígbà náà ni Jehu kọ lẹ́tà kejì sí wọn, wí pé, “Tí ìwọ bá wà ní ìhà tèmi, tí o sì pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, mú orí àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ wá sí ọ̀dọ̀ mi ní Jesreeli ní ìwòyí ọ̀la.” Nísinsin yìí, àwọn ọmọ-aládé àádọ́rin ọkùnrin, ń bẹ pẹ̀lú àwọn ènìyàn ńlá ìlú náà tí ń tọ́ wọn.
Și el le-a scris o scrisoare a doua oară, spunând: Dacă voi sunteți pentru mine și dacă veți da ascultare vocii mele, luați capetele oamenilor, ale fiilor stăpânului vostru, și veniți la mine în Izreel până mâine pe timpul acesta. Și fiii împăratului, fiind șaptezeci de persoane, erau cu marii bărbați ai cetății care îi crescuseră.
7 Nígbà tí ìwé náà dé ọ̀dọ̀ wọn, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí mú gbogbo àwọn ọmọ ọba tí gbogbo wọ́n jẹ́ àádọ́rin wọ́n sì pa gbogbo wọn. Wọ́n gbé orí wọn sí inú apẹ̀rẹ̀, wọ́n fi ránṣẹ́ sí Jehu ní Jesreeli.
Și s-a întâmplat, după ce scrisoarea a venit la ei, că au luat pe fiii împăratului și au ucis șaptezeci de persoane și le-au pus capetele în coșuri și i le-au trimis la Izreel.
8 Nígbà tí ìránṣẹ́ náà dé, ó sọ fún Jehu, “Wọ́n ti gbé orí àwọn ọmọ ọba náà wá.” Nígbà náà Jehu pàṣẹ, “Ẹ tò wọ́n ní òkìtì méjì ní àtiwọ ẹnu ibodè ìlú ńlá títí di òwúrọ̀.”
Și a venit un mesager și i-a spus, zicând: Au adus capetele fiilor împăratului. Iar el a spus: Puneți-le în două grămezi la intrarea porții până dimineață.
9 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Jehu jáde lọ. Ó dúró níwájú gbogbo àwọn ènìyàn, ó sì wí pé, “Ẹ̀yin jẹ́ aláìjẹ̀bi. Èmi ni mo dìtẹ̀ sí ọ̀gá mi, tí mo sì pa á, ṣùgbọ́n ta ni ó pa gbogbo àwọn wọ̀nyí?
Și s-a întâmplat dimineața, că el a ieșit și a stat în picioare și a spus întregului popor: Voi sunteți drepți; iată, eu am uneltit împotriva stăpânului meu și l-am ucis; dar cine i-a ucis pe toți aceștia?
10 Nígbà yìí, kò sí ọ̀rọ̀ kan tí Olúwa ti sọ sí ilé Ahabu tí yóò kùnà. Olúwa ti ṣe ohun tí ó ṣèlérí nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ Elijah.”
Să știți acum că nu va cădea la pământ nimic din cuvântul DOMNULUI, pe care DOMNUL l-a vorbit referitor la casa lui Ahab, pentru că DOMNUL a făcut ceea ce a vorbit prin servitorul său Ilie.
11 Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa gbogbo ẹni tí ó kù Jesreeli ní ilé Ahabu, pẹ̀lúpẹ̀lú gbogbo àwọn ọkùnrin ìjòyè rẹ̀, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tímọ́tímọ́ àti àwọn àlùfáà rẹ̀, láì ku ẹni tí ó yọ nínú ewu fún un.
Astfel Iehu a ucis pe toți câți rămăseseră din casa lui Ahab în Izreel și pe toți marii bărbați ai lui și pe rudele lui și pe preoții lui, până când nu i-a lăsat nicio rămășiță.
12 Jehu jáde lọ, ó sì lọ sí ọ̀kánkán Samaria. Ní Beti-Ekedi tí àwọn olùṣọ́-àgùntàn.
Și el s-a ridicat și a plecat și a venit la Samaria. Și pe drum, la tunzătoarea oilor,
13 Jehu pàdé díẹ̀ lára àwọn ìbátan Ahasiah ọba Juda, ó sì béèrè, “Ta ni ẹ̀yin ń ṣe?” Wọ́n wí pé, “Àwa jẹ́ ìbátan Ahasiah, àwa sì ti wá láti kí ìdílé ọba àti ti màmá ayaba.”
Iehu s-a întâlnit cu frații lui Ahazia, împăratul lui Iuda, și a spus: Cine sunteți voi? Iar ei au răspuns: Noi suntem frații lui Ahazia; și coborâm să salutăm pe copiii împăratului și pe copiii împărătesei.
14 “Mú wọn láààyè!” ó pàṣẹ. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú wọn láààyè, wọ́n sì pa wọ́n ní ẹ̀bá kọ̀nga Beti-Ekedi, ọkùnrin méjìlélógójì. Kò sì fi ẹnìkan sílẹ̀ láìkù.
Și el a spus: Prindeți-i vii. Și i-au prins vii și i-au ucis la groapa tunzătorii oilor, patruzeci și doi de oameni; nu au lăsat pe niciunul dintre ei.
15 Nígbà tí a sì jáde níbẹ̀, ó rí Jehonadabu ọmọ Rekabu ń bọ̀ wá pàdé rẹ̀, ó sì súre fún un, ó sì wí fún pé, “Ọkàn rẹ ha ṣe déédé bí ọkàn mi ti rí sí ọkàn rẹ?” Jehonadabu dáhùn wí pé, “Èmi wà.” Jehu wí pé, “Bí ó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, fún mi ní ọwọ́ ọ̀ rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe pẹ̀lú, Jehu sì fà á lọ́wọ́ sókè sọ́dọ̀ rẹ̀ nínú kẹ̀kẹ́.
Și după ce a plecat de acolo, a găsit pe Ionadab, fiul lui Recab, venind să îl întâlnească; și l-a salutat și i-a spus: Este inima ta dreaptă, precum inima mea este cu inima ta? Și Ionadab a răspuns: Este. Dacă este, dă-mi mâna ta. Și i-a dat mâna; și l-a luat la el în car.
16 Jehu wí pé, “Wá pẹ̀lú mi, kí o sì rí ìtara mi fún Olúwa.” Nígbà náà ó jẹ́ kí ó gun kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
Și el a spus: Vino cu mine și vei vedea zelul meu pentru DOMNUL. Astfel ei l-au făcut să meargă în carul său.
17 Nígbà tí Jehu wá sí Samaria, ó pa gbogbo àwọn tí a fi kalẹ̀ ní ìdílé Ahabu; ó pa wọ́n run, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí a sọ sí Elijah.
Și după ce a venit la Samaria, a ucis pe toți cei rămași lui Ahab în Samaria, până l-a nimicit, conform spusei DOMNULUI, pe care o vorbise lui Ilie.
18 Nígbà náà, Jehu kó gbogbo àwọn ènìyàn jọ, ó sì wí fún wọn pé, “Ahabu sin Baali díẹ̀; ṣùgbọ́n Jehu yóò sìn ín púpọ̀.
Și Iehu a adunat tot poporul și le-a zis: Ahab a servit puțin lui Baal; dar Iehu îi va servi mult.
19 Nísinsin yìí, ẹ pe gbogbo àwọn wòlíì Baali jọ fún mi, gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti gbogbo àlùfáà rẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọ̀kan kí ó kù, nítorí èmí yóò rú ẹbọ ńlá sí Baali. Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti wá, kò ní wà láààyè mọ́.” Ṣùgbọ́n Jehu fi ẹ̀tàn ṣe é, kí ó lè pa àwọn òjíṣẹ́ Baali run.
Și acum, chemați-mi pe toți profeții lui Baal, pe toți servitorii lui și pe toți preoții lui; să nu lipsească nimeni, pentru că am un mare sacrificiu de făcut lui Baal; oricine va lipsi nu va mai trăi. Dar Iehu a făcut aceasta cu viclenie, pentru a-i nimici pe închinătorii lui Baal.
20 Jehu wí pé, “ẹ pe àpéjọ ní ìwòyí ọ̀la fún Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kéde rẹ.
Și Iehu a spus: Proclamați o adunare solemnă pentru Baal. Și ei au proclamat-o.
21 Nígbà náà, Jehu rán ọ̀rọ̀ káàkiri Israẹli, gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali sì wá: kò sí ẹnìkan tí ó dúró lẹ́yìn. Wọ́n kún ilé tí a kọ́ fún òrìṣà títí tí ó fi kún láti ìkangun èkínní títí dé èkejì.
Și Iehu a trimis în tot Israelul; și toți închinătorii lui Baal au venit, astfel încât nu a rămas niciun om care să nu fi venit. Și au intrat în casa lui Baal; și casa lui Baal era plină de la un capăt până la altul.
22 Jehu sì sọ fún olùṣọ́ pé, “Kí ó mú aṣọ ìgúnwà wá fún gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni ó mú aṣọ ìgúnwà jáde wá fún wọn.
Și el a spus celui care era peste veștminte: Adu veștminte pentru toți închinătorii lui Baal. Iar el le-a adus veștminte.
23 Nígbà náà, Jehu àti Jehonadabu ọmọ Rekabu lọ sí inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali. Jehu sì wí fún àwọn òjíṣẹ́ Baali pé, “Wò ó yíká, kí o sì rí i pé kò sí ìránṣẹ́ Olúwa kankan pẹ̀lú yín níbí—kìkì òjíṣẹ́ Baali.”
Și Iehu și Ionadab, fiul lui Recab, au intrat în casa lui Baal, și Iehu a spus închinătorilor lui Baal: Cercetați și vedeți să nu fie aici cu voi niciunul dintre servitorii DOMNULUI, ci numai închinătorii lui Baal.
24 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wọ inú ilé lọ láti lọ rú ẹbọ àti ẹbọ sísun. Nísinsin yìí Jehu ti rán ọgọ́rin ọkùnrin sí ìta pẹ̀lú ìkìlọ̀ yìí: “Tí ẹnikẹ́ni nínú yín bá jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọkùnrin tí mo ń gbé sí ọwọ́ yín ó sálọ, yóò jẹ́ ẹ̀mí yín fún ẹ̀mí rẹ.”
Și după ce au intrat să ofere sacrificii și ofrande arse, Iehu a rânduit afară optzeci de oameni și a spus: Cine lasă pe vreunul dintre oamenii pe care i-am adus în mâinile voastre să scape, viața sa va fi pentru viața lui.
25 Ní kété tí Jehu ti parí ṣíṣe ẹbọ sísun, ó pàṣẹ fún àwọn olùṣọ́ àti àwọn ìjòyè: “Wọlé lọ, kí o sì pa wọ́n, má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kí ó sálọ.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà. Àwọn olùṣọ́ àti ìjòyè ju ara wọn síta, wọ́n sì wọ inú ojúbọ ti ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali.
Și s-a întâmplat, cum au terminat de oferit ofranda arsă, că Iehu a spus gardei și căpeteniilor: Intrați și ucideți-i, să nu iasă nimeni. Și ei i-au lovit cu ascuțișul sabiei; și garda și căpeteniile i-au aruncat afară și au mers la cetatea casei lui Baal.
26 Wọ́n gbé òkúta bíbọ náà jáde láti inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali, wọ́n sì jó o.
Și au scos chipurile din casa lui Baal și le-au ars.
27 Wọ́n fọ́ òkúta bíbọ ti Baali náà túútúú, wọ́n sì ya ilé òrìṣà Baali bolẹ̀. Àwọn ènìyàn sì ń lò ó fún ilé ìgbẹ́ títí di ọjọ́ òní.
Și au dărâmat chipul lui Baal și au dărâmat casa lui Baal și au făcut-o casă de hazna până în această zi.
28 Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa sí sin Baali run ní Israẹli.
Astfel Iehu a nimicit pe Baal din Israel.
29 Bí ó ti wù kí ó rí, Jehu kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá—ti sí sin ẹgbọrọ màlúù wúrà ní Beteli àti Dani.
Totuși Iehu nu s-a depărtat de păcatele lui Ieroboam, fiul lui Nebat, care a făcut pe Israel să păcătuiască: de la vițeii de aur care erau în Betel și care erau în Dan.
30 Olúwa sì sọ fún Jehu pé, “Nítorí ìwọ ti ṣe dáradára ní ṣíṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú mi, tí o sì ti ṣe sí ilé Ahabu gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí ó wà ní ọkàn mi, àwọn ọmọ ọ̀ rẹ yóò jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli títí dé ìran kẹrin.”
Și DOMNUL i-a spus lui Iehu: Pentru că ai împlinit bine ceea ce este drept în ochii mei și ai făcut casei lui Ahab conform cu tot ce era în inima mea, copiii tăi până la a patra generație vor ședea pe tronul lui Israel.
31 Síbẹ̀ Jehu kò ṣe pẹ̀lẹ́ láti pa òfin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli mọ́ pẹ̀lú tọkàntọkàn. Òun kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu èyí tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá.
Dar Iehu nu a fost atent să umble în legea DOMNULUI Dumnezeul lui Israel cu toată inima sa, fiindcă nu s-a depărtat de păcatele lui Ieroboam, care a făcut pe Israel să păcătuiască.
32 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Olúwa ti bẹ̀rẹ̀ sí ní dín iye Israẹli kù. Hasaeli fi agbára jẹ ọba lórí àwọn ọmọ Israẹli ní gbogbo agbègbè wọn.
În acele zile, DOMNUL a început să scurteze din Israel; și Hazael i-a lovit în toate ținuturile lui Israel;
33 Ìlà-oòrùn ti Jordani ni gbogbo ilẹ̀ ti Gileadi (ẹ̀kún ilẹ̀ ti ará Gadi, Reubeni, àti Manase) láti Aroeri, tí ó wà létí kòtò Arnoni láti ìhà Gileadi sí Baṣani.
De la Iordan spre est, toată țara Galaadului, pe gadiți și pe rubeniți și pe manasiți, de la Aroer, care este lângă râul Arnon, și Galaadul și Basanul.
34 Fún ti òmíràn ti iṣẹ́ ìjọba Jehu, gbogbo ohun tí ó ṣe, gbogbo àṣeyọrí rẹ̀, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli?
Și restul faptelor lui Iehu și tot ce a făcut și toată puterea lui, nu sunt ele scrise în cartea cronicilor împăraților lui Israel?
35 Jehu sinmi pẹ̀lú baba a rẹ̀, a sì sin ín sí Samaria Jehoahasi ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Și Iehu a adormit cu părinții săi și l-au îngropat în Samaria. Și Ioahaz, fiul său, a domnit în locul său.
36 Àkókò tí Jehu fi jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria jẹ́ ọdún méjìdínlọ́gbọ̀n.
Și timpul cât a domnit Iehu peste Israel în Samaria a fost douăzeci și opt de ani.

< 2 Kings 10 >