< 2 Kings 10 >

1 Nísinsin yìí, Ahabu ṣì ní àádọ́rin ọmọkùnrin ní ìdílé rẹ̀ ní Samaria. Bẹ́ẹ̀ ni, Jehu kọ lẹ́tà, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí Samaria: sí àwọn oníṣẹ́ Jesreeli, sí àwọn àgbàgbà àti sí àwọn olùtọ́jú àwọn ọmọ Ahabu. Ó wí pé,
هفتاد پسر اَخاب در سامره بودند. پس ییهو برای مقامات و بزرگان شهر و نیز سرپرستان پسران اَخاب نامه‌ای به این مضمون نوشت: «به محض رسیدن این نامه، شایسته‌ترین پسر اَخاب را انتخاب کرده، او را به پادشاهی برگزینید و برای دفاع از خاندان اَخاب آماده جنگ شوید، زیرا شما ارابه‌ها و اسبها و شهرهای حصاردار و ساز و برگ نظامی در اختیار دارید.»
2 “Ní kété tí lẹ́tà bá ti dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí àwọn ọmọ ọ̀gá rẹ wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ sì ní àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹṣin, ìlú olódi kan pẹ̀lú ohun ìjà,
3 yan èyí tí ó dára àti èyí tí ó níye jùlọ nínú àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ, kí o sì gbé e lé orí ìtẹ́ baba a rẹ̀. Nígbà náà, kí o sì jà fún ilé ọ̀gá à rẹ.”
4 Ṣùgbọ́n ẹ̀rù bà wọ́n, wọ́n sì wí pé, “Tí ọba méjì kò bá le kojú ìjà sí i, báwo ni a ṣẹ le è ṣe é?”
اما بزرگان شهر به شدت ترسیدند که این کار را انجام دهند و گفتند: «دو پادشاه از عهدهٔ این مرد برنیامدند، ما چه می‌توانیم بکنیم؟»
5 Bẹ́ẹ̀ ẹni tí ń ṣe olórí ilé, ẹni tí ń ṣe olórí ìlú ńlá, àwọn àgbàgbà àti àwọn olùtọ́jú náà rán iṣẹ́ yìí sí Jehu, pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ni àwa jẹ́ pẹ̀lú, àwa yóò ṣe ohunkóhun tí o bá sọ. Àwa kì yóò yan ẹnikẹ́ni gẹ́gẹ́ bí ọba; ìwọ ṣe ohunkóhun tí o rò pé ó dára jù lójú rẹ.”
پس رئیس دربار و رئیس شهر با بزرگان شهر و سرپرستان پسران اَخاب این پیغام را برای ییهو فرستادند: «ما خدمتگزاران تو هستیم و هر دستوری بفرمایی انجام خواهیم داد. ما کسی را پادشاه نخواهیم ساخت. هر چه در نظر داری همان را انجام بده.»
6 Nígbà náà ni Jehu kọ lẹ́tà kejì sí wọn, wí pé, “Tí ìwọ bá wà ní ìhà tèmi, tí o sì pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, mú orí àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ wá sí ọ̀dọ̀ mi ní Jesreeli ní ìwòyí ọ̀la.” Nísinsin yìí, àwọn ọmọ-aládé àádọ́rin ọkùnrin, ń bẹ pẹ̀lú àwọn ènìyàn ńlá ìlú náà tí ń tọ́ wọn.
ییهو در پاسخ آنها این پیغام را فرستاد: «اگر شما طرفدار من هستید و می‌خواهید تابع من باشید، سرهای پسران اَخاب را بریده، فردا در همین وقت آنها را برایم به یزرعیل بیاورید.» هفتاد پسر اَخاب در خانه‌های بزرگان شهر که سرپرستان ایشان بودند، زندگی می‌کردند.
7 Nígbà tí ìwé náà dé ọ̀dọ̀ wọn, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí mú gbogbo àwọn ọmọ ọba tí gbogbo wọ́n jẹ́ àádọ́rin wọ́n sì pa gbogbo wọn. Wọ́n gbé orí wọn sí inú apẹ̀rẹ̀, wọ́n fi ránṣẹ́ sí Jehu ní Jesreeli.
وقتی نامهٔ ییهو به بزرگان شهر رسید، هفتاد شاهزاده را سر بریدند و سرهای آنها را در سبد گذاشته، به یزرعیل بردند و به ییهو تقدیم کردند.
8 Nígbà tí ìránṣẹ́ náà dé, ó sọ fún Jehu, “Wọ́n ti gbé orí àwọn ọmọ ọba náà wá.” Nígbà náà Jehu pàṣẹ, “Ẹ tò wọ́n ní òkìtì méjì ní àtiwọ ẹnu ibodè ìlú ńlá títí di òwúrọ̀.”
وقتی به ییهو خبر رسید که سرهای شاهزادگان را آورده‌اند، دستور داد آنها را به دو توده تقسیم کنند و کنار دروازهٔ شهر قرار دهند و تا صبح بگذارند در آنجا بمانند.
9 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Jehu jáde lọ. Ó dúró níwájú gbogbo àwọn ènìyàn, ó sì wí pé, “Ẹ̀yin jẹ́ aláìjẹ̀bi. Èmi ni mo dìtẹ̀ sí ọ̀gá mi, tí mo sì pa á, ṣùgbọ́n ta ni ó pa gbogbo àwọn wọ̀nyí?
صبح روز بعد، ییهو بیرون رفت و به جمعیتی که کنار دروازهٔ شهر گرد آمده بودند، گفت: «این من بودم که بر ضد ارباب خود برخاستم و او را کشتم. شما در این مورد بی‌گناهید. ولی پسران او را چه کسی کشته است؟
10 Nígbà yìí, kò sí ọ̀rọ̀ kan tí Olúwa ti sọ sí ilé Ahabu tí yóò kùnà. Olúwa ti ṣe ohun tí ó ṣèlérí nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ Elijah.”
این نشان می‌دهد که هر چه خداوند دربارهٔ خاندان اَخاب فرموده، به انجام می‌رسد. خداوند آنچه را که توسط ایلیای نبی فرموده، بجا آورده است.»
11 Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa gbogbo ẹni tí ó kù Jesreeli ní ilé Ahabu, pẹ̀lúpẹ̀lú gbogbo àwọn ọkùnrin ìjòyè rẹ̀, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tímọ́tímọ́ àti àwọn àlùfáà rẹ̀, láì ku ẹni tí ó yọ nínú ewu fún un.
سپس ییهو تمام بازماندگان خاندان اَخاب را که در یزرعیل بودند، کشت. همچنین تمام افسران ارشد، دوستان نزدیک و کاهنان او را از بین برد، به طوری که هیچ‌یک از نزدیکان او باقی نماند.
12 Jehu jáde lọ, ó sì lọ sí ọ̀kánkán Samaria. Ní Beti-Ekedi tí àwọn olùṣọ́-àgùntàn.
سپس ییهو عازم سامره شد و در بین راه در محلی به نام «اردوگاه شبانان»
13 Jehu pàdé díẹ̀ lára àwọn ìbátan Ahasiah ọba Juda, ó sì béèrè, “Ta ni ẹ̀yin ń ṣe?” Wọ́n wí pé, “Àwa jẹ́ ìbátan Ahasiah, àwa sì ti wá láti kí ìdílé ọba àti ti màmá ayaba.”
به خویشاوندان اخزیا، پادشاه یهودا برخورد. ییهو از آنها پرسید: «شما کیستید؟» جواب دادند: «ما خویشاوندان اخزیای پادشاه هستیم و برای دیدن پسران اَخاب و ایزابل به سامره می‌رویم.»
14 “Mú wọn láààyè!” ó pàṣẹ. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú wọn láààyè, wọ́n sì pa wọ́n ní ẹ̀bá kọ̀nga Beti-Ekedi, ọkùnrin méjìlélógójì. Kò sì fi ẹnìkan sílẹ̀ láìkù.
ییهو به افراد خود گفت: «آنها را زنده بگیرید!» پس آنها را زنده گرفتند و همه را که بر روی هم چهل و دو نفر بودند، کنار چاهِ بِیت‌عِقِد کشتند. او کسی را زنده نگذاشت.
15 Nígbà tí a sì jáde níbẹ̀, ó rí Jehonadabu ọmọ Rekabu ń bọ̀ wá pàdé rẹ̀, ó sì súre fún un, ó sì wí fún pé, “Ọkàn rẹ ha ṣe déédé bí ọkàn mi ti rí sí ọkàn rẹ?” Jehonadabu dáhùn wí pé, “Èmi wà.” Jehu wí pé, “Bí ó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, fún mi ní ọwọ́ ọ̀ rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe pẹ̀lú, Jehu sì fà á lọ́wọ́ sókè sọ́dọ̀ rẹ̀ nínú kẹ̀kẹ́.
ییهو در ادامهٔ سفر خود به یهوناداب پسر رکاب که به استقبالش می‌آمد، برخورد. پس از احوالپرسی، ییهو از او پرسید: «آیا همان‌طور که من نسبت به تو وفادار هستم، تو هم نسبت به من وفادار هستی؟» جواب داد: «بله.» ییهو گفت: «پس دستت را به من بده.» و دست او را گرفت و بر ارابه‌اش سوار کرده،
16 Jehu wí pé, “Wá pẹ̀lú mi, kí o sì rí ìtara mi fún Olúwa.” Nígbà náà ó jẹ́ kí ó gun kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
به او گفت: «همراه من بیا و ببین چه غیرتی برای خداوند دارم.» پس یهوناداب سوار بر ارابه همراه او رفت.
17 Nígbà tí Jehu wá sí Samaria, ó pa gbogbo àwọn tí a fi kalẹ̀ ní ìdílé Ahabu; ó pa wọ́n run, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí a sọ sí Elijah.
وقتی به سامره رسیدند، ییهو تمام دوستان و بستگان اَخاب را کشت، به طوری که یک نفر هم باقی نماند و این همان بود که خداوند به ایلیای نبی گفته بود.
18 Nígbà náà, Jehu kó gbogbo àwọn ènìyàn jọ, ó sì wí fún wọn pé, “Ahabu sin Baali díẹ̀; ṣùgbọ́n Jehu yóò sìn ín púpọ̀.
آنگاه ییهو تمام اهالی شهر را جمع کرد و به ایشان گفت: «من می‌خواهم بیشتر از اَخاب بعل را بپرستم!
19 Nísinsin yìí, ẹ pe gbogbo àwọn wòlíì Baali jọ fún mi, gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti gbogbo àlùfáà rẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọ̀kan kí ó kù, nítorí èmí yóò rú ẹbọ ńlá sí Baali. Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti wá, kò ní wà láààyè mọ́.” Ṣùgbọ́n Jehu fi ẹ̀tàn ṣe é, kí ó lè pa àwọn òjíṣẹ́ Baali run.
پس تمام انبیا و کاهنان و پرستندگان بعل را جمع کنید. نگذارید حتی یک نفر غایب باشد، چون می‌خواهم قربانی بزرگی به بعل تقدیم کنم. هر کس از پرستندگان بعل در این جشن حاضر نشود، کشته خواهد شد.» (ولی ییهو می‌خواست به حیله، پرستندگان بعل را نابود کند.)
20 Jehu wí pé, “ẹ pe àpéjọ ní ìwòyí ọ̀la fún Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kéde rẹ.
ییهو به سراسر اسرائیل پیغام فرستاد که تمام کسانی که بعل را می‌پرستیدند برای عبادت او جمع شوند. همهٔ آنها آمدند و سراسر معبد بعل را پر ساختند.
21 Nígbà náà, Jehu rán ọ̀rọ̀ káàkiri Israẹli, gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali sì wá: kò sí ẹnìkan tí ó dúró lẹ́yìn. Wọ́n kún ilé tí a kọ́ fún òrìṣà títí tí ó fi kún láti ìkangun èkínní títí dé èkejì.
22 Jehu sì sọ fún olùṣọ́ pé, “Kí ó mú aṣọ ìgúnwà wá fún gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni ó mú aṣọ ìgúnwà jáde wá fún wọn.
ییهو به مسئول انبار لباس دستور داد که به هر یک از بت‌پرستان بعل لباس مخصوص بدهد.
23 Nígbà náà, Jehu àti Jehonadabu ọmọ Rekabu lọ sí inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali. Jehu sì wí fún àwọn òjíṣẹ́ Baali pé, “Wò ó yíká, kí o sì rí i pé kò sí ìránṣẹ́ Olúwa kankan pẹ̀lú yín níbí—kìkì òjíṣẹ́ Baali.”
سپس ییهو با یهوناداب (پسر رکاب) وارد معبد بعل شد و به بت‌پرستان گفت: «مواظب باشید که کسی از پرستندگان خداوند در اینجا نباشد. فقط پرستندگان بعل باید در داخل معبد باشند.»
24 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wọ inú ilé lọ láti lọ rú ẹbọ àti ẹbọ sísun. Nísinsin yìí Jehu ti rán ọgọ́rin ọkùnrin sí ìta pẹ̀lú ìkìlọ̀ yìí: “Tí ẹnikẹ́ni nínú yín bá jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọkùnrin tí mo ń gbé sí ọwọ́ yín ó sálọ, yóò jẹ́ ẹ̀mí yín fún ẹ̀mí rẹ.”
وقتی کاهنان بعل مشغول قربانی کردن شدند، ییهو هشتاد نفر از افراد ماهر خود را اطراف معبد گماشت و به آنها گفت: «اگر بگذارید یک نفر زنده خارج شود، شما را به جای آن یک نفر خواهم کشت!»
25 Ní kété tí Jehu ti parí ṣíṣe ẹbọ sísun, ó pàṣẹ fún àwọn olùṣọ́ àti àwọn ìjòyè: “Wọlé lọ, kí o sì pa wọ́n, má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kí ó sálọ.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà. Àwọn olùṣọ́ àti ìjòyè ju ara wọn síta, wọ́n sì wọ inú ojúbọ ti ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali.
وقتی آنها از قربانی کردن فارغ شدند، ییهو بیرون رفت و به سربازان و افراد خود گفت: «داخل شوید و همه را بکشید. نگذارید حتی یک نفر زنده بماند!» پس داخل شده، همه را کشتند و اجسادشان را بیرون انداختند. سپس افراد ییهو داخل محراب معبد بعل شدند
26 Wọ́n gbé òkúta bíbọ náà jáde láti inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali, wọ́n sì jó o.
و مجسمه بعل را بیرون آورده، سوزاندند.
27 Wọ́n fọ́ òkúta bíbọ ti Baali náà túútúú, wọ́n sì ya ilé òrìṣà Baali bolẹ̀. Àwọn ènìyàn sì ń lò ó fún ilé ìgbẹ́ títí di ọjọ́ òní.
آنها معبد بعل را ویران کرده، آن را به مزبله تبدیل نمودند، که تا به امروز به همان شکل باقیست.
28 Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa sí sin Baali run ní Israẹli.
به این ترتیب، ییهو تمام آثار بعل را از خاک اسرائیل محو کرد؛
29 Bí ó ti wù kí ó rí, Jehu kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá—ti sí sin ẹgbọrọ màlúù wúrà ní Beteli àti Dani.
ولی از پرستش گوساله‌های طلایی دست نکشید. این گوساله‌ها را یربعام (پسر نباط) در بیت‌ئیل و دان ساخته بود و از گناهان بزرگ وی محسوب می‌شد، زیرا تمام اسرائیل را به بت‌پرستی کشانده بود.
30 Olúwa sì sọ fún Jehu pé, “Nítorí ìwọ ti ṣe dáradára ní ṣíṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú mi, tí o sì ti ṣe sí ilé Ahabu gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí ó wà ní ọkàn mi, àwọn ọmọ ọ̀ rẹ yóò jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli títí dé ìran kẹrin.”
پس از آن، خداوند به ییهو فرمود: «تو دستور مرا اجرا کرده، مطابق میل من با خاندان اَخاب عمل نمودی؛ پس به سبب این کار خوب تو، فرزندان تو را تا چهار نسل بر تخت پادشاهی اسرائیل خواهم نشاند.»
31 Síbẹ̀ Jehu kò ṣe pẹ̀lẹ́ láti pa òfin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli mọ́ pẹ̀lú tọkàntọkàn. Òun kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu èyí tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá.
ولی ییهو با تمام دل خود از دستورهای خداوند، خدای اسرائیل اطاعت نکرد، بلکه از گناهان یربعام که اسرائیل را به گناه کشانده بود، پیروی نمود.
32 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Olúwa ti bẹ̀rẹ̀ sí ní dín iye Israẹli kù. Hasaeli fi agbára jẹ ọba lórí àwọn ọmọ Israẹli ní gbogbo agbègbè wọn.
در آن زمان، خداوند شروع به ویران کردن اسرائیل نمود. حزائیل، پادشاه سوریه، آن قسمت از سرزمین اسرائیل را که در شرق رود اردن بود، تصرف کرد. قسمت متصرف شده تا شهر عروعیر در وادی ارنون می‌رسید و شامل سرزمین جلعاد و باشان می‌شد که قبایل جاد، رئوبین و مَنَسی در آن زندگی می‌کردند.
33 Ìlà-oòrùn ti Jordani ni gbogbo ilẹ̀ ti Gileadi (ẹ̀kún ilẹ̀ ti ará Gadi, Reubeni, àti Manase) láti Aroeri, tí ó wà létí kòtò Arnoni láti ìhà Gileadi sí Baṣani.
34 Fún ti òmíràn ti iṣẹ́ ìjọba Jehu, gbogbo ohun tí ó ṣe, gbogbo àṣeyọrí rẹ̀, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli?
شرح بقیهٔ رویدادهای دوران سلطنت ییهو و کارها و فتوحات او در کتاب «تاریخ پادشاهان اسرائیل» ثبت شده است.
35 Jehu sinmi pẹ̀lú baba a rẹ̀, a sì sin ín sí Samaria Jehoahasi ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
وقتی ییهو مرد، او را در سامره دفن کردند و پسرش یهوآحاز به جای او پادشاه شد.
36 Àkókò tí Jehu fi jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria jẹ́ ọdún méjìdínlọ́gbọ̀n.
ییهو روی‌هم‌رفته بیست و هشت سال در سامره بر اسرائیل سلطنت کرد.

< 2 Kings 10 >