< 2 Kings 10 >

1 Nísinsin yìí, Ahabu ṣì ní àádọ́rin ọmọkùnrin ní ìdílé rẹ̀ ní Samaria. Bẹ́ẹ̀ ni, Jehu kọ lẹ́tà, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí Samaria: sí àwọn oníṣẹ́ Jesreeli, sí àwọn àgbàgbà àti sí àwọn olùtọ́jú àwọn ọmọ Ahabu. Ó wí pé,
Měl pak Achab sedmdesáte synů v Samaří. I napsal Jéhu list, a poslal jej do Samaří k knížatům Jezreelským, starším, a kteříž chovali syny Achabovy, s tímto poručením:
2 “Ní kété tí lẹ́tà bá ti dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí àwọn ọmọ ọ̀gá rẹ wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ sì ní àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹṣin, ìlú olódi kan pẹ̀lú ohun ìjà,
Hned jakž vás dojde list tento, poněvadž u vás jsou synové pána vašeho, jsou i vozové u vás, i koni, i město hrazené a zbroj,
3 yan èyí tí ó dára àti èyí tí ó níye jùlọ nínú àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ, kí o sì gbé e lé orí ìtẹ́ baba a rẹ̀. Nígbà náà, kí o sì jà fún ilé ọ̀gá à rẹ.”
Vybeřte nejlepšího a nejzpůsobnějšího z synů pána svého, a posaďte na stolici otce jeho, a bojujte za dům pána svého.
4 Ṣùgbọ́n ẹ̀rù bà wọ́n, wọ́n sì wí pé, “Tí ọba méjì kò bá le kojú ìjà sí i, báwo ni a ṣẹ le è ṣe é?”
Kteříž bojíce se náramně, pravili: Aj, dva králové neostáli před ním, a kterak my ostojíme?
5 Bẹ́ẹ̀ ẹni tí ń ṣe olórí ilé, ẹni tí ń ṣe olórí ìlú ńlá, àwọn àgbàgbà àti àwọn olùtọ́jú náà rán iṣẹ́ yìí sí Jehu, pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ni àwa jẹ́ pẹ̀lú, àwa yóò ṣe ohunkóhun tí o bá sọ. Àwa kì yóò yan ẹnikẹ́ni gẹ́gẹ́ bí ọba; ìwọ ṣe ohunkóhun tí o rò pé ó dára jù lójú rẹ.”
A tak poslal ten, kterýž byl ustanoven nad domem, a kterýž ustanoven byl nad městem, i starší, a kteříž chovali syny Achabovy, k Jéhu, řkouce: Služebníci tvoji jsme, a všecko, což nám rozkážeš, učiníme. Neustanovíme žádného krále; což se tobě dobře líbí, učiň.
6 Nígbà náà ni Jehu kọ lẹ́tà kejì sí wọn, wí pé, “Tí ìwọ bá wà ní ìhà tèmi, tí o sì pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, mú orí àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ wá sí ọ̀dọ̀ mi ní Jesreeli ní ìwòyí ọ̀la.” Nísinsin yìí, àwọn ọmọ-aládé àádọ́rin ọkùnrin, ń bẹ pẹ̀lú àwọn ènìyàn ńlá ìlú náà tí ń tọ́ wọn.
I napsal k nim list po druhé, řka: Jste-li moji a hlasu mého posloucháte-li, vezmouce hlavy všech synů pána svého, přiďte ke mně zítra o tomto času do Jezreel. (Synů pak králových bylo sedmdesáte mužů u nejpřednějších v městě, kteříž chovali je.)
7 Nígbà tí ìwé náà dé ọ̀dọ̀ wọn, àwọn ọkùnrin wọ̀nyí mú gbogbo àwọn ọmọ ọba tí gbogbo wọ́n jẹ́ àádọ́rin wọ́n sì pa gbogbo wọn. Wọ́n gbé orí wọn sí inú apẹ̀rẹ̀, wọ́n fi ránṣẹ́ sí Jehu ní Jesreeli.
Tedy stalo se, jakž jich došel list ten, že zjímali syny královské, a zbili sedmdesáte mužů, a vkladše hlavy jejich do košů, poslali je k němu do Jezreel.
8 Nígbà tí ìránṣẹ́ náà dé, ó sọ fún Jehu, “Wọ́n ti gbé orí àwọn ọmọ ọba náà wá.” Nígbà náà Jehu pàṣẹ, “Ẹ tò wọ́n ní òkìtì méjì ní àtiwọ ẹnu ibodè ìlú ńlá títí di òwúrọ̀.”
A přišed posel, oznámil jemu, řka: Přinesli hlavy synů královských. A on řekl: Sklaďte je na dvě hromady u vrat brány až do jitra.
9 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Jehu jáde lọ. Ó dúró níwájú gbogbo àwọn ènìyàn, ó sì wí pé, “Ẹ̀yin jẹ́ aláìjẹ̀bi. Èmi ni mo dìtẹ̀ sí ọ̀gá mi, tí mo sì pa á, ṣùgbọ́n ta ni ó pa gbogbo àwọn wọ̀nyí?
Potom ráno vyšed, postavil se a řekl všemu lidu: Spravedliví jste vy. Aj, já spuntoval jsem se proti pánu svému a zabil jsem jej; kdo by pobil tyto všecky?
10 Nígbà yìí, kò sí ọ̀rọ̀ kan tí Olúwa ti sọ sí ilé Ahabu tí yóò kùnà. Olúwa ti ṣe ohun tí ó ṣèlérí nípasẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ̀ Elijah.”
Věztež nyní, žeť nepochybilo nižádné slovo Hospodinovo, kteréž mluvil Hospodin proti domu Achabovu, ale vykonal Hospodin to, což byl mluvil skrze služebníka svého Eliáše.
11 Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa gbogbo ẹni tí ó kù Jesreeli ní ilé Ahabu, pẹ̀lúpẹ̀lú gbogbo àwọn ọkùnrin ìjòyè rẹ̀, àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tímọ́tímọ́ àti àwọn àlùfáà rẹ̀, láì ku ẹni tí ó yọ nínú ewu fún un.
A tak pobil Jéhu všecky, kteříž pozůstali z domu Achabova v Jezreel, i všecky nejpřednější jeho, i známé jeho, i kněží jeho, tak že nezůstalo z nich žádného živého.
12 Jehu jáde lọ, ó sì lọ sí ọ̀kánkán Samaria. Ní Beti-Ekedi tí àwọn olùṣọ́-àgùntàn.
Potom vstav, odebral se a jel do Samaří, a již byl v Betekedu pastýřů na cestě.
13 Jehu pàdé díẹ̀ lára àwọn ìbátan Ahasiah ọba Juda, ó sì béèrè, “Ta ni ẹ̀yin ń ṣe?” Wọ́n wí pé, “Àwa jẹ́ ìbátan Ahasiah, àwa sì ti wá láti kí ìdílé ọba àti ti màmá ayaba.”
I nalezl tam Jéhu bratří Ochoziáše, krále Judského, a řekl: Kdo jste vy? Odpověděli: Jsme bratří Ochoziášovi a jdeme, abychom pozdravili synů králových a synů královny.
14 “Mú wọn láààyè!” ó pàṣẹ. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú wọn láààyè, wọ́n sì pa wọ́n ní ẹ̀bá kọ̀nga Beti-Ekedi, ọkùnrin méjìlélógójì. Kò sì fi ẹnìkan sílẹ̀ láìkù.
Tedy řekl: Zjímejte je živé. I zjímali je živé, a pobili je u čisterny v Betekedu, čtyřidceti a dva muže, a nezůstal z nich žádný.
15 Nígbà tí a sì jáde níbẹ̀, ó rí Jehonadabu ọmọ Rekabu ń bọ̀ wá pàdé rẹ̀, ó sì súre fún un, ó sì wí fún pé, “Ọkàn rẹ ha ṣe déédé bí ọkàn mi ti rí sí ọkàn rẹ?” Jehonadabu dáhùn wí pé, “Èmi wà.” Jehu wí pé, “Bí ó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, fún mi ní ọwọ́ ọ̀ rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe pẹ̀lú, Jehu sì fà á lọ́wọ́ sókè sọ́dọ̀ rẹ̀ nínú kẹ̀kẹ́.
Potom bera se odtud, nalezl Jonadaba syna Rechabova, kterýž se s ním potkal, a pozdravil ho. I řekl jemu: Jest-liž srdce tvé přímé, jako jest srdce mé s srdcem tvým? Odpověděl Jonadab: Jest, arci jest. Řekl Jéhu: Podejž mi ruky své. I podal mu ruky své. A on kázal mu vsednouti k sobě na vůz,
16 Jehu wí pé, “Wá pẹ̀lú mi, kí o sì rí ìtara mi fún Olúwa.” Nígbà náà ó jẹ́ kí ó gun kẹ̀kẹ́ rẹ̀.
A řekl: Pojeď se mnou, a viz horlivost mou pro Hospodina. A tak vezli jej na voze jeho.
17 Nígbà tí Jehu wá sí Samaria, ó pa gbogbo àwọn tí a fi kalẹ̀ ní ìdílé Ahabu; ó pa wọ́n run, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí a sọ sí Elijah.
Když pak přijel do Samaří, pobil všecky, kteříž byli pozůstali z domu Achabova v Samaří, a vyhladil jej vedlé řeči Hospodinovy, kterouž byl mluvil k Eliášovi.
18 Nígbà náà, Jehu kó gbogbo àwọn ènìyàn jọ, ó sì wí fún wọn pé, “Ahabu sin Baali díẹ̀; ṣùgbọ́n Jehu yóò sìn ín púpọ̀.
Zatím shromáždiv Jéhu všecken lid, řekl jim: Achab málo sloužil Bálovi, Jéhu bude mu více sloužiti.
19 Nísinsin yìí, ẹ pe gbogbo àwọn wòlíì Baali jọ fún mi, gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti gbogbo àlùfáà rẹ̀, má ṣe jẹ́ kí ọ̀kan kí ó kù, nítorí èmí yóò rú ẹbọ ńlá sí Baali. Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti wá, kò ní wà láààyè mọ́.” Ṣùgbọ́n Jehu fi ẹ̀tàn ṣe é, kí ó lè pa àwọn òjíṣẹ́ Baali run.
Protož nyní všecky proroky Bálovy, všecky služebníky jeho, a všecky kněží jeho svolejte ke mně, ať žádný tam nezůstává; nebo velikou obět budu obětovati Bálovi. Kdož by koli nebyl přítomen, nezůstane živ. Ale Jéhu činil to chytře, aby vyhladil ctitele Bálovy.
20 Jehu wí pé, “ẹ pe àpéjọ ní ìwòyí ọ̀la fún Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kéde rẹ.
Řekl také Jéhu: Zasvěťte svátek Bálovi. I prohlásili jej.
21 Nígbà náà, Jehu rán ọ̀rọ̀ káàkiri Israẹli, gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali sì wá: kò sí ẹnìkan tí ó dúró lẹ́yìn. Wọ́n kún ilé tí a kọ́ fún òrìṣà títí tí ó fi kún láti ìkangun èkínní títí dé èkejì.
Rozeslal zajisté Jéhu po vší zemi Izraelské. I sešli se všickni ctitelé Bálovi, tak že nezůstalo ani jednoho, ješto by nepřišel. A když vešli do domu Bálova, naplněn jest dům Bálův, od jednoho konce až do druhého.
22 Jehu sì sọ fún olùṣọ́ pé, “Kí ó mú aṣọ ìgúnwà wá fún gbogbo àwọn òjíṣẹ́ Baali.” Bẹ́ẹ̀ ni ó mú aṣọ ìgúnwà jáde wá fún wọn.
Tedy řekl tomu, kterýž vládl rouchem: Vynes roucha všechněm ctitelům Bálovým. I přinesl jim roucha.
23 Nígbà náà, Jehu àti Jehonadabu ọmọ Rekabu lọ sí inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali. Jehu sì wí fún àwọn òjíṣẹ́ Baali pé, “Wò ó yíká, kí o sì rí i pé kò sí ìránṣẹ́ Olúwa kankan pẹ̀lú yín níbí—kìkì òjíṣẹ́ Baali.”
Potom všel i Jéhu a Jonadab syn Rechabův do domu Bálova, a řekl ctitelům Bálovým: Vyhledejte a vizte, ať není zde s vámi někdo z ctitelů Hospodinových, kromě samých ctitelů Bálových.
24 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wọ inú ilé lọ láti lọ rú ẹbọ àti ẹbọ sísun. Nísinsin yìí Jehu ti rán ọgọ́rin ọkùnrin sí ìta pẹ̀lú ìkìlọ̀ yìí: “Tí ẹnikẹ́ni nínú yín bá jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọkùnrin tí mo ń gbé sí ọwọ́ yín ó sálọ, yóò jẹ́ ẹ̀mí yín fún ẹ̀mí rẹ.”
A tak vešli, aby obětovali oběti a zápaly. Jéhu pak postavil sobě vně osmdesáte mužů, jimž byl řekl: Jestliže kdo uteče z lidí těch, kteréž já uvozuji vám v ruce vaše, život váš za život jeho.
25 Ní kété tí Jehu ti parí ṣíṣe ẹbọ sísun, ó pàṣẹ fún àwọn olùṣọ́ àti àwọn ìjòyè: “Wọlé lọ, kí o sì pa wọ́n, má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kí ó sálọ.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà. Àwọn olùṣọ́ àti ìjòyè ju ara wọn síta, wọ́n sì wọ inú ojúbọ ti ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali.
I stalo se, když kněz dokonal obětování zápalu, řekl Jéhu drabantům a hejtmanům: Vejdětež a zbíte je, ať žádný neuchází. Kteřížto pobili je ostrostí meče, a rozmetali těla jejich drabanti a hejtmané. Potom šli dále do každého města, kdež byl dům Bálův,
26 Wọ́n gbé òkúta bíbọ náà jáde láti inú ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali, wọ́n sì jó o.
A vymítajíce modly z domu Bálova, pálili je.
27 Wọ́n fọ́ òkúta bíbọ ti Baali náà túútúú, wọ́n sì ya ilé òrìṣà Baali bolẹ̀. Àwọn ènìyàn sì ń lò ó fún ilé ìgbẹ́ títí di ọjọ́ òní.
Zkazili také modlu Bálovu, a zbořivše dům jeho, nadělali z něho záchodů až do dnešního dne.
28 Bẹ́ẹ̀ ni Jehu pa sí sin Baali run ní Israẹli.
A tak vyplénil Jéhu Bále z lidu Izraelského.
29 Bí ó ti wù kí ó rí, Jehu kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá—ti sí sin ẹgbọrọ màlúù wúrà ní Beteli àti Dani.
A však proto od hříchů Jeroboáma syna Nebatova, kterýž přivedl k hřešení Izraele, neodstoupil Jéhu, totiž od těch telat zlatých, kteráž byla v Bethel a v Dan.
30 Olúwa sì sọ fún Jehu pé, “Nítorí ìwọ ti ṣe dáradára ní ṣíṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú mi, tí o sì ti ṣe sí ilé Ahabu gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí ó wà ní ọkàn mi, àwọn ọmọ ọ̀ rẹ yóò jókòó lórí ìtẹ́ Israẹli títí dé ìran kẹrin.”
Tedy řekl Hospodin Jéhu: Poněvadž jsi snažně vykonal to, což dobrého jest před očima mýma, a všecky věci, kteréž jsem měl v srdci svém, učinil jsi domu Achabovu, synové tvoji až do čtvrtého pokolení seděti budou na stolici Izraelské.
31 Síbẹ̀ Jehu kò ṣe pẹ̀lẹ́ láti pa òfin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli mọ́ pẹ̀lú tọkàntọkàn. Òun kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu èyí tí ó ṣokùnfà Israẹli láti dá.
Ale Jéhu nebyl toho pilen, aby chodil v zákoně Hospodina, Boha Izraelského, celým srdcem svým, aniž odstoupil od hříchů Jeroboáma, kterýž byl uvedl v hříchy lid Izraelský.
32 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Olúwa ti bẹ̀rẹ̀ sí ní dín iye Israẹli kù. Hasaeli fi agbára jẹ ọba lórí àwọn ọmọ Israẹli ní gbogbo agbègbè wọn.
Za těch dnů počal Hospodin zmenšovati Izraele; nebo je porazil Hazael po všech končinách Izraelských,
33 Ìlà-oòrùn ti Jordani ni gbogbo ilẹ̀ ti Gileadi (ẹ̀kún ilẹ̀ ti ará Gadi, Reubeni, àti Manase) láti Aroeri, tí ó wà létí kòtò Arnoni láti ìhà Gileadi sí Baṣani.
Od Jordánu, proti východu slunce, všecku zemi Galád, Gádovu a Rubenovu i Manassesovu, od Aroer, kteréž jest při potoku Arnon, tak Galád jako Bázan.
34 Fún ti òmíràn ti iṣẹ́ ìjọba Jehu, gbogbo ohun tí ó ṣe, gbogbo àṣeyọrí rẹ̀, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Israẹli?
O jiných věcech Jéhu, a cožkoli činil, i o vší síle jeho, sepsáno jest v knize o králích Izraelských.
35 Jehu sinmi pẹ̀lú baba a rẹ̀, a sì sin ín sí Samaria Jehoahasi ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
I usnul Jéhu s otci svými, a pochovali jej v Samaří, a kraloval Joachaz syn jeho místo něho.
36 Àkókò tí Jehu fi jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria jẹ́ ọdún méjìdínlọ́gbọ̀n.
Dnů pak, v nichž kraloval Jéhu nad lidem Izraelským v Samaří, bylo let osmmecítma.

< 2 Kings 10 >