< 2 Kings 10 >

1 Nísinsin yìí, Ahabu ṣì ní àádọ́rin ọmọkùnrin ní ìdílé rẹ̀ ní Samaria. Bẹ́ẹ̀ ni, Jehu kọ lẹ́tà, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí Samaria: sí àwọn oníṣẹ́ Jesreeli, sí àwọn àgbàgbà àti sí àwọn olùtọ́jú àwọn ọmọ Ahabu. Ó wí pé,
Achábnak pedig hetven fia volt Sómrónban. És írt Jéhú leveleket és küldte Sómrónba Jizreél nagyjaihoz, a vénekhez és az Acháb nevelőihez, mondván:
2 “Ní kété tí lẹ́tà bá ti dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí àwọn ọmọ ọ̀gá rẹ wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ sì ní àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹṣin, ìlú olódi kan pẹ̀lú ohun ìjà,
most, amint hozzátok jut e levél – hisz nálatok vannak uratok fiai, nálatok a szekérhad és a lovak, az erősített városok és fegyverek.
3 yan èyí tí ó dára àti èyí tí ó níye jùlọ nínú àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ, kí o sì gbé e lé orí ìtẹ́ baba a rẹ̀. Nígbà náà, kí o sì jà fún ilé ọ̀gá à rẹ.”
Szemeljétek ki uratok fiai közül a legjobbat és legalkalmasabbat és tegyétek atyjának a trónjára és harcoljatok uratok házáért.
4 Ṣùgbọ́n ẹ̀rù bà wọ́n, wọ́n sì wí pé, “Tí ọba méjì kò bá le kojú ìjà sí i, báwo ni a ṣẹ le è ṣe é?”
S megfélemlettek felette nagyon és mondták: Íme a két király nem állt meg előtte, hogy álljunk hát meg mi!
5 Bẹ́ẹ̀ ẹni tí ń ṣe olórí ilé, ẹni tí ń ṣe olórí ìlú ńlá, àwọn àgbàgbà àti àwọn olùtọ́jú náà rán iṣẹ́ yìí sí Jehu, pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ni àwa jẹ́ pẹ̀lú, àwa yóò ṣe ohunkóhun tí o bá sọ. Àwa kì yóò yan ẹnikẹ́ni gẹ́gẹ́ bí ọba; ìwọ ṣe ohunkóhun tí o rò pé ó dára jù lójú rẹ.”
Küldött tehát az, aki a ház fölött volt, meg az, a ki a város fölött volt és a vének és a nevelők Jéhúhoz, mondván: Szolgáid vagyunk; mindent, a mit mondassz nekünk, megteszünk. Nem teszünk meg senkit királynak; ami jó a te szemeidben, azt tedd.
6 Nígbà náà ni Jehu kọ lẹ́tà kejì sí wọn, wí pé, “Tí ìwọ bá wà ní ìhà tèmi, tí o sì pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, mú orí àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ wá sí ọ̀dọ̀ mi ní Jesreeli ní ìwòyí ọ̀la.” Nísinsin yìí, àwọn ọmọ-aládé àádọ́rin ọkùnrin, ń bẹ pẹ̀lú àwọn ènìyàn ńlá ìlú náà tí ń tọ́ wọn.
Erre másodszor írt hozzájuk levelet, mondván: Ha ti enyéim vagytok és szavamra hallgattok, vegyétek az embereknek, uratok fiainak fejeit és jöjjetek hozzám holnap ilyenkor Jizreélbe. A királyfiak pedig, hetven ember, a város nagyjainál voltak, kik őket fölnevelték.
7 Nígbà tí ìwé náà dé ọ̀dọ̀ wọn, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí mú gbogbo àwọn ọmọ ọba tí gbogbo wọ́n jẹ́ àádọ́rin wọ́n sì pa gbogbo wọn. Wọ́n gbé orí wọn sí inú apẹ̀rẹ̀, wọ́n fi ránṣẹ́ sí Jehu ní Jesreeli.
És volt, amint hozzájuk jutott a levél, vették a királyfiakat, lemészárolták a hetven embert, kosarakba tették fejeiket és elküldték hozzá Jizreélbe.
8 Nígbà tí ìránṣẹ́ náà dé, ó sọ fún Jehu, “Wọ́n ti gbé orí àwọn ọmọ ọba náà wá.” Nígbà náà Jehu pàṣẹ, “Ẹ tò wọ́n ní òkìtì méjì ní àtiwọ ẹnu ibodè ìlú ńlá títí di òwúrọ̀.”
Megérkezett a követ és jelentette neki, mondván: Elhozták a királyfiak fejeit. Erre mondta: Tegyétek őket két rakásba a kapu bejáratán, egész reggelig!
9 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Jehu jáde lọ. Ó dúró níwájú gbogbo àwọn ènìyàn, ó sì wí pé, “Ẹ̀yin jẹ́ aláìjẹ̀bi. Èmi ni mo dìtẹ̀ sí ọ̀gá mi, tí mo sì pa á, ṣùgbọ́n ta ni ó pa gbogbo àwọn wọ̀nyí?
Volt pedig reggel, kiment, oda állt és szólt az egész néphez: Igazak vagytok! Íme én esküdtem össze uram ellen és öltem meg őt, de mindezeket ki ütötte agyon?
10 Nígbà yìí, kò sí ọ̀rọ̀ kan tí Olúwa ti sọ sí ilé Ahabu tí yóò kùnà. Olúwa ti ṣe ohun tí ó ṣèlérí nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ Elijah.”
Tudjátok meg tehát, hogy nem esik földre semmi az Örökkévaló igéjéből, melyet szólt az Örökkévaló Acháb háza felől. Az Örökkévaló ugyanis megcselekedte azt, amit szól Élijáhú, az ő szolgája által.
11 Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa gbogbo ẹni tí ó kù Jesreeli ní ilé Ahabu, pẹ̀lúpẹ̀lú gbogbo àwọn ọkùnrin ìjòyè rẹ̀, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tímọ́tímọ́ àti àwọn àlùfáà rẹ̀, láì ku ẹni tí ó yọ nínú ewu fún un.
S megölte Jéhú mindazokat, kik megmaradtak Acháb házából Jizreélben, meg mind a nagyjait, meghittjeit és papjait, míg menekülőt sem hagyott neki.
12 Jehu jáde lọ, ó sì lọ sí ọ̀kánkán Samaria. Ní Beti-Ekedi tí àwọn olùṣọ́-àgùntàn.
Fölkelt, elment és Sómrónba indult. Ő éppen a pásztorok gyülekező házánál volt az úton,
13 Jehu pàdé díẹ̀ lára àwọn ìbátan Ahasiah ọba Juda, ó sì béèrè, “Ta ni ẹ̀yin ń ṣe?” Wọ́n wí pé, “Àwa jẹ́ ìbátan Ahasiah, àwa sì ti wá láti kí ìdílé ọba àti ti màmá ayaba.”
amikor találta Jéhú Achazjáhúnak, Jehúda királyának, testvéreit. És mondta: Kik vagytok? Mondták: Achazjáhú testvérei vagyunk és lejöttünk üdvözlésére a királyfiaknak és az uralkodónő fiainak.
14 “Mú wọn láààyè!” ó pàṣẹ. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú wọn láààyè, wọ́n sì pa wọ́n ní ẹ̀bá kọ̀nga Beti-Ekedi, ọkùnrin méjìlélógójì. Kò sì fi ẹnìkan sílẹ̀ láìkù.
Erre mondta: Fogjátok meg őket elevenen! És megfogták őket elevenen és lemészárolták a gyülekező ház gödrébe, negyvenkét embert, és nem hagyott meg közülök senkit.
15 Nígbà tí a sì jáde níbẹ̀, ó rí Jehonadabu ọmọ Rekabu ń bọ̀ wá pàdé rẹ̀, ó sì súre fún un, ó sì wí fún pé, “Ọkàn rẹ ha ṣe déédé bí ọkàn mi ti rí sí ọkàn rẹ?” Jehonadabu dáhùn wí pé, “Èmi wà.” Jehu wí pé, “Bí ó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, fún mi ní ọwọ́ ọ̀ rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe pẹ̀lú, Jehu sì fà á lọ́wọ́ sókè sọ́dọ̀ rẹ̀ nínú kẹ̀kẹ́.
Elment onnan és magával szembe találta Jehónádábot, Rékháb fiát, köszöntötte őt és szólt hozzá: Van-e oly becsületes a te szíved, mint az én szívem a te szíved iránt? Jehónádáb mondta: Van! – Ha van, add kezedet! Kezét adta és ő fölemelte magához a kocsiba.
16 Jehu wí pé, “Wá pẹ̀lú mi, kí o sì rí ìtara mi fún Olúwa.” Nígbà náà ó jẹ́ kí ó gun kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
És mondta: Jer velem, és nézd buzgólkodásomat az Örökkévalóért! És vitték őt a kocsiján.
17 Nígbà tí Jehu wá sí Samaria, ó pa gbogbo àwọn tí a fi kalẹ̀ ní ìdílé Ahabu; ó pa wọ́n run, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí a sọ sí Elijah.
Erre bevonult Sómrónba és megölte mindazokat, kik megmaradtak Achábtól Sómrónban, míg el nem pusztította, az Örökkévaló szava szerint, melyet szólt Élijáhúhoz.
18 Nígbà náà, Jehu kó gbogbo àwọn ènìyàn jọ, ó sì wí fún wọn pé, “Ahabu sin Baali díẹ̀; ṣùgbọ́n Jehu yóò sìn ín púpọ̀.
Ekkor összegyűjtötte Jéhú az egész népet és szólt hozzájuk: Acháb keveset szolgálta Báalt, Jéhú majd sokat szolgálja!
19 Nísinsin yìí, ẹ pe gbogbo àwọn wòlíì Baali jọ fún mi, gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti gbogbo àlùfáà rẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọ̀kan kí ó kù, nítorí èmí yóò rú ẹbọ ńlá sí Baali. Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti wá, kò ní wà láààyè mọ́.” Ṣùgbọ́n Jehu fi ẹ̀tàn ṣe é, kí ó lè pa àwọn òjíṣẹ́ Baali run.
Most tehát mind a Báal prófétáit, mind a tisztelőit és mind a papjait hívjátok hozzám, senki se hiányozzék, mert nagy áldozást tartok a Báalnak; bárki hiányzik, nem marad életben. Jéhú pedig cselből tette, azért hogy megsemmisítse a Báal tisztelőit.
20 Jehu wí pé, “ẹ pe àpéjọ ní ìwòyí ọ̀la fún Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kéde rẹ.
És mondta Jéhú: Rendezzetek szent gyülekezést a Báal számára. És kihirdették.
21 Nígbà náà, Jehu rán ọ̀rọ̀ káàkiri Israẹli, gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali sì wá: kò sí ẹnìkan tí ó dúró lẹ́yìn. Wọ́n kún ilé tí a kọ́ fún òrìṣà títí tí ó fi kún láti ìkangun èkínní títí dé èkejì.
És küldött Jéhú egész Izraélbe; s eljöttek mind a Báal tisztelői, nem maradt senki, aki nem jött volna. Bementek a Báal házába s megtelt a Báal háza végtől végig.
22 Jehu sì sọ fún olùṣọ́ pé, “Kí ó mú aṣọ ìgúnwà wá fún gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni ó mú aṣọ ìgúnwà jáde wá fún wọn.
Ekkor mondta a ruhatár felügyelőjének: Hozz ki öltözéket mind a Báa1 tisztelőinek! És kihozta nekik az öltözetet.
23 Nígbà náà, Jehu àti Jehonadabu ọmọ Rekabu lọ sí inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali. Jehu sì wí fún àwọn òjíṣẹ́ Baali pé, “Wò ó yíká, kí o sì rí i pé kò sí ìránṣẹ́ Olúwa kankan pẹ̀lú yín níbí—kìkì òjíṣẹ́ Baali.”
És bement Jéhú, meg Jehónádáb, Rékháb fia, a Báal házába, és mondta a Báal tisztelőinek: Kutassatok és nézzétek, nehogy legyen itt veletek valaki az Örökkévaló tisztelői közül, hanem egyedül a Báal tisztelői.
24 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wọ inú ilé lọ láti lọ rú ẹbọ àti ẹbọ sísun. Nísinsin yìí Jehu ti rán ọgọ́rin ọkùnrin sí ìta pẹ̀lú ìkìlọ̀ yìí: “Tí ẹnikẹ́ni nínú yín bá jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọkùnrin tí mo ń gbé sí ọwọ́ yín ó sálọ, yóò jẹ́ ẹ̀mí yín fún ẹ̀mí rẹ.”
És bementek, hogy bemutassanak vágóáldozatokat és égőáldozatokat. Jéhú elhelyezett magának künn nyolcvan embert és mondta: Azon embernek, aki megmenekszik az emberek közül, kiket kezetekbe juttatok, lelke helyett legyen a ti lelketek.
25 Ní kété tí Jehu ti parí ṣíṣe ẹbọ sísun, ó pàṣẹ fún àwọn olùṣọ́ àti àwọn ìjòyè: “Wọlé lọ, kí o sì pa wọ́n, má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kí ó sálọ.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà. Àwọn olùṣọ́ àti ìjòyè ju ara wọn síta, wọ́n sì wọ inú ojúbọ ti ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali.
És volt, amint végzett azzal, hogy bemutassa az égőáldozatot, mondta Jéhú a futároknak és a hadnagyoknak: Jöjjetek, üssétek le őket, senki ki ne mehessen! És leütötték őket a kard élével; és oda hányták őket a futárok és a hadnagyok és mentek a Báal házának városáig.
26 Wọ́n gbé òkúta bíbọ náà jáde láti inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali, wọ́n sì jó o.
Kivitték a Báal házának szobrait és elégették.
27 Wọ́n fọ́ òkúta bíbọ ti Baali náà túútúú, wọ́n sì ya ilé òrìṣà Baali bolẹ̀. Àwọn ènìyàn sì ń lò ó fún ilé ìgbẹ́ títí di ọjọ́ òní.
És lerombolták a Báal szobrát, lerombolták a Báal házát és árnyékszékekké tették e mai napig.
28 Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa sí sin Baali run ní Israẹli.
Kipusztította tehát Jéhú a Báalt Izraélből.
29 Bí ó ti wù kí ó rí, Jehu kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá—ti sí sin ẹgbọrọ màlúù wúrà ní Beteli àti Dani.
Csak Járobeámnak, Nebát fiának vétkei, a ki vétkezésre indította Izraélt – azoktól nem tért el Jéhú: az arany borjuktól, melyek Bét-Élben és Dánban voltak.
30 Olúwa sì sọ fún Jehu pé, “Nítorí ìwọ ti ṣe dáradára ní ṣíṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú mi, tí o sì ti ṣe sí ilé Ahabu gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí ó wà ní ọkàn mi, àwọn ọmọ ọ̀ rẹ yóò jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli títí dé ìran kẹrin.”
És szólt az Örökkévaló Jéhúhoz: Mivel hogy jól cselekedtél, azt téve, ami helyes szemeimben, egészen szívem szerint bántál el Acháb házával, negyedíziglen fognak ülni utódjaid Izraél trónján.
31 Síbẹ̀ Jehu kò ṣe pẹ̀lẹ́ láti pa òfin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli mọ́ pẹ̀lú tọkàntọkàn. Òun kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu èyí tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá.
De Jéhú nem vigyázott, hogy járjon az Örökkévalónak, Izraél Istenének tana szerint egész szívével: nem tért el Járobeám vétkeitől, aki vétkezésre indította Izraélt.
32 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Olúwa ti bẹ̀rẹ̀ sí ní dín iye Israẹli kù. Hasaeli fi agbára jẹ ọba lórí àwọn ọmọ Israẹli ní gbogbo agbègbè wọn.
Azokban a napokban kezdte az Örökkévaló csonkítani Izraélt: Chazáél megverte őket Izraél egész határában.
33 Ìlà-oòrùn ti Jordani ni gbogbo ilẹ̀ ti Gileadi (ẹ̀kún ilẹ̀ ti ará Gadi, Reubeni, àti Manase) láti Aroeri, tí ó wà létí kòtò Arnoni láti ìhà Gileadi sí Baṣani.
A Jordántól napkeletre Gileád egész országát, a Gádit, Reúbénit és Menaseit, Aróértól, mely az Arnón patakjánál van, Gileádot is, Básánt is.
34 Fún ti òmíràn ti iṣẹ́ ìjọba Jehu, gbogbo ohun tí ó ṣe, gbogbo àṣeyọrí rẹ̀, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli?
Jéhú egyéb dolgai pedig és mindaz, amit tett és minden hőstette, nemde meg vannak írva Izraél királyai történetének könyvében.
35 Jehu sinmi pẹ̀lú baba a rẹ̀, a sì sin ín sí Samaria Jehoahasi ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
És feküdt Jéhú ősei mellé és eltemették őt Sómrónban. És király lett helyette fia, Jehóácház.
36 Àkókò tí Jehu fi jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria jẹ́ ọdún méjìdínlọ́gbọ̀n.
Az idő pedig, melegben uralkodott Jéhú Izraél fölött Sómrónban, huszonnyolc esztendő.

< 2 Kings 10 >