< 2 Kings 10 >

1 Nísinsin yìí, Ahabu ṣì ní àádọ́rin ọmọkùnrin ní ìdílé rẹ̀ ní Samaria. Bẹ́ẹ̀ ni, Jehu kọ lẹ́tà, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí Samaria: sí àwọn oníṣẹ́ Jesreeli, sí àwọn àgbàgbà àti sí àwọn olùtọ́jú àwọn ọmọ Ahabu. Ó wí pé,
A HE kanahiku na keiki a Ahaba ma Samaria. A kakau iho la o Iehu i na palapala, hoouna aku i Samaria, na na luna o Iezereela, na na luna kahiko, a na na kahu o na keiki a Ahaba, i ka i ana'e,
2 “Ní kété tí lẹ́tà bá ti dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí àwọn ọmọ ọ̀gá rẹ wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ sì ní àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹṣin, ìlú olódi kan pẹ̀lú ohun ìjà,
Ano, a hiki aku keia palapala io oukou la, no ka noho ana o na keiki a ko oukou haku me oukou, a ia oukou na halekaa a me na lio, a me ke kulanakauhale paa i ka papohaku, a me na mea kaua;
3 yan èyí tí ó dára àti èyí tí ó níye jùlọ nínú àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ, kí o sì gbé e lé orí ìtẹ́ baba a rẹ̀. Nígbà náà, kí o sì jà fún ilé ọ̀gá à rẹ.”
E imi aku oukou i ka mea maikai a me ka mea pono o na keiki a ko oukou haku, a e hoonoho ia ia maluna o ka nohoalii o kona makuakane, a e kaua mai no ko ka hale o ko oukou haku.
4 Ṣùgbọ́n ẹ̀rù bà wọ́n, wọ́n sì wí pé, “Tí ọba méjì kò bá le kojú ìjà sí i, báwo ni a ṣẹ le è ṣe é?”
A makau loa iho la lakou, i ae la, Aia hoi, aole i ku na'lii elua imua ona; pehea la kakou e ku ai?
5 Bẹ́ẹ̀ ẹni tí ń ṣe olórí ilé, ẹni tí ń ṣe olórí ìlú ńlá, àwọn àgbàgbà àti àwọn olùtọ́jú náà rán iṣẹ́ yìí sí Jehu, pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ni àwa jẹ́ pẹ̀lú, àwa yóò ṣe ohunkóhun tí o bá sọ. Àwa kì yóò yan ẹnikẹ́ni gẹ́gẹ́ bí ọba; ìwọ ṣe ohunkóhun tí o rò pé ó dára jù lójú rẹ.”
A o ka luna o ko ka hale, a me ka luna o ke kulanakauhale, o na lunakahiko, a me na haku, hoouna aku la lakou io Iehu la, i aku la, He poe kauwa makou nau, a e hana no makou i na mea a pau au e olelo mai ai; aole e hoaliiia kekahi; e hana oe i ka mea pono i kou manao.
6 Nígbà náà ni Jehu kọ lẹ́tà kejì sí wọn, wí pé, “Tí ìwọ bá wà ní ìhà tèmi, tí o sì pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, mú orí àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ wá sí ọ̀dọ̀ mi ní Jesreeli ní ìwòyí ọ̀la.” Nísinsin yìí, àwọn ọmọ-aládé àádọ́rin ọkùnrin, ń bẹ pẹ̀lú àwọn ènìyàn ńlá ìlú náà tí ń tọ́ wọn.
Alaila palapala hou aku la oia ia lakou, i aku la, ina no'u oukou, a e hoolohe hoi i ko'u leo, alaila, e lawe oukou i na poo o na kanaka, o na keiki a ko oukou haku, a e hele mai i o'u nei i Iezereela ma keia manawa i ka la apopo. (A o na keiki a ke alii, he kanahiku lakou e noho ana me na kanaka koikoi o ke kulanakauhale, nana lakou i hanai.)
7 Nígbà tí ìwé náà dé ọ̀dọ̀ wọn, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí mú gbogbo àwọn ọmọ ọba tí gbogbo wọ́n jẹ́ àádọ́rin wọ́n sì pa gbogbo wọn. Wọ́n gbé orí wọn sí inú apẹ̀rẹ̀, wọ́n fi ránṣẹ́ sí Jehu ní Jesreeli.
A hiki aku ka palapala io lakou la, lawe lakou i na keiki a ke alii, a pepehi iho la i na mea he kanahiku, a waiho lakou i na poo maloko o na hinai, a hoouna aku io na la ma Iezereela.
8 Nígbà tí ìránṣẹ́ náà dé, ó sọ fún Jehu, “Wọ́n ti gbé orí àwọn ọmọ ọba náà wá.” Nígbà náà Jehu pàṣẹ, “Ẹ tò wọ́n ní òkìtì méjì ní àtiwọ ẹnu ibodè ìlú ńlá títí di òwúrọ̀.”
A hele mai kekahi elele a hai aku ia ia, i aku la, Ua lawe mai lakou i na poo o na keiki a ke alii. I mai la ia, E waiho ia lakou ma na puu elua, ma kahi i komo ai i ka ipuka, a kakahiaka.
9 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Jehu jáde lọ. Ó dúró níwájú gbogbo àwọn ènìyàn, ó sì wí pé, “Ẹ̀yin jẹ́ aláìjẹ̀bi. Èmi ni mo dìtẹ̀ sí ọ̀gá mi, tí mo sì pa á, ṣùgbọ́n ta ni ó pa gbogbo àwọn wọ̀nyí?
A i kakahiaka, hele aku ia, a ku, i aku la i na kanaka a pau, Ua pono oukou: aia hoi, ua kipi aku au i kuu haku, a pepehi aku ia ia: aka, owai la ka i pepehi i keia mau mea a pau?
10 Nígbà yìí, kò sí ọ̀rọ̀ kan tí Olúwa ti sọ sí ilé Ahabu tí yóò kùnà. Olúwa ti ṣe ohun tí ó ṣèlérí nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ Elijah.”
E ike ana oukou, aole e haule i ka honua kekahi o ka olelo a Iehova i olelo mai ai no ko ka hale o Ahaba: no ka mea, ua hana mai o Iehova i ka mea ana i olelo mai ai ma o Elia la kana kauwa.
11 Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa gbogbo ẹni tí ó kù Jesreeli ní ilé Ahabu, pẹ̀lúpẹ̀lú gbogbo àwọn ọkùnrin ìjòyè rẹ̀, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tímọ́tímọ́ àti àwọn àlùfáà rẹ̀, láì ku ẹni tí ó yọ nínú ewu fún un.
A pepehi aku la o Iehu i na mea a pau i koe no ko ka hale o Ahaba ma Iezereela, a me kona poe koikoi a pau, a me kona poe hoalauna, a me kana poe kahuna, aole ia i hookoe i kekahi nona.
12 Jehu jáde lọ, ó sì lọ sí ọ̀kánkán Samaria. Ní Beti-Ekedi tí àwọn olùṣọ́-àgùntàn.
A ku ae la ia, a hele aku la a hiki i Samaria. Aia no ia ma ka hale hoopaa o na kahuhipa ma ke aia.
13 Jehu pàdé díẹ̀ lára àwọn ìbátan Ahasiah ọba Juda, ó sì béèrè, “Ta ni ẹ̀yin ń ṣe?” Wọ́n wí pé, “Àwa jẹ́ ìbátan Ahasiah, àwa sì ti wá láti kí ìdílé ọba àti ti màmá ayaba.”
A loaa ia Iehu na hoahanau o Ahazia ke alii o ka Iuda, a ninau aku la, Owai oukou? I mai la lakou, He mau hoahanau makou no Ahazia, a e iho ana makou e ike i na keiki a ke alii a me na keiki a ke aliiwahine.
14 “Mú wọn láààyè!” ó pàṣẹ. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú wọn láààyè, wọ́n sì pa wọ́n ní ẹ̀bá kọ̀nga Beti-Ekedi, ọkùnrin méjìlélógójì. Kò sì fi ẹnìkan sílẹ̀ láìkù.
I aku la, E hoopaa ola aku ia lakou: a hoopaa ola aku la na kanaka ia lakou, a luku aku la ia lakou ma ka luawai o ka hale hoopaa, he kanaha kumamalua na kanaka; aole ia i hookoe i kekahi o lakou.
15 Nígbà tí a sì jáde níbẹ̀, ó rí Jehonadabu ọmọ Rekabu ń bọ̀ wá pàdé rẹ̀, ó sì súre fún un, ó sì wí fún pé, “Ọkàn rẹ ha ṣe déédé bí ọkàn mi ti rí sí ọkàn rẹ?” Jehonadabu dáhùn wí pé, “Èmi wà.” Jehu wí pé, “Bí ó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, fún mi ní ọwọ́ ọ̀ rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe pẹ̀lú, Jehu sì fà á lọ́wọ́ sókè sọ́dọ̀ rẹ̀ nínú kẹ̀kẹ́.
A hele ia mailaila aku a loaa ia ia o Iehonadaba ke keiki a Rekaba e halawai me ia: a hoomaikai aku o Iehu ia ia, i aku la, Ua pono anei kou naau, e like me ko'u naau me kou naau? I mai la o Iehonadaba, Oia no. Ina pela, e haawi mai oe i kou lima. A haawi aku ia i kona lima, a hoee aku la ia ia ma ka halekaa me ia.
16 Jehu wí pé, “Wá pẹ̀lú mi, kí o sì rí ìtara mi fún Olúwa.” Nígbà náà ó jẹ́ kí ó gun kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
I aku la ia, E hele pu oe me au, a ike oe i kuu ikaika no Iehova. A hooholo lakou ia ia ma kona halekaa.
17 Nígbà tí Jehu wá sí Samaria, ó pa gbogbo àwọn tí a fi kalẹ̀ ní ìdílé Ahabu; ó pa wọ́n run, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí a sọ sí Elijah.
A hiki aku la ia i Samaria, pepehi aku la ia i na mea a pau i koe no Ahaba ma Samaria, a pau ia i ka lukuia, e like me ka olelo a Iehova ana i olelo mai ai ma o Elia la.
18 Nígbà náà, Jehu kó gbogbo àwọn ènìyàn jọ, ó sì wí fún wọn pé, “Ahabu sin Baali díẹ̀; ṣùgbọ́n Jehu yóò sìn ín púpọ̀.
Houluulu ae la o Iehu i na kanaka a pau, a i aku la ia lakou, Malama uuku aku o Ahaba ia Baala, e malama nui auanei o Iehu ia ia.
19 Nísinsin yìí, ẹ pe gbogbo àwọn wòlíì Baali jọ fún mi, gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti gbogbo àlùfáà rẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọ̀kan kí ó kù, nítorí èmí yóò rú ẹbọ ńlá sí Baali. Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti wá, kò ní wà láààyè mọ́.” Ṣùgbọ́n Jehu fi ẹ̀tàn ṣe é, kí ó lè pa àwọn òjíṣẹ́ Baali run.
Ano hoi, e hoakoakoa mai oukou i na kaula a pau a Baala, a me kana poe kauwa a pau, a me kana poe kahuna a pau io'u nei, mai hookoeia kekahi; no ka mea, he mohai nui ka'u no Baala; o kela mea keia mea e koe ana, aole ia e ola. Aka, hana no o Iehu me ka hoopunipuni, i luku aku ai ia i ka poe malama ia Baala.
20 Jehu wí pé, “ẹ pe àpéjọ ní ìwòyí ọ̀la fún Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kéde rẹ.
I aku la o Iehu, E hoolaa aku i ka houluulu ana no Baala. A hoolaa aku la lakou.
21 Nígbà náà, Jehu rán ọ̀rọ̀ káàkiri Israẹli, gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali sì wá: kò sí ẹnìkan tí ó dúró lẹ́yìn. Wọ́n kún ilé tí a kọ́ fún òrìṣà títí tí ó fi kún láti ìkangun èkínní títí dé èkejì.
A hoouna aku la o Iehu i ka Iseraela a puni; a hele mai na kauwa a pau a Baala, aole i koe aku kekahi i hele ole mai. A komo lakou i ka hale o Baala, a piha loa ka hale o Baala mai kela aoao a i keia aoao.
22 Jehu sì sọ fún olùṣọ́ pé, “Kí ó mú aṣọ ìgúnwà wá fún gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni ó mú aṣọ ìgúnwà jáde wá fún wọn.
I aku la ia i ka mea nana i malama ke keena lole, E lawe mai iwaho i ka lole no na kauwa a Baala. A lawe mai no ia i ka lole no lakou.
23 Nígbà náà, Jehu àti Jehonadabu ọmọ Rekabu lọ sí inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali. Jehu sì wí fún àwọn òjíṣẹ́ Baali pé, “Wò ó yíká, kí o sì rí i pé kò sí ìránṣẹ́ Olúwa kankan pẹ̀lú yín níbí—kìkì òjíṣẹ́ Baali.”
Komo aku o Iehu, a me Iehonadaba, ke keiki a Rekaba, iloko o ka hale o Baala, a i aku la i na kauwa a Baala, E nana oukou a ike, i ole maanei me oukou kekahi o na kauwa a Iehova, o na kauwa a Baala wale no.
24 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wọ inú ilé lọ láti lọ rú ẹbọ àti ẹbọ sísun. Nísinsin yìí Jehu ti rán ọgọ́rin ọkùnrin sí ìta pẹ̀lú ìkìlọ̀ yìí: “Tí ẹnikẹ́ni nínú yín bá jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọkùnrin tí mo ń gbé sí ọwọ́ yín ó sálọ, yóò jẹ́ ẹ̀mí yín fún ẹ̀mí rẹ.”
A komo aku la lakou e kaumaha aku i ka mohai, a me na mohaikuni, alaila hoonoho iho la o Iehu i na kanaka, he kanawalu mawaho, i aku la, O ka mea nana e hoopakele kekahi o na kanaka a'u i lawe mai nei iloko o ko oukou lima, o lilo no kona ola no ko ia la ola.
25 Ní kété tí Jehu ti parí ṣíṣe ẹbọ sísun, ó pàṣẹ fún àwọn olùṣọ́ àti àwọn ìjòyè: “Wọlé lọ, kí o sì pa wọ́n, má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kí ó sálọ.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà. Àwọn olùṣọ́ àti ìjòyè ju ara wọn síta, wọ́n sì wọ inú ojúbọ ti ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali.
A pau kana kaumaha ana'ku i ka mohaikuni, i aku la o Iehu i ka poe kiai, a i na luna, E komo iloko, e luku ia lakou; mai puka iwaho kekahi. A luku aku la ua poe la ia lakou me ka maka o ka pahikaua; a o ka poe kiai a me na luna hoolei aku la ia lakou, a hele aku la i ke kulanakauhale o Baala.
26 Wọ́n gbé òkúta bíbọ náà jáde láti inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali, wọ́n sì jó o.
A lawe mai lakou i na kii mawaho o ka hale o Baala, a puhi aku la i ke ahi.
27 Wọ́n fọ́ òkúta bíbọ ti Baali náà túútúú, wọ́n sì ya ilé òrìṣà Baali bolẹ̀. Àwọn ènìyàn sì ń lò ó fún ilé ìgbẹ́ títí di ọjọ́ òní.
A wawahi lakou i ke kii o Baala, a wawahi hoi i ka hale o Baala, a hoolilo lakou ia mea i hale kiona a hiki i keia la.
28 Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa sí sin Baali run ní Israẹli.
A luku aku la o Iehu ia Baala mai loko aku o ka Iseraela.
29 Bí ó ti wù kí ó rí, Jehu kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá—ti sí sin ẹgbọrọ màlúù wúrà ní Beteli àti Dani.
Aka hoi, o na hewa o Ieroboama ke keiki a Nebata, nana i hoolilo ka Iseraela i ka hewa, aole i haalele o Iehu i ka hahai ana mamuli o lakou, o na keikibipi gula ma Betela a ma Dana.
30 Olúwa sì sọ fún Jehu pé, “Nítorí ìwọ ti ṣe dáradára ní ṣíṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú mi, tí o sì ti ṣe sí ilé Ahabu gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí ó wà ní ọkàn mi, àwọn ọmọ ọ̀ rẹ yóò jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli títí dé ìran kẹrin.”
A olelo mai o Iehova ia Iehu, no ka mea, ua maikai oe i ka hana ana i ka pono ia'u, a ua hana aku oe i ko ka hale o Ahaba, e like me ka mea a pau ma ko'u naau, e noho auanei kau poe keiki maluna o ka nohoalii o ka Iseraela a hiki i ke kualua.
31 Síbẹ̀ Jehu kò ṣe pẹ̀lẹ́ láti pa òfin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli mọ́ pẹ̀lú tọkàntọkàn. Òun kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu èyí tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá.
Aka, aole o Iehu i malama i ka hele ana ma ke kanawai o Iehova ke Akua o ka Iseraela me kona naau a pau: no ka mea, aole ia i haalele i na hewa o Ieroboama, nana i hoolilo ka Iseraela i ka hewa.
32 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Olúwa ti bẹ̀rẹ̀ sí ní dín iye Israẹli kù. Hasaeli fi agbára jẹ ọba lórí àwọn ọmọ Israẹli ní gbogbo agbègbè wọn.
I kela manawa i hoomaka ai o Iehova e paipai i ka Iseraela: a luku mai la o Hazaela ia lakou ma na mokuna a pau o ka Iseraela;
33 Ìlà-oòrùn ti Jordani ni gbogbo ilẹ̀ ti Gileadi (ẹ̀kún ilẹ̀ ti ará Gadi, Reubeni, àti Manase) láti Aroeri, tí ó wà létí kòtò Arnoni láti ìhà Gileadi sí Baṣani.
Mai Ioredane, mai ka hikina o ka la, i ka aina a pau o Gileada, i ka Gada, a me ka Reubena, a me ka Manase, mai Aroera ma ke kahawai o Arenona, a hiki i Gileada a me Basana.
34 Fún ti òmíràn ti iṣẹ́ ìjọba Jehu, gbogbo ohun tí ó ṣe, gbogbo àṣeyọrí rẹ̀, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli?
A o na mea i koe a Iehu, a o na mea a pau ana i hana'i, a me kona ikaika a pau, aole anei i kakauia lakou iloko o ka buke oihanaalii a na'lii o ka Iseraela?
35 Jehu sinmi pẹ̀lú baba a rẹ̀, a sì sin ín sí Samaria Jehoahasi ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
A hiamoe iho la o Iehu me kona poe makua; a kanu lakou ia ia ma Samaria. A noho alii o Iehoahaza kana keiki ma kona wahi.
36 Àkókò tí Jehu fi jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria jẹ́ ọdún méjìdínlọ́gbọ̀n.
A o ka manawa a Iehu i alii ai maluna o ka Iseraela ma Samaria, he iwakalua na makahiki ia a me kumamawalu.

< 2 Kings 10 >