< 2 Kings 10 >

1 Nísinsin yìí, Ahabu ṣì ní àádọ́rin ọmọkùnrin ní ìdílé rẹ̀ ní Samaria. Bẹ́ẹ̀ ni, Jehu kọ lẹ́tà, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí Samaria: sí àwọn oníṣẹ́ Jesreeli, sí àwọn àgbàgbà àti sí àwọn olùtọ́jú àwọn ọmọ Ahabu. Ó wí pé,
Na rĩrĩ, Samaria kwarĩ na ariũ a nyũmba ya Ahabu mĩrongo mũgwanja. Nĩ ũndũ ũcio Jehu akĩandĩka marũa akĩmatũma Samaria kũrĩ anene a Jezireeli, na athuuri, na areri a ciana cia Ahabu, akĩmeera atĩrĩ,
2 “Ní kété tí lẹ́tà bá ti dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí àwọn ọmọ ọ̀gá rẹ wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ sì ní àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹṣin, ìlú olódi kan pẹ̀lú ohun ìjà,
“Tondũ mũrĩ na ciana cia mwathi wanyu, na ningĩ mũrĩ na ngaari cia ita na mbarathi, na itũũra inene rĩirigĩre na thingo cia hinya, o na indo cia mbaara-rĩ, marũa maya maamũkinyĩra-rĩ,
3 yan èyí tí ó dára àti èyí tí ó níye jùlọ nínú àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ, kí o sì gbé e lé orí ìtẹ́ baba a rẹ̀. Nígbà náà, kí o sì jà fún ilé ọ̀gá à rẹ.”
thuurai mũriũ ũrĩa mwega na mwagĩrĩru mũno wa mwathi wanyu, na mũmũikarĩrie gĩtĩ kĩa ũnene gĩa ithe. Mũcooke mũrũĩrĩre nyũmba ya mwathi wanyu.”
4 Ṣùgbọ́n ẹ̀rù bà wọ́n, wọ́n sì wí pé, “Tí ọba méjì kò bá le kojú ìjà sí i, báwo ni a ṣẹ le è ṣe é?”
No-o makĩmaka makiuga atĩrĩ, “Angĩkorwo athamaki eerĩ matiigana kũmũtooria-rĩ, ithuĩ twakĩhota atĩa?”
5 Bẹ́ẹ̀ ẹni tí ń ṣe olórí ilé, ẹni tí ń ṣe olórí ìlú ńlá, àwọn àgbàgbà àti àwọn olùtọ́jú náà rán iṣẹ́ yìí sí Jehu, pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ni àwa jẹ́ pẹ̀lú, àwa yóò ṣe ohunkóhun tí o bá sọ. Àwa kì yóò yan ẹnikẹ́ni gẹ́gẹ́ bí ọba; ìwọ ṣe ohunkóhun tí o rò pé ó dára jù lójú rẹ.”
Nĩ ũndũ ũcio ũrĩa warĩ mũrori wa maũndũ ma nyũmba ya ũthamaki, na mwathi wa itũũra, na athuuri, na areri a ciana magĩtũmĩra Jehu ndũmĩrĩri ĩno: “Ithuĩ tũrĩ ndungata ciaku, na nĩtũgwĩka ũrĩa wothe ũkuuga. Tũtiigũtua mũndũ o na ũmwe mũthamaki; wee ĩka o ũrĩa ũngĩona kwagĩrĩire.”
6 Nígbà náà ni Jehu kọ lẹ́tà kejì sí wọn, wí pé, “Tí ìwọ bá wà ní ìhà tèmi, tí o sì pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, mú orí àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ wá sí ọ̀dọ̀ mi ní Jesreeli ní ìwòyí ọ̀la.” Nísinsin yìí, àwọn ọmọ-aládé àádọ́rin ọkùnrin, ń bẹ pẹ̀lú àwọn ènìyàn ńlá ìlú náà tí ń tọ́ wọn.
Nake Jehu akĩmaandĩkĩra marũa ma keerĩ akĩmeera atĩrĩ, “Angĩkorwo mũrĩ mwena wakwa na nĩmũkũnjathĩkĩra, ũragai ariũ a mwathi wanyu, mũgooka na ciongo ciao gũkũ Jezireeli ihinda o ta rĩĩrĩ rũciũ.” Na rĩrĩ, ariũ a mũthamaki mĩrongo mũgwanja maarĩ na atongoria a itũũra arĩa maamareraga.
7 Nígbà tí ìwé náà dé ọ̀dọ̀ wọn, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí mú gbogbo àwọn ọmọ ọba tí gbogbo wọ́n jẹ́ àádọ́rin wọ́n sì pa gbogbo wọn. Wọ́n gbé orí wọn sí inú apẹ̀rẹ̀, wọ́n fi ránṣẹ́ sí Jehu ní Jesreeli.
Na rĩrĩa marũa maakinyire, andũ acio makĩnyiita ariũ acio mĩrongo mũgwanja a mũthamaki na makĩmooraga othe. Magĩĩkĩra ciongo ciao ikabũ-inĩ, magĩcitwarĩra Jehu o kũu Jezireeli.
8 Nígbà tí ìránṣẹ́ náà dé, ó sọ fún Jehu, “Wọ́n ti gbé orí àwọn ọmọ ọba náà wá.” Nígbà náà Jehu pàṣẹ, “Ẹ tò wọ́n ní òkìtì méjì ní àtiwọ ẹnu ibodè ìlú ńlá títí di òwúrọ̀.”
Rĩrĩa mũndũ ũrĩa watũmĩtwo aakinyire, akĩĩra Jehu atĩrĩ, “Nĩmarehe ciongo cia ciana cia mũthamaki.” Nake Jehu agĩathana, akiuga atĩrĩ, “Ciigei irũndo igĩrĩ itoonyero-inĩ rĩa itũũra o nginya rũciinĩ.”
9 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Jehu jáde lọ. Ó dúró níwájú gbogbo àwọn ènìyàn, ó sì wí pé, “Ẹ̀yin jẹ́ aláìjẹ̀bi. Èmi ni mo dìtẹ̀ sí ọ̀gá mi, tí mo sì pa á, ṣùgbọ́n ta ni ó pa gbogbo àwọn wọ̀nyí?
Rũciinĩ rũrũ rũngĩ Jehu akiumagara. Akĩrũgama mbere ya andũ othe, akiuga atĩrĩ, “Inyuĩ mũtihĩtĩtie. Niĩ nĩ niĩ ndaciirĩire ndundu ya gũũkĩrĩra mwathi wakwa na ngĩmũũraga, no nũũ ũragĩte andũ aya othe?
10 Nígbà yìí, kò sí ọ̀rọ̀ kan tí Olúwa ti sọ sí ilé Ahabu tí yóò kùnà. Olúwa ti ṣe ohun tí ó ṣèlérí nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ Elijah.”
Menyai ũũ, atĩ gũtirĩ kiugo o na kĩmwe kĩarĩtio nĩ Jehova igũrũ rĩa nyũmba ya Ahabu gĩtakahingio. Jehova ekĩte o ũrĩa oigĩte na kanua ka ndungata yake Elija.”
11 Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa gbogbo ẹni tí ó kù Jesreeli ní ilé Ahabu, pẹ̀lúpẹ̀lú gbogbo àwọn ọkùnrin ìjòyè rẹ̀, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tímọ́tímọ́ àti àwọn àlùfáà rẹ̀, láì ku ẹni tí ó yọ nínú ewu fún un.
Nĩ ũndũ ũcio Jehu akĩũraga andũ othe a nyũmba ya Ahabu arĩa maatigaire kũu Jezireeli, o ũndũ ũmwe na atongoria ake othe, na arata ake a hakuhĩ, o na athĩnjĩri-ngai ake, na gũtirĩ mũndũ wahonokire.
12 Jehu jáde lọ, ó sì lọ sí ọ̀kánkán Samaria. Ní Beti-Ekedi tí àwọn olùṣọ́-àgùntàn.
Jehu agĩcooka akiumagara, agĩthiĩ Samaria. Aakinya Bethi-Ekedi ya Arĩithi-rĩ,
13 Jehu pàdé díẹ̀ lára àwọn ìbátan Ahasiah ọba Juda, ó sì béèrè, “Ta ni ẹ̀yin ń ṣe?” Wọ́n wí pé, “Àwa jẹ́ ìbátan Ahasiah, àwa sì ti wá láti kí ìdílé ọba àti ti màmá ayaba.”
agĩtũngana na andũ amwe arĩa maatarainie na Ahazia mũthamaki wa Juda akĩmooria atĩrĩ, “Inyuĩ mũrĩ a?” Nao magĩcookia atĩrĩ, “Ithuĩ tũrĩ a nyũmba ya Ahazia, na tũũkĩte kũgeithia mbarĩ ya mũthamaki, na ya mũtumia wa mũthamaki.”
14 “Mú wọn láààyè!” ó pàṣẹ. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú wọn láààyè, wọ́n sì pa wọ́n ní ẹ̀bá kọ̀nga Beti-Ekedi, ọkùnrin méjìlélógójì. Kò sì fi ẹnìkan sílẹ̀ láìkù.
Nake agĩathana atĩrĩ, “Nĩmanyiitwo marĩ muoyo!” Nĩ ũndũ ũcio makĩmatwara marĩ muoyo makĩmooragĩra gĩthima-inĩ kĩa Bethi-Ekedi, maarĩ andũ mĩrongo ĩna na eerĩ. Gũtirĩ mũndũ o na ũmwe wahonokire.
15 Nígbà tí a sì jáde níbẹ̀, ó rí Jehonadabu ọmọ Rekabu ń bọ̀ wá pàdé rẹ̀, ó sì súre fún un, ó sì wí fún pé, “Ọkàn rẹ ha ṣe déédé bí ọkàn mi ti rí sí ọkàn rẹ?” Jehonadabu dáhùn wí pé, “Èmi wà.” Jehu wí pé, “Bí ó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, fún mi ní ọwọ́ ọ̀ rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe pẹ̀lú, Jehu sì fà á lọ́wọ́ sókè sọ́dọ̀ rẹ̀ nínú kẹ̀kẹ́.
Nake aarĩkia kuuma kũu, agĩkora Jehonadabu mũrũ wa Rekabu, o nake okĩte kũmũtũnga. Nake Jehu akĩmũgeithia, akĩmũũria atĩrĩ, “Wee ũrĩ na ũiguano na niĩ, o ta ũrĩa ndĩ na ũiguano nawe?” Nake Jehonadabu akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ĩĩ ndĩ naguo.” Nake Jehu akiuga atĩrĩ, “Kũngĩkorwo nĩ ũguo-rĩ, rehe guoko.” Nĩ ũndũ ũcio Jehonadabu agĩĩka ũguo, nake Jehu akĩmũteithĩrĩria kũhaica ngaari-inĩ ya ita.
16 Jehu wí pé, “Wá pẹ̀lú mi, kí o sì rí ìtara mi fún Olúwa.” Nígbà náà ó jẹ́ kí ó gun kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
Nake Jehu akĩmwĩra atĩrĩ, “Ũka tũthiĩ nawe ũkeonere ũrĩa ndĩĩrutanĩirie na kĩyo nĩ ũndũ wa Jehova.” Nake akĩmũkuua na ngaari yake ya ita.
17 Nígbà tí Jehu wá sí Samaria, ó pa gbogbo àwọn tí a fi kalẹ̀ ní ìdílé Ahabu; ó pa wọ́n run, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí a sọ sí Elijah.
Rĩrĩa Jehu aakinyire Samaria-rĩ, akĩũraga andũ othe a nyũmba ya Ahabu arĩa maatigaire, akĩmaniina kũringana na kiugo kĩa Jehova kĩrĩa kĩarĩtio nĩ Elija.
18 Nígbà náà, Jehu kó gbogbo àwọn ènìyàn jọ, ó sì wí fún wọn pé, “Ahabu sin Baali díẹ̀; ṣùgbọ́n Jehu yóò sìn ín púpọ̀.
Ningĩ Jehu agĩcookereria andũ othe hamwe, akĩmeera atĩrĩ, “Ahabu aatungatĩire Baali o hanini; no Jehu ekũmũtungatĩra makĩria.
19 Nísinsin yìí, ẹ pe gbogbo àwọn wòlíì Baali jọ fún mi, gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti gbogbo àlùfáà rẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọ̀kan kí ó kù, nítorí èmí yóò rú ẹbọ ńlá sí Baali. Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti wá, kò ní wà láààyè mọ́.” Ṣùgbọ́n Jehu fi ẹ̀tàn ṣe é, kí ó lè pa àwọn òjíṣẹ́ Baali run.
Na rĩrĩ, tũmanĩrai anabii othe a Baali, na atungati othe ayo, o na athĩnjĩri-ngai ayo othe. Tigĩrĩrai atĩ gũtirĩ o na ũmwe ũtarĩ ho, tondũ nĩngũrutĩra Baali igongona inene. Mũndũ wothe ũkwaga gũũka, ndegũtũũra muoyo.” Nowe Jehu ekaga ũguo arĩ na wara wa kũũraga atungati othe a Baali.
20 Jehu wí pé, “ẹ pe àpéjọ ní ìwòyí ọ̀la fún Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kéde rẹ.
Nake Jehu akiuga atĩrĩ, “Ĩtanai kĩũngano gĩa gũtĩĩithia Baali.” Nĩ ũndũ ũcio magĩkĩanĩrĩra kĩũngano kĩu.
21 Nígbà náà, Jehu rán ọ̀rọ̀ káàkiri Israẹli, gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali sì wá: kò sí ẹnìkan tí ó dúró lẹ́yìn. Wọ́n kún ilé tí a kọ́ fún òrìṣà títí tí ó fi kún láti ìkangun èkínní títí dé èkejì.
Nake agĩcooka agĩtũma ũhoro kũndũ guothe Isiraeli, nao atungati othe a Baali magĩũka; na gũtirĩ o na ũmwe watĩĩrire. Makĩgomana hekarũ-inĩ ya Baali o nginya ĩkĩiyũra kuuma mwena ũmwe nginya ũrĩa ũngĩ.
22 Jehu sì sọ fún olùṣọ́ pé, “Kí ó mú aṣọ ìgúnwà wá fún gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni ó mú aṣọ ìgúnwà jáde wá fún wọn.
Nake Jehu akĩĩra mũikaria wa harĩa nguo ciaigagwo atĩrĩ, “Rehere ndungata ciothe cia Baali nguo.” Nĩ ũndũ ũcio agĩcirehere nguo.
23 Nígbà náà, Jehu àti Jehonadabu ọmọ Rekabu lọ sí inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali. Jehu sì wí fún àwọn òjíṣẹ́ Baali pé, “Wò ó yíká, kí o sì rí i pé kò sí ìránṣẹ́ Olúwa kankan pẹ̀lú yín níbí—kìkì òjíṣẹ́ Baali.”
Hĩndĩ ĩyo Jehu na Jehonadabu mũrũ wa Rekabu magĩtoonya hekarũ ya Baali. Jehu akĩĩra ndungata cia Baali atĩrĩ, “Rorai mĩena yothe muone atĩ gũtirĩ ndungata cia Jehova irĩ haha hamwe na inyuĩ, o tiga ndungata cia Baali.”
24 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wọ inú ilé lọ láti lọ rú ẹbọ àti ẹbọ sísun. Nísinsin yìí Jehu ti rán ọgọ́rin ọkùnrin sí ìta pẹ̀lú ìkìlọ̀ yìí: “Tí ẹnikẹ́ni nínú yín bá jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọkùnrin tí mo ń gbé sí ọwọ́ yín ó sálọ, yóò jẹ́ ẹ̀mí yín fún ẹ̀mí rẹ.”
Nĩ ũndũ ũcio magĩtoonya marute magongona, na maruta ma njino. Na rĩrĩ, Jehu nĩaigĩte arũme mĩrongo ĩnana kũu nja akameera atĩrĩ: “Ũmwe wanyu angĩrekereria mũndũ wa arĩa ngũneana moko-inĩ manyu oore-rĩ, we egũkua ithenya rĩa mũndũ ũcio.”
25 Ní kété tí Jehu ti parí ṣíṣe ẹbọ sísun, ó pàṣẹ fún àwọn olùṣọ́ àti àwọn ìjòyè: “Wọlé lọ, kí o sì pa wọ́n, má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kí ó sálọ.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà. Àwọn olùṣọ́ àti ìjòyè ju ara wọn síta, wọ́n sì wọ inú ojúbọ ti ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali.
Rĩrĩa Jehu aarĩkirie kũruta igongona rĩa njino-rĩ, agĩatha arangĩri na anene ao atĩrĩ, “Toonyai thĩinĩ mũmoorage; mũtikareke mũndũ o na ũmwe wao oore.” Nĩ ũndũ ũcio makĩmooraga na hiũ cia njora. Nao arangĩri na anene ao magĩikia mĩĩrĩ yao nja, magĩcooka magĩtoonya ihooero rĩa na thĩinĩ rĩa hekarũ ya Baali.
26 Wọ́n gbé òkúta bíbọ náà jáde láti inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali, wọ́n sì jó o.
Nao makĩruta ihiga rĩrĩa rĩamũre nja ya hekarũ ya Baali na makĩrĩcina.
27 Wọ́n fọ́ òkúta bíbọ ti Baali náà túútúú, wọ́n sì ya ilé òrìṣà Baali bolẹ̀. Àwọn ènìyàn sì ń lò ó fún ilé ìgbẹ́ títí di ọjọ́ òní.
Makĩmomora ihiga rĩrĩa rĩamũre rĩa Baali, na magĩtharia hekarũ ya Baali makĩmĩtua kĩoro o na nginya ũmũthĩ.
28 Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa sí sin Baali run ní Israẹli.
Nĩ ũndũ ũcio Jehu akĩniina biũ ũhooi wa Baali thĩinĩ wa Isiraeli.
29 Bí ó ti wù kí ó rí, Jehu kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá—ti sí sin ẹgbọrọ màlúù wúrà ní Beteli àti Dani.
No rĩrĩ, ndaatiganire na mehia ma Jeroboamu mũrũ wa Nebati, marĩa aatũmire Isiraeli meehie ma kũhooya mĩhianano ya njaũ ya thahabu kũu Betheli na Dani.
30 Olúwa sì sọ fún Jehu pé, “Nítorí ìwọ ti ṣe dáradára ní ṣíṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú mi, tí o sì ti ṣe sí ilé Ahabu gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí ó wà ní ọkàn mi, àwọn ọmọ ọ̀ rẹ yóò jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli títí dé ìran kẹrin.”
Nake Jehova akĩĩra Jehu atĩrĩ, “Tondũ nĩwĩkĩte wega, ũkahingia ũrĩa kwagĩrĩire maitho-inĩ makwa, na ũgeeka nyũmba ya Ahabu ũrĩa ndaatanyĩte kũmeka-rĩ, njiaro ciaku igũtũũra ithamakagĩra Isiraeli nginya rũciaro rwa kana.”
31 Síbẹ̀ Jehu kò ṣe pẹ̀lẹ́ láti pa òfin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli mọ́ pẹ̀lú tọkàntọkàn. Òun kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu èyí tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá.
No Jehu ndaigana kũmenyerera kũiga watho wa Jehova, Ngai wa Isiraeli, na ngoro yake yothe. Ndaigana gũtigana na mehia ma Jeroboamu, marĩa atũmĩte andũ a Isiraeli mehie.
32 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Olúwa ti bẹ̀rẹ̀ sí ní dín iye Israẹli kù. Hasaeli fi agbára jẹ ọba lórí àwọn ọmọ Israẹli ní gbogbo agbègbè wọn.
Matukũ-inĩ macio, Jehova nĩambĩrĩirie kũnyiihia mĩhaka ya Isiraeli. Hazaeli nĩatooririe andũ a Isiraeli bũrũri-inĩ wao wothe
33 Ìlà-oòrùn ti Jordani ni gbogbo ilẹ̀ ti Gileadi (ẹ̀kún ilẹ̀ ti ará Gadi, Reubeni, àti Manase) láti Aroeri, tí ó wà létí kòtò Arnoni láti ìhà Gileadi sí Baṣani.
mwena wa irathĩro wa Jorodani na bũrũri-inĩ wothe wa Gileadi, (Bũrũri wa Gadi na Rubeni na Manase), kuuma Aroeri gũtwarana na mũkuru wa Arinoni, kũgerera Gileadi nginya Bashani.
34 Fún ti òmíràn ti iṣẹ́ ìjọba Jehu, gbogbo ohun tí ó ṣe, gbogbo àṣeyọrí rẹ̀, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli?
Ha ũhoro wa maũndũ marĩa mangĩ makoniĩ wathani wa Jehu-rĩ, na marĩa mothe eekire, na marĩa mothe ahingirie-rĩ, githĩ matiandĩkĩtwo ibuku-inĩ rĩa mahinda ma athamaki a Isiraeli?
35 Jehu sinmi pẹ̀lú baba a rẹ̀, a sì sin ín sí Samaria Jehoahasi ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
Nake Jehu akĩhurũka na maithe make na agĩthikwo Samaria. Nake mũriũ Jehoahazu agĩtuĩka mũthamaki ithenya rĩake.
36 Àkókò tí Jehu fi jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria jẹ́ ọdún méjìdínlọ́gbọ̀n.
Narĩo ihinda rĩrĩa Jehu aathamakĩire Isiraeli kũu Samaria rĩarĩ mĩaka mĩrongo ĩĩrĩ na ĩnana.

< 2 Kings 10 >