< 2 Kings 10 >

1 Nísinsin yìí, Ahabu ṣì ní àádọ́rin ọmọkùnrin ní ìdílé rẹ̀ ní Samaria. Bẹ́ẹ̀ ni, Jehu kọ lẹ́tà, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí Samaria: sí àwọn oníṣẹ́ Jesreeli, sí àwọn àgbàgbà àti sí àwọn olùtọ́jú àwọn ọmọ Ahabu. Ó wí pé,
Achab zaś miał siedemdziesięciu synów w Samarii. I Jehu napisał list, i wysłał [go] do Samarii do książąt Jizreel – do starszych i do tych, którzy wychowywali [synów] Achaba – ze słowami:
2 “Ní kété tí lẹ́tà bá ti dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí àwọn ọmọ ọ̀gá rẹ wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ sì ní àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹṣin, ìlú olódi kan pẹ̀lú ohun ìjà,
Jak tylko dotrze do was ten list, a są przecież z wami synowie waszego pana, macie też rydwany, konie, miasto obronne i uzbrojenie;
3 yan èyí tí ó dára àti èyí tí ó níye jùlọ nínú àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ, kí o sì gbé e lé orí ìtẹ́ baba a rẹ̀. Nígbà náà, kí o sì jà fún ilé ọ̀gá à rẹ.”
Upatrzcie sobie najlepszego i najodpowiedniejszego z synów waszego pana, posadźcie na tronie jego ojca i walczcie o dom waszego pana.
4 Ṣùgbọ́n ẹ̀rù bà wọ́n, wọ́n sì wí pé, “Tí ọba méjì kò bá le kojú ìjà sí i, báwo ni a ṣẹ le è ṣe é?”
Lecz oni bardzo się przerazili i powiedzieli: Oto dwaj królowie nie ostali się przed nim, a jakże my się ostoimy?
5 Bẹ́ẹ̀ ẹni tí ń ṣe olórí ilé, ẹni tí ń ṣe olórí ìlú ńlá, àwọn àgbàgbà àti àwọn olùtọ́jú náà rán iṣẹ́ yìí sí Jehu, pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ni àwa jẹ́ pẹ̀lú, àwa yóò ṣe ohunkóhun tí o bá sọ. Àwa kì yóò yan ẹnikẹ́ni gẹ́gẹ́ bí ọba; ìwọ ṣe ohunkóhun tí o rò pé ó dára jù lójú rẹ.”
Wtedy ten, który był [postawiony] nad domem, i ten, który był nad miastem, starsi oraz wychowawcy [synów króla] wysłali do Jehu wiadomość: Jesteśmy twoimi sługami. Uczynimy wszystko, co nam rozkażesz. Nie ustanowimy żadnego króla. Czyń, co uznasz za dobre w swoich oczach.
6 Nígbà náà ni Jehu kọ lẹ́tà kejì sí wọn, wí pé, “Tí ìwọ bá wà ní ìhà tèmi, tí o sì pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, mú orí àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ wá sí ọ̀dọ̀ mi ní Jesreeli ní ìwòyí ọ̀la.” Nísinsin yìí, àwọn ọmọ-aládé àádọ́rin ọkùnrin, ń bẹ pẹ̀lú àwọn ènìyàn ńlá ìlú náà tí ń tọ́ wọn.
I napisał do nich drugi list ze słowami: Jeśli jesteście moi i chcecie słuchać mego głosu, weźcie głowy synów waszego pana i przyjdźcie do mnie jutro o tym czasie do Jizreel. A synów królewskich było siedemdziesięciu mężczyzn, przebywających u znakomitych obywateli miasta, którzy ich wychowywali.
7 Nígbà tí ìwé náà dé ọ̀dọ̀ wọn, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí mú gbogbo àwọn ọmọ ọba tí gbogbo wọ́n jẹ́ àádọ́rin wọ́n sì pa gbogbo wọn. Wọ́n gbé orí wọn sí inú apẹ̀rẹ̀, wọ́n fi ránṣẹ́ sí Jehu ní Jesreeli.
A gdy doszedł do nich list, wzięli synów królewskich, zabili wszystkich siedemdziesięciu, włożyli ich głowy do koszy i posłali je do niego do Jizreel.
8 Nígbà tí ìránṣẹ́ náà dé, ó sọ fún Jehu, “Wọ́n ti gbé orí àwọn ọmọ ọba náà wá.” Nígbà náà Jehu pàṣẹ, “Ẹ tò wọ́n ní òkìtì méjì ní àtiwọ ẹnu ibodè ìlú ńlá títí di òwúrọ̀.”
Posłaniec przyszedł i oznajmił mu: Przyniesiono głowy synów królewskich. A [on] powiedział: Ułóżcie je w dwa stosy u wejścia bramy – aż do poranku.
9 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Jehu jáde lọ. Ó dúró níwájú gbogbo àwọn ènìyàn, ó sì wí pé, “Ẹ̀yin jẹ́ aláìjẹ̀bi. Èmi ni mo dìtẹ̀ sí ọ̀gá mi, tí mo sì pa á, ṣùgbọ́n ta ni ó pa gbogbo àwọn wọ̀nyí?
Rano zaś wyszedł, stanął i przemówił do całego ludu: Jesteście sprawiedliwi. Oto uknułem spisek przeciw swemu panu i zabiłem go, ale kto zabił tych wszystkich?
10 Nígbà yìí, kò sí ọ̀rọ̀ kan tí Olúwa ti sọ sí ilé Ahabu tí yóò kùnà. Olúwa ti ṣe ohun tí ó ṣèlérí nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ Elijah.”
Wiedzcie teraz, że nie upadnie na ziemię [nic] ze słowa PANA, które PAN wypowiedział przeciwko domowi Achaba. PAN bowiem uczynił to, co wypowiedział przez swego sługę Eliasza.
11 Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa gbogbo ẹni tí ó kù Jesreeli ní ilé Ahabu, pẹ̀lúpẹ̀lú gbogbo àwọn ọkùnrin ìjòyè rẹ̀, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tímọ́tímọ́ àti àwọn àlùfáà rẹ̀, láì ku ẹni tí ó yọ nínú ewu fún un.
Jehu więc zabił wszystkich, którzy pozostali z domu Achaba w Jizreel, wszystkich jego możnych, jego bliskich i jego kapłanów, tak że nie zostawił spośród nich żadnego przy życiu.
12 Jehu jáde lọ, ó sì lọ sí ọ̀kánkán Samaria. Ní Beti-Ekedi tí àwọn olùṣọ́-àgùntàn.
Potem wstał, odszedł i wyruszył do Samarii. Po drodze, [gdy] był w domu, gdzie pasterze strzygli owce;
13 Jehu pàdé díẹ̀ lára àwọn ìbátan Ahasiah ọba Juda, ó sì béèrè, “Ta ni ẹ̀yin ń ṣe?” Wọ́n wí pé, “Àwa jẹ́ ìbátan Ahasiah, àwa sì ti wá láti kí ìdílé ọba àti ti màmá ayaba.”
Jehu spotkał braci Achazjasza, króla Judy, i zapytał: Kim jesteście? Odpowiedzieli: Jesteśmy braćmi Achazjasza i idziemy pozdrowić synów króla i synów królowej.
14 “Mú wọn láààyè!” ó pàṣẹ. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú wọn láààyè, wọ́n sì pa wọ́n ní ẹ̀bá kọ̀nga Beti-Ekedi, ọkùnrin méjìlélógójì. Kò sì fi ẹnìkan sílẹ̀ láìkù.
Wtedy rozkazał: Pojmijcie ich żywcem. I pojmali ich żywcem, i zabili przy studni tego domu, gdzie strzyżono owce [w liczbie] czterdziestu dwóch mężczyzn. Nie oszczędził żadnego z nich.
15 Nígbà tí a sì jáde níbẹ̀, ó rí Jehonadabu ọmọ Rekabu ń bọ̀ wá pàdé rẹ̀, ó sì súre fún un, ó sì wí fún pé, “Ọkàn rẹ ha ṣe déédé bí ọkàn mi ti rí sí ọkàn rẹ?” Jehonadabu dáhùn wí pé, “Èmi wà.” Jehu wí pé, “Bí ó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, fún mi ní ọwọ́ ọ̀ rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe pẹ̀lú, Jehu sì fà á lọ́wọ́ sókè sọ́dọ̀ rẹ̀ nínú kẹ̀kẹ́.
Potem odjechał stamtąd i spotkał Jonadaba, syna Rechaba, idącego mu naprzeciw. Pozdrowił go i zapytał: Czy twoje serce jest tak szczere jak moje serce wobec twojego serca? Jonadab odpowiedział: Jest. A jeśli jest, to daj mi swoją rękę. Wtedy dał mu swą rękę i wziął go do siebie na rydwan.
16 Jehu wí pé, “Wá pẹ̀lú mi, kí o sì rí ìtara mi fún Olúwa.” Nígbà náà ó jẹ́ kí ó gun kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
Potem powiedział: Jedź ze mną i zobaczysz moją gorliwość dla PANA. I wiózł go na swoim rydwanie.
17 Nígbà tí Jehu wá sí Samaria, ó pa gbogbo àwọn tí a fi kalẹ̀ ní ìdílé Ahabu; ó pa wọ́n run, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí a sọ sí Elijah.
A gdy przyjechał do Samarii, zabił wszystkich, którzy pozostali [z domu] Achaba w Samarii, i wytracił ich według słowa PANA, które wypowiedział do Eliasza.
18 Nígbà náà, Jehu kó gbogbo àwọn ènìyàn jọ, ó sì wí fún wọn pé, “Ahabu sin Baali díẹ̀; ṣùgbọ́n Jehu yóò sìn ín púpọ̀.
Potem Jehu zebrał cały lud i powiedział do niego: Achab mało służył Baalowi, Jehu będzie mu służył bardziej.
19 Nísinsin yìí, ẹ pe gbogbo àwọn wòlíì Baali jọ fún mi, gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti gbogbo àlùfáà rẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọ̀kan kí ó kù, nítorí èmí yóò rú ẹbọ ńlá sí Baali. Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti wá, kò ní wà láààyè mọ́.” Ṣùgbọ́n Jehu fi ẹ̀tàn ṣe é, kí ó lè pa àwọn òjíṣẹ́ Baali run.
Teraz więc zwołajcie do mnie wszystkich proroków Baala, wszystkie jego sługi i wszystkich jego kapłanów, niech nikogo nie zabraknie. Złożę bowiem wielką ofiarę Baalowi. Ktokolwiek się nie stawi, nie pozostanie przy życiu. Lecz Jehu działał podstępnie, chcąc wytracić czcicieli Baala.
20 Jehu wí pé, “ẹ pe àpéjọ ní ìwòyí ọ̀la fún Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kéde rẹ.
Jehu dalej rozkazał: Ogłoście święto dla Baala. I obwołano [je].
21 Nígbà náà, Jehu rán ọ̀rọ̀ káàkiri Israẹli, gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali sì wá: kò sí ẹnìkan tí ó dúró lẹ́yìn. Wọ́n kún ilé tí a kọ́ fún òrìṣà títí tí ó fi kún láti ìkangun èkínní títí dé èkejì.
Potem Jehu rozesłał posłańców po całym Izraelu. I zeszli się wszyscy czciciele Baala, tak że nie było [spośród nich] nikogo, kto by nie przyszedł. Weszli do domu Baala i wypełnił się dom Baala od krańca aż do krańca.
22 Jehu sì sọ fún olùṣọ́ pé, “Kí ó mú aṣọ ìgúnwà wá fún gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni ó mú aṣọ ìgúnwà jáde wá fún wọn.
Następnie powiedział przełożonemu szatni: Wyłóż szaty dla wszystkich czcicieli Baala. I wyłożył dla nich szaty.
23 Nígbà náà, Jehu àti Jehonadabu ọmọ Rekabu lọ sí inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali. Jehu sì wí fún àwọn òjíṣẹ́ Baali pé, “Wò ó yíká, kí o sì rí i pé kò sí ìránṣẹ́ Olúwa kankan pẹ̀lú yín níbí—kìkì òjíṣẹ́ Baali.”
Wtedy Jehu wraz z Jonadabem, synem Rechaba, wszedł do domu Baala i powiedział czcicielom Baala: Zbadajcie i upewnijcie się, że nie ma z wami nikogo z czcicieli PANA, ale tylko czciciele Baala.
24 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wọ inú ilé lọ láti lọ rú ẹbọ àti ẹbọ sísun. Nísinsin yìí Jehu ti rán ọgọ́rin ọkùnrin sí ìta pẹ̀lú ìkìlọ̀ yìí: “Tí ẹnikẹ́ni nínú yín bá jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọkùnrin tí mo ń gbé sí ọwọ́ yín ó sálọ, yóò jẹ́ ẹ̀mí yín fún ẹ̀mí rẹ.”
Weszli więc, aby złożyć ofiary i całopalenia. Lecz Jehu postawił sobie na zewnątrz osiemdziesięciu mężczyzn, którym powiedział: Jeśli ujdzie ktokolwiek z tego ludu, który wydaję w wasze ręce, to wasze życie będzie [zapłatą] za jego życie.
25 Ní kété tí Jehu ti parí ṣíṣe ẹbọ sísun, ó pàṣẹ fún àwọn olùṣọ́ àti àwọn ìjòyè: “Wọlé lọ, kí o sì pa wọ́n, má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kí ó sálọ.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà. Àwọn olùṣọ́ àti ìjòyè ju ara wọn síta, wọ́n sì wọ inú ojúbọ ti ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali.
A gdy dokończono składanie całopalenia, Jehu powiedział żołnierzom i dowódcom: Wejdźcie i zabijajcie ich, [aby] nikt nie uszedł. Zabili więc [ich] ostrzem miecza i żołnierze i dowódcy powyrzucali ich. Potem poszli do miasta domu Baala.
26 Wọ́n gbé òkúta bíbọ náà jáde láti inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali, wọ́n sì jó o.
Wyrzucili posągi z domu Baala i spalili je.
27 Wọ́n fọ́ òkúta bíbọ ti Baali náà túútúú, wọ́n sì ya ilé òrìṣà Baali bolẹ̀. Àwọn ènìyàn sì ń lò ó fún ilé ìgbẹ́ títí di ọjọ́ òní.
Rozbili też posąg Baala, zburzyli dom Baala i uczynili z niego wychodek, [i jest tak] aż do dziś.
28 Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa sí sin Baali run ní Israẹli.
W ten sposób Jehu wytępił Baala z Izraela.
29 Bí ó ti wù kí ó rí, Jehu kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá—ti sí sin ẹgbọrọ màlúù wúrà ní Beteli àti Dani.
Nie odstąpił jednak od grzechów Jeroboama, syna Nebata, który do grzechu przywiódł Izraela – od złotych cielców, które [były] w Betel i w Dan.
30 Olúwa sì sọ fún Jehu pé, “Nítorí ìwọ ti ṣe dáradára ní ṣíṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú mi, tí o sì ti ṣe sí ilé Ahabu gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí ó wà ní ọkàn mi, àwọn ọmọ ọ̀ rẹ yóò jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli títí dé ìran kẹrin.”
Wtedy PAN powiedział do Jehu: Ponieważ dobrze postąpiłeś, wykonując to, co słuszne w moich oczach, i uczyniłeś domowi Achaba według wszystkiego, co było w moim sercu, to twoi synowie aż do czwartego pokolenia będą zasiadać na tronie Izraela.
31 Síbẹ̀ Jehu kò ṣe pẹ̀lẹ́ láti pa òfin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli mọ́ pẹ̀lú tọkàntọkàn. Òun kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu èyí tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá.
Lecz Jehu nie pilnował [tego], aby postępować z całego swego serca według prawa PANA, Boga Izraela. Nie odstąpił od grzechów Jeroboama, który przywiódł Izraela do grzechu.
32 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Olúwa ti bẹ̀rẹ̀ sí ní dín iye Israẹli kù. Hasaeli fi agbára jẹ ọba lórí àwọn ọmọ Israẹli ní gbogbo agbègbè wọn.
W tych dniach PAN zaczął umniejszać Izrael: Chazael pobił ich na całym obszarze Izraela;
33 Ìlà-oòrùn ti Jordani ni gbogbo ilẹ̀ ti Gileadi (ẹ̀kún ilẹ̀ ti ará Gadi, Reubeni, àti Manase) láti Aroeri, tí ó wà létí kòtò Arnoni láti ìhà Gileadi sí Baṣani.
Od Jordanu ku wschodowi, całą ziemię Gileadu, Gadytów, Rubenitów i Manassytów, od Aroeru, który leży nad rzeką Arnon – Gilead i Baszan.
34 Fún ti òmíràn ti iṣẹ́ ìjọba Jehu, gbogbo ohun tí ó ṣe, gbogbo àṣeyọrí rẹ̀, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli?
A pozostałe dzieje Jehu i wszystko, co czynił, cała jego potęga, czy nie są zapisane w kronikach królów Izraela?
35 Jehu sinmi pẹ̀lú baba a rẹ̀, a sì sin ín sí Samaria Jehoahasi ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
I Jehu zasnął ze swymi ojcami, i pogrzebano go w Samarii. A w jego miejsce królował jego syn Jehoachaz.
36 Àkókò tí Jehu fi jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria jẹ́ ọdún méjìdínlọ́gbọ̀n.
A czas, w którym Jehu królował nad Izraelem w Samarii, [wynosił] dwadzieścia osiem lat.

< 2 Kings 10 >